< Numbers 12 >

1 Miriamu àti Aaroni sọ̀rọ̀-òdì sí Mose nítorí pé ó fẹ́ obìnrin ará Etiopia.
O HUMU ae la o Miriama laua o Aarona i ke ku e ia Mose, no ka wahine Aitiopa ana i lawe ai: no ka mea, ua lawe in i wahine no Aitiopa nana.
2 Wọ́n sì wí pé, “Nípa Mose nìkan ni Olúwa ti sọ̀rọ̀ bí, kò ha ti ipa wa sọ̀rọ̀ bí?” Olúwa sì gbọ́ èyí.
I ae la laua, Ma o Mose la wale no anei ka Iehova olelo ana mai? Aole anei ia i olelo ma o kaua nei kekahi? A lohe mai la o Iehova.
3 (Mose sì jẹ́ ọlọ́kàn tútù ju gbogbo ènìyàn tó wà lórí ilẹ̀ ayé lọ).
(A o ua kanaka la o Mose, ua oi aku kona akahai mamua o ko na kanaka a pau maluna o ka honua.)
4 Lẹ́ẹ̀kan náà ni Olúwa sọ fún Mose, Aaroni àti Miriamu pé, “Ẹ̀yin mẹ́tẹ̀ẹ̀ta, jáde wá sínú àgọ́ ìpàdé.” Àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta sì jáde síta.
Olelo koke mai la o Iehova ia Mose me Aarona a me Miriama, E hele mai oukou a ekolu i ka halelewa anaina. A hele aku la lakou a ekolu.
5 Nígbà náà ni Olúwa sọ̀kalẹ̀ nínú ọ̀wọ́n ìkùùkuu, ó sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́, ó ké sí Aaroni àti Miriamu. Àwọn méjèèjì sì bọ́ síwájú,
Iho iho la o Iehova maloko o ke kia ao, ku mai la ia ma ka puka o ka halelowa, kahea mai la ia Aarona laua o Miriama; a hele aku la laua.
6 Ó wí pé, “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, “Bí wòlíì Olúwa bá wà láàrín yín, Èmi Olúwa a máa fi ara à mi hàn án ní ojúran, Èmi a máa bá a sọ̀rọ̀ nínú àlá.
Olelo mai la ia, E hoolohe mai olua i ka'u olelo: A i noho kekahi kaula iwaena o oukou, owau o Iehova e hoike aku ia'u iho ia ia ma ka hihio, a e olelo aku no wau ia ia ma ka moeuhane.
7 Ṣùgbọ́n èyí kò rí bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú Mose ìránṣẹ́ mi; ó jẹ́ olóòtítọ́ nínú gbogbo ilé mi.
Aole nae pela ka'u kauwa o Mose, ka mea malama pono ma ko'u hale a pau.
8 Mo sì ń bá a sọ̀rọ̀ ní ojúkojú, ọ̀rọ̀ yékéyéké tí kì í ṣe òwe, ó rí àwòrán Olúwa. Kí ló wá dé tí ẹ̀yin kò ṣe bẹ̀rù láti sọ̀rọ̀-òdì sí Mose ìránṣẹ́ mi?”
E olelo aku ana au me ia he waha no he waha, ma ka mea akaka, aole ma ka olelonane: a e ike mai no ia i ke aka o Iehova: no ke aha la hoi i makau ole ai olua i ka ohumu aku i kuu kauwa ia Mose?
9 Ìbínú Olúwa sì ru sókè sí wọn Olúwa sì fi wọ́n sílẹ̀.
Hoaia mai la ka inaina o Iehova ia laua, a hoi aku la ia.
10 Nígbà tí ìkùùkuu kúrò lórí àgọ́ lójijì ni Miriamu di adẹ́tẹ̀, ó funfun bí i yìnyín. Aaroni sì padà wo Miriamu ó sì rí i pé ó ti di adẹ́tẹ̀,
A hoi hou aku la ke ao maluna aku o ka halelewa; aia hoi, ua lepers o Miriama me he hau la: nana aku la o Aarona ia Miriama, aia hoi, ua lepera ia.
11 Aaroni sì wí fún Mose pé, “Jọ̀wọ́ olúwa mi, má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀, èyí tí a fi ìwà òmùgọ̀ dá sí wa lọ́rùn.
I aku la o Aarona ia Mose, Auwe! e kuu haku, ke nonoi aku nei au ia oe, mai kau mai oe i keia hewa maluna o maua, i kahi a maua i hana lapuwale ai, a ua hana hewa malaila.
12 Má ṣe jẹ́ kí ó dàbí òkú ọmọ tí a bí, tí ìdajì ara rẹ̀ ti rà dànù.”
Mai waiho wale ia ia me he mea make la, me he mea la i pala kona io i ka wa o kona puka ana mai iwaho o ka opu o kona makuwahine.
13 Torí èyí Mose sì kígbe sí Olúwa, “Ọlọ́run, jọ̀wọ́, mú un láradá!”
Kahea aku la o Mose ia Iehova, i aku la, E ke Akua e, ke noi aku nei au ia oe, e hoola mai oe ia ia.
14 Olúwa sì dá Mose lóhùn, “Bí baba rẹ̀ bá tutọ́ sí i lójú, ojú kò wa ní í tì í fún ọjọ́ méje? Dá a dúró sí ẹ̀yìn ibùdó fún ọjọ́ méje, lẹ́yìn èyí ki a tó ó le mú wọlé.”
I mai la o Iehova ia Mose, Ina paha i kuha wale aku kona makuakane i kona maka, aole anei i hoohilahilaia oia i na la ehiku? E kipakuia oia iwaho o kahi hoomoana i na la ehiku, a mahope iho e hookipaia mai ia iloko.
15 Miriamu sì dúró sí ẹ̀yìn ibùdó fún ọjọ́ méje, àwọn ènìyàn kò sì tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò wọn títí tí Miriamu fi wọ inú ibùdó padà.
A ua kipakuia o Miriama iwaho o kahi hoomoana i na la ehiku; aole ka poe kanaka i hele, a hoi hou mai o Miriama maloko.
16 Lẹ́yìn èyí, àwọn ènìyàn kúrò ní Haserotu, wọ́n sì pa ibùdó sí aginjù Parani.
A mahope iho, neenee aku la ka poe kanaka mai Hazerota aku, a kukulu hou iho la ma ka waouahele o Parana.

< Numbers 12 >