< Numbers 10 >
Un Tas Kungs runāja uz Mozu un sacīja:
2 “Ṣe fèrè fàdákà méjì pẹ̀lú fàdákà lílù, kí o máa lò ó láti máa fi pe ìjọ ènìyàn àti láti máa fi darí ìrìnàjò lọ sí ibùdó yín.
Taisi sev divas trumetes(taures), no sudraba tev tās būs izkalt, un tās lai ir priekš draudzes sasaukšanas un priekš lēģera pacelšanas.
3 Nígbà tí o bá fọn méjèèjì gbogbo ìjọ ènìyàn yóò pé síwájú rẹ ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
Kad ar viņām abām pūtīs, tad visai draudzei pie tevis būs sapulcēties priekš saiešanas telts durvīm,
4 Bí ó bá jẹ́ ọ̀kan ni o fọn, nígbà náà ni àwọn olórí ẹ̀yà Israẹli yóò péjọ síwájú rẹ.
Bet ja ar vienu vien pūtīs, tad tiem lieliem kungiem, tiem virsniekiem pār Israēla tūkstošiem pie tevis būs sapulcēties.
5 Nígbà tí o bá fun ìpè ìdágìrì, àwọn ẹ̀yà tó pa ibùdó sí ìhà ìlà-oòrùn ni yóò gbéra.
Kad jūs ar varenu skaņu pūšat, tad tiem lēģeriem būs celties, kas pret rītiem apmetušies.
6 Nígbà tí o bá fun ìpè ìdágìrì kejì, ibùdó tó wà ní ìhà gúúsù ni yóò gbéra. Ìpè ìdágìrì yìí ni yóò jẹ́ àmì fún gbígbéra.
Bet kad jūs ar varenu skaņu otrā kārtā pūšat, tad tiem lēģeriem būs celties, kas pret dienas vidiem apmetušies; ar varenu skaņu būs pūst, kad viņiem jāceļas.
7 Nígbà tí o bá fẹ́ pe ìjọ ènìyàn jọ, fun fèrè nìkan, má ṣe fun ti ìdágìrì pẹ̀lú rẹ̀.
Bet to draudzi sapulcinājot jums būs pūst, tomēr ne ar varenu skaņu.
8 “Àwọn ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ni kí ó máa fun fèrè. Èyí yóò jẹ́ ìlànà láéláé fún yín àti fún ìran tó ń bọ̀.
Un Ārona dēliem, tiem priesteriem, būs tās trumetes pūst, un tas lai jums ir par likumu mūžīgi pie jūsu pēcnākamiem.
9 Nígbà tí ẹ bá lọ jagun pẹ̀lú àwọn ọ̀tá tó ń ni yín lára ní ilẹ̀ yín, ẹ fun ìpè ìdágìrì pẹ̀lú fèrè. A ó sì rántí yín níwájú Olúwa, Ọlọ́run yín yóò sì gbà yín lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá yín.
Un kad jūs savā zemē iesiet karā pret saviem ienaidniekiem, kas jūs spiež, tad jums būs pūst ar varenu skaņu; tad Tas Kungs, jūsu Dievs, jūs pieminēs, un jūs tapsiet izglābti no saviem ienaidniekiem.
10 Bẹ́ẹ̀ náà ni ní ọjọ́ ayọ̀ yín, ní gbogbo àjọ̀dún tí a yàn àti ní ìbẹ̀rẹ̀ oṣù yín, ni kí ẹ máa fun fèrè lórí ẹbọ sísun àti ọrẹ àlàáfíà yín, wọn yóò sì jẹ́ ìrántí fún yín níwájú Ọlọ́run. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.”
Un savā līksmības laikā un savos svētkos un savos jaunos mēnešos jums arīdzan trumetes būs pūst, pie saviem dedzināmiem upuriem un pie saviem pateicības upuriem, lai jūsu Dievs jūs piemin. Es esmu Tas Kungs, jūsu Dievs.
11 Ní ogúnjọ́ oṣù kejì, ní ọdún kejì ni ìkùùkuu kúrò lórí tabanaku ẹ̀rí.
Un notikās otrā gadā, otrā mēnesī, divdesmitā mēneša dienā, ka tās padebesis pacēlās no tā liecības dzīvokļa.
12 Àwọn ọmọ Israẹli sì gbéra kúrò ní aginjù Sinai wọ́n sì rin ìrìnàjò wọn káàkiri títí tí ìkùùkuu fi dúró sí aginjù Parani.
Un Israēla bērni cēlās pēc saviem pulkiem no Sinaī tuksneša, un tas padebesis nolaidās Pārana tuksnesī.
13 Wọ́n gbéra nígbà àkọ́kọ́ yìí nípa àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose.
Tā tie pirmoreiz cēlās pēc Tā Kunga vārda caur Mozu.
14 Àwọn ìpín ti ibùdó Juda ló kọ́kọ́ gbéra tẹ̀lé wọn lábẹ́ ogun wọn Nahiṣoni ọmọ Amminadabu ni ọ̀gágun wọn.
Pa priekšu cēlās Jūda bērnu lēģera karogs, pēc saviem pulkiem, un pār viņa pulku bija Nahšons, Aminadaba dēls,
15 Netaneli ọmọ Suari ni ọ̀gágun ti ẹ̀yà Isakari;
Un pār Īsašara bērnu cilts pulku bija Netaneēls, Cuara dēls,
16 Eliabu ọmọ Heloni ni ọ̀gágun ni ìpín ti ẹ̀yà Sebuluni.
Un pār Zebulona bērnu cilts pulku bija Eliabs, Helona dēls.
17 Nígbà náà ni wọ́n sọ tabanaku kalẹ̀ àwọn ọmọ Gerṣoni àti Merari tó gbé àgọ́ sì gbéra.
Un tas dzīvoklis tapa nocelts, un Geršona bērni un Merarus bērni cēlās un nesa to dzīvokli.
18 Àwọn ìpín ti ibùdó ti Reubeni ló gbéra tẹ̀lé wọn, lábẹ́ ọ̀págun wọn. Elisuri ọmọ Ṣedeuri ni ọ̀gágun wọn.
Pēc tam cēlās Rūbena lēģera karogs pēc saviem pulkiem, un pār viņa pulku bija Elicurs, Šedeūra dēls.
19 Ṣelumieli ọmọ Suriṣaddai ni ọ̀gágun ti ẹ̀yà Simeoni.
Un pār Sīmeana bērnu cilts pulku bija Šelumiēls, Curi-Šadaja dēls.
20 Eliasafu ọmọ Deueli ni ọ̀gágun ìpín ti ẹ̀yà Gadi.
Un pār Gada bērnu cilts pulku bija Eliazavs, Deguēļa dēls.
21 Nígbà náà ni àwọn ọmọ Kohati tí ń ru ohun mímọ́ náà gbéra. Àwọn ti àkọ́kọ́ yóò sì ti gbé tabanaku dúró kí wọn tó dé.
Tad Kehāta bērni cēlās un nesa tās svētuma lietas, un tas dzīvoklis tika uzcelts, kamēr šie atnāca.
22 Àwọn ìpín tó wà ní ibùdó Efraimu ló tún kàn lábẹ́ ọ̀págun wọn. Eliṣama ọmọ Ammihudu ni ọ̀gágun wọn.
Un pēc tam cēlās Efraīma bērnu lēģera karogs pēc saviem pulkiem, un pār viņa pulku bija Elišamus, Amiuda dēls.
23 Gamalieli ọmọ Pedasuri ni ọ̀gágun ìpín ti ẹ̀yà Manase.
Un pār Manasus bērnu cilts pulku bija Gamaliēls, Pedacura dēls.
24 Abidani ọmọ Gideoni ni ọ̀gágun ìpín ti ẹ̀yà Benjamini.
Un pār Benjamina bērnu cilts pulku bija Abidans, Gideona dēls.
25 Lákòótan, àwọn ọmọ-ogun tó ń mójútó ẹ̀yìn ló tún kàn, àwọn ni ìpín ti ibùdó Dani lábẹ́ ọ̀págun wọn. Ahieseri ọmọ Ammiṣaddai ni ọ̀gágun wọn.
Tad cēlās Dana bērnu lēģera karogs visu lēģeru beidzamā galā pēc saviem pulkiem, un pār viņa pulku bija Ahiēzars, Ami-Šadaja dēls.
26 Pagieli ọmọ Okanri ni ìpín ti ẹ̀yà Aṣeri,
Un pār Ašera bērnu cilts pulku bija Paģiēls, Okrana dēls.
27 Ahira ọmọ Enani ni ọ̀gágun ti ẹ̀yà Naftali.
Un pār Naftalus bērnu cilts pulku bija Ahirus, Enana dēls.
28 Báyìí ni àwọn ọmọ Israẹli ṣe tò jáde gẹ́gẹ́ bí ogun nígbà tí wọ́n bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn.
Tā Israēla bērni cēlās pēc saviem pulkiem.
29 Mose sì sọ fún Hobabu ọmọ Reueli ará Midiani tí í ṣe àna rẹ̀ pé, “A ń gbéra láti lọ sí ibi tí Olúwa sọ pé, ‘Èmi ó fi fún un yín.’ Bá wa lọ, àwa ó ṣe ọ́ dáradára nítorí pé Olúwa ti ṣèlérí ohun rere fún Israẹli.”
Un Mozus sacīja uz Hobabu, Reguēļa, tā Midijanieša, dēlu, Mozus sievas brāli: mēs ejam uz to vietu, par ko Tas Kungs ir sacījis: “To Es jums došu.” Nāc līdz ar mums, mēs tev gribam labu darīt, jo Tas Kungs Israēlim labumu apsolījis.
30 Ó sì dáhùn pé, “Rárá, èmi kò ní bá yín lọ, mò ń padà lọ sí ilẹ̀ mi àti sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn mi.”
Bet viņš sacīja: es neiešu, bet es gribu iet uz savu zemi un pie saviem radiem.
31 Mose sì sọ pé, “Jọ̀wọ́ ma fi wá sílẹ̀, ìwọ mọ ibi tí a lè pa ibùdó sí nínú aginjù, ìwọ yóò sì jẹ́ ojú fún wa.
Bet tas viņam sacīja: neatstājies no mums, jo tāpēc ka tu zini, kur mums tuksnesī jāapmetas, tad tev būs mums būt par aci.
32 Bí o bá bá wa lọ, a ó sì pín fún ọ nínú ohun rere yówù tí Olúwa bá fún wa.”
Un notiks, ja tu mums iesi līdz un mums nāks tas labums, ko Tas Kungs mums darīs, tad mēs tev arīdzan gribam labu darīt.
33 Wọ́n sì gbéra láti orí òkè Olúwa ní ìrìn ọjọ́ mẹ́ta. Àpótí ẹ̀rí Olúwa ń lọ níwájú wọn fún gbogbo ọjọ́ mẹ́ta yìí láti wá ibi ìsinmi fún wọn.
Un tie cēlās no Tā Kunga kalna treju dienu gājumu, un Tā Kunga derības šķirsts viņiem gāja priekšā treju dienu gājumu, viņiem rādīt dusamu vietu.
34 Ìkùùkuu Olúwa wà lórí wọn lọ́sàn nígbà tí wọ́n gbéra kúrò ní ibùdó.
Un Tā Kunga padebesis bija pār viņiem dienas laikā, kad tie no lēģera cēlās.
35 Nígbàkígbà tí àpótí ẹ̀rí bá gbéra Mose yóò sì wí pé, “Dìde, Olúwa! Kí a tú àwọn ọ̀tá rẹ ká, kí àwọn tí ó kórìíra rẹ sì sálọ níwájú rẹ.”
Un notikās, kad tas šķirsts cēlās, tad Mozus sacīja: celies, Kungs, lai Tavi ienaidnieki top izkaisīti un Tavi nīdētāji lai bēg priekš Tava vaiga.
36 Nígbàkígbà tí àpótí ẹ̀rí bá sinmi yóò wí pé, “Padà, Olúwa, sọ́dọ̀ àwọn àìmoye ẹgbẹẹgbẹ̀rún Israẹli.”
Un kad tas dusēja, tad viņš sacīja: atgriezies, Kungs, pie Israēla pulku tūkstošiem.