< Numbers 11 >

1 Àwọn ènìyàn ń ṣe àròyé nípa wàhálà wọn sí etí ìgbọ́ Olúwa. Ìbínú Olúwa sì ru sókè nígbà tí ó gbọ́ àròyé yìí. Nígbà náà ni iná jáde láti ọ̀dọ̀ Olúwa bọ́ sí àárín wọn, ó sì run àwọn tó wà ní òpin ibùdó.
Na rĩrĩ, andũ a Isiraeli magĩteta nĩ ũndũ wa moritũ mao, nakuo gũteta kwao gũkĩiguuo nĩ Jehova, na rĩrĩa aamaiguire, agĩakanwo nĩ marakara, naguo mwaki ũkiuma kũrĩ Jehova, ũgĩakana gatagatĩ kao, na ũgĩcina ndeere imwe cia kambĩ.
2 Nígbà náà ni àwọn ènìyàn kígbe sí Mose, Mose sì gbàdúrà sí Olúwa iná náà sì kú.
Rĩrĩa andũ acio maakaĩire Musa, Musa akĩhooya Jehova, naguo mwaki ũcio ũkĩhora.
3 Wọ́n sì ń pe ibẹ̀ ní Tabera nítorí pé, iná láti ọ̀dọ̀ Olúwa jó láàrín wọn.
Nĩ ũndũ ũcio handũ hau hagĩĩtwo Tabera, tondũ mwaki ũcio woimĩte kũrĩ Jehova nĩwakanĩte gatagatĩ kao.
4 Àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn aláìníláárí tó wà láàrín àwọn ọmọ Israẹli pẹ̀lú ọkàn ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wọn fi ìtara béèrè fún oúnjẹ mìíràn, àwọn ọmọ Israẹli náà bá bẹ̀rẹ̀ sí í sọkún wí pé, “Bí i pé kí á rí ẹran jẹ báyìí!
Kĩrĩndĩ kĩrĩa kĩarũmanĩrĩire nao makiuma bũrũri wa Misiri gĩkĩambĩrĩria kwĩrirĩria irio cia mĩthemba ĩngĩ, na o rĩngĩ andũ a Isiraeli makĩambĩrĩria kũrĩra, makiuga atĩrĩ, “Naarĩ korwo tũrĩ na nyama cia kũrĩa!
5 Àwa rántí ẹja tí à ń jẹ lọ́fẹ̀ẹ́ ní Ejibiti, apálà, bàrà, ewébẹ̀, àlùbọ́sà àti àwọn ẹ̀fọ́ mìíràn.
Nĩtũkũririkana thamaki iria twarĩĩaga kũu bũrũri wa Misiri tũtekũgũra, o na marenge ma mĩthemba mĩthemba, na itũngũrũ cia mahuti, na itũngũrũ iria ndungu, o na itũngũrũ thumu.
6 Ṣùgbọ́n báyìí gbogbo ara wa ti gbẹ, kò sí ohun mìíràn láti jẹ àfi manna nìkan tí a rí yìí!”
No rĩu, tũtirĩ na wendo wa kũrĩa; na tũtirĩ kĩndũ o nakĩ tuonaga, tiga o mana maya moiki!”
7 Manna náà dàbí èso korianderi, ìrísí rẹ̀ sì dàbí oje igi.
Mana macio maahaanaga ta mbegũ cia mũtĩ ũrĩa wĩtagwo korianda, na mũhianĩre wamo watariĩ ta bedola.
8 Àwọn ènìyàn náà ń lọ káàkiri láti kó o, wọn ó lọ̀ ọ́ lórí ọlọ tàbí kí wọ́n gún un nínú odó. Wọ́n le sè é nínú ìkòkò tàbí kí wọn ó fi ṣe àkàrà, adùn rẹ̀ yóò sì dàbí adùn ohun tí a fi òróró ṣe.
Andũ maathiiaga makamongania, magacooka makamathĩa na gĩthĩi kĩa moko, kana makamahũrĩra ndĩrĩ-inĩ na mũũthĩ. Maamarugaga na nyũngũ kana magathondeka tũmĩgate. Na maacamaga ta kĩndũ gĩthondeketwo na maguta ma mũtamaiyũ.
9 Nígbà tí ìrì bá ẹ̀ sí ibùdó lórí ni manna náà máa ń bọ́ pẹ̀lú rẹ̀.
Rĩrĩa kwagĩa ime ũtukũ kũu kambĩ-inĩ, mana macio makagũanĩra narĩo.
10 Mose sì gbọ́ tí àwọn ènìyàn ń sọkún ní gbogbo ìdílé wọn, oníkálùkù ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ tirẹ̀. Olúwa sì bínú gidigidi. Inú Mose sì bàjẹ́ pẹ̀lú.
Musa nĩaiguire andũ a nyũmba ciothe makĩrĩra, o mũndũ arĩ mũromo-inĩ wa hema yake. Nake Jehova nĩarakarire mũno makĩria, na Musa agĩthĩĩnĩka.
11 Mose sì béèrè lọ́wọ́ Olúwa pé, “Kí ló dé tí o fi mú wàhálà yìí bá ìránṣẹ́ rẹ? Kí ni mo ṣe tí n kò fi tẹ ọ lọ́rùn tí ìwọ fi di ẹrù àwọn ènìyàn wọ̀nyí lé mi lórí.
Akĩũria Jehova atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ gĩtũmĩte ũrehere ndungata yaku thĩĩna ũyũ? Nĩ atĩa njĩkĩte ũkaaga gũgũkenia nĩguo ũnjigĩrĩre mũrigo wa andũ aya othe?
12 Èmi ni mo ha lóyún gbogbo àwọn ènìyàn wọ̀nyí bí? Àbí èmi ló bí wọn? Tí ìwọ fi sọ fún mi pé, máa gbé wọn sí oókan àyà rẹ, gẹ́gẹ́ bí abiyamọ ti máa ń gbe ọmọ ọmú lọ sí ilẹ̀ tí o ti búra láti fún àwọn baba ńlá wọn.
Kaĩ arĩ niĩ ithe wao? Kaĩ arĩ niĩ ndaamaciarire? Nĩ kĩĩ kĩratũma ũnjĩĩre ndĩmakuue na moko makwa, ta ũrĩa mũreri wa mwana akuuaga kaana ka rũkenge, ndĩmatware bũrũri ũrĩa werĩire maithe mao ma tene na mwĩhĩtwa?
13 Níbo ni n ó ti rí ẹran fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí? Nítorí wọ́n ń sọkún sí mi pé, ‘Fún wa lẹ́ran jẹ́!’
Ingĩruta nyama cia kũhe andũ aya othe kũ? Marandĩrĩra makiugaga atĩrĩ, ‘Tũhe nyama tũrĩe!’
14 Èmi nìkan kò lè dágbé wàhálà àwọn ènìyàn wọ̀nyí, ẹrù wọn ti wúwo jù fún mi.
Ndingĩhota gũkuua andũ aya othe ndĩ nyiki; mũrigo ũyũ nĩ mũritũ mũno kũrĩ niĩ.
15 Bí ó bá sì ṣe pé báyìí ni ìwọ ó ṣe máa ṣe fún mi, kúkú pa mí báyìí, tí mo bá ti bá ojúrere rẹ pàdé—kí ojú mi má ba à rí ìparun mi.”
Angĩkorwo ũguo nĩguo ũkũnjĩka-rĩ, njũraga o ro rĩu, angĩkorwo nĩnjĩtĩkĩrĩkĩte nĩwe, na ndũkareke nyone mwanangĩko wakwa mwene.”
16 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú àádọ́rin ọkùnrin nínú àwọn àgbàgbà àwọn ọmọ Israẹli, àwọn tí o mọ̀ gẹ́gẹ́ bí olórí àti olóyè láàrín àwọn ènìyàn wá sínú àgọ́ ìpàdé, kí wọ́n lé dúró níwájú mi.
Nake Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ: “Ndehere athuuri mĩrongo mũgwanja a Isiraeli arĩa wee ũũĩ atĩ nĩ atongoria na anene thĩinĩ wa andũ aya. Ũmarehe Hema-inĩ-ya-Gũtũnganwo, nĩguo marũgame hau hamwe nawe.
17 Èmi ó sì sọ̀kalẹ̀ wá bá yín sọ̀rọ̀ níbẹ̀. Èmi ó sì mú díẹ̀ nínú agbára Ẹ̀mí tí ń bẹ lára rẹ láti fi sí orí àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Wọn ó sì máa ràn ọ́ lọ́wọ́ láti ru àjàgà àwọn ènìyàn kí ó má ṣe pé ìwọ nìkan ni ó o máa ru àjàgà náà.
Niĩ na niĩ nĩngũikũrũka ngwarĩrie ho, njoe Roho ũrĩa ũrĩ naguo na ndĩmekĩre Roho ũcio. Nao nĩmarĩgũteithagia gũkuua mũrigo wa andũ aya nĩgeetha ndũkaũkuuage ũrĩ wiki.
18 “Sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, ‘Ẹ ya ara yín sí mímọ́ ní ìmúrasílẹ̀ fún ọ̀la, ẹ ó sì jẹ ẹran. Nítorí pé Olúwa ti gbọ́ igbe ẹkún yín, èyí tí ẹ sun pé, “Ìbá ṣe pé a lè rí ẹran jẹ ni! Ó sàn fún wa ní Ejibiti jù báyìí lọ!” Nítorí náà ni Olúwa yóò fi fún yín ní ẹran, ẹ ó sì jẹ ẹ́.
“Ningĩ wĩre andũ atĩrĩ, ‘Mwĩtheriei, mwĩhaarĩrie nĩ ũndũ wa rũciũ, rĩrĩa mũkaarĩa nyama. Jehova nĩaramũiguire rĩrĩa mũrarĩraga, mũkiugaga atĩrĩ, “Naarĩ korwo tũrĩ na nyama cia kũrĩa! Maũndũ maitũ maarĩ mega rĩrĩa twarĩ bũrũri wa Misiri!” Rĩu-rĩ, Jehova nĩekũmũhe nyama, na nĩmũgũcirĩa.
19 Ẹ kò ní i jẹ ẹ́ fún ọjọ́ kan, ọjọ́ méjì, ọjọ́ márùn-ún, ọjọ́ mẹ́wàá tàbí ogúnjọ́ lásán,
Na rĩrĩ, mũtigũcirĩa o mũthenya ũmwe, kana mĩthenya ĩĩrĩ, kana ĩtano, kana ikũmi, kana mĩthenya mĩrongo ĩĩrĩ,
20 ṣùgbọ́n fún odidi oṣù kan, títí tí ẹran náà yóò fi máa yọ ní imú yín, tí yóò sì sú yín, nítorí pé ẹ ti kẹ́gàn Olúwa tí ó wà láàrín yín, ẹ sì ti sọkún fún un wí pé, “Kí ló dé tí a fi kúrò ní Ejibiti gan an?”’”
no mũgũcirĩa mweri mũgima, o nginya ciume na maniũrũ manyu, na inyuĩ mũcinyire, nĩ ũndũ nĩmũregete Jehova ũrĩa ũrĩ hamwe na inyuĩ, na mũkarĩra mũrĩ mbere yake, mũkiugaga atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ gĩatũmire tuume bũrũri wa Misiri?”’”
21 Ṣùgbọ́n Mose sọ pé, “Mo wà láàrín ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ènìyàn ni ìrìnkiri, ó sì sọ pé, ‘Èmi ó fún wọn ní ẹran láti jẹ fún oṣù kan gbáko!’
No Musa akĩĩra Jehova atĩrĩ, “Andũ arĩa ndĩ nao haha nĩ ngiri magana matandatũ arĩa maretwara na magũrũ, nawe woiga atĩ, ‘Nĩngũmahe nyama cia kũrĩa mweri mũgima!’
22 Ǹjẹ́ bí a tilẹ̀ pa àgbò ẹran àti ọmọ ẹran, yóò ha tó wọn bí? Tàbí bí a tilẹ̀ pa gbogbo ẹja inú omi fún wọn, yóò wa tó bí?”
Andũ aya o na mangĩthĩnjĩrwo ndũũru cia mbũri na cia ngʼombe-rĩ, no imaigane? O na mangĩtegerwo thamaki ciothe cia iria-inĩ-rĩ, no imaigane?”
23 Olúwa sì dá Mose lóhùn pé, “Ọwọ́ Olúwa ha kúrú bí? Ìwọ yóò ri nísinsin yìí bóyá ọ̀rọ̀ tí mo sọ yóò ṣẹ tàbí kò ni í ṣẹ.”
Jehova agĩcookeria Musa atĩrĩ, “Anga hinya wa guoko kwa Jehova nĩũnyiihĩte? Rĩu wee, nĩũkuona kana ũrĩa njugĩte nĩũkahingio kana ndũkahingio.”
24 Mose sì jáde, ó sọ ohun tí Olúwa wí fún àwọn ènìyàn. Ó mú àwọn àádọ́rin àgbàgbà Israẹli dúró yí àgọ́ ká.
Nĩ ũndũ ũcio Musa akiuma nja, akĩĩra andũ acio ũrĩa Jehova oigĩte. Nake agĩcookanĩrĩria athuuri amwe ao mĩrongo mũgwanja, akĩmarũgamia marigiicĩirie Hema ĩyo.
25 Nígbà náà ni Olúwa sọ̀kalẹ̀ nínú àwọ̀ sánmọ̀ ó sì bá wọn sọ̀rọ̀, ó sì mú lára Ẹ̀mí tó wà lára Mose sí ara àwọn àádọ́rin àgbàgbà náà, Ó sì ṣẹlẹ̀ pé nígbà tí Ẹ̀mí náà bà lé wọn, wọ́n sọtẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n lẹ́yìn èyí wọn kò sọtẹ́lẹ̀ mọ́.
Nake Jehova agĩikũrũka na itu akĩaria na Musa, akĩoya Roho ũrĩa warĩ thĩinĩ wa Musa, na agĩĩkĩra Roho ũcio thĩinĩ wa athuuri acio mĩrongo mũgwanja. Rĩrĩa Roho okire igũrũ rĩao-rĩ, makĩratha mohoro, no matiacookire gwĩka ũguo hĩndĩ ĩngĩ.
26 Àwọn ọkùnrin méjì, tí orúkọ wọn ń jẹ́ Eldadi àti Medadi kò kúrò nínú àgọ́. Orúkọ wọn wà lára àádọ́rin àgbàgbà yìí ṣùgbọ́n wọn kò jáde nínú àgọ́ síbẹ̀ Ẹ̀mí náà bà lé wọn, wọ́n sì sọtẹ́lẹ̀ nínú àgọ́.
No rĩrĩ, andũ eerĩ, nĩo Elidadi na Medadi, nĩmatigĩtwo kambĩ. Nao nĩmandĩkĩtwo hamwe na athuuri acio angĩ no matiathiĩte Hema-inĩ ĩyo. No rĩrĩ, Roho nĩ okire igũrũ rĩao, nao makĩratha mohoro marĩ kũu kambĩ.
27 Ọmọkùnrin kan sì sáré lọ sọ fún Mose pé, “Eldadi àti Medadi ń sọtẹ́lẹ̀ nínú àgọ́.”
Mwanake ũmwe agĩtengʼera akĩĩra Musa atĩrĩ, “Elidadi na Medadi nĩmararatha mohoro kũu kambĩ.”
28 Joṣua ọmọ Nuni tí í ṣe ìránṣẹ́ Mose, láti kékeré tó jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ dáhùn pé, “Mose olúwa mi, dá wọn lẹ́kun!”
Joshua mũrũ wa Nuni, ũrĩa wateithagia Musa kuuma arĩ mũnini, akĩarĩria Musa, akĩmwĩra atĩrĩ, “Musa, mwathi wakwa, makaanie!”
29 Mose sì wí fún un pé, “Àbí ìwọ ń jowú nítorí mi? Ìbá ti wù mí tó, kí gbogbo àwọn ènìyàn Olúwa jẹ́ wòlíì, kí Olúwa sì fi Ẹ̀mí rẹ̀ sí wọn lára!”
No Musa akĩmũcookeria atĩrĩ, “Kaĩ ũkũigua ũiru nĩ ũndũ wakwa? Niĩ ingĩenda andũ othe a Jehova makorwo marĩ anabii, na atĩ Jehova amekĩre Roho wake!”
30 Mose àti àwọn àgbàgbà Israẹli yìí sì padà sínú àgọ́.
Thuutha ũcio Musa na athuuri acio a Isiraeli magĩcooka kambĩ.
31 Afẹ́fẹ́ sì jáde láti ọ̀dọ̀ Olúwa ó sì kó àparò wá láti inú Òkun. Ó sì dà wọ́n káàkiri gbogbo ibùdó ní ìwọ̀n gíga ẹsẹ̀ bàtà mẹ́ta sórí ilẹ̀, bí ìwọ̀n ìrìn ọjọ́ kan ní gbogbo àyíká.
Na rĩrĩ, rũhuho rũkiuma harĩ Jehova, rũkĩrehe tũmakia-arũme kuuma iria-inĩ. Rũgĩtũgũithia tũthiũrũrũkĩirie mĩena yothe ya kambĩ buti ithatũ kuuma thĩ, handũ ha itĩĩna rĩa rũgendo rwa mũthenya mũgima mbarĩ ciothe.
32 Ní gbogbo ọjọ́ náà àti òru, títí dé ọjọ́ kejì ni àwọn ènìyàn fi ń kó àparò yìí, ẹni tó kó kéré jùlọ kó ìwọ̀n homeri mẹ́wàá, wọ́n sì ṣà wọ́n sílẹ̀ fún ara wọn yí gbogbo ibùdó.
Mũthenya ũcio wothe na ũtukũ, na mũthenya ũcio ũngĩ wothe, andũ acio makiumagara makĩũngania tũmakia-arũme. Gũtirĩ mũndũ wonganirie thuutha wa homeri ikũmi. Ningĩ magĩtwanĩka gũthiũrũrũkĩria kambĩ yothe.
33 Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹran náà sì wà láàrín eyín wọn, kó tó di pé wọ́n jẹ ẹ́, ìbínú Olúwa sì ru sí àwọn ènìyàn, ó sì pa wọ́n pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn.
No rĩrĩ, rĩrĩa nyama icio ciarĩ tũnua-inĩ twao, o na itarĩ ndanuke-rĩ, marakara ma Jehova magĩakanĩra andũ acio, akĩmahũũra na mũthiro mũnene.
34 Torí èyí ni wọ́n ṣe pe ibẹ̀ ní Kibirotu-Hattaafa nítorí pé níbẹ̀ ni wọ́n gbé sìnkú àwọn ènìyàn tó ní ọ̀kánjúwà oúnjẹ sí.
Tondũ ũcio handũ hau hagĩĩtwo Kibirothu-Hataava, nĩ ũndũ hau nĩho maathikire andũ arĩa maaiguĩte thuti ya irio ingĩ.
35 Àwọn ènìyàn yòókù sì gbéra láti Kibirotu-Hattaafa lọ pa ibùdó sí Haserotu wọ́n sì dúró níbẹ̀.
Kuuma Kibirothu-Hataava, andũ acio nĩmathiire rũgendo, magĩkinya Hazerothu, magĩikara kuo.

< Numbers 11 >