< Numbers 12 >
1 Miriamu àti Aaroni sọ̀rọ̀-òdì sí Mose nítorí pé ó fẹ́ obìnrin ará Etiopia.
Na ka whakahe a Miriama rau ko Arona ki a Mohi mo te wahine Kuhi i marenatia e ia: he wahine Kuhi hoki tana i marena ai.
2 Wọ́n sì wí pé, “Nípa Mose nìkan ni Olúwa ti sọ̀rọ̀ bí, kò ha ti ipa wa sọ̀rọ̀ bí?” Olúwa sì gbọ́ èyí.
A ka mea raua, Koia ranei i a Mohi anake nga korero a Ihowa? kahore ranei ana korero hoki i a maua? A ka rongo a Ihowa.
3 (Mose sì jẹ́ ọlọ́kàn tútù ju gbogbo ènìyàn tó wà lórí ilẹ̀ ayé lọ).
Na, he tangata mahaki rawa a Mohi i nga tangata katoa o te mata o te whenua.
4 Lẹ́ẹ̀kan náà ni Olúwa sọ fún Mose, Aaroni àti Miriamu pé, “Ẹ̀yin mẹ́tẹ̀ẹ̀ta, jáde wá sínú àgọ́ ìpàdé.” Àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta sì jáde síta.
Na i ohorere tunu te korerotanga a Ihowa ki a Mohi ratou ko Arona, ko Miriama, Puta mai koutou tokotoru ki te tapenakara o te whakaminenga. A ka puta atu ratu tokotoru.
5 Nígbà náà ni Olúwa sọ̀kalẹ̀ nínú ọ̀wọ́n ìkùùkuu, ó sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́, ó ké sí Aaroni àti Miriamu. Àwọn méjèèjì sì bọ́ síwájú,
Na ka heke iho a Ihowa i roto i te pou kapua, a ka tu ki te whatitoka o te tapenakara, ka karanga hoki ki a Arona raua ko Miriama: a ka puta raua.
6 Ó wí pé, “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, “Bí wòlíì Olúwa bá wà láàrín yín, Èmi Olúwa a máa fi ara à mi hàn án ní ojúran, Èmi a máa bá a sọ̀rọ̀ nínú àlá.
A ka mea ia, Tena, whakarongo ki aku korero: ki te mea he poropiti kei a koutou, ka whakaatu atu ahau, a Ihowa i ahau ki a ia, he mea whakakite, he korero moemoea ki a ia.
7 Ṣùgbọ́n èyí kò rí bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú Mose ìránṣẹ́ mi; ó jẹ́ olóòtítọ́ nínú gbogbo ilé mi.
Ehara taku pononga, a Mohi i te pera; he pono ia i toku whare katoa:
8 Mo sì ń bá a sọ̀rọ̀ ní ojúkojú, ọ̀rọ̀ yékéyéké tí kì í ṣe òwe, ó rí àwòrán Olúwa. Kí ló wá dé tí ẹ̀yin kò ṣe bẹ̀rù láti sọ̀rọ̀-òdì sí Mose ìránṣẹ́ mi?”
Ka korero ahau ki a ia, he mangai, he mangai, he korero mata nui, kahore hoki he kupu ngaro; a e kite ano ia i te ahua o Ihowa: he aha ra korua te wehi ai ki te whakahe mo taku pononga, mo Mohi?
9 Ìbínú Olúwa sì ru sókè sí wọn Olúwa sì fi wọ́n sílẹ̀.
Na ka mutu te riri o Ihowa ki a raua, a haere ana ia.
10 Nígbà tí ìkùùkuu kúrò lórí àgọ́ lójijì ni Miriamu di adẹ́tẹ̀, ó funfun bí i yìnyín. Aaroni sì padà wo Miriamu ó sì rí i pé ó ti di adẹ́tẹ̀,
Na ka riro atu te kapua i runga i te tapenakara: na! he repera a Miriama, kua rite ki te hukarere: a ka titiro a Arona ki a Miriama, e! he repera.
11 Aaroni sì wí fún Mose pé, “Jọ̀wọ́ olúwa mi, má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀, èyí tí a fi ìwà òmùgọ̀ dá sí wa lọ́rùn.
Na ka mea a Arona ki a Mohi, Aue, e toku ariki, kaua e utaina ki a maua tenei hara i poauau nei, i hara nei maua.
12 Má ṣe jẹ́ kí ó dàbí òkú ọmọ tí a bí, tí ìdajì ara rẹ̀ ti rà dànù.”
Kei rite ia ki te mea kua mate, ki te mea kua pau tetahi wahi o ona kikokiko i te putanga mai i te kopu o tona whaea.
13 Torí èyí Mose sì kígbe sí Olúwa, “Ọlọ́run, jọ̀wọ́, mú un láradá!”
Na ka karanga atu a Mohi ki a Ihowa, ka mea, E te Atua, tena ra, whakaorangia ia.
14 Olúwa sì dá Mose lóhùn, “Bí baba rẹ̀ bá tutọ́ sí i lójú, ojú kò wa ní í tì í fún ọjọ́ méje? Dá a dúró sí ẹ̀yìn ibùdó fún ọjọ́ méje, lẹ́yìn èyí ki a tó ó le mú wọlé.”
Na ka mea a Ihowa, ki a Mohi, Me i tuwha kau tona papa ki tona mata e kore ianei ia e whakama, a whitu noa nga ra? kia whitu nga ra e tutakina atu ai ia ki waho o te puni, a muri iho ka mauria mai ano.
15 Miriamu sì dúró sí ẹ̀yìn ibùdó fún ọjọ́ méje, àwọn ènìyàn kò sì tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò wọn títí tí Miriamu fi wọ inú ibùdó padà.
Na tutakina atu ana a Miriama ki waho o te puni, e whitu nga ra; kihai ano hoki te iwi i haere, kia whakahokia mai ra ano a Miriama.
16 Lẹ́yìn èyí, àwọn ènìyàn kúrò ní Haserotu, wọ́n sì pa ibùdó sí aginjù Parani.
A muri iho ka turia e te iwi i Hateroto, a noho ana i te koraha o Parana.