< Numbers 12 >

1 Miriamu àti Aaroni sọ̀rọ̀-òdì sí Mose nítorí pé ó fẹ́ obìnrin ará Etiopia.
Meriyem bilen Harun Musaning hebeshlik qizni xotunluqqa alghini üchün uninggha qarshi söz qildi (chünki u hebeshlik bir qizni alghanidi).
2 Wọ́n sì wí pé, “Nípa Mose nìkan ni Olúwa ti sọ̀rọ̀ bí, kò ha ti ipa wa sọ̀rọ̀ bí?” Olúwa sì gbọ́ èyí.
Ular: — Perwerdigar peqet Musa bilenla sözliship, biz bilen sözleshmeptimu? — déyishti. Bu gepni Perwerdigar anglidi.
3 (Mose sì jẹ́ ọlọ́kàn tútù ju gbogbo ènìyàn tó wà lórí ilẹ̀ ayé lọ).
Musa dégen bu adem intayin kemter-mömin adem bolup, bu terepte yer yüzidikiler arisida uning aldigha ötidighini yoq idi.
4 Lẹ́ẹ̀kan náà ni Olúwa sọ fún Mose, Aaroni àti Miriamu pé, “Ẹ̀yin mẹ́tẹ̀ẹ̀ta, jáde wá sínú àgọ́ ìpàdé.” Àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta sì jáde síta.
Perwerdigar Musa, Harun we Meriyemge tuyuqsiz: — Siler üchünglar jamaet chédirigha kélinglar, — dédi. Üchilisi chiqip keldi.
5 Nígbà náà ni Olúwa sọ̀kalẹ̀ nínú ọ̀wọ́n ìkùùkuu, ó sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́, ó ké sí Aaroni àti Miriamu. Àwọn méjèèjì sì bọ́ síwájú,
Andin Perwerdigar [ershtin] bulut tüwrüki ichide chüshüp, jamaet chédirining aldida toxtap, Harun bilen Meryemni qichqiriwidi, ular aldigha keldi.
6 Ó wí pé, “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, “Bí wòlíì Olúwa bá wà láàrín yín, Èmi Olúwa a máa fi ara à mi hàn án ní ojúran, Èmi a máa bá a sọ̀rọ̀ nínú àlá.
U ulargha: — Emdi siler gépimni anglanglar, eger silerning aranglarda peyghember bolsa, Men Perwerdigar alamet körünüshte uninggha Özümni ayan qilimen, chüshide uning bilen sözlishimen.
7 Ṣùgbọ́n èyí kò rí bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú Mose ìránṣẹ́ mi; ó jẹ́ olóòtítọ́ nínú gbogbo ilé mi.
Lékin qulum Musagha nisbeten undaq emes; u barliq ailem ichide tolimu sadiqtur;
8 Mo sì ń bá a sọ̀rọ̀ ní ojúkojú, ọ̀rọ̀ yékéyéké tí kì í ṣe òwe, ó rí àwòrán Olúwa. Kí ló wá dé tí ẹ̀yin kò ṣe bẹ̀rù láti sọ̀rọ̀-òdì sí Mose ìránṣẹ́ mi?”
Men uning bilen tépishmaq éytip olturmay, yüzmu yüz turup biwasite sözlishimen; u Men Perwerdigarning qiyapitini köreleydu. Emdi siler némishqa qulum Musa toghruluq yaman gep qilishtin qorqmidinglar? — dédi.
9 Ìbínú Olúwa sì ru sókè sí wọn Olúwa sì fi wọ́n sílẹ̀.
Perwerdigarning otluq ghezipi ulargha qozghaldi we u kétip qaldi.
10 Nígbà tí ìkùùkuu kúrò lórí àgọ́ lójijì ni Miriamu di adẹ́tẹ̀, ó funfun bí i yìnyín. Aaroni sì padà wo Miriamu ó sì rí i pé ó ti di adẹ́tẹ̀,
Shuning bilen bulut jamaet chédiri üstidin ketti, we mana, Meryem xuddi ap’aq qardek pése-maxaw bolup ketti; Harun burulup Meryemge qariwidi, mana, u pése-maxaw bolup qalghanidi.
11 Aaroni sì wí fún Mose pé, “Jọ̀wọ́ olúwa mi, má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀, èyí tí a fi ìwà òmùgọ̀ dá sí wa lọ́rùn.
Harun Musagha: — Way xojam! Nadanliq qilip gunah ötküzüp qoyghanliqimiz sewebidin bu gunahni bizning üstimizge artmighaysen.
12 Má ṣe jẹ́ kí ó dàbí òkú ọmọ tí a bí, tí ìdajì ara rẹ̀ ti rà dànù.”
U xuddi anisining qorsiqidin chiqqandila bedini yérim chirik, ölük tughulghan balidek bolup qalmighay! — dédi.
13 Torí èyí Mose sì kígbe sí Olúwa, “Ọlọ́run, jọ̀wọ́, mú un láradá!”
Shuning bilen Musa Perwerdigargha: — I Tengri, uning késilini saqaytiwetken bolsang, — dep nida qildi.
14 Olúwa sì dá Mose lóhùn, “Bí baba rẹ̀ bá tutọ́ sí i lójú, ojú kò wa ní í tì í fún ọjọ́ méje? Dá a dúró sí ẹ̀yìn ibùdó fún ọjọ́ méje, lẹ́yìn èyí ki a tó ó le mú wọlé.”
Perwerdigar Musagha: — Eger atisi uning yüzige tükürgen bolsa, u yette kün xijilchiliq ichide turghan bolatti emesmu? Emdi u bargahning sirtigha yette kün qamap qoyulsun, andin u qaytip kelsun, — dédi.
15 Miriamu sì dúró sí ẹ̀yìn ibùdó fún ọjọ́ méje, àwọn ènìyàn kò sì tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò wọn títí tí Miriamu fi wọ inú ibùdó padà.
Shuning bilen Meryem bargah sirtigha yette kün qamap qoyuldi, taki Meryem qaytip kelgüche xelq yolgha chiqmay turup turdi.
16 Lẹ́yìn èyí, àwọn ènìyàn kúrò ní Haserotu, wọ́n sì pa ibùdó sí aginjù Parani.
Andin kéyin xelq Hazirottin yolgha chiqip, Paran chölide bargah qurdi.

< Numbers 12 >