< Numbers 10 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Hoe ty nitsara’ Iehovà amy Mosè:
2 “Ṣe fèrè fàdákà méjì pẹ̀lú fàdákà lílù, kí o máa lò ó láti máa fi pe ìjọ ènìyàn àti láti máa fi darí ìrìnàjò lọ sí ibùdó yín.
Tseneo trompetra volafoty roe am-pipepèhañe; hanontonañe i valobohokey naho hikoihañe ty fiavotañe amy tobey.
3 Nígbà tí o bá fọn méjèèjì gbogbo ìjọ ènìyàn yóò pé síwájú rẹ ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
Ie tiofeñe in-droe le fonga hifanontoñe ama’o an-dalan-kibohom-pamantañañe eo i valobohòkey.
4 Bí ó bá jẹ́ ọ̀kan ni o fọn, nígbà náà ni àwọn olórí ẹ̀yà Israẹli yóò péjọ síwájú rẹ.
F’ie tiofeñe in-draike, le o mpiaoloo, o talèm-pifokoa’ Israeleo, ty hiropak’ ama’o.
5 Nígbà tí o bá fun ìpè ìdágìrì, àwọn ẹ̀yà tó pa ibùdó sí ìhà ìlà-oòrùn ni yóò gbéra.
Ie itiofan-koike le hiavotse o mpitobe atiñanañe eio.
6 Nígbà tí o bá fun ìpè ìdágìrì kejì, ibùdó tó wà ní ìhà gúúsù ni yóò gbéra. Ìpè ìdágìrì yìí ni yóò jẹ́ àmì fún gbígbéra.
Ie tiofen-koike fañindroe’e le o mpitobe atimoo ro hienga; mionjoñe iereo te itiofan-koike.
7 Nígbà tí o bá fẹ́ pe ìjọ ènìyàn jọ, fun fèrè nìkan, má ṣe fun ti ìdágìrì pẹ̀lú rẹ̀.
Naho hatontoñe i valobohòkey, le mitiofa fe tsy an-koike.
8 “Àwọn ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ni kí ó máa fun fèrè. Èyí yóò jẹ́ ìlànà láéláé fún yín àti fún ìran tó ń bọ̀.
O ana’ i Aharoneo, o mpisoroñeo, ro hitioke i trompetray; ho fañè’ areo hanitsike o hene tarira’ areo mifandimbeo.
9 Nígbà tí ẹ bá lọ jagun pẹ̀lú àwọn ọ̀tá tó ń ni yín lára ní ilẹ̀ yín, ẹ fun ìpè ìdágìrì pẹ̀lú fèrè. A ó sì rántí yín níwájú Olúwa, Ọlọ́run yín yóò sì gbà yín lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá yín.
Ie mionjoñe mb’ añ’aly an-tane’ areo ao mb’ ami’ty rafelahy mañembetse anahareo, le hitiofan-koike amo trompetrao, vaho ho tiahy añatrefa’ Iehovà Andrianañahare’ areo vaho ho rombaheñe amo rafelahi’areoo.
10 Bẹ́ẹ̀ náà ni ní ọjọ́ ayọ̀ yín, ní gbogbo àjọ̀dún tí a yàn àti ní ìbẹ̀rẹ̀ oṣù yín, ni kí ẹ máa fun fèrè lórí ẹbọ sísun àti ọrẹ àlàáfíà yín, wọn yóò sì jẹ́ ìrántí fún yín níwájú Ọlọ́run. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.”
Ie amo andro firebeha’ areoo, naho amo andro nifantañeñeo, naho amo jiri-bolañeo le ho tiofe’ areo ambone’ o fisoroña’ areoo naho ambone’ o engam-pañanintsi’ areoo o trompetrao, ho faniahiañe anahareo añatrefan’ Andrianañahare’ areo. Izaho Iehovà Andrianañahare’ areo.
11 Ní ogúnjọ́ oṣù kejì, ní ọdún kejì ni ìkùùkuu kúrò lórí tabanaku ẹ̀rí.
Ie amy andro faha roapolo’ ty volam-paharoe’ i taom-paharoeiy, le naonjoñe ambone’ i kibohom-pañinay i rahoñey.
12 Àwọn ọmọ Israẹli sì gbéra kúrò ní aginjù Sinai wọ́n sì rin ìrìnàjò wọn káàkiri títí tí ìkùùkuu fi dúró sí aginjù Parani.
Le nionjom-beo an-kifange’e o ana’ Israeleo, nienga i fatram-bei’ i Sinaiy vaho nitsangañe am-patrambei’ i Parane eo i rahoñey.
13 Wọ́n gbéra nígbà àkọ́kọ́ yìí nípa àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose.
Izay ty fienga’ iareo valoha’e ami’ty nandilia’ Iehovà am-pità’ i Mosè.
14 Àwọn ìpín ti ibùdó Juda ló kọ́kọ́ gbéra tẹ̀lé wọn lábẹ́ ogun wọn Nahiṣoni ọmọ Amminadabu ni ọ̀gágun wọn.
Ty sain-tobe’ Iehodà ty niavotse valoha’e, an-ki-lia’ ki-lian-dahin-defoñe, talè’ i firimboñan-dahindefo’ey t’i Nakesone ana’ i Aminadabe,
15 Netaneli ọmọ Suari ni ọ̀gágun ti ẹ̀yà Isakari;
naho talè’ i firimboñan-dahin-defom-pifokoa’ o ana’ Isakhareoy t’i Netanele ana’ i Tsoare,
16 Eliabu ọmọ Heloni ni ọ̀gágun ni ìpín ti ẹ̀yà Sebuluni.
vaho talè’ o lahindefom-pifokoa’ o nte-Zeboloneo t’i Eliabe ana’ i Kelone.
17 Nígbà náà ni wọ́n sọ tabanaku kalẹ̀ àwọn ọmọ Gerṣoni àti Merari tó gbé àgọ́ sì gbéra.
Nazotso amy zao i kivohoy vaho nionjoñe o ana’ i Geresoneo naho o ana’ i Merario, ninday i kivohoy.
18 Àwọn ìpín ti ibùdó ti Reubeni ló gbéra tẹ̀lé wọn, lábẹ́ ọ̀págun wọn. Elisuri ọmọ Ṣedeuri ni ọ̀gágun wọn.
Nionjom-beo ka ty sain-tobe’ i Reòbene, naho nitalèm-pirimboñam-pifokoa’e t’i Elitsore ana’ i Sedeore, ty amo lian-dahin-defo’eo,
19 Ṣelumieli ọmọ Suriṣaddai ni ọ̀gágun ti ẹ̀yà Simeoni.
naho talè’ o lahin­defom-pifokoan’ ana’ i Simoneo t’i Selomiele ana’ i Tsorisadahy,
20 Eliasafu ọmọ Deueli ni ọ̀gágun ìpín ti ẹ̀yà Gadi.
vaho talè’ o lahindefom-pifokoan’ ana’ i Gadeo t’i Eliasafe ana’ i Rehoele.
21 Nígbà náà ni àwọn ọmọ Kohati tí ń ru ohun mímọ́ náà gbéra. Àwọn ti àkọ́kọ́ yóò sì ti gbé tabanaku dúró kí wọn tó dé.
Nionjoñe amy zao o nte-Kehàteo ninday o raha miavakeo, fa naoreñe aolo’ ty fiavi’ iareo i kivohoy.
22 Àwọn ìpín tó wà ní ibùdó Efraimu ló tún kàn lábẹ́ ọ̀págun wọn. Eliṣama ọmọ Ammihudu ni ọ̀gágun wọn.
Nionjoñe amy zao ty sain-tobe’ o ana’ i Efraimeo ty amo lian-dahin-defo’eo, i Elisama ana’i Amihode ty talèm-pirimboña’e,
23 Gamalieli ọmọ Pedasuri ni ọ̀gágun ìpín ti ẹ̀yà Manase.
naho talèn-dahin-defom-pifokoan’ ana’ i Menase t’i Gamliele ana’ i Pedatsore,
24 Abidani ọmọ Gideoni ni ọ̀gágun ìpín ti ẹ̀yà Benjamini.
vaho talèn-dahin-defom-pifokoa’ o nte-Beniamèneo t’i Abidane ana’ i Gedoný.
25 Lákòótan, àwọn ọmọ-ogun tó ń mójútó ẹ̀yìn ló tún kàn, àwọn ni ìpín ti ibùdó Dani lábẹ́ ọ̀págun wọn. Ahieseri ọmọ Ammiṣaddai ni ọ̀gágun wọn.
Nionjoñe ami’ty naha-mpivoli’ i tobey ty sain-tobe’ o ana’ i Daneo ty amo lian-dahin-defo’eo; talè’ i firimboña’ey t’i Akièzere, ana’ i Amisedahy,
26 Pagieli ọmọ Okanri ni ìpín ti ẹ̀yà Aṣeri,
naho talèn-dahin-defom-pifokoan’ ana’ i Asere t’i Pejiele ana’ i Okrane,
27 Ahira ọmọ Enani ni ọ̀gágun ti ẹ̀yà Naftali.
vaho talèn-dahin-defom-pifokoan’ ana’ i Naftaly t’i Akirà ana’ i Ainane.
28 Báyìí ni àwọn ọmọ Israẹli ṣe tò jáde gẹ́gẹ́ bí ogun nígbà tí wọ́n bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn.
Izay ty nionjona’ o ana’ Israeleo, ty amo lia-rain-dahin-defo’eo—ie nionjoñe.
29 Mose sì sọ fún Hobabu ọmọ Reueli ará Midiani tí í ṣe àna rẹ̀ pé, “A ń gbéra láti lọ sí ibi tí Olúwa sọ pé, ‘Èmi ó fi fún un yín.’ Bá wa lọ, àwa ó ṣe ọ́ dáradára nítorí pé Olúwa ti ṣèlérí ohun rere fún Israẹli.”
Le hoe t’i Mosè amy Kobabe ana’ i Reoele nte-Midiane, rafoza’ i Mosè, Mionjoñe mb’an-tane’ nitsa­rae’ Iehovà ty hoe: Hatoloko azo. Min­dreza ama’ay, le hanoe’ay soa; amy te nitsara soa ho am’ Israele t’Iehovà.
30 Ó sì dáhùn pé, “Rárá, èmi kò ní bá yín lọ, mò ń padà lọ sí ilẹ̀ mi àti sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn mi.”
Le hoe ty natoi’e, Tsy homb’eo iraho, fa hienga mb’an-taneko naho mb’an-drolongoko añe.
31 Mose sì sọ pé, “Jọ̀wọ́ ma fi wá sílẹ̀, ìwọ mọ ibi tí a lè pa ibùdó sí nínú aginjù, ìwọ yóò sì jẹ́ ojú fún wa.
Aa hoe re, Miambane ama’o, ko mienga kanao fohi’o te hitobe ampatrambey añe vaho ho solom-pihaino’ay irehe.
32 Bí o bá bá wa lọ, a ó sì pín fún ọ nínú ohun rere yówù tí Olúwa bá fún wa.”
Ie amy zao, naho indreza’o lia, le ze hasoa hanoe’ Iehovà ama’ay ro hanoe’ay ama’o.
33 Wọ́n sì gbéra láti orí òkè Olúwa ní ìrìn ọjọ́ mẹ́ta. Àpótí ẹ̀rí Olúwa ń lọ níwájú wọn fún gbogbo ọjọ́ mẹ́ta yìí láti wá ibi ìsinmi fún wọn.
Aa le nenga’ iareo telo andro ty vohi’ Iehovà le niaolo iareo telo andro ty vatam-pañina’ Iehovà hipay fitobeañe.
34 Ìkùùkuu Olúwa wà lórí wọn lọ́sàn nígbà tí wọ́n gbéra kúrò ní ibùdó.
Tambone’ iereo ey i raho’ Iehovày amy antoandro niengà’ iereo i tobeiy.
35 Nígbàkígbà tí àpótí ẹ̀rí bá gbéra Mose yóò sì wí pé, “Dìde, Olúwa! Kí a tú àwọn ọ̀tá rẹ ká, kí àwọn tí ó kórìíra rẹ sì sálọ níwájú rẹ.”
Aa ndra mbia’ mbia ty nionjona’ i vatam-pañinay le niongake t’i Mosè nanao ty ti-hoe: Miongaha, ry Iehovà, abaibaio o rafelahi’oo vaho ampitribaho an-day añatrefa’o o malaiñe Azoo.
36 Nígbàkígbà tí àpótí ẹ̀rí bá sinmi yóò wí pé, “Padà, Olúwa, sọ́dọ̀ àwọn àìmoye ẹgbẹẹgbẹ̀rún Israẹli.”
Ie nitsangañe, le ty hoe ka ty nanoe’e: Mimpolia ry Iehovà amo alealem-pifokoa’ Israeleo.

< Numbers 10 >