< Numbers 13 >
Then spake Yahweh unto Moses, saying:
2 “Rán ènìyàn díẹ̀ láti lọ yẹ ilẹ̀ Kenaani wò èyí tí mo ti fún àwọn ọmọ Israẹli. Rán ẹnìkọ̀ọ̀kan, tí ó jẹ́ olórí láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan.”
Send for thee men and let them spy out the land of Canaan, which I am giving unto the sons of Israel, —one man each for the tribe of his fathers, shalt thou send, each one a prince among them.
3 Mose sì rán wọn jáde láti aginjù Parani gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa. Gbogbo wọn jẹ́ olórí àwọn ènìyàn Israẹli.
So then Moses sent them out of the desert of Paran, at the bidding of Yahweh, —all of them, great men, heads of the sons of Israel, were they.
4 Orúkọ wọn nìwọ̀nyí: láti inú ẹ̀yà Reubeni, Ṣammua ọmọ Sakkuri;
And, these, are their names, —Of the tribe of Reuben, Shammua, son of Zaccur;
5 láti inú ẹ̀yà Simeoni, Ṣafati ọmọ Hori;
Of the tribe of Simeon, Shaphat, son of Hori;
6 láti inú ẹ̀yà Juda, Kalebu ọmọ Jefunne;
Of the tribe of Judah, Caleb, son of Jephunneh;
7 láti inú ẹ̀yà Isakari, Igali ọmọ Josẹfu;
Of the tribe of Issachar, Igal, son of Joseph;
8 láti inú ẹ̀yà Efraimu, Hosea ọmọ Nuni;
Of the tribe of Ephraim, Hoshea, son of Nun;
9 láti inú ẹ̀yà Benjamini, Palti ọmọ Rafu;
Of the tribe of Benjamin, Palti, son of Raphu;
10 láti inú ẹ̀yà Sebuluni, Daddieli ọmọ Sodi;
Of the tribe of Zebulun, Gaddiel, son of Sodi;
11 láti inú ẹ̀yà Manase (ẹ̀yà Josẹfu), Gaddi ọmọ Susi;
Of the tribe of Joseph—of the tribe of Manasseh, Gaddi son of Susi;
12 láti inú ẹ̀yà Dani, Ammieli ọmọ Gemalli;
Of the tribe of Dan, Ammiel, son of Gemalli;
13 láti inú ẹ̀yà Aṣeri, Seturu ọmọ Mikaeli.
Of the tribe of Asher, Sethur, son of Michael;
14 láti inú ẹ̀yà Naftali, Nabi ọmọ Fofsi;
Of the tribe of Naphtali, Nahbi, son of Vophsi;
15 láti inú ẹ̀yà Gadi, Geueli ọmọ Maki.
Of the tribe of Gad, Geuel, son of Machi.
16 Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ènìyàn tí Mose rán láti lọ yẹ ilẹ̀ náà wò. (Hosea ọmọ Nuni ni Mose sọ ní Joṣua.)
These, are the names of the men, whom Moses sent to spy out the land, —but Moses called Hoshea son of Nun, Joshua.
17 Nígbà tí Mose rán wọn lọ láti yẹ ilẹ̀ Kenaani wò, ó sọ fún wọn pé, “Ẹ gba ọ̀nà gúúsù lọ títí dé àwọn ìlú olókè.
So Moses sent them, to spy out the land of Canaan, —and said unto them—Go up, here in the South, Yea ye shall go up the mountain;
18 Ẹ wò ó bí ilẹ̀ náà ti rí, bóyá àwọn tó ń gbé ilẹ̀ náà jẹ́ alágbára tàbí aláìlágbára, bóyá wọ́n pọ̀ tàbí wọn kéré.
And shall see the land, what it is, —And the people that dwell thereupon, Whether they are, strong, or weak, Whether they are, few or many;
19 Irú ilẹ̀ wo ni wọ́n gbé? Ṣé ilẹ̀ tó dára ni àbí èyí tí kò dára? Báwo ni ìlú wọn ti rí? Ṣé ìlú olódi ni àbí èyí tí kò ní odi?
And what, the land, is, wherein they dwell, Whether it is, good, or, bad, —And the cities within which they dwell, Whether in camps or in strongholds;
20 Báwo ni ilẹ̀ náà ti rí? Ṣé ilẹ̀ ọlọ́ràá ni tàbí aṣálẹ̀? Ṣé igi wà níbẹ̀ àbí kò sí? E sa ipá yín láti rí i pé ẹ mú díẹ̀ nínú èso ilẹ̀ náà wá.” (Ìgbà náà sì jẹ́ àkókò àkọ́pọ́n èso àjàrà gireepu.)
And what the land is, Whether, fat, or, lean, Whether there is timber therein or is not, Then shall ye pluck up courage and take of the fruit of the land. Now the days, were the days of the first-fruits of grapes.
21 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gòkè lọ láti yẹ ilẹ̀ náà wò, wọ́n lọ láti aginjù Sini títí dé Rehobu lọ́nà Lebo-Hamati.
So they went up, and spied out the land, —from the wilderness of Zin unto Rehob at the entering in of Hamath.
22 Wọ́n gba gúúsù lọ sí Hebroni níbi tí Ahimani, Ṣeṣai àti Talmai tí í ṣe irú-ọmọ Anaki ń gbé. (A ti kọ́ Hebroni ní ọdún méje ṣáájú Ṣoani ní Ejibiti.)
Yea they went up in the South and entered as far as Hebron, and there, were Ahiman Sheshai and Talmai descendants of the Anak. Now, Hebron, was built seven years, before Zoan of Egypt.
23 Nígbà tí wọ́n dé àfonífojì Eṣkolu, wọ́n gé ẹ̀ka kan tó ní ìdì èso àjàrà gireepu kan. Àwọn méjì sì fi ọ̀pá kan gbé e; wọ́n tún mú èso pomegiranate àti èso ọ̀pọ̀tọ́ pẹ̀lú.
And they entered as far as the ravine of Eschol, and cut down, from thence a branch with one cluster of grapes, and bare it on a pole between two, —also of the pomegranates and of the figs.
24 Wọ́n sì sọ ibẹ̀ ní àfonífojì Eṣkolu nítorí ìdì èso gireepu tí àwọn ọmọ Israẹli gé níbẹ̀.
That place, was called, The Ravine of Eschol ["Cluster-ravine"]—on account of the cluster, which was cut down from thence by the sons of Israel.
25 Wọ́n padà sílé lẹ́yìn ogójì ọjọ́ tí wọ́n ti lọ yẹ ilẹ̀ náà wò.
And they returned from spying out the land, —at the end of forty days.
26 Wọ́n padà wá bá Mose àti Aaroni àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ní ijù Kadeṣi Parani. Wọ́n mú ìròyìn wá fún wọn àti fún gbogbo ìjọ ènìyàn, wọ́n fi èso ilẹ̀ náà hàn wọ́n.
So they took their journey, and came in unto Moses and unto Aaron and unto all the assembly of the sons of Israel into the wilderness of Paran, towards Kadesh, —and brought back word—unto them and unto all the assembly, and showed them the fruit of the land.
27 Wọ́n sì fún Mose ní ìròyìn báyìí, “A lọ sí ilẹ̀ ibi tí o rán wa, lóòtítọ́ ló sì ń sàn fún wàrà àti fún oyin! Èso ibẹ̀ nìyìí.
And they recounted unto him, and said, We entered into the land whither thou didst send us, and surely it doth flow with milk and honey, and, this, is the fruit thereof.
28 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn tó ń gbé níbẹ̀ lágbára, àwọn ìlú náà jẹ́ ìlú olódi bẹ́ẹ̀ ni ó sì tóbi púpọ̀. A tilẹ̀ rí àwọn irú-ọmọ Anaki níbẹ̀.
Nevertheless surely mighty, are the people that dwell in the land, —and, the cities, walled in, exceeding great, moreover also, the descendants of the Anak, saw we there.
29 Àwọn Amaleki ń gbé ní ìhà gúúsù; àwọn ará Hiti, àwọn ará Jebusi àti àwọn ará Amori ni wọ́n ń gbé ní orí òkè ilẹ̀ náà, àwọn ará Kenaani sì ń gbé ẹ̀bá òkun àti ní etí bèbè Jordani.”
Amalek, dwelleth in the land of the South; And, the Hittite, and the Jebusite and the Amorite, dwell in the mountain And the Canaanite, dwelleth by the sea, and by the side of the Jordan.
30 Kalebu sì pa àwọn ènìyàn náà lẹ́nu mọ́ níwájú Mose, ó wí pé, “Ẹ jẹ́ kí á gòkè lọ lẹ́ẹ̀kan náà láti lọ gba ilẹ̀ náà, nítorí pé àwa le è gbà á.”
And Caleb stilled the people unto Moses, —and said unto them—Let us go straight up, and possess it, for we shall, surely prevail, against it.
31 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin tí wọ́n jọ gòkè lọ yẹ ilẹ̀ wò sọ pé, “Àwa kò le gòkè lọ bá àwọn ènìyàn wọ̀nyí nítorí pé wọ́n lágbára jù wá lọ.”
But the men who went up with him said, We cannot go up against the people, —for stronger, are they than we.
32 Báyìí ni wọ́n ṣe mú ìròyìn búburú ti ilẹ̀ náà, tí wọ́n lọ yọ́wò wá fún àwọn ọmọ Israẹli. Wọ́n wí pé, “Ilẹ̀ tí a lọ yẹ̀ wò jẹ́ ilẹ̀ tí ń run àwọn olùgbé ibẹ̀. Gbogbo àwọn ènìyàn tí a rí níbẹ̀ jẹ́ ènìyàn tó fìrìgbọ̀n tó sì síngbọnlẹ̀.
So they sent forth a rumour of the land which they had spied out, among the sons of Israel, saying, —As touching the land through which we passed to spy it out, it is, land that eateth up them who dwell therein, And all the people that we saw in the midst thereof, were men of great stature.
33 A sì tún rí àwọn òmíràn (irú àwọn ọmọ Anaki) àwa sì rí bí i kòkòrò tata ní ojú ara wa, bẹ́ẹ̀ ni àwa náà sì rí ní ojú wọn.”
And, there, saw we the giants, sons of Anak [descended] of the giants, —And we were in our own eyes, as grass-hoppers, And, so, were we in their eyes.