< Numbers 13 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
And Jehovah spoke to Moses, saying,
2 “Rán ènìyàn díẹ̀ láti lọ yẹ ilẹ̀ Kenaani wò èyí tí mo ti fún àwọn ọmọ Israẹli. Rán ẹnìkọ̀ọ̀kan, tí ó jẹ́ olórí láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan.”
Send thou men, that they may search out the land of Canaan, which I give unto the children of Israel. Ye shall send a man of every tribe of his fathers, each a prince among them.
3 Mose sì rán wọn jáde láti aginjù Parani gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa. Gbogbo wọn jẹ́ olórí àwọn ènìyàn Israẹli.
And Moses sent them from the wilderness of Paran: according to the commandment of Jehovah, all of them heads of the children of Israel.
4 Orúkọ wọn nìwọ̀nyí: láti inú ẹ̀yà Reubeni, Ṣammua ọmọ Sakkuri;
And these are their names: for the tribe of Reuben, Shammua the son of Zaccur;
5 láti inú ẹ̀yà Simeoni, Ṣafati ọmọ Hori;
for the tribe of Simeon, Shaphat the son of Hori;
6 láti inú ẹ̀yà Juda, Kalebu ọmọ Jefunne;
for the tribe of Judah, Caleb the son of Jephunneh;
7 láti inú ẹ̀yà Isakari, Igali ọmọ Josẹfu;
for the tribe of Issachar, Igal the son of Joseph;
8 láti inú ẹ̀yà Efraimu, Hosea ọmọ Nuni;
for the tribe of Ephraim, Hoshea the son of Nun;
9 láti inú ẹ̀yà Benjamini, Palti ọmọ Rafu;
for the tribe of Benjamin, Palti the son of Raphu;
10 láti inú ẹ̀yà Sebuluni, Daddieli ọmọ Sodi;
for the tribe of Zebulun, Gaddiel the son of Sodi;
11 láti inú ẹ̀yà Manase (ẹ̀yà Josẹfu), Gaddi ọmọ Susi;
for the tribe of Joseph, for the tribe of Manasseh, Gaddi the son of Susi;
12 láti inú ẹ̀yà Dani, Ammieli ọmọ Gemalli;
for the tribe of Dan, Ammiel the son of Gemalli;
13 láti inú ẹ̀yà Aṣeri, Seturu ọmọ Mikaeli.
for the tribe of Asher, Sethur the son of Michael;
14 láti inú ẹ̀yà Naftali, Nabi ọmọ Fofsi;
for the tribe of Naphtali, Nahbi the son of Vophsi;
15 láti inú ẹ̀yà Gadi, Geueli ọmọ Maki.
for the tribe of Gad, Geuel the son of Machi.
16 Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ènìyàn tí Mose rán láti lọ yẹ ilẹ̀ náà wò. (Hosea ọmọ Nuni ni Mose sọ ní Joṣua.)
These are the names of the men whom Moses sent to search out the land. And Moses called Hoshea the son of Nun, Jehoshua.
17 Nígbà tí Mose rán wọn lọ láti yẹ ilẹ̀ Kenaani wò, ó sọ fún wọn pé, “Ẹ gba ọ̀nà gúúsù lọ títí dé àwọn ìlú olókè.
And Moses sent them to search out the land of Canaan, and said to them, Go up this way by the south and go up into the hill-country,
18 Ẹ wò ó bí ilẹ̀ náà ti rí, bóyá àwọn tó ń gbé ilẹ̀ náà jẹ́ alágbára tàbí aláìlágbára, bóyá wọ́n pọ̀ tàbí wọn kéré.
and ye shall see the land, what it is; and the people that dwell in it, whether they are strong or weak, few or many;
19 Irú ilẹ̀ wo ni wọ́n gbé? Ṣé ilẹ̀ tó dára ni àbí èyí tí kò dára? Báwo ni ìlú wọn ti rí? Ṣé ìlú olódi ni àbí èyí tí kò ní odi?
and what the land is that they dwell in, whether it is good or bad; and what cities they are that they dwell in, whether in camps, or in strongholds;
20 Báwo ni ilẹ̀ náà ti rí? Ṣé ilẹ̀ ọlọ́ràá ni tàbí aṣálẹ̀? Ṣé igi wà níbẹ̀ àbí kò sí? E sa ipá yín láti rí i pé ẹ mú díẹ̀ nínú èso ilẹ̀ náà wá.” (Ìgbà náà sì jẹ́ àkókò àkọ́pọ́n èso àjàrà gireepu.)
and what the land is, whether it is fat or lean, whether there are trees in it, or not. And take courage, and bring of the fruit of the land. Now the time was the time of the first grapes.
21 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gòkè lọ láti yẹ ilẹ̀ náà wò, wọ́n lọ láti aginjù Sini títí dé Rehobu lọ́nà Lebo-Hamati.
And they went up, and searched out the land from the wilderness of Zin to Rehob, where one comes towards Hamath.
22 Wọ́n gba gúúsù lọ sí Hebroni níbi tí Ahimani, Ṣeṣai àti Talmai tí í ṣe irú-ọmọ Anaki ń gbé. (A ti kọ́ Hebroni ní ọdún méje ṣáájú Ṣoani ní Ejibiti.)
And they went up by the south, and came to Hebron; and Ahiman, Sheshai, and Talmai, the children of Anak, were there. Now Hebron had been built seven years before Zoan in Egypt.
23 Nígbà tí wọ́n dé àfonífojì Eṣkolu, wọ́n gé ẹ̀ka kan tó ní ìdì èso àjàrà gireepu kan. Àwọn méjì sì fi ọ̀pá kan gbé e; wọ́n tún mú èso pomegiranate àti èso ọ̀pọ̀tọ́ pẹ̀lú.
And they came as far as the valley of Eshcol, and cut down thence a branch with one bunch of grapes, and they bore it between two upon a pole; and [they brought] of the pomegranates, and of the figs.
24 Wọ́n sì sọ ibẹ̀ ní àfonífojì Eṣkolu nítorí ìdì èso gireepu tí àwọn ọmọ Israẹli gé níbẹ̀.
That place was called the valley of Eshcol, because of the grapes which the children of Israel had cut down there.
25 Wọ́n padà sílé lẹ́yìn ogójì ọjọ́ tí wọ́n ti lọ yẹ ilẹ̀ náà wò.
And they returned from searching out the land after forty days.
26 Wọ́n padà wá bá Mose àti Aaroni àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ní ijù Kadeṣi Parani. Wọ́n mú ìròyìn wá fún wọn àti fún gbogbo ìjọ ènìyàn, wọ́n fi èso ilẹ̀ náà hàn wọ́n.
And they came, and went to Moses and to Aaron, and to the whole assembly of the children of Israel, to the wilderness of Paran, to Kadesh; and brought back word to them, and to the whole assembly; and shewed them the fruit of the land.
27 Wọ́n sì fún Mose ní ìròyìn báyìí, “A lọ sí ilẹ̀ ibi tí o rán wa, lóòtítọ́ ló sì ń sàn fún wàrà àti fún oyin! Èso ibẹ̀ nìyìí.
And they told him, and said, We came to the land to which thou didst send us, and surely it floweth with milk and honey; and this is the fruit of it.
28 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn tó ń gbé níbẹ̀ lágbára, àwọn ìlú náà jẹ́ ìlú olódi bẹ́ẹ̀ ni ó sì tóbi púpọ̀. A tilẹ̀ rí àwọn irú-ọmọ Anaki níbẹ̀.
Only, the people are strong that dwell in the land, and the cities are walled, very great; moreover we saw the children of Anak there.
29 Àwọn Amaleki ń gbé ní ìhà gúúsù; àwọn ará Hiti, àwọn ará Jebusi àti àwọn ará Amori ni wọ́n ń gbé ní orí òkè ilẹ̀ náà, àwọn ará Kenaani sì ń gbé ẹ̀bá òkun àti ní etí bèbè Jordani.”
Amalek dwells in the land of the south; and the Hittites, and the Jebusites, and the Amorites dwell in the hill-country; and the Canaanites dwell by the sea, and by the side of the Jordan.
30 Kalebu sì pa àwọn ènìyàn náà lẹ́nu mọ́ níwájú Mose, ó wí pé, “Ẹ jẹ́ kí á gòkè lọ lẹ́ẹ̀kan náà láti lọ gba ilẹ̀ náà, nítorí pé àwa le è gbà á.”
And Caleb stilled the people before Moses, and said, Let us go up boldly and possess it, for we are well able to do it.
31 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin tí wọ́n jọ gòkè lọ yẹ ilẹ̀ wò sọ pé, “Àwa kò le gòkè lọ bá àwọn ènìyàn wọ̀nyí nítorí pé wọ́n lágbára jù wá lọ.”
But the men that went up with him said, We are not able to go up against the people, for they are stronger than we.
32 Báyìí ni wọ́n ṣe mú ìròyìn búburú ti ilẹ̀ náà, tí wọ́n lọ yọ́wò wá fún àwọn ọmọ Israẹli. Wọ́n wí pé, “Ilẹ̀ tí a lọ yẹ̀ wò jẹ́ ilẹ̀ tí ń run àwọn olùgbé ibẹ̀. Gbogbo àwọn ènìyàn tí a rí níbẹ̀ jẹ́ ènìyàn tó fìrìgbọ̀n tó sì síngbọnlẹ̀.
And they brought to the children of Israel an evil report of the land which they had searched out, saying, The land, which we have passed through to search it out, is a land that eateth up its inhabitants; and all the people that we have seen in it are men of great stature;
33 A sì tún rí àwọn òmíràn (irú àwọn ọmọ Anaki) àwa sì rí bí i kòkòrò tata ní ojú ara wa, bẹ́ẹ̀ ni àwa náà sì rí ní ojú wọn.”
and there have we seen giants — the sons of Anak are of the giants — and we were in our sight as grasshoppers, and so we were also in their sight.

< Numbers 13 >