< Numbers 10 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Potem Pan rzekł do Mojżesza, mówiąc:
2 “Ṣe fèrè fàdákà méjì pẹ̀lú fàdákà lílù, kí o máa lò ó láti máa fi pe ìjọ ènìyàn àti láti máa fi darí ìrìnàjò lọ sí ibùdó yín.
Spraw sobie dwie trąby srebrne; robotą ciągnioną uczynisz je, których używać będziesz do zwoływania ludu, i gdyby się wojsko ruszać miało.
3 Nígbà tí o bá fọn méjèèjì gbogbo ìjọ ènìyàn yóò pé síwájú rẹ ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
A gdy zatrąbią w nie, tedy się do ciebie zbieży wszystek lud ku drzwiom namiotu zgromadzenia.
4 Bí ó bá jẹ́ ọ̀kan ni o fọn, nígbà náà ni àwọn olórí ẹ̀yà Israẹli yóò péjọ síwájú rẹ.
A jeźliby w jednę tylko zatrąbiono, tedy się zejdą do ciebie książęta, i hetmani wojsk Izraelskich.
5 Nígbà tí o bá fun ìpè ìdágìrì, àwọn ẹ̀yà tó pa ibùdó sí ìhà ìlà-oòrùn ni yóò gbéra.
Gdyby zaś zatrąbiono głos przerywając, tedy się ruszy obóz leżących na wschód słońca.
6 Nígbà tí o bá fun ìpè ìdágìrì kejì, ibùdó tó wà ní ìhà gúúsù ni yóò gbéra. Ìpè ìdágìrì yìí ni yóò jẹ́ àmì fún gbígbéra.
A gdy drugi raz zatrąbią, głos przerywając, tedy się ruszy obóz leżących na południe; z przerywaniem trąbić będą, gdy się ruszyć będą mieli.
7 Nígbà tí o bá fẹ́ pe ìjọ ènìyàn jọ, fun fèrè nìkan, má ṣe fun ti ìdágìrì pẹ̀lú rẹ̀.
Ale gdy zwoływać lud będziecie, trąbić będziecie, a nie będziecie przerywać.
8 “Àwọn ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ni kí ó máa fun fèrè. Èyí yóò jẹ́ ìlànà láéláé fún yín àti fún ìran tó ń bọ̀.
A synowie Aaronowi, kapłani, trąbić będą w trąby: i będzie wam to za ustawę wieczną w potomstwie waszem.
9 Nígbà tí ẹ bá lọ jagun pẹ̀lú àwọn ọ̀tá tó ń ni yín lára ní ilẹ̀ yín, ẹ fun ìpè ìdágìrì pẹ̀lú fèrè. A ó sì rántí yín níwájú Olúwa, Ọlọ́run yín yóò sì gbà yín lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá yín.
A gdy wyciągniecie na wojnę w ziemi waszej przeciwko nieprzyjacielowi, któryby was trapił, z przerywaniem w trąby trąbić będziecie; a przyjdziecie na pamięć przed Panem, Bogiem waszym, i zachowani będziecie od nieprzyjciół waszych.
10 Bẹ́ẹ̀ náà ni ní ọjọ́ ayọ̀ yín, ní gbogbo àjọ̀dún tí a yàn àti ní ìbẹ̀rẹ̀ oṣù yín, ni kí ẹ máa fun fèrè lórí ẹbọ sísun àti ọrẹ àlàáfíà yín, wọn yóò sì jẹ́ ìrántí fún yín níwájú Ọlọ́run. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.”
W dzień także wesela waszego, i w święta uroczyste wasze, i na nowiu miesięcy waszych, będziecie trąbić w te trąby przy ofiarach waszych całopalnych, i przy ofiarach waszych spokojnych, i przywiodą was na pamięć przed Bogiem waszym; Ja Pan, Bóg wasz.
11 Ní ogúnjọ́ oṣù kejì, ní ọdún kejì ni ìkùùkuu kúrò lórí tabanaku ẹ̀rí.
I stało się roku wtórego, miesiąca wtórego, dnia dwudziestego tegoż miesiąca, że się podniósł obłok przybytku świadectwa.
12 Àwọn ọmọ Israẹli sì gbéra kúrò ní aginjù Sinai wọ́n sì rin ìrìnàjò wọn káàkiri títí tí ìkùùkuu fi dúró sí aginjù Parani.
I ruszyli się synowie Izraelscy z hufcami swymi z puszczy Synaj, a stanął obłok na puszczy Faran.
13 Wọ́n gbéra nígbà àkọ́kọ́ yìí nípa àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose.
I ruszyli się najpierwej tak, jako był Pan rozkazał przez Mojżesza.
14 Àwọn ìpín ti ibùdó Juda ló kọ́kọ́ gbéra tẹ̀lé wọn lábẹ́ ogun wọn Nahiṣoni ọmọ Amminadabu ni ọ̀gágun wọn.
Albowiem ruszyła się chorągiew obozu synów Judowych naprzód z hufcami swemi, a nad wojskiem jego był hetman Naason, syn Aminadabów.
15 Netaneli ọmọ Suari ni ọ̀gágun ti ẹ̀yà Isakari;
A nad wojskiem pokolenia synów Isascharowych był hetmanem Natanael, syn Suharów.
16 Eliabu ọmọ Heloni ni ọ̀gágun ni ìpín ti ẹ̀yà Sebuluni.
A nad wojskiem pokolenia synów Zabulonowych był hetmanem Elijab, syn Helonów.
17 Nígbà náà ni wọ́n sọ tabanaku kalẹ̀ àwọn ọmọ Gerṣoni àti Merari tó gbé àgọ́ sì gbéra.
Zatem złożono przybytek, i ciągnęli synowie Gersonowi, i synowie Merarego, niosąc przybytek.
18 Àwọn ìpín ti ibùdó ti Reubeni ló gbéra tẹ̀lé wọn, lábẹ́ ọ̀págun wọn. Elisuri ọmọ Ṣedeuri ni ọ̀gágun wọn.
Ruszyła się zaś chorągiew obozu Rubenowego z hufcami swemi, a nad wojskiem jego był hetmanem Elisur, syn Sedeurów.
19 Ṣelumieli ọmọ Suriṣaddai ni ọ̀gágun ti ẹ̀yà Simeoni.
A nad wojskiem pokolenia synów Symeonowych był hetmanem Selumijel, syn Surysaddajów.
20 Eliasafu ọmọ Deueli ni ọ̀gágun ìpín ti ẹ̀yà Gadi.
A nad wojskiem też pokolenia synów Gadowych był hetmanem Elijazaf, syn Duelów.
21 Nígbà náà ni àwọn ọmọ Kohati tí ń ru ohun mímọ́ náà gbéra. Àwọn ti àkọ́kọ́ yóò sì ti gbé tabanaku dúró kí wọn tó dé.
Zatem ruszyli się Kaatytowie, niosąc świątnicę, i stanowili przybytek, aż ci nadciągnęli.
22 Àwọn ìpín tó wà ní ibùdó Efraimu ló tún kàn lábẹ́ ọ̀págun wọn. Eliṣama ọmọ Ammihudu ni ọ̀gágun wọn.
Potem ruszyła się chorągiew obozu synów Efraimowych z hufcami swemi, a nad wojskiem jego był hetmanem Elisama, syn Ammiudów.
23 Gamalieli ọmọ Pedasuri ni ọ̀gágun ìpín ti ẹ̀yà Manase.
Nad wojskiem zaś pokolenia synów Manasesowych był hetmanem Gamalijel, syn Pedasurów.
24 Abidani ọmọ Gideoni ni ọ̀gágun ìpín ti ẹ̀yà Benjamini.
Nad wojskiem zaś pokolenia synów Benjaminowych był hetmanem Abidan, syn Gedeonów.
25 Lákòótan, àwọn ọmọ-ogun tó ń mójútó ẹ̀yìn ló tún kàn, àwọn ni ìpín ti ibùdó Dani lábẹ́ ọ̀págun wọn. Ahieseri ọmọ Ammiṣaddai ni ọ̀gágun wọn.
Potem ruszyła się chorągiew obozu synów Danowych zawierając wszystkie obozy z wojski ich, a nad wojskiem jego był hetmanem Achyjezer, syn Ammisaddajów.
26 Pagieli ọmọ Okanri ni ìpín ti ẹ̀yà Aṣeri,
A nad wojskiem pokolenia synów Eserowych był hetmanem Pagijel, syn Ochranów.
27 Ahira ọmọ Enani ni ọ̀gágun ti ẹ̀yà Naftali.
A nad wojskiem pokolenia synów Neftalimowych był hetmanem Ahira, syn Enanów.
28 Báyìí ni àwọn ọmọ Israẹli ṣe tò jáde gẹ́gẹ́ bí ogun nígbà tí wọ́n bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn.
Takieć było ciągnienie synów Izraelskich z hufcami ich; i tak ciągnęli.
29 Mose sì sọ fún Hobabu ọmọ Reueli ará Midiani tí í ṣe àna rẹ̀ pé, “A ń gbéra láti lọ sí ibi tí Olúwa sọ pé, ‘Èmi ó fi fún un yín.’ Bá wa lọ, àwa ó ṣe ọ́ dáradára nítorí pé Olúwa ti ṣèlérí ohun rere fún Israẹli.”
Potem rzekł Mojżesz do Hobaba, syna Raguelowego Madyjańczyka, świekra swego: My ciągniemy do miejsca, o którem rzekł Pan: Dam je wam. Pójdź z nami, a uczynimyć dobrze, ponieważ Pan obiecał wiele dobrego Izraelowi.
30 Ó sì dáhùn pé, “Rárá, èmi kò ní bá yín lọ, mò ń padà lọ sí ilẹ̀ mi àti sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn mi.”
Któremu on odpowiedział: Nie pójdę: ale się wrócę do ziemi mojej i do rodziny mojej.
31 Mose sì sọ pé, “Jọ̀wọ́ ma fi wá sílẹ̀, ìwọ mọ ibi tí a lè pa ibùdó sí nínú aginjù, ìwọ yóò sì jẹ́ ojú fún wa.
I rzekł Mojżesz: Proszę, nie opuszczaj nas; bo ty wiesz, gdzie byśmy na puszczy obóz stanowić mieli, i będziesz przewodnikiem naszym.
32 Bí o bá bá wa lọ, a ó sì pín fún ọ nínú ohun rere yówù tí Olúwa bá fún wa.”
A jeźliż pójdziesz z nami, i spotka nas to dobre, którem nam Pan uczyni dobrze, i my dobrze uczynimy tobie.
33 Wọ́n sì gbéra láti orí òkè Olúwa ní ìrìn ọjọ́ mẹ́ta. Àpótí ẹ̀rí Olúwa ń lọ níwájú wọn fún gbogbo ọjọ́ mẹ́ta yìí láti wá ibi ìsinmi fún wọn.
I odciągnęli od góry Pańskiej drogą trzech dni, a skrzynia przymierza Pańskiego szła przed nimi drogą trzech dni, aby im upatrzyła miejsce odpocznienia.
34 Ìkùùkuu Olúwa wà lórí wọn lọ́sàn nígbà tí wọ́n gbéra kúrò ní ibùdó.
A obłok Pański szedł nad nimi we dnie, gdy się ruszali z stanowiska.
35 Nígbàkígbà tí àpótí ẹ̀rí bá gbéra Mose yóò sì wí pé, “Dìde, Olúwa! Kí a tú àwọn ọ̀tá rẹ ká, kí àwọn tí ó kórìíra rẹ sì sálọ níwájú rẹ.”
A gdy się ruszyć miała skrzynia, tedy mawiał Mojżesz: Powstań Panie, a niech będą rozproszeni nieprzyjaciele twoi, a niech uciekają, którzy cię nienawidzą, przed obliczem twojem.
36 Nígbàkígbà tí àpótí ẹ̀rí bá sinmi yóò wí pé, “Padà, Olúwa, sọ́dọ̀ àwọn àìmoye ẹgbẹẹgbẹ̀rún Israẹli.”
A gdy zaś stanęła, tedy mówił: Nawróć się Panie do niezliczonego mnóstwa wojska Izraelskiego.

< Numbers 10 >