< Numbers 13 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Yahweh said to Moses/me,
2 “Rán ènìyàn díẹ̀ láti lọ yẹ ilẹ̀ Kenaani wò èyí tí mo ti fún àwọn ọmọ Israẹli. Rán ẹnìkọ̀ọ̀kan, tí ó jẹ́ olórí láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan.”
“Send some men to Canaan [land] to explore it. That is the land that I will give to you Israelis. Send men who are leaders in their tribes.”
3 Mose sì rán wọn jáde láti aginjù Parani gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa. Gbogbo wọn jẹ́ olórí àwọn ènìyàn Israẹli.
So Moses/I did what Yahweh commanded him/me. He/I sent out twelve Israeli men who were all leaders of their tribes. He/I sent them from their/our camp at Paran in the desert.
4 Orúkọ wọn nìwọ̀nyí: láti inú ẹ̀yà Reubeni, Ṣammua ọmọ Sakkuri;
These are the names of the men [and the tribes they belonged to: ] Shammua, the son of Zaccur, from the tribe of Reuben;
5 láti inú ẹ̀yà Simeoni, Ṣafati ọmọ Hori;
Shaphat, the son of Hori, from the tribe of Simeon;
6 láti inú ẹ̀yà Juda, Kalebu ọmọ Jefunne;
Caleb, the son of Jephunneh, from the tribe of Judah;
7 láti inú ẹ̀yà Isakari, Igali ọmọ Josẹfu;
Igal, the son of Joseph, from the tribe of Issachar;
8 láti inú ẹ̀yà Efraimu, Hosea ọmọ Nuni;
Hoshea, the son of Nun, from the tribe of Ephraim;
9 láti inú ẹ̀yà Benjamini, Palti ọmọ Rafu;
Palti, the son of Raphu, from the tribe of Benjamin;
10 láti inú ẹ̀yà Sebuluni, Daddieli ọmọ Sodi;
Gaddiel, the son of Sodi, from the tribe of Zebulun;
11 láti inú ẹ̀yà Manase (ẹ̀yà Josẹfu), Gaddi ọmọ Susi;
Gaddi, the son of Susi, from the tribe of Manasseh;
12 láti inú ẹ̀yà Dani, Ammieli ọmọ Gemalli;
Ammiel, the son of Gemalli, from the tribe of Dan;
13 láti inú ẹ̀yà Aṣeri, Seturu ọmọ Mikaeli.
Sethur, the son of Michael, from the tribe of Asher;
14 láti inú ẹ̀yà Naftali, Nabi ọmọ Fofsi;
Nahbi, the son of Vophsi, from the tribe of Naphtali;
15 láti inú ẹ̀yà Gadi, Geueli ọmọ Maki.
and Geuel, the son of Maki, from the tribe of Gad.
16 Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ènìyàn tí Mose rán láti lọ yẹ ilẹ̀ náà wò. (Hosea ọmọ Nuni ni Mose sọ ní Joṣua.)
Those are the names of the men whom Moses/I sent out to explore Canaan. [Before they left], Moses/I gave Hoshea a new name, Joshua, [which means ‘Yahweh is the one who saves].’
17 Nígbà tí Mose rán wọn lọ láti yẹ ilẹ̀ Kenaani wò, ó sọ fún wọn pé, “Ẹ gba ọ̀nà gúúsù lọ títí dé àwọn ìlú olókè.
Before Moses/I sent them to explore Canaan, he/I said to them, “Go through the southern part of Canaan, and then go [north] into the hilly area.
18 Ẹ wò ó bí ilẹ̀ náà ti rí, bóyá àwọn tó ń gbé ilẹ̀ náà jẹ́ alágbára tàbí aláìlágbára, bóyá wọ́n pọ̀ tàbí wọn kéré.
See what the land is like. See if the people who live there are strong or weak. See if there are many people or only a few people.
19 Irú ilẹ̀ wo ni wọ́n gbé? Ṣé ilẹ̀ tó dára ni àbí èyí tí kò dára? Báwo ni ìlú wọn ti rí? Ṣé ìlú olódi ni àbí èyí tí kò ní odi?
Find out what kind of land they live in [RHQ]. Is it good or bad? Find out about the towns in which they live [RHQ]. Do they have walls around them or not?
20 Báwo ni ilẹ̀ náà ti rí? Ṣé ilẹ̀ ọlọ́ràá ni tàbí aṣálẹ̀? Ṣé igi wà níbẹ̀ àbí kò sí? E sa ipá yín láti rí i pé ẹ mú díẹ̀ nínú èso ilẹ̀ náà wá.” (Ìgbà náà sì jẹ́ àkókò àkọ́pọ́n èso àjàrà gireepu.)
Find out about the soil [RHQ]. Is it (fertile/good for growing crops) or not? Find out if there are trees there [RHQ]. Try to bring back some of the fruit that grows in that land.” [He/I said that because] it was the beginning of the time to harvest grapes.
21 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gòkè lọ láti yẹ ilẹ̀ náà wò, wọ́n lọ láti aginjù Sini títí dé Rehobu lọ́nà Lebo-Hamati.
So those men went to Canaan. They went [through the entire land], from the Zin desert [in the south] all the way to Rehob [town] near Lebo-Hamath [in the north].
22 Wọ́n gba gúúsù lọ sí Hebroni níbi tí Ahimani, Ṣeṣai àti Talmai tí í ṣe irú-ọmọ Anaki ń gbé. (A ti kọ́ Hebroni ní ọdún méje ṣáájú Ṣoani ní Ejibiti.)
In the south, they went to Hebron, where Ahiman, Sheshai, and Talmai, [huge men] descended from Anak, lived. Hebron was a city that was built seven years before Zoan [city] was built in Egypt.
23 Nígbà tí wọ́n dé àfonífojì Eṣkolu, wọ́n gé ẹ̀ka kan tó ní ìdì èso àjàrà gireepu kan. Àwọn méjì sì fi ọ̀pá kan gbé e; wọ́n tún mú èso pomegiranate àti èso ọ̀pọ̀tọ́ pẹ̀lú.
In one valley, they cut from a grapevine one cluster of grapes. [Because it was very large, they needed] two men to carry it on a pole. They also picked some pomegranates and some figs [to carry back to their camp].
24 Wọ́n sì sọ ibẹ̀ ní àfonífojì Eṣkolu nítorí ìdì èso gireepu tí àwọn ọmọ Israẹli gé níbẹ̀.
They called that place Eshcol [which means ‘cluster’] because they had cut that [huge] cluster of grapes there.
25 Wọ́n padà sílé lẹ́yìn ogójì ọjọ́ tí wọ́n ti lọ yẹ ilẹ̀ náà wò.
After they explored the land for 40 days, they returned to their camp.
26 Wọ́n padà wá bá Mose àti Aaroni àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ní ijù Kadeṣi Parani. Wọ́n mú ìròyìn wá fún wọn àti fún gbogbo ìjọ ènìyàn, wọ́n fi èso ilẹ̀ náà hàn wọ́n.
They came to Aaron and Moses/me and the rest of the Israeli people in the desert at Paran. They reported to everyone what they had seen. They also showed them the fruit that they had brought back.
27 Wọ́n sì fún Mose ní ìròyìn báyìí, “A lọ sí ilẹ̀ ibi tí o rán wa, lóòtítọ́ ló sì ń sàn fún wàrà àti fún oyin! Èso ibẹ̀ nìyìí.
But this is what they reported to Moses/me: “We arrived in the land that you sent us to explore. It is truly a beautiful land, and it is very fertile [IDM]. Here is some of the fruit.
28 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn tó ń gbé níbẹ̀ lágbára, àwọn ìlú náà jẹ́ ìlú olódi bẹ́ẹ̀ ni ó sì tóbi púpọ̀. A tilẹ̀ rí àwọn irú-ọmọ Anaki níbẹ̀.
But the people who live there are very strong. Their cities are large and are surrounded by walls. We even saw some of the [huge] descendants of Anak there.
29 Àwọn Amaleki ń gbé ní ìhà gúúsù; àwọn ará Hiti, àwọn ará Jebusi àti àwọn ará Amori ni wọ́n ń gbé ní orí òkè ilẹ̀ náà, àwọn ará Kenaani sì ń gbé ẹ̀bá òkun àti ní etí bèbè Jordani.”
The descendants of Amalek live in the southern part [of the land], and the descendants of Heth, Jebus, and Amor live in the hilly area [to the north]. The descendants of Canaan live along the coast of the [Mediterranean] sea and along the Jordan [River].”
30 Kalebu sì pa àwọn ènìyàn náà lẹ́nu mọ́ níwájú Mose, ó wí pé, “Ẹ jẹ́ kí á gòkè lọ lẹ́ẹ̀kan náà láti lọ gba ilẹ̀ náà, nítorí pé àwa le è gbà á.”
[When they said that, the people were afraid and started to cry out very loudly]. But Caleb told the people who were standing near Moses/me to be quiet. Then he said, “We should go there and take the land, because we are certainly able to conquer it!”
31 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin tí wọ́n jọ gòkè lọ yẹ ilẹ̀ wò sọ pé, “Àwa kò le gòkè lọ bá àwọn ènìyàn wọ̀nyí nítorí pé wọ́n lágbára jù wá lọ.”
But the men who had gone with him said, “No, we cannot attack [and defeat] those people! They are much stronger than we are!”
32 Báyìí ni wọ́n ṣe mú ìròyìn búburú ti ilẹ̀ náà, tí wọ́n lọ yọ́wò wá fún àwọn ọmọ Israẹli. Wọ́n wí pé, “Ilẹ̀ tí a lọ yẹ̀ wò jẹ́ ilẹ̀ tí ń run àwọn olùgbé ibẹ̀. Gbogbo àwọn ènìyàn tí a rí níbẹ̀ jẹ́ ènìyàn tó fìrìgbọ̀n tó sì síngbọnlẹ̀.
So those men gave to the Israeli people a bad report about the land that they had explored. They said, “The land that we explored is very large; we cannot conquer it. And all the people whom we saw are very tall.
33 A sì tún rí àwọn òmíràn (irú àwọn ọmọ Anaki) àwa sì rí bí i kòkòrò tata ní ojú ara wa, bẹ́ẹ̀ ni àwa náà sì rí ní ojú wọn.”
We even saw the descendants of Nephili there. The descendants of Anak [whom we saw there] are descended from the giant Nephili people. When we saw them, we felt [as small] as grasshoppers [SIM], and they thought that we looked like grasshoppers too!”

< Numbers 13 >