< Numbers 11 >

1 Àwọn ènìyàn ń ṣe àròyé nípa wàhálà wọn sí etí ìgbọ́ Olúwa. Ìbínú Olúwa sì ru sókè nígbà tí ó gbọ́ àròyé yìí. Nígbà náà ni iná jáde láti ọ̀dọ̀ Olúwa bọ́ sí àárín wọn, ó sì run àwọn tó wà ní òpin ibùdó.
We shundaq boldiki, xelq ghotuldishatti, ularning ghotuldashliri Perwerdigarning quliqigha yétip intayin rezil anglandi; U bu sözlerni anglidi we Uning ghezipi qozghaldi; Perwerdigarning ot-yalquni ularning arisida tutiship, bargahning chétidiki bezilerni köydürüshke bashlidi.
2 Nígbà náà ni àwọn ènìyàn kígbe sí Mose, Mose sì gbàdúrà sí Olúwa iná náà sì kú.
Xelq bu chaghda Musagha yalwuriwidi, Musa Perwerdigardin tilidi; shuning bilen ot pesiyip öchti.
3 Wọ́n sì ń pe ibẹ̀ ní Tabera nítorí pé, iná láti ọ̀dọ̀ Olúwa jó láàrín wọn.
Perwerdigarning oti ularning otturisida tutashqanliqi üchün u u yerge «Taberah» dep at qoydi.
4 Àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn aláìníláárí tó wà láàrín àwọn ọmọ Israẹli pẹ̀lú ọkàn ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wọn fi ìtara béèrè fún oúnjẹ mìíràn, àwọn ọmọ Israẹli náà bá bẹ̀rẹ̀ sí í sọkún wí pé, “Bí i pé kí á rí ẹran jẹ báyìí!
Ularning arisidiki shalghut kishilerning nepsi taqildap ketti, Israillarmu yene yighlashqa bashlidi: «Emdi bizge kim gösh béridu?
5 Àwa rántí ẹja tí à ń jẹ lọ́fẹ̀ẹ́ ní Ejibiti, apálà, bàrà, ewébẹ̀, àlùbọ́sà àti àwọn ẹ̀fọ́ mìíràn.
Hélimu ésimizdiki, biz Misirdiki chaghlarda pul xejlimey turupmu béliq yéyeleyttuq, yene terxemek, tawuz, piyaz we küde piyaz bilen samsaqmu bar idi.
6 Ṣùgbọ́n báyìí gbogbo ara wa ti gbẹ, kò sí ohun mìíràn láti jẹ àfi manna nìkan tí a rí yìí!”
Mana bu yerde hazir köz aldimizda mannadin bashqa héchnéme yoq, emdi bizning jénimizmu qurup kétiwatidu» déyishti.
7 Manna náà dàbí èso korianderi, ìrísí rẹ̀ sì dàbí oje igi.
Manna goya yumghaqsüt uruqigha, körünüshi goya kehriwagha oxshaytti.
8 Àwọn ènìyàn náà ń lọ káàkiri láti kó o, wọn ó lọ̀ ọ́ lórí ọlọ tàbí kí wọ́n gún un nínú odó. Wọ́n le sè é nínú ìkòkò tàbí kí wọn ó fi ṣe àkàrà, adùn rẹ̀ yóò sì dàbí adùn ohun tí a fi òróró ṣe.
Kishiler uyan-buyan chépip uni yighip, bezide yarghunchaqta ézip, bezide hawanchida soqup, ya bezide qazanda pishurup nan qilip yeytti; temi zeytun mayliq toqachlargha oxshaytti.
9 Nígbà tí ìrì bá ẹ̀ sí ibùdó lórí ni manna náà máa ń bọ́ pẹ̀lú rẹ̀.
Kéchide bargahqa shebnem chüshkende, mannamu shuning üstige chüshetti.
10 Mose sì gbọ́ tí àwọn ènìyàn ń sọkún ní gbogbo ìdílé wọn, oníkálùkù ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ tirẹ̀. Olúwa sì bínú gidigidi. Inú Mose sì bàjẹ́ pẹ̀lú.
Musa xelqning ailimu-aile herbiri öz chédirining ishiki aldida yigha-zar qilishiwatqinini anglidi; buninggha Perwerdigarning ghezipi qattiq qozghaldi, bu ish Musaning neziridimu yaman köründi.
11 Mose sì béèrè lọ́wọ́ Olúwa pé, “Kí ló dé tí o fi mú wàhálà yìí bá ìránṣẹ́ rẹ? Kí ni mo ṣe tí n kò fi tẹ ọ lọ́rùn tí ìwọ fi di ẹrù àwọn ènìyàn wọ̀nyí lé mi lórí.
Musa Perwerdigargha: — Sen bu barliq xelqning éghir yükini manga artip qoyup, men qulungni némishqa bundaq qiynaysen; némishqa men Séning aldingda iltipat tapmaymen?
12 Èmi ni mo ha lóyún gbogbo àwọn ènìyàn wọ̀nyí bí? Àbí èmi ló bí wọn? Tí ìwọ fi sọ fún mi pé, máa gbé wọn sí oókan àyà rẹ, gẹ́gẹ́ bí abiyamọ ti máa ń gbe ọmọ ọmú lọ sí ilẹ̀ tí o ti búra láti fún àwọn baba ńlá wọn.
Ya men bu pütün xelqqe hamilidar bolup, ularni tughdummu? Sen téxi manga: «Sen ularni Men qesem ichip ularning ata-bowilirigha miras qilghan shu yerge yetküzgüche, xuddi baqqan atisi emchektiki bowaqni baghrigha alghandek baghringgha élip kötürüp mang» dewatisen?
13 Níbo ni n ó ti rí ẹran fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí? Nítorí wọ́n ń sọkún sí mi pé, ‘Fún wa lẹ́ran jẹ́!’
Men bu xelqqe nedin gösh tépip béreleymen? Chünki ular manga yighlap: «Sen bizge yégüdek gösh tépip ber!» déyishmekte.
14 Èmi nìkan kò lè dágbé wàhálà àwọn ènìyàn wọ̀nyí, ẹrù wọn ti wúwo jù fún mi.
Men bu xelqni kötürüshni yalghuz üstümge élip kételmeydikenmen, bu ish manga bek éghir kéliwatidu.
15 Bí ó bá sì ṣe pé báyìí ni ìwọ ó ṣe máa ṣe fún mi, kúkú pa mí báyìí, tí mo bá ti bá ojúrere rẹ pàdé—kí ojú mi má ba à rí ìparun mi.”
Eger Sen manga mushundaq muamile qilmaqchi bolsang, men ötünüp qalay, bu xarab halitimni manga körsetmey, iltipat qilip méni öltürüwet! — dédi.
16 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú àádọ́rin ọkùnrin nínú àwọn àgbàgbà àwọn ọmọ Israẹli, àwọn tí o mọ̀ gẹ́gẹ́ bí olórí àti olóyè láàrín àwọn ènìyàn wá sínú àgọ́ ìpàdé, kí wọ́n lé dúró níwájú mi.
Perwerdigar Musagha mundaq dédi: — Israil aqsaqalliri ichidin, sen yénimgha tonuydighan xelq aqsaqalliri we beglerdin yetmishni tallap yighqin, ularni jamaet chédirining aldigha ekel. Ular séning bilen bille shu yerde tursun.
17 Èmi ó sì sọ̀kalẹ̀ wá bá yín sọ̀rọ̀ níbẹ̀. Èmi ó sì mú díẹ̀ nínú agbára Ẹ̀mí tí ń bẹ lára rẹ láti fi sí orí àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Wọn ó sì máa ràn ọ́ lọ́wọ́ láti ru àjàgà àwọn ènìyàn kí ó má ṣe pé ìwọ nìkan ni ó o máa ru àjàgà náà.
Men shu yerge chüshüp séning bilen sözlishimen; we séning üstüngde turuwatqan Rohni élip ularning üstigimu bölüp qoyimen. Shuning bilen ular sen bilen bille xelqni kötürüsh mes’uliyitini üstige alidu, andin sen uni özüng yalghuz kötürmeydighan bolisen.
18 “Sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, ‘Ẹ ya ara yín sí mímọ́ ní ìmúrasílẹ̀ fún ọ̀la, ẹ ó sì jẹ ẹran. Nítorí pé Olúwa ti gbọ́ igbe ẹkún yín, èyí tí ẹ sun pé, “Ìbá ṣe pé a lè rí ẹran jẹ ni! Ó sàn fún wa ní Ejibiti jù báyìí lọ!” Nítorí náà ni Olúwa yóò fi fún yín ní ẹran, ẹ ó sì jẹ ẹ́.
Sen xelqqe mundaq dégin: «Ete gösh yiyishke teyyarlinip özenglerni [Xudagha] atap paklanglar; chünki siler Perwerdigarning quliqini aghritip yighlap: «Emdi kim bizge gösh béridu? Ah, Misirdiki halimiz bek yaxshi idi!» dégenidinglar emesmu? Perwerdigar derweqe silerge gösh béridu, siler uningdin yeysiler.
19 Ẹ kò ní i jẹ ẹ́ fún ọjọ́ kan, ọjọ́ méjì, ọjọ́ márùn-ún, ọjọ́ mẹ́wàá tàbí ogúnjọ́ lásán,
Siler bir kün, ikki kün emes, besh kün, on kün emes, yigirme künmu emes,
20 ṣùgbọ́n fún odidi oṣù kan, títí tí ẹran náà yóò fi máa yọ ní imú yín, tí yóò sì sú yín, nítorí pé ẹ ti kẹ́gàn Olúwa tí ó wà láàrín yín, ẹ sì ti sọkún fún un wí pé, “Kí ló dé tí a fi kúrò ní Ejibiti gan an?”’”
belki pütün bir ay yeysiler, taki burninglardin étilip chiqip hö bolghuche yeysiler; chünki siler aranglarda turuwatqan Perwerdigarni mensitmey, uning aldida yighlap turup: «Biz néme üchün Misirdin chiqtuq?» — dédinglar».
21 Ṣùgbọ́n Mose sọ pé, “Mo wà láàrín ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ènìyàn ni ìrìnkiri, ó sì sọ pé, ‘Èmi ó fún wọn ní ẹran láti jẹ fún oṣù kan gbáko!’
Musa: — Men ularning arisida turuwatqan bu xelqtin yolgha chiqalaydighan erkekler alte yüz ming tursa, Sen téxi: «Men ularni gösh yeydighan, hetta pütün bir ay gösh yeydighan qilimen» deysen;
22 Ǹjẹ́ bí a tilẹ̀ pa àgbò ẹran àti ọmọ ẹran, yóò ha tó wọn bí? Tàbí bí a tilẹ̀ pa gbogbo ẹja inú omi fún wọn, yóò wa tó bí?”
emise qoy, kala padilirining hemmisi soyulsa ulargha yétemdu? Yaki déngizdiki hemme béliq ulargha tutup bérilse, ularning yiyishige yitermu? — dédi.
23 Olúwa sì dá Mose lóhùn pé, “Ọwọ́ Olúwa ha kúrú bí? Ìwọ yóò ri nísinsin yìí bóyá ọ̀rọ̀ tí mo sọ yóò ṣẹ tàbí kò ni í ṣẹ.”
Shuning bilen Perwerdigar Musagha: — Perwerdigarning qoli qisqa bolup qaptimu? Emdi körüp baqqine, Méning sanga dégen sözüm emelge ashurulamdu-yoq? — dédi.
24 Mose sì jáde, ó sọ ohun tí Olúwa wí fún àwọn ènìyàn. Ó mú àwọn àádọ́rin àgbàgbà Israẹli dúró yí àgọ́ ká.
Shuning bilen Musa chiqip Perwerdigarning sözini xelqqe yetküzdi we xelq ichidiki aqsaqallardin yetmish ademni tallap yighip ularni jamaet chédirining etrapida turghuzdi.
25 Nígbà náà ni Olúwa sọ̀kalẹ̀ nínú àwọ̀ sánmọ̀ ó sì bá wọn sọ̀rọ̀, ó sì mú lára Ẹ̀mí tó wà lára Mose sí ara àwọn àádọ́rin àgbàgbà náà, Ó sì ṣẹlẹ̀ pé nígbà tí Ẹ̀mí náà bà lé wọn, wọ́n sọtẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n lẹ́yìn èyí wọn kò sọtẹ́lẹ̀ mọ́.
Andin Perwerdigar bulut ichidin chüshüp, Musa bilen sözliship, uningdiki Rohtin élip yetmish aqsaqalgha qoydi; Roh ularning üstige qonushi bilen ular bésharet bérishke kirishti. Lékin shu waqittin kéyin ular undaq qilmidi.
26 Àwọn ọkùnrin méjì, tí orúkọ wọn ń jẹ́ Eldadi àti Medadi kò kúrò nínú àgọ́. Orúkọ wọn wà lára àádọ́rin àgbàgbà yìí ṣùgbọ́n wọn kò jáde nínú àgọ́ síbẹ̀ Ẹ̀mí náà bà lé wọn, wọ́n sì sọtẹ́lẹ̀ nínú àgọ́.
Lékin u chaghda ulardin ikki adem bargahta qaldi; birsining ismi Eldad, ikkinchisi Médad idi (ular eslide aqsaqallarning arisida tizimlan’ghanidi, lékin ibadet chédirigha chiqmay qalghanidi). Roh ularning üstidimu qondi we ular bargah ichide bésharet bérishke bashlidi.
27 Ọmọkùnrin kan sì sáré lọ sọ fún Mose pé, “Eldadi àti Medadi ń sọtẹ́lẹ̀ nínú àgọ́.”
Yash bir yigit yügürüp kélip Musagha: — Eldad bilen Médad bargahta bésharet bériwatidu, — dédi.
28 Joṣua ọmọ Nuni tí í ṣe ìránṣẹ́ Mose, láti kékeré tó jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ dáhùn pé, “Mose olúwa mi, dá wọn lẹ́kun!”
Musaning xizmetkari, Musa tallighan serxil yigitliridin biri, Nunning oghli Yeshua qopup: — I xojam Musa, ularni tosughayla, — dédi.
29 Mose sì wí fún un pé, “Àbí ìwọ ń jowú nítorí mi? Ìbá ti wù mí tó, kí gbogbo àwọn ènìyàn Olúwa jẹ́ wòlíì, kí Olúwa sì fi Ẹ̀mí rẹ̀ sí wọn lára!”
Lékin Musa uninggha: — Sen méning sewebimdin heset qiliwatamsen? Perwerdigarning pütün xelqi peyghember bolup ketse idi, Perwerdigar Özining Rohini ularning üstige qoysa idi! — dédi.
30 Mose àti àwọn àgbàgbà Israẹli yìí sì padà sínú àgọ́.
Shuning bilen Musa bilen Israil aqsaqallirining hemmisi bargahqa qaytip kétishti.
31 Afẹ́fẹ́ sì jáde láti ọ̀dọ̀ Olúwa ó sì kó àparò wá láti inú Òkun. Ó sì dà wọ́n káàkiri gbogbo ibùdó ní ìwọ̀n gíga ẹsẹ̀ bàtà mẹ́ta sórí ilẹ̀, bí ìwọ̀n ìrìn ọjọ́ kan ní gbogbo àyíká.
Emdi Perwerdigar aldidin bir shamal chiqip, u déngiz tereptin bödünilerni uchurtup kélip, bargahning etrapigha yéyiwetti; bödüniler bargahning u teripidimu bir künlük yol, bu teripidimu bir künlük yol kelgüdek yer yüzini ikki gez égizlikte kelgüdek qaplidi.
32 Ní gbogbo ọjọ́ náà àti òru, títí dé ọjọ́ kejì ni àwọn ènìyàn fi ń kó àparò yìí, ẹni tó kó kéré jùlọ kó ìwọ̀n homeri mẹ́wàá, wọ́n sì ṣà wọ́n sílẹ̀ fún ara wọn yí gbogbo ibùdó.
Xelq ornidin turup pütkül shu küni, shu kéchisi we etisi pütün kün bödüne tutup yighdi, eng az dégenlirimu alahazel ikki xomir yighdi; ular bularni bargahning töt etrapigha özliri üchün yéyishti.
33 Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹran náà sì wà láàrín eyín wọn, kó tó di pé wọ́n jẹ ẹ́, ìbínú Olúwa sì ru sí àwọn ènìyàn, ó sì pa wọ́n pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn.
Ular göshni chaynap ézip bolmay, gösh téxi chishliri arisida turghanda, Perwerdigarning ghezipi ulargha qozghilip, xelqni intayin éghir bir waba bilen urdi.
34 Torí èyí ni wọ́n ṣe pe ibẹ̀ ní Kibirotu-Hattaafa nítorí pé níbẹ̀ ni wọ́n gbé sìnkú àwọn ènìyàn tó ní ọ̀kánjúwà oúnjẹ sí.
Shunga kishiler shu yerni «Qibrot-Hattawah» dep atidi; chünki ular shu yerde nepsi taqildighan kishilerni yerlikke qoyghanidi.
35 Àwọn ènìyàn yòókù sì gbéra láti Kibirotu-Hattaafa lọ pa ibùdó sí Haserotu wọ́n sì dúró níbẹ̀.
Kéyin xelq Qibrot-Hattawahtin yolgha chiqip Hazirotqa kélip, Hazirotta toxtidi.

< Numbers 11 >