< Numbers 10 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Yahweh also told Moses/me,
2 “Ṣe fèrè fàdákà méjì pẹ̀lú fàdákà lílù, kí o máa lò ó láti máa fi pe ìjọ ènìyàn àti láti máa fi darí ìrìnàjò lọ sí ibùdó yín.
“[Tell someone to] make two trumpets by hammering each one from [one lump of] silver. Blow the trumpets to summon the people to come together and also to signal that they must move their tents [to a new location].
3 Nígbà tí o bá fọn méjèèjì gbogbo ìjọ ènìyàn yóò pé síwájú rẹ ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
If both trumpets are blown, it means that everyone must gather together at the entrance of the Sacred Tent.
4 Bí ó bá jẹ́ ọ̀kan ni o fọn, nígbà náà ni àwọn olórí ẹ̀yà Israẹli yóò péjọ síwájú rẹ.
If only one trumpet is blown, it means that only the [twelve] leaders of the tribes must gather together.
5 Nígbà tí o bá fun ìpè ìdágìrì, àwọn ẹ̀yà tó pa ibùdó sí ìhà ìlà-oòrùn ni yóò gbéra.
If the trumpets are blown loudly, the tribes that are to the east [of the Sacred Tent] should start to travel.
6 Nígbà tí o bá fun ìpè ìdágìrì kejì, ibùdó tó wà ní ìhà gúúsù ni yóò gbéra. Ìpè ìdágìrì yìí ni yóò jẹ́ àmì fún gbígbéra.
When the trumpets are blown loudly the second time, the tribes that are to the south should start to travel. The loud blasts on the trumpet will signal that they should start to travel.
7 Nígbà tí o bá fẹ́ pe ìjọ ènìyàn jọ, fun fèrè nìkan, má ṣe fun ti ìdágìrì pẹ̀lú rẹ̀.
When you want only to gather the people together, blow the trumpets, but do not blow them as loudly.
8 “Àwọn ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ni kí ó máa fun fèrè. Èyí yóò jẹ́ ìlànà láéláé fún yín àti fún ìran tó ń bọ̀.
“The priests who are descended from Aaron are the ones who should blow the trumpets. That is a regulation that will never be changed.
9 Nígbà tí ẹ bá lọ jagun pẹ̀lú àwọn ọ̀tá tó ń ni yín lára ní ilẹ̀ yín, ẹ fun ìpè ìdágìrì pẹ̀lú fèrè. A ó sì rántí yín níwájú Olúwa, Ọlọ́run yín yóò sì gbà yín lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá yín.
When you fight against enemies who attack you in your own land, tell the priests to blow the trumpets loudly. I, Yahweh, your God, will hear that, and I will rescue you from your enemies.
10 Bẹ́ẹ̀ náà ni ní ọjọ́ ayọ̀ yín, ní gbogbo àjọ̀dún tí a yàn àti ní ìbẹ̀rẹ̀ oṣù yín, ni kí ẹ máa fun fèrè lórí ẹbọ sísun àti ọrẹ àlàáfíà yín, wọn yóò sì jẹ́ ìrántí fún yín níwájú Ọlọ́run. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.”
Also tell the priests to blow the trumpets when the people are happy, and at the festivals [each year], and at the times when they celebrate the new moon each month. Tell them to blow the trumpets when the people bring offerings that will be completely burned, and when they bring offerings to maintain fellowship with me. If they do that, it will help you to remember that I, Yahweh your God, [will help you].”
11 Ní ogúnjọ́ oṣù kejì, ní ọdún kejì ni ìkùùkuu kúrò lórí tabanaku ẹ̀rí.
On the twentieth day of May in the second year [after the/we Israelis left Egypt], the cloud rose up from above the Sacred Tent.
12 Àwọn ọmọ Israẹli sì gbéra kúrò ní aginjù Sinai wọ́n sì rin ìrìnàjò wọn káàkiri títí tí ìkùùkuu fi dúró sí aginjù Parani.
So we/the Israelis traveled from the Sinai Desert, and we/they continued traveling [north] until the cloud stopped in the Paran Desert.
13 Wọ́n gbéra nígbà àkọ́kọ́ yìí nípa àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose.
That was the first time we/they moved, obeying the instructions that Yahweh had given to Moses/me to tell them.
14 Àwọn ìpín ti ibùdó Juda ló kọ́kọ́ gbéra tẹ̀lé wọn lábẹ́ ogun wọn Nahiṣoni ọmọ Amminadabu ni ọ̀gágun wọn.
The group that went first, carrying their flag/banner, was the group from the tribe of Judah. Nahshon, the son of Amminadab, was their leader.
15 Netaneli ọmọ Suari ni ọ̀gágun ti ẹ̀yà Isakari;
The group from the tribe of Issachar [followed them]. Nethanel, the son of Zuar, was their leader.
16 Eliabu ọmọ Heloni ni ọ̀gágun ni ìpín ti ẹ̀yà Sebuluni.
The group from the tribe of Zebulun went next. Eliab, the son of Helon, was their leader.
17 Nígbà náà ni wọ́n sọ tabanaku kalẹ̀ àwọn ọmọ Gerṣoni àti Merari tó gbé àgọ́ sì gbéra.
Then they dismantled the Sacred Tent, and the descendants of Gershon and Merari carried it, and they went next.
18 Àwọn ìpín ti ibùdó ti Reubeni ló gbéra tẹ̀lé wọn, lábẹ́ ọ̀págun wọn. Elisuri ọmọ Ṣedeuri ni ọ̀gágun wọn.
The group from the tribe of Reuben went next, carrying their flag. Elizur, the son of Shedeur, was their leader.
19 Ṣelumieli ọmọ Suriṣaddai ni ọ̀gágun ti ẹ̀yà Simeoni.
The group from the tribe of Simeon was next. Shelumiel, the son of Zurishaddai, was their leader.
20 Eliasafu ọmọ Deueli ni ọ̀gágun ìpín ti ẹ̀yà Gadi.
The group from the tribe of Gad was next. Eliasaph, the son of Deuel, was their leader.
21 Nígbà náà ni àwọn ọmọ Kohati tí ń ru ohun mímọ́ náà gbéra. Àwọn ti àkọ́kọ́ yóò sì ti gbé tabanaku dúró kí wọn tó dé.
The group descended from Kohath was next. They carried the sacred items from the Sacred Tent. The Sacred Tent itself was set up at the new location before they arrived there.
22 Àwọn ìpín tó wà ní ibùdó Efraimu ló tún kàn lábẹ́ ọ̀págun wọn. Eliṣama ọmọ Ammihudu ni ọ̀gágun wọn.
The group from the tribe of Ephraim was next, carrying their flag. Elishama, the son of Ammihud, was their leader.
23 Gamalieli ọmọ Pedasuri ni ọ̀gágun ìpín ti ẹ̀yà Manase.
The group from the tribe of Manasseh went next. Gamaliel, the son of Pedahzur, was their leader.
24 Abidani ọmọ Gideoni ni ọ̀gágun ìpín ti ẹ̀yà Benjamini.
The group from the tribe of Benjamin, went next. Abidan, the son of Gideoni, was their leader.
25 Lákòótan, àwọn ọmọ-ogun tó ń mójútó ẹ̀yìn ló tún kàn, àwọn ni ìpín ti ibùdó Dani lábẹ́ ọ̀págun wọn. Ahieseri ọmọ Ammiṣaddai ni ọ̀gágun wọn.
The ones who went last were the group from the tribe of Dan, carrying their flag. Ahiezer, the son of Ammishaddai, was their leader.
26 Pagieli ọmọ Okanri ni ìpín ti ẹ̀yà Aṣeri,
The group from the tribe of Asher went next. Pagiel, the son of Ocran, was their leader.
27 Ahira ọmọ Enani ni ọ̀gágun ti ẹ̀yà Naftali.
The group from the tribe of Naphtali went last. Ahira, the son of Enan, was their leader.
28 Báyìí ni àwọn ọmọ Israẹli ṣe tò jáde gẹ́gẹ́ bí ogun nígbà tí wọ́n bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn.
That was the order in which the groups of Israeli tribes traveled.
29 Mose sì sọ fún Hobabu ọmọ Reueli ará Midiani tí í ṣe àna rẹ̀ pé, “A ń gbéra láti lọ sí ibi tí Olúwa sọ pé, ‘Èmi ó fi fún un yín.’ Bá wa lọ, àwa ó ṣe ọ́ dáradára nítorí pé Olúwa ti ṣèlérí ohun rere fún Israẹli.”
One day Moses/I said to his/my brother-in-law Hobab, the son of Reuel from the Midian people-group, “We are on the way to the place that Yahweh promised to give to us. Come with us, and we will take good care of you, because Yahweh has promised [to do] good things for us Israeli people.”
30 Ó sì dáhùn pé, “Rárá, èmi kò ní bá yín lọ, mò ń padà lọ sí ilẹ̀ mi àti sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn mi.”
But Hobab replied, “No, I will not go with you. I want to return to my own land and to my own family.”
31 Mose sì sọ pé, “Jọ̀wọ́ ma fi wá sílẹ̀, ìwọ mọ ibi tí a lè pa ibùdó sí nínú aginjù, ìwọ yóò sì jẹ́ ojú fún wa.
But Moses/I said, “Please do not leave us. You know the places where we can set up our tents in this desert, and you can guide us.
32 Bí o bá bá wa lọ, a ó sì pín fún ọ nínú ohun rere yówù tí Olúwa bá fún wa.”
Come with us. We will share with you all the good things that Yahweh gives to us.”
33 Wọ́n sì gbéra láti orí òkè Olúwa ní ìrìn ọjọ́ mẹ́ta. Àpótí ẹ̀rí Olúwa ń lọ níwájú wọn fún gbogbo ọjọ́ mẹ́ta yìí láti wá ibi ìsinmi fún wọn.
[So Hobab agreed to go with them]. The Israelis left Sinai Mountain, [which they called] Yahweh’s Mountain, and they walked for three days. The [men carrying the] sacred chest went in front of the other people for those three days, and they kept looking for a place to set up their tents.
34 Ìkùùkuu Olúwa wà lórí wọn lọ́sàn nígbà tí wọ́n gbéra kúrò ní ibùdó.
The cloud sent by Yahweh was over them every day.
35 Nígbàkígbà tí àpótí ẹ̀rí bá gbéra Mose yóò sì wí pé, “Dìde, Olúwa! Kí a tú àwọn ọ̀tá rẹ ká, kí àwọn tí ó kórìíra rẹ sì sálọ níwájú rẹ.”
Each morning when the men who were carrying the sacred chest started to walk, Moses/I said, “Yahweh, arise! Scatter your enemies! Cause those who hate you to run away from you!”
36 Nígbàkígbà tí àpótí ẹ̀rí bá sinmi yóò wí pé, “Padà, Olúwa, sọ́dọ̀ àwọn àìmoye ẹgbẹẹgbẹ̀rún Israẹli.”
And each time the men [stopped to] set down the sacred chest, Moses/I said, “Yahweh, stay close to the thousands of us Israelis!”

< Numbers 10 >