< Numbers 11 >

1 Àwọn ènìyàn ń ṣe àròyé nípa wàhálà wọn sí etí ìgbọ́ Olúwa. Ìbínú Olúwa sì ru sókè nígbà tí ó gbọ́ àròyé yìí. Nígbà náà ni iná jáde láti ọ̀dọ̀ Olúwa bọ́ sí àárín wọn, ó sì run àwọn tó wà ní òpin ibùdó.
Le peuple se plaignait aux oreilles de l'Éternel. Lorsque l'Éternel l'entendit, sa colère s'enflamma; le feu de l'Éternel brûla au milieu d'eux et consuma une partie des abords du camp.
2 Nígbà náà ni àwọn ènìyàn kígbe sí Mose, Mose sì gbàdúrà sí Olúwa iná náà sì kú.
Le peuple cria à Moïse; Moïse pria l'Éternel, et le feu s'apaisa.
3 Wọ́n sì ń pe ibẹ̀ ní Tabera nítorí pé, iná láti ọ̀dọ̀ Olúwa jó láàrín wọn.
On donna à ce lieu le nom de Tabérah, parce que le feu de Yahvé brûlait au milieu d'eux.
4 Àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn aláìníláárí tó wà láàrín àwọn ọmọ Israẹli pẹ̀lú ọkàn ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wọn fi ìtara béèrè fún oúnjẹ mìíràn, àwọn ọmọ Israẹli náà bá bẹ̀rẹ̀ sí í sọkún wí pé, “Bí i pé kí á rí ẹran jẹ báyìí!
La multitude mélangée qui était au milieu d'eux se livra à des excès de luxure; et les enfants d'Israël pleurèrent de nouveau, et dirent: Qui nous donnera de la viande à manger?
5 Àwa rántí ẹja tí à ń jẹ lọ́fẹ̀ẹ́ ní Ejibiti, apálà, bàrà, ewébẹ̀, àlùbọ́sà àti àwọn ẹ̀fọ́ mìíràn.
Nous nous souvenons du poisson que nous avons mangé pour rien en Égypte, des concombres, des melons, des poireaux, des oignons et de l'ail;
6 Ṣùgbọ́n báyìí gbogbo ara wa ti gbẹ, kò sí ohun mìíràn láti jẹ àfi manna nìkan tí a rí yìí!”
mais maintenant nous avons perdu l'appétit. Il n'y a rien du tout, sauf cette manne, à regarder ».
7 Manna náà dàbí èso korianderi, ìrísí rẹ̀ sì dàbí oje igi.
La manne était semblable à de la graine de coriandre, et elle ressemblait à du bdellium.
8 Àwọn ènìyàn náà ń lọ káàkiri láti kó o, wọn ó lọ̀ ọ́ lórí ọlọ tàbí kí wọ́n gún un nínú odó. Wọ́n le sè é nínú ìkòkò tàbí kí wọn ó fi ṣe àkàrà, adùn rẹ̀ yóò sì dàbí adùn ohun tí a fi òróró ṣe.
Le peuple la parcourait, la ramassait, la broyait dans des moulins, la battait dans des mortiers, la faisait bouillir dans des marmites et en faisait des gâteaux. Son goût était comme celui de l'huile fraîche.
9 Nígbà tí ìrì bá ẹ̀ sí ibùdó lórí ni manna náà máa ń bọ́ pẹ̀lú rẹ̀.
Lorsque la rosée tombait sur le camp pendant la nuit, la manne y tombait.
10 Mose sì gbọ́ tí àwọn ènìyàn ń sọkún ní gbogbo ìdílé wọn, oníkálùkù ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ tirẹ̀. Olúwa sì bínú gidigidi. Inú Mose sì bàjẹ́ pẹ̀lú.
Moïse entendit le peuple pleurer dans toute sa famille, chacun à l'entrée de sa tente; la colère de Yahvé s'enflamma, et Moïse fut mécontent.
11 Mose sì béèrè lọ́wọ́ Olúwa pé, “Kí ló dé tí o fi mú wàhálà yìí bá ìránṣẹ́ rẹ? Kí ni mo ṣe tí n kò fi tẹ ọ lọ́rùn tí ìwọ fi di ẹrù àwọn ènìyàn wọ̀nyí lé mi lórí.
Moïse dit à Yahvé: « Pourquoi as-tu traité ton serviteur si mal? Pourquoi n'ai-je pas trouvé grâce à tes yeux, pour que tu fasses peser sur moi le poids de tout ce peuple?
12 Èmi ni mo ha lóyún gbogbo àwọn ènìyàn wọ̀nyí bí? Àbí èmi ló bí wọn? Tí ìwọ fi sọ fún mi pé, máa gbé wọn sí oókan àyà rẹ, gẹ́gẹ́ bí abiyamọ ti máa ń gbe ọmọ ọmú lọ sí ilẹ̀ tí o ti búra láti fún àwọn baba ńlá wọn.
Ai-je conçu tout ce peuple? Les ai-je fait sortir pour que tu me dises: Porte-les dans ton sein, comme une nourrice porte un nourrisson, jusqu'au pays que tu as juré à leurs pères?
13 Níbo ni n ó ti rí ẹran fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí? Nítorí wọ́n ń sọkún sí mi pé, ‘Fún wa lẹ́ran jẹ́!’
Où pourrais-je trouver de la viande pour donner à tous ces gens? Car ils pleurent devant moi en disant: « Donne-nous de la viande, que nous puissions manger.
14 Èmi nìkan kò lè dágbé wàhálà àwọn ènìyàn wọ̀nyí, ẹrù wọn ti wúwo jù fún mi.
Je ne suis pas capable de porter tout ce peuple tout seul, car c'est trop lourd pour moi.
15 Bí ó bá sì ṣe pé báyìí ni ìwọ ó ṣe máa ṣe fún mi, kúkú pa mí báyìí, tí mo bá ti bá ojúrere rẹ pàdé—kí ojú mi má ba à rí ìparun mi.”
Si tu me traites ainsi, tue-moi tout de suite, si j'ai trouvé grâce à tes yeux, et ne me laisse pas voir ma misère. »
16 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú àádọ́rin ọkùnrin nínú àwọn àgbàgbà àwọn ọmọ Israẹli, àwọn tí o mọ̀ gẹ́gẹ́ bí olórí àti olóyè láàrín àwọn ènìyàn wá sínú àgọ́ ìpàdé, kí wọ́n lé dúró níwájú mi.
Yahvé dit à Moïse: « Rassemble auprès de moi soixante-dix hommes parmi les anciens d'Israël, que tu connais comme étant les anciens du peuple et ses dirigeants, et amène-les à la tente de la Rencontre, afin qu'ils s'y tiennent avec toi.
17 Èmi ó sì sọ̀kalẹ̀ wá bá yín sọ̀rọ̀ níbẹ̀. Èmi ó sì mú díẹ̀ nínú agbára Ẹ̀mí tí ń bẹ lára rẹ láti fi sí orí àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Wọn ó sì máa ràn ọ́ lọ́wọ́ láti ru àjàgà àwọn ènìyàn kí ó má ṣe pé ìwọ nìkan ni ó o máa ru àjàgà náà.
Je descendrai et je vous parlerai là. Je prendrai de l'Esprit qui est sur toi et je le mettrai sur eux; ils porteront avec toi le fardeau du peuple, afin que tu ne le portes pas seul.
18 “Sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, ‘Ẹ ya ara yín sí mímọ́ ní ìmúrasílẹ̀ fún ọ̀la, ẹ ó sì jẹ ẹran. Nítorí pé Olúwa ti gbọ́ igbe ẹkún yín, èyí tí ẹ sun pé, “Ìbá ṣe pé a lè rí ẹran jẹ ni! Ó sàn fún wa ní Ejibiti jù báyìí lọ!” Nítorí náà ni Olúwa yóò fi fún yín ní ẹran, ẹ ó sì jẹ ẹ́.
« Dis au peuple: « Sanctifiez-vous en prévision de demain, et vous mangerez de la viande; car vous avez pleuré aux oreilles de Yahvé, en disant: « Qui nous donnera de la viande à manger? Car vous avez pleuré aux oreilles de Yahvé, en disant: « Qui nous donnera de la viande à manger, car nous étions bien en Égypte? ». C'est pourquoi l'Éternel vous donnera de la viande, et vous mangerez.
19 Ẹ kò ní i jẹ ẹ́ fún ọjọ́ kan, ọjọ́ méjì, ọjọ́ márùn-ún, ọjọ́ mẹ́wàá tàbí ogúnjọ́ lásán,
Vous ne mangerez pas un jour, ni deux jours, ni cinq jours, ni dix jours, ni vingt jours,
20 ṣùgbọ́n fún odidi oṣù kan, títí tí ẹran náà yóò fi máa yọ ní imú yín, tí yóò sì sú yín, nítorí pé ẹ ti kẹ́gàn Olúwa tí ó wà láàrín yín, ẹ sì ti sọkún fún un wí pé, “Kí ló dé tí a fi kúrò ní Ejibiti gan an?”’”
mais un mois entier, jusqu'à ce qu'elle vous vienne aux narines et qu'elle vous soit répugnante; car vous avez rejeté l'Éternel qui est au milieu de vous, et vous avez pleuré devant lui, en disant: « Pourquoi sommes-nous sortis d'Égypte? »".
21 Ṣùgbọ́n Mose sọ pé, “Mo wà láàrín ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ènìyàn ni ìrìnkiri, ó sì sọ pé, ‘Èmi ó fún wọn ní ẹran láti jẹ fún oṣù kan gbáko!’
Moïse dit: « Le peuple au milieu duquel je suis est composé de six cent mille hommes à pied; et tu as dit: « Je leur donnerai de la viande, pour qu'ils mangent un mois entier ».
22 Ǹjẹ́ bí a tilẹ̀ pa àgbò ẹran àti ọmọ ẹran, yóò ha tó wọn bí? Tàbí bí a tilẹ̀ pa gbogbo ẹja inú omi fún wọn, yóò wa tó bí?”
Abattra-t-on pour eux des brebis et des bœufs, pour qu'ils en aient assez? Est-ce qu'on rassemblera pour eux tous les poissons de la mer, pour qu'ils en aient assez? ».
23 Olúwa sì dá Mose lóhùn pé, “Ọwọ́ Olúwa ha kúrú bí? Ìwọ yóò ri nísinsin yìí bóyá ọ̀rọ̀ tí mo sọ yóò ṣẹ tàbí kò ni í ṣẹ.”
Yahvé dit à Moïse: « La main de Yahvé est-elle devenue courte? Tu verras maintenant si ma parole s'accomplira pour toi ou non. »
24 Mose sì jáde, ó sọ ohun tí Olúwa wí fún àwọn ènìyàn. Ó mú àwọn àádọ́rin àgbàgbà Israẹli dúró yí àgọ́ ká.
Moïse sortit, et rapporta au peuple les paroles de Yahvé. Il rassembla soixante-dix hommes parmi les anciens du peuple, et les plaça autour de la Tente.
25 Nígbà náà ni Olúwa sọ̀kalẹ̀ nínú àwọ̀ sánmọ̀ ó sì bá wọn sọ̀rọ̀, ó sì mú lára Ẹ̀mí tó wà lára Mose sí ara àwọn àádọ́rin àgbàgbà náà, Ó sì ṣẹlẹ̀ pé nígbà tí Ẹ̀mí náà bà lé wọn, wọ́n sọtẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n lẹ́yìn èyí wọn kò sọtẹ́lẹ̀ mọ́.
Yahvé descendit dans la nuée et lui parla; il prit de l'Esprit qui était sur lui et le mit sur les soixante-dix anciens. Lorsque l'Esprit reposa sur eux, ils prophétisèrent, mais ils ne le firent plus.
26 Àwọn ọkùnrin méjì, tí orúkọ wọn ń jẹ́ Eldadi àti Medadi kò kúrò nínú àgọ́. Orúkọ wọn wà lára àádọ́rin àgbàgbà yìí ṣùgbọ́n wọn kò jáde nínú àgọ́ síbẹ̀ Ẹ̀mí náà bà lé wọn, wọ́n sì sọtẹ́lẹ̀ nínú àgọ́.
Mais deux hommes restèrent dans le camp. Le nom de l'un était Eldad, et le nom de l'autre Médad; et l'Esprit reposa sur eux. Ils étaient de ceux qui avaient été écrits, mais qui n'étaient pas sortis pour aller à la Tente; et ils prophétisaient dans le camp.
27 Ọmọkùnrin kan sì sáré lọ sọ fún Mose pé, “Eldadi àti Medadi ń sọtẹ́lẹ̀ nínú àgọ́.”
Un jeune homme courut en informer Moïse, et dit: « Eldad et Médad prophétisent dans le camp! »
28 Joṣua ọmọ Nuni tí í ṣe ìránṣẹ́ Mose, láti kékeré tó jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ dáhùn pé, “Mose olúwa mi, dá wọn lẹ́kun!”
Josué, fils de Nun, serviteur de Moïse, l'un de ses hommes d'élite, répondit: « Mon seigneur Moïse, interdis-leur! »
29 Mose sì wí fún un pé, “Àbí ìwọ ń jowú nítorí mi? Ìbá ti wù mí tó, kí gbogbo àwọn ènìyàn Olúwa jẹ́ wòlíì, kí Olúwa sì fi Ẹ̀mí rẹ̀ sí wọn lára!”
Moïse lui dit: « Es-tu jaloux à cause de moi? Je voudrais que tout le peuple de Yahvé soit prophète, que Yahvé mette son Esprit sur eux! ».
30 Mose àti àwọn àgbàgbà Israẹli yìí sì padà sínú àgọ́.
Moïse entra dans le camp, lui et les anciens d'Israël.
31 Afẹ́fẹ́ sì jáde láti ọ̀dọ̀ Olúwa ó sì kó àparò wá láti inú Òkun. Ó sì dà wọ́n káàkiri gbogbo ibùdó ní ìwọ̀n gíga ẹsẹ̀ bàtà mẹ́ta sórí ilẹ̀, bí ìwọ̀n ìrìn ọjọ́ kan ní gbogbo àyíká.
Un vent de Yahvé sortit et fit sortir de la mer des cailles qu'il laissa tomber près du camp, à environ un jour de marche de ce côté et un jour de marche de l'autre côté, autour du camp, et à environ deux coudées au-dessus de la surface de la terre.
32 Ní gbogbo ọjọ́ náà àti òru, títí dé ọjọ́ kejì ni àwọn ènìyàn fi ń kó àparò yìí, ẹni tó kó kéré jùlọ kó ìwọ̀n homeri mẹ́wàá, wọ́n sì ṣà wọ́n sílẹ̀ fún ara wọn yí gbogbo ibùdó.
Le peuple se leva tout ce jour-là, toute cette nuit-là et tout le lendemain, et il ramassa les cailles. Celui qui en ramassait le moins en ramassait dix, et ils se les répartirent autour du camp.
33 Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹran náà sì wà láàrín eyín wọn, kó tó di pé wọ́n jẹ ẹ́, ìbínú Olúwa sì ru sí àwọn ènìyàn, ó sì pa wọ́n pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn.
Comme la viande était encore entre leurs dents, avant qu'ils l'aient mâchée, la colère de l'Éternel s'enflamma contre le peuple, et l'Éternel frappa le peuple d'une très grande plaie.
34 Torí èyí ni wọ́n ṣe pe ibẹ̀ ní Kibirotu-Hattaafa nítorí pé níbẹ̀ ni wọ́n gbé sìnkú àwọn ènìyàn tó ní ọ̀kánjúwà oúnjẹ sí.
On donna à ce lieu le nom de Kibroth Hattaavah, parce qu'on y enterra le peuple qui avait eu de la convoitise.
35 Àwọn ènìyàn yòókù sì gbéra láti Kibirotu-Hattaafa lọ pa ibùdó sí Haserotu wọ́n sì dúró níbẹ̀.
De Kibroth Hattaavah, le peuple se rendit à Hatséroth, et il resta à Hatséroth.

< Numbers 11 >