< Numbers 11 >

1 Àwọn ènìyàn ń ṣe àròyé nípa wàhálà wọn sí etí ìgbọ́ Olúwa. Ìbínú Olúwa sì ru sókè nígbà tí ó gbọ́ àròyé yìí. Nígbà náà ni iná jáde láti ọ̀dọ̀ Olúwa bọ́ sí àárín wọn, ó sì run àwọn tó wà ní òpin ibùdó.
І став народ голосно нарікати до Господніх ушей. І почув Господь, і запалав Його гнів, — і загорівся між ними Господній огонь, та й пожер їх у кінці табо́ру.
2 Nígbà náà ni àwọn ènìyàn kígbe sí Mose, Mose sì gbàdúrà sí Olúwa iná náà sì kú.
І наро́д став кричати до Мойсея. А Мойсей помолився до Господа, — і погас той огонь.
3 Wọ́n sì ń pe ibẹ̀ ní Tabera nítorí pé, iná láti ọ̀dọ̀ Olúwa jó láàrín wọn.
І він назвав ім'я́ того місця: Тав'ера, бо між ними горів був Господній огонь.
4 Àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn aláìníláárí tó wà láàrín àwọn ọmọ Israẹli pẹ̀lú ọkàn ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wọn fi ìtara béèrè fún oúnjẹ mìíràn, àwọn ọmọ Israẹli náà bá bẹ̀rẹ̀ sí í sọkún wí pé, “Bí i pé kí á rí ẹran jẹ báyìí!
А збирани́на, що була серед нього, стала вередувати, і також Ізраїлеві сини стали плакати з ними та говорити: „Хто нагодує нас м'ясом?
5 Àwa rántí ẹja tí à ń jẹ lọ́fẹ̀ẹ́ ní Ejibiti, apálà, bàrà, ewébẹ̀, àlùbọ́sà àti àwọn ẹ̀fọ́ mìíràn.
Ми згадуємо рибу, що їли в Єгипті даремно, огірки й дині, і пір, і цибулю, і часник.
6 Ṣùgbọ́n báyìí gbogbo ara wa ti gbẹ, kò sí ohun mìíràn láti jẹ àfi manna nìkan tí a rí yìí!”
А тепер душа наша в'яне, немає нічого, — тільки ма́нна нам перед очима“.
7 Manna náà dàbí èso korianderi, ìrísí rẹ̀ sì dàbí oje igi.
А манна — як корія́ндрове насіння вона, а вигляд її, — як вигляд кришталу.
8 Àwọn ènìyàn náà ń lọ káàkiri láti kó o, wọn ó lọ̀ ọ́ lórí ọlọ tàbí kí wọ́n gún un nínú odó. Wọ́n le sè é nínú ìkòkò tàbí kí wọn ó fi ṣe àkàrà, adùn rẹ̀ yóò sì dàbí adùn ohun tí a fi òróró ṣe.
Люди розхо́дилися, і збирали її та мололи жо́рнами або товкли в ступі, і варили в горшку та й робили з неї калачі. А смак її був, як смак олійного коржа́.
9 Nígbà tí ìrì bá ẹ̀ sí ibùdó lórí ni manna náà máa ń bọ́ pẹ̀lú rẹ̀.
А коли роса спада́ла на та́бір, спада́ла й та манна на нього.
10 Mose sì gbọ́ tí àwọn ènìyàn ń sọkún ní gbogbo ìdílé wọn, oníkálùkù ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ tirẹ̀. Olúwa sì bínú gidigidi. Inú Mose sì bàjẹ́ pẹ̀lú.
І почув Мойсей, що наро́д плаче в родинах своїх, кожен при вході наме́ту свого́. І сильно запалав гнів Господній, і в оча́х Мойсеєвих то було зле.
11 Mose sì béèrè lọ́wọ́ Olúwa pé, “Kí ló dé tí o fi mú wàhálà yìí bá ìránṣẹ́ rẹ? Kí ni mo ṣe tí n kò fi tẹ ọ lọ́rùn tí ìwọ fi di ẹrù àwọn ènìyàn wọ̀nyí lé mi lórí.
І сказав Мойсей до Господа: „На́що вчинив Ти зло своєму рабові, і чому́ я не знайшов милости в оча́х Твоїх, що Ти поклав тягара́ всього наро́ду на мене?
12 Èmi ni mo ha lóyún gbogbo àwọn ènìyàn wọ̀nyí bí? Àbí èmi ló bí wọn? Tí ìwọ fi sọ fún mi pé, máa gbé wọn sí oókan àyà rẹ, gẹ́gẹ́ bí abiyamọ ti máa ń gbe ọmọ ọmú lọ sí ilẹ̀ tí o ti búra láti fún àwọn baba ńlá wọn.
Чи я був вагітни́й усім тим наро́дом, чи я його породив, що Ти кажеш мені: Неси його на лоні своїм, як мамка носить ссунця́, до землі, яку Ти присягну́в батька́м його?
13 Níbo ni n ó ti rí ẹran fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí? Nítorí wọ́n ń sọkún sí mi pé, ‘Fún wa lẹ́ran jẹ́!’
Звідки мені взяти м'яса, щоб дати всьому цьому наро́дові? Бо вони плачуть передо мною, говорячи: Дай же нам м'яса, і ми бу́демо їсти!
14 Èmi nìkan kò lè dágbé wàhálà àwọn ènìyàn wọ̀nyí, ẹrù wọn ti wúwo jù fún mi.
Не подола́ю я сам носити всього цього народа, — бо він тяжчий за мене!
15 Bí ó bá sì ṣe pé báyìí ni ìwọ ó ṣe máa ṣe fún mi, kúkú pa mí báyìí, tí mo bá ti bá ojúrere rẹ pàdé—kí ojú mi má ba à rí ìparun mi.”
А якщо Ти таке мені робиш, то краще забий мене, якщо я знайшов милість в очах Твоїх, щоб я не побачив нещастя свого!“
16 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú àádọ́rin ọkùnrin nínú àwọn àgbàgbà àwọn ọmọ Israẹli, àwọn tí o mọ̀ gẹ́gẹ́ bí olórí àti olóyè láàrín àwọn ènìyàn wá sínú àgọ́ ìpàdé, kí wọ́n lé dúró níwájú mi.
І сказав Господь до Мойсея: „Збери ж мені сімдесятеро люда зо старши́х Ізраїлевих, яких знаєш, що вони старші́ народу та його наглядачі, і візьми їх до скинії заповіту, і стануть вони там із тобою.
17 Èmi ó sì sọ̀kalẹ̀ wá bá yín sọ̀rọ̀ níbẹ̀. Èmi ó sì mú díẹ̀ nínú agbára Ẹ̀mí tí ń bẹ lára rẹ láti fi sí orí àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Wọn ó sì máa ràn ọ́ lọ́wọ́ láti ru àjàgà àwọn ènìyàn kí ó má ṣe pé ìwọ nìkan ni ó o máa ru àjàgà náà.
І Я зійду́, і буду розмовляти там із тобою, і візьму́ від Духа, що на тобі, і покладу на них, — і вони носитимуть із тобою тягара́ того народу, і не будеш носити ти сам.
18 “Sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, ‘Ẹ ya ara yín sí mímọ́ ní ìmúrasílẹ̀ fún ọ̀la, ẹ ó sì jẹ ẹran. Nítorí pé Olúwa ti gbọ́ igbe ẹkún yín, èyí tí ẹ sun pé, “Ìbá ṣe pé a lè rí ẹran jẹ ni! Ó sàn fún wa ní Ejibiti jù báyìí lọ!” Nítorí náà ni Olúwa yóò fi fún yín ní ẹran, ẹ ó sì jẹ ẹ́.
А до наро́ду скажи: Освятіться наза́втра, і будете їсти м'ясо, бо ви плакали до Господніх ушей, говорячи: Хто дасть нам їсти м'яса, бо добре було нам в Єгипті? І дасть Господь вам м'яса, і ви будете їсти.
19 Ẹ kò ní i jẹ ẹ́ fún ọjọ́ kan, ọjọ́ méjì, ọjọ́ márùn-ún, ọjọ́ mẹ́wàá tàbí ogúnjọ́ lásán,
Не один день будете ви їсти, і не два дні, і не п'ять день, і не десять день, і не двадцять день,
20 ṣùgbọ́n fún odidi oṣù kan, títí tí ẹran náà yóò fi máa yọ ní imú yín, tí yóò sì sú yín, nítorí pé ẹ ti kẹ́gàn Olúwa tí ó wà láàrín yín, ẹ sì ti sọkún fún un wí pé, “Kí ló dé tí a fi kúrò ní Ejibiti gan an?”’”
але ці́лий місяць, аж поки не ви́йде воно з ваших ніздрів, і стане вам на огиду, бо ви зне́хтували собі Господа, що серед вас, і плакали перед лицем Його, говорячи: Чого це ми вийшли з Єгипту?“
21 Ṣùgbọ́n Mose sọ pé, “Mo wà láàrín ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ènìyàn ni ìrìnkiri, ó sì sọ pé, ‘Èmi ó fún wọn ní ẹran láti jẹ fún oṣù kan gbáko!’
І сказав Мойсей: „Шістсот тисяч піхоти той наро́д, що я серед нього, а Ти сказав: Я дам їм м'яса, і вони будуть їсти місяць ча́су.
22 Ǹjẹ́ bí a tilẹ̀ pa àgbò ẹran àti ọmọ ẹran, yóò ha tó wọn bí? Tàbí bí a tilẹ̀ pa gbogbo ẹja inú omi fún wọn, yóò wa tó bí?”
Чи худоба дрібна та худоба велика заріжеться для них, — і ви́стачить їм? Чи також збереться для них уся морська риба, — і вистачить їм?“
23 Olúwa sì dá Mose lóhùn pé, “Ọwọ́ Olúwa ha kúrú bí? Ìwọ yóò ri nísinsin yìí bóyá ọ̀rọ̀ tí mo sọ yóò ṣẹ tàbí kò ni í ṣẹ.”
А Господь сказав до Мойсея: „Чи Господня рука буває коротка? Тепер ти побачиш, чи спо́вниться тобі Моє слово, чи ні“.
24 Mose sì jáde, ó sọ ohun tí Olúwa wí fún àwọn ènìyàn. Ó mú àwọn àádọ́rin àgbàgbà Israẹli dúró yí àgọ́ ká.
І вийшов Мойсей, і промовляв до того народу Господні слова. І зібрав він сімдесятеро чоловіка зо старши́х народу, і поставив їх навколо скинії.
25 Nígbà náà ni Olúwa sọ̀kalẹ̀ nínú àwọ̀ sánmọ̀ ó sì bá wọn sọ̀rọ̀, ó sì mú lára Ẹ̀mí tó wà lára Mose sí ara àwọn àádọ́rin àgbàgbà náà, Ó sì ṣẹlẹ̀ pé nígbà tí Ẹ̀mí náà bà lé wọn, wọ́n sọtẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n lẹ́yìn èyí wọn kò sọtẹ́lẹ̀ mọ́.
І зійшов Господь у хмарі, та й промовляв до нього, і взяв від Духа, що на ньому, і дав на сімдеся́т чоловіка старши́х. І сталося, як спочив на них Дух той, то вони стали пророкувати, та потім перестали.
26 Àwọn ọkùnrin méjì, tí orúkọ wọn ń jẹ́ Eldadi àti Medadi kò kúrò nínú àgọ́. Orúkọ wọn wà lára àádọ́rin àgbàgbà yìí ṣùgbọ́n wọn kò jáde nínú àgọ́ síbẹ̀ Ẹ̀mí náà bà lé wọn, wọ́n sì sọtẹ́lẹ̀ nínú àgọ́.
І зоста́лося двоє людей в табо́рі, ім'я́ одному Елдад, а ймення дру́гому Медад. І спочив на них Дух; а вони були серед записаних, та не вийшли до скинії, і пророкували в табо́рі.
27 Ọmọkùnrin kan sì sáré lọ sọ fún Mose pé, “Eldadi àti Medadi ń sọtẹ́lẹ̀ nínú àgọ́.”
І побіг юнак, і промовив до Мойсея й сказав: „Елдад і Медад пророкують у табо́рі!“
28 Joṣua ọmọ Nuni tí í ṣe ìránṣẹ́ Mose, láti kékeré tó jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ dáhùn pé, “Mose olúwa mi, dá wọn lẹ́kun!”
І відповів Ісус, син Навинів, Мойсеїв слуга від своєї мо́лодости, та й сказав: „Пане мій Мойсею, — заборонни їм!“
29 Mose sì wí fún un pé, “Àbí ìwọ ń jowú nítorí mi? Ìbá ti wù mí tó, kí gbogbo àwọn ènìyàn Olúwa jẹ́ wòlíì, kí Olúwa sì fi Ẹ̀mí rẹ̀ sí wọn lára!”
І сказав йому Мойсей: „Чи ти за́здрісний за мене? О, якби то ввесь Господній наро́д став пророками, коли б дав Господь Духа Свого і на них!“
30 Mose àti àwọn àgbàgbà Israẹli yìí sì padà sínú àgọ́.
І вернувся Мойсей до табо́ру, він та старші́ Ізра́їлеві.
31 Afẹ́fẹ́ sì jáde láti ọ̀dọ̀ Olúwa ó sì kó àparò wá láti inú Òkun. Ó sì dà wọ́n káàkiri gbogbo ibùdó ní ìwọ̀n gíga ẹsẹ̀ bàtà mẹ́ta sórí ilẹ̀, bí ìwọ̀n ìrìn ọjọ́ kan ní gbogbo àyíká.
І знявся вітер від Господа, і навіяв перепелиці від моря, і опустив їх над табо́ром, — як денна дорога туди й як денна дорога сюди навко́ло табо́ру, і коло двох ліктів на поверхні землі.
32 Ní gbogbo ọjọ́ náà àti òru, títí dé ọjọ́ kejì ni àwọn ènìyàn fi ń kó àparò yìí, ẹni tó kó kéré jùlọ kó ìwọ̀n homeri mẹ́wàá, wọ́n sì ṣà wọ́n sílẹ̀ fún ara wọn yí gbogbo ibùdó.
І встав наро́д, і ці́лий той день і ці́лу ту ніч, і ці́лий день назавтра збирали перепели́цю. Хто збирав мало, той зібрав десять хомерів, і порозкладали їх собі скрізь навколо табо́ру.
33 Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹran náà sì wà láàrín eyín wọn, kó tó di pé wọ́n jẹ ẹ́, ìbínú Olúwa sì ru sí àwọn ènìyàn, ó sì pa wọ́n pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn.
Те м'ясо було ще між їхніми зубами, поки було пожуване, а гнів Господній запалився на народ! І вдарив Господь дуже великою пора́зкою в народ...
34 Torí èyí ni wọ́n ṣe pe ibẹ̀ ní Kibirotu-Hattaafa nítorí pé níbẹ̀ ni wọ́n gbé sìnkú àwọn ènìyàn tó ní ọ̀kánjúwà oúnjẹ sí.
І названо ймення того місця: Ківрот-Гаттаава, бо там поховали народ пожадли́вий.
35 Àwọn ènìyàn yòókù sì gbéra láti Kibirotu-Hattaafa lọ pa ibùdó sí Haserotu wọ́n sì dúró níbẹ̀.
З Ківрот-Гаттаави рушили люди до Гацероту, і були в Гацероті.

< Numbers 11 >