< Numbers 12 >
1 Miriamu àti Aaroni sọ̀rọ̀-òdì sí Mose nítorí pé ó fẹ́ obìnrin ará Etiopia.
Mousese da Giusiai soge uda lale esalu. Amaiba: le, Milia: me amola Elane da amoga hahawane hameba: le, egane sia: i.
2 Wọ́n sì wí pé, “Nípa Mose nìkan ni Olúwa ti sọ̀rọ̀ bí, kò ha ti ipa wa sọ̀rọ̀ bí?” Olúwa sì gbọ́ èyí.
Ela da amane sia: i, “Hina Gode da Mousese ea lafidili fawane sia: bela: ? Hame mabu! E da ania lafidili amola sia: dasu:” Hina Gode da elea egasu sia: nabi.
3 (Mose sì jẹ́ ọlọ́kàn tútù ju gbogbo ènìyàn tó wà lórí ilẹ̀ ayé lọ).
(Mousese da bodogi dunu esalu, gasa fi hame dawa: i. Ea bodogi hou da osobo bagade dunu eno huluane ilia asaboi hou baligi dagoi.)
4 Lẹ́ẹ̀kan náà ni Olúwa sọ fún Mose, Aaroni àti Miriamu pé, “Ẹ̀yin mẹ́tẹ̀ẹ̀ta, jáde wá sínú àgọ́ ìpàdé.” Àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta sì jáde síta.
Hedolowane, Hina Gode da Mousese, Elane amola Milia: me ilima amane sia: i “Dilia udiana! Gadili misa! Na Abula Diasuga misa!” Ilia da asi.
5 Nígbà náà ni Olúwa sọ̀kalẹ̀ nínú ọ̀wọ́n ìkùùkuu, ó sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́, ó ké sí Aaroni àti Miriamu. Àwọn méjèèjì sì bọ́ síwájú,
Hina Gode da mu mobi ganumu ganodini gudu sa: ili, Abula Diasu ea logo holeiga lelu, amane wei, “Elane! Milia: me!” Ela da elea midadi aliaguda: i.
6 Ó wí pé, “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, “Bí wòlíì Olúwa bá wà láàrín yín, Èmi Olúwa a máa fi ara à mi hàn án ní ojúran, Èmi a máa bá a sọ̀rọ̀ nínú àlá.
Hina Gode da amane sia: i, “Na alima sia: be goe nabima! Balofede dunu ilia da dilia gilisisu ganodini esalea, ili da Na ba: ma: ne, Na da ilia esala ba: su ganodini maha amola ilia simasia ganodini ilima sia: sa.
7 Ṣùgbọ́n èyí kò rí bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú Mose ìránṣẹ́ mi; ó jẹ́ olóòtítọ́ nínú gbogbo ilé mi.
Be Na da Na hawa: hamosu dunu Mousesema sia: sea, hou hisu da ba: sa. Na da e amo Na Isala: ili fi dunu huluane ouligima: ne ilegei.
8 Mo sì ń bá a sọ̀rọ̀ ní ojúkojú, ọ̀rọ̀ yékéyéké tí kì í ṣe òwe, ó rí àwòrán Olúwa. Kí ló wá dé tí ẹ̀yin kò ṣe bẹ̀rù láti sọ̀rọ̀-òdì sí Mose ìránṣẹ́ mi?”
Amaiba: le, Na da ea odagia moloiwane idinamasu agoane mae dawa: le sia: sa. E da Na da: i defele ba: i dagoi. Alia da Na hawa: hamosu dunu ema ha laiwane sia: mu da defea hame!”
9 Ìbínú Olúwa sì ru sókè sí wọn Olúwa sì fi wọ́n sílẹ̀.
Hina Gode da elama ougi galu. Amaiba: le, E da ahoanoba,
10 Nígbà tí ìkùùkuu kúrò lórí àgọ́ lójijì ni Miriamu di adẹ́tẹ̀, ó funfun bí i yìnyín. Aaroni sì padà wo Miriamu ó sì rí i pé ó ti di adẹ́tẹ̀,
amola mu ganumu da Abula Diasu fisili, Milia: me ea gadofo da lebolosi oloi madelale, ahea: iai agoane ba: i. Elane da ea dalusi amo lebolosiga dedeboi ba: beba: le,
11 Aaroni sì wí fún Mose pé, “Jọ̀wọ́ olúwa mi, má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀, èyí tí a fi ìwà òmùgọ̀ dá sí wa lọ́rùn.
e da Mousesema amane sia: i, “Hina! Fidima! Ania da gagaoui agoane wadela: le hamoi. Be ania se bagade nabima: ne, logo mae doasima.
12 Má ṣe jẹ́ kí ó dàbí òkú ọmọ tí a bí, tí ìdajì ara rẹ̀ ti rà dànù.”
E da liligi bogoiwane lalelegei amo ea hu la: idi dasaidafa ba: sa, agoane ba: mu da defea hame. Dia amo logo hedofama!”
13 Torí èyí Mose sì kígbe sí Olúwa, “Ọlọ́run, jọ̀wọ́, mú un láradá!”
Amaiba: le, Mousese da Hina Godema amane wei, “Gode! E uhinisima!”
14 Olúwa sì dá Mose lóhùn, “Bí baba rẹ̀ bá tutọ́ sí i lójú, ojú kò wa ní í tì í fún ọjọ́ méje? Dá a dúró sí ẹ̀yìn ibùdó fún ọjọ́ méje, lẹ́yìn èyí ki a tó ó le mú wọlé.”
Hina Gode da bu adole i, “Ea ada da ea odagia defo adugagala: i ganiaba, e da ea gogosiasu dawa: ma: ne eso fesuale agoane dialumu. Amaiba: le, e da fisisu gadili eso fesuale esaloma: ne, sefasima. Amalalu, e ganodini oule misunu da defea.”
15 Miriamu sì dúró sí ẹ̀yìn ibùdó fún ọjọ́ méje, àwọn ènìyàn kò sì tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò wọn títí tí Miriamu fi wọ inú ibùdó padà.
Ilia da Milia: me fisisu gadili oule asili, fisisu logo ga: le fisiagai. E da eso fesuale gadili ouesalu, amalalu ilia da e bu ganodini oule misi. Amalalu, ilia da bu logoga ahoasu.
16 Lẹ́yìn èyí, àwọn ènìyàn kúrò ní Haserotu, wọ́n sì pa ibùdó sí aginjù Parani.
Ilia da Hasilode soge fisili asili, wadela: i hafoga: i soge ea dio Ba: ila: ne amo ganodini ilia abula fisisu bu hiougi.