< Numbers 13 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
The Lord told Moses,
2 “Rán ènìyàn díẹ̀ láti lọ yẹ ilẹ̀ Kenaani wò èyí tí mo ti fún àwọn ọmọ Israẹli. Rán ẹnìkọ̀ọ̀kan, tí ó jẹ́ olórí láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan.”
“Send some men to explore the land of Canaan, the country I'm giving to the Israelites. Choose one of the leaders from each of the tribes to go and do this.”
3 Mose sì rán wọn jáde láti aginjù Parani gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa. Gbogbo wọn jẹ́ olórí àwọn ènìyàn Israẹli.
Moses did as the Lord had ordered and sent the men out from the Desert of Paran. They were all leaders of the Israelites.
4 Orúkọ wọn nìwọ̀nyí: láti inú ẹ̀yà Reubeni, Ṣammua ọmọ Sakkuri;
Their names were: Shammua son of Zaccur, from the tribe of Reuben.
5 láti inú ẹ̀yà Simeoni, Ṣafati ọmọ Hori;
Shaphat, son of Hori, from the tribe of Simeon.
6 láti inú ẹ̀yà Juda, Kalebu ọmọ Jefunne;
Caleb, son of Jephunneh, from the tribe of Judah.
7 láti inú ẹ̀yà Isakari, Igali ọmọ Josẹfu;
Igal, son of Joseph, from the tribe of Issachar.
8 láti inú ẹ̀yà Efraimu, Hosea ọmọ Nuni;
Hoshea, son of Nun, from the tribe of Ephraim.
9 láti inú ẹ̀yà Benjamini, Palti ọmọ Rafu;
Palti son of Raphu, from the tribe of Benjamin.
10 láti inú ẹ̀yà Sebuluni, Daddieli ọmọ Sodi;
Gaddiel, son of Sodi, from the tribe of Zebulun.
11 láti inú ẹ̀yà Manase (ẹ̀yà Josẹfu), Gaddi ọmọ Susi;
Gaddi, son of Susi, from the tribe of Manasseh (a tribe of Joseph).
12 láti inú ẹ̀yà Dani, Ammieli ọmọ Gemalli;
Ammiel, son of Gemalli, from the tribe of Dan.
13 láti inú ẹ̀yà Aṣeri, Seturu ọmọ Mikaeli.
Sethur, son of Michael, from the tribe of Asher.
14 láti inú ẹ̀yà Naftali, Nabi ọmọ Fofsi;
Nahbi, son of Vophsi, from the tribe of Naphtali.
15 láti inú ẹ̀yà Gadi, Geueli ọmọ Maki.
Geuel, son of Machi, from the tribe of Gad.
16 Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ènìyàn tí Mose rán láti lọ yẹ ilẹ̀ náà wò. (Hosea ọmọ Nuni ni Mose sọ ní Joṣua.)
These were the names of the men that Moses sent to explore the country. Moses called Hoshea Joshua.
17 Nígbà tí Mose rán wọn lọ láti yẹ ilẹ̀ Kenaani wò, ó sọ fún wọn pé, “Ẹ gba ọ̀nà gúúsù lọ títí dé àwọn ìlú olókè.
Moses sent them out to explore the land of Canaan, telling them, “Go through the Negev and on into the hill country.
18 Ẹ wò ó bí ilẹ̀ náà ti rí, bóyá àwọn tó ń gbé ilẹ̀ náà jẹ́ alágbára tàbí aláìlágbára, bóyá wọ́n pọ̀ tàbí wọn kéré.
See what the place looks like, and find out about the people living there—are they strong or weak? Are there many of them or only a few?
19 Irú ilẹ̀ wo ni wọ́n gbé? Ṣé ilẹ̀ tó dára ni àbí èyí tí kò dára? Báwo ni ìlú wọn ti rí? Ṣé ìlú olódi ni àbí èyí tí kò ní odi?
Is the land where they're living good or bad? Are their towns like open camps, or do they have defensive walls?
20 Báwo ni ilẹ̀ náà ti rí? Ṣé ilẹ̀ ọlọ́ràá ni tàbí aṣálẹ̀? Ṣé igi wà níbẹ̀ àbí kò sí? E sa ipá yín láti rí i pé ẹ mú díẹ̀ nínú èso ilẹ̀ náà wá.” (Ìgbà náà sì jẹ́ àkókò àkọ́pọ́n èso àjàrà gireepu.)
Is the soil productive or not? Is it forested? Be brave, and bring back some of the country's fruit.” (It was the beginning of the grape harvest.)
21 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gòkè lọ láti yẹ ilẹ̀ náà wò, wọ́n lọ láti aginjù Sini títí dé Rehobu lọ́nà Lebo-Hamati.
So the men went and explored the land all the way from the Desert of Zin to Rehob, bear Lebo-hamath.
22 Wọ́n gba gúúsù lọ sí Hebroni níbi tí Ahimani, Ṣeṣai àti Talmai tí í ṣe irú-ọmọ Anaki ń gbé. (A ti kọ́ Hebroni ní ọdún méje ṣáájú Ṣoani ní Ejibiti.)
They went through the Negev and arrived in Hebron where Ahiman, Sheshai, and Talmai, the descendants of Anak, lived. This town was built seven years before the Egyptian town of Zoan.
23 Nígbà tí wọ́n dé àfonífojì Eṣkolu, wọ́n gé ẹ̀ka kan tó ní ìdì èso àjàrà gireepu kan. Àwọn méjì sì fi ọ̀pá kan gbé e; wọ́n tún mú èso pomegiranate àti èso ọ̀pọ̀tọ́ pẹ̀lú.
When they arrived at the Valley of Eshcol they chopped down a branch that had just one bunch of grapes. They had to carry it on a pole held between two men. They also collected some pomegranates and figs.
24 Wọ́n sì sọ ibẹ̀ ní àfonífojì Eṣkolu nítorí ìdì èso gireepu tí àwọn ọmọ Israẹli gé níbẹ̀.
(The place was named the Valley of Eshcol because of the bunch of grapes they took from there.)
25 Wọ́n padà sílé lẹ́yìn ogójì ọjọ́ tí wọ́n ti lọ yẹ ilẹ̀ náà wò.
Forty days later the men returned from exploring the country.
26 Wọ́n padà wá bá Mose àti Aaroni àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ní ijù Kadeṣi Parani. Wọ́n mú ìròyìn wá fún wọn àti fún gbogbo ìjọ ènìyàn, wọ́n fi èso ilẹ̀ náà hàn wọ́n.
They went to see Moses and Aaron, and all the Israelites gathered there at their camp in Kadesh in the Desert of Paran. They gave a report before everyone and showed them the fruit they had brought back from the country.
27 Wọ́n sì fún Mose ní ìròyìn báyìí, “A lọ sí ilẹ̀ ibi tí o rán wa, lóòtítọ́ ló sì ń sàn fún wàrà àti fún oyin! Èso ibẹ̀ nìyìí.
This is the report they gave to Moses: “We went and explored the country you sent us to, and it is definitely very productive, as if it was flowing with milk and honey. Just look at some of its fruit!
28 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn tó ń gbé níbẹ̀ lágbára, àwọn ìlú náà jẹ́ ìlú olódi bẹ́ẹ̀ ni ó sì tóbi púpọ̀. A tilẹ̀ rí àwọn irú-ọmọ Anaki níbẹ̀.
But the people living there are strong, and their towns are big and have defensive walls. We also saw some descendants of Anak there.
29 Àwọn Amaleki ń gbé ní ìhà gúúsù; àwọn ará Hiti, àwọn ará Jebusi àti àwọn ará Amori ni wọ́n ń gbé ní orí òkè ilẹ̀ náà, àwọn ará Kenaani sì ń gbé ẹ̀bá òkun àti ní etí bèbè Jordani.”
The Amalekites live in the Negev. The Hittites, Jebusites, and the Amorites live in the hill country. The Canaanites live on the sea coast and also beside the Jordan.”
30 Kalebu sì pa àwọn ènìyàn náà lẹ́nu mọ́ níwájú Mose, ó wí pé, “Ẹ jẹ́ kí á gòkè lọ lẹ́ẹ̀kan náà láti lọ gba ilẹ̀ náà, nítorí pé àwa le è gbà á.”
Then Caleb asked for quiet as the people stood before Moses and told them, “Let's go and take over the land. We can conquer the country, no doubt about it!”
31 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin tí wọ́n jọ gòkè lọ yẹ ilẹ̀ wò sọ pé, “Àwa kò le gòkè lọ bá àwọn ènìyàn wọ̀nyí nítorí pé wọ́n lágbára jù wá lọ.”
But the men who had gone with him disagreed. “We can't go and fight these people! They're much stronger than us!”
32 Báyìí ni wọ́n ṣe mú ìròyìn búburú ti ilẹ̀ náà, tí wọ́n lọ yọ́wò wá fún àwọn ọmọ Israẹli. Wọ́n wí pé, “Ilẹ̀ tí a lọ yẹ̀ wò jẹ́ ilẹ̀ tí ń run àwọn olùgbé ibẹ̀. Gbogbo àwọn ènìyàn tí a rí níbẹ̀ jẹ́ ènìyàn tó fìrìgbọ̀n tó sì síngbọnlẹ̀.
They spread a negative report among the Israelites about the country they had explored. They told people, “The country we explored destroys the people that live there. Plus everyone we saw was really big!
33 A sì tún rí àwọn òmíràn (irú àwọn ọmọ Anaki) àwa sì rí bí i kòkòrò tata ní ojú ara wa, bẹ́ẹ̀ ni àwa náà sì rí ní ojú wọn.”
We even saw giants there—people descended from Anak the giant! Compared to them we looked like grasshoppers, and we must have looked like that to them too!”

< Numbers 13 >