< Numbers 10 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
OLELO mai la o Iehova ia Mose, i mai la,
2 “Ṣe fèrè fàdákà méjì pẹ̀lú fàdákà lílù, kí o máa lò ó láti máa fi pe ìjọ ènìyàn àti láti máa fi darí ìrìnàjò lọ sí ibùdó yín.
E hana oe i elua pu kala nou; no ka apana kala okoa kau e hana'i ia mau mea, i mea nau e houluulu ae ai i ke anaina kanaka, a no ka hele ana o ka poe hoomoana.
3 Nígbà tí o bá fọn méjèèjì gbogbo ìjọ ènìyàn yóò pé síwájú rẹ ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
Aia puhi aku lakou ma ia mau mea, alaila e hoakoakoa ae ke anaina kanaka a pau ma ka puka o ka halelewa anaina.
4 Bí ó bá jẹ́ ọ̀kan ni o fọn, nígbà náà ni àwọn olórí ẹ̀yà Israẹli yóò péjọ síwájú rẹ.
Ina paha e puhi lakou ma ka pu hookahi, alaila o na lii, ka poe luna o na tausani ke houluulu mai i ou la.
5 Nígbà tí o bá fun ìpè ìdágìrì, àwọn ẹ̀yà tó pa ibùdó sí ìhà ìlà-oòrùn ni yóò gbéra.
Aia puhi oukou i ka puwaikaua, alaila o ka poe hoomoana ma ka aoao hikina ke hele imua.
6 Nígbà tí o bá fun ìpè ìdágìrì kejì, ibùdó tó wà ní ìhà gúúsù ni yóò gbéra. Ìpè ìdágìrì yìí ni yóò jẹ́ àmì fún gbígbéra.
A puhi hou oukou i ka puwaikaua, alaila o ka poe hoomoana ma ke kukuluhema ke hele aku: e puhi lakou i ka puwaikaua no ko lakou hele ana.
7 Nígbà tí o bá fẹ́ pe ìjọ ènìyàn jọ, fun fèrè nìkan, má ṣe fun ti ìdágìrì pẹ̀lú rẹ̀.
A i ka wa e houluuluia'na ke anaina kanaka, e puhi no oukou, aole nae e hookani oukou i ka puwaikaua.
8 “Àwọn ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ni kí ó máa fun fèrè. Èyí yóò jẹ́ ìlànà láéláé fún yín àti fún ìran tó ń bọ̀.
O na keiki a Aarona, o na kahuna, e puhi lakou i na pu: a he kanawai mau loa ia no oukou a no na hanauna mahope o oukou.
9 Nígbà tí ẹ bá lọ jagun pẹ̀lú àwọn ọ̀tá tó ń ni yín lára ní ilẹ̀ yín, ẹ fun ìpè ìdágìrì pẹ̀lú fèrè. A ó sì rántí yín níwájú Olúwa, Ọlọ́run yín yóò sì gbà yín lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá yín.
Ina paha e hele oukou i ke kaua ma ko oukou aina, e ku e i ka poe enemi hooluhi mai ia oukou; alaila oukou e puhi ai i ka puwaikaua ma na pu: a e hoomanaoia auanei oukou imua o Iehova o ko oukou Akua, a e hoolaia oukou i ko oukou poe enemi.
10 Bẹ́ẹ̀ náà ni ní ọjọ́ ayọ̀ yín, ní gbogbo àjọ̀dún tí a yàn àti ní ìbẹ̀rẹ̀ oṣù yín, ni kí ẹ máa fun fèrè lórí ẹbọ sísun àti ọrẹ àlàáfíà yín, wọn yóò sì jẹ́ ìrántí fún yín níwájú Ọlọ́run. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.”
Pela hoi i ka la e olioli ai oukou, a me na la houluulu o oukou a me na la mua o ko oukou mau malama, e puhi hoi oukou i na pu maluna o na mohaikuni a oukou, a maluna o na mohaimalu o oukou, i lilo ia mau mea ia oukou i mea e hoomanaoia'i imua o ko oukou Akua: owau no Iehova ko oukou Akua.
11 Ní ogúnjọ́ oṣù kejì, ní ọdún kejì ni ìkùùkuu kúrò lórí tabanaku ẹ̀rí.
A i ka la iwakalua o ka lua o ka malama, i ka lua o ka makahiki, lei ae la ke ao maluna aku o ka halelewa o ke kanawai.
12 Àwọn ọmọ Israẹli sì gbéra kúrò ní aginjù Sinai wọ́n sì rin ìrìnàjò wọn káàkiri títí tí ìkùùkuu fi dúró sí aginjù Parani.
A hele aku la ka poe mamo a Iseraela mailoko aku o ka waonahele o Sinai; a ku malie iho la ke ao ma ka waonahele o Parana.
13 Wọ́n gbéra nígbà àkọ́kọ́ yìí nípa àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose.
O ka mua keia o ko lakou hele ana, e like me ka Iehova kauoha ana mai ma ka lima o Mose.
14 Àwọn ìpín ti ibùdó Juda ló kọ́kọ́ gbéra tẹ̀lé wọn lábẹ́ ogun wọn Nahiṣoni ọmọ Amminadabu ni ọ̀gágun wọn.
Hele mua aku la ka hae o ka poe hoomoana o na mamo a Iuda, ma ko lakou poe kaua: a o Nahesona ke keiki a Aminadaba, oia no maluna o kona poe kaua.
15 Netaneli ọmọ Suari ni ọ̀gágun ti ẹ̀yà Isakari;
A o Nataneela ke keiki a Zuara, oia no maluna o ka poe kaua o ka ohana mamo a Isekara.
16 Eliabu ọmọ Heloni ni ọ̀gágun ni ìpín ti ẹ̀yà Sebuluni.
A o Eliaba ke keiki a Helona, oia no maluna o ka poe kaua o ka ohana mamo a Zebuluna.
17 Nígbà náà ni wọ́n sọ tabanaku kalẹ̀ àwọn ọmọ Gerṣoni àti Merari tó gbé àgọ́ sì gbéra.
Ua wawahiia'e ka halelewa: a hele aku la na mamo a Geresona, a me na mamo a Merari, e hali ana i ka halelewa
18 Àwọn ìpín ti ibùdó ti Reubeni ló gbéra tẹ̀lé wọn, lábẹ́ ọ̀págun wọn. Elisuri ọmọ Ṣedeuri ni ọ̀gágun wọn.
A hele aku la ka hae oko Reubena poe hoomoana, ma ko lakou poe kaua: a o Elizura ke keiki a Sedeura, oia no maluna o kona poe kaua.
19 Ṣelumieli ọmọ Suriṣaddai ni ọ̀gágun ti ẹ̀yà Simeoni.
A o Selumiela ke keiki a Zurisadai, oia no maluna o ka poe kaua o ka ohana mamo a Simeona.
20 Eliasafu ọmọ Deueli ni ọ̀gágun ìpín ti ẹ̀yà Gadi.
A o Eliasapa ke keiki a Deuela, oia maluna o ka poe kaua o ka ohana mamo a Gada.
21 Nígbà náà ni àwọn ọmọ Kohati tí ń ru ohun mímọ́ náà gbéra. Àwọn ti àkọ́kọ́ yóò sì ti gbé tabanaku dúró kí wọn tó dé.
A hele aku la ka Kohata, e hali ana i na mea hoano; a na kela poe i kukulu ae i ka halelewa no ka wa i hiki aku ai lakou nei.
22 Àwọn ìpín tó wà ní ibùdó Efraimu ló tún kàn lábẹ́ ọ̀págun wọn. Eliṣama ọmọ Ammihudu ni ọ̀gágun wọn.
Hele aku la hoi ka hae o ka poe hoomoana o na mamo a Eperaima, ma ko lakou mau poe kaua: a o Elisama ke keiki a Amihuda, oia no maluna o kona poe kaua.
23 Gamalieli ọmọ Pedasuri ni ọ̀gágun ìpín ti ẹ̀yà Manase.
A o Gamaliela ke keiki a Pedazura, oia no maluna o ka poe kaua o ka ohana mamo a Manase.
24 Abidani ọmọ Gideoni ni ọ̀gágun ìpín ti ẹ̀yà Benjamini.
A o Abidana ke keiki a Gideoni, oia no maluna o ka poe kaua o ka ohana mamo a Beniamina.
25 Lákòótan, àwọn ọmọ-ogun tó ń mójútó ẹ̀yìn ló tún kàn, àwọn ni ìpín ti ibùdó Dani lábẹ́ ọ̀págun wọn. Ahieseri ọmọ Ammiṣaddai ni ọ̀gágun wọn.
Hele aku la hoi ka hae o ka poe hoomoana o na mamo a Dana, oia no ka hope o na poe hoomoana a pau ma ko lakou poe kaua: a o Ahiezera ke keiki a Amisadai, oia ka luna o kona poe kaua.
26 Pagieli ọmọ Okanri ni ìpín ti ẹ̀yà Aṣeri,
A o Pagiela ke keiki a Okera na, oia no maluna o ka poe kaua o ka ohana mamo a Asera.
27 Ahira ọmọ Enani ni ọ̀gágun ti ẹ̀yà Naftali.
Maluna hoi o ka poe kaua o ka ohana mamo a Napetali, o Ahira ke keiki a Enana.
28 Báyìí ni àwọn ọmọ Israẹli ṣe tò jáde gẹ́gẹ́ bí ogun nígbà tí wọ́n bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn.
Pela na hele ana o na mamo a Iseraela, ma ko lakou mau poe kaua, i ka wa i hele aku ai lakou.
29 Mose sì sọ fún Hobabu ọmọ Reueli ará Midiani tí í ṣe àna rẹ̀ pé, “A ń gbéra láti lọ sí ibi tí Olúwa sọ pé, ‘Èmi ó fi fún un yín.’ Bá wa lọ, àwa ó ṣe ọ́ dáradára nítorí pé Olúwa ti ṣèlérí ohun rere fún Israẹli.”
Olelo aku la o Mose ia Hobaba, i ke keikikane a Reuela ka Midiana, ka makuahonowaikane o Mose, Ke hele aku nei makou i kahi a Iehova i i mai ai, E haawi ana au ia no oukou: e hele pu oe me makou, a e hana aku makou ia oe i ka maikai; no ka mea, ua olelo mai o Iehova i ka maikai no ka Iseraela.
30 Ó sì dáhùn pé, “Rárá, èmi kò ní bá yín lọ, mò ń padà lọ sí ilẹ̀ mi àti sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn mi.”
I mai la kela ia ia, Aole au e hele, e hoi hou ana au i ko'u aina iho, a i ko'u poe hoahanau.
31 Mose sì sọ pé, “Jọ̀wọ́ ma fi wá sílẹ̀, ìwọ mọ ibi tí a lè pa ibùdó sí nínú aginjù, ìwọ yóò sì jẹ́ ojú fún wa.
I aku la ia, Ke noi aku nei au ia oe, mai haalele oe ia makou; no ka mea, ua ike oe e hoomoana iho ana makou ma ka waonahele, a e lilo mai oe i maka no makou.
32 Bí o bá bá wa lọ, a ó sì pín fún ọ nínú ohun rere yówù tí Olúwa bá fún wa.”
Eia hoi kekahi, a i hele pu oe me makou, he oiaio no, o ka maikai a Iehova e hana mai ai ia makou, oia ka makou e hana aku ai ia oe.
33 Wọ́n sì gbéra láti orí òkè Olúwa ní ìrìn ọjọ́ mẹ́ta. Àpótí ẹ̀rí Olúwa ń lọ níwájú wọn fún gbogbo ọjọ́ mẹ́ta yìí láti wá ibi ìsinmi fún wọn.
Haele aku la lakou i ekolu la hele, mai ka mauna o Iehova aku: a hele aku la ka pahu berita o Iehova imua o lakou i ua mau la la i hele ai ekolu, e imi ana i kahi e oioi ai lakou.
34 Ìkùùkuu Olúwa wà lórí wọn lọ́sàn nígbà tí wọ́n gbéra kúrò ní ibùdó.
Uhi iho la ke ao o Iehova maluna o lakou i ke ao i ko lakou hele ana aku mawaho o kahi hoomoana.
35 Nígbàkígbà tí àpótí ẹ̀rí bá gbéra Mose yóò sì wí pé, “Dìde, Olúwa! Kí a tú àwọn ọ̀tá rẹ ká, kí àwọn tí ó kórìíra rẹ sì sálọ níwájú rẹ.”
Aia i ka hele ana aku o ka pahu imua, alaila, i aku la o Mose, E ku ae oe iluna, e Iehova; a e hoopuehuia'e kou poe enemi; a e hooauheeia'ku imua ou ka poe inaina ia oe.
36 Nígbàkígbà tí àpótí ẹ̀rí bá sinmi yóò wí pé, “Padà, Olúwa, sọ́dọ̀ àwọn àìmoye ẹgbẹẹgbẹ̀rún Israẹli.”
A ku malie iho ia, alaila, i aku la ia, E hoi hou mai oe, e Iehova, i na lehulehu o ka Iseraela.

< Numbers 10 >