< Numbers 10 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
And Jehovah spoke to Moses, saying,
2 “Ṣe fèrè fàdákà méjì pẹ̀lú fàdákà lílù, kí o máa lò ó láti máa fi pe ìjọ ènìyàn àti láti máa fi darí ìrìnàjò lọ sí ibùdó yín.
Make thee two trumpets of silver; of beaten work shalt thou make them; and they shall serve for the calling together of the assembly, and for the journeying of the camps.
3 Nígbà tí o bá fọn méjèèjì gbogbo ìjọ ènìyàn yóò pé síwájú rẹ ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
And when they shall blow with them, the whole assembly shall gather to thee at the entrance of the tent of meeting.
4 Bí ó bá jẹ́ ọ̀kan ni o fọn, nígbà náà ni àwọn olórí ẹ̀yà Israẹli yóò péjọ síwájú rẹ.
And if they blow with one, then the princes, the heads of the thousands of Israel, shall gather unto thee.
5 Nígbà tí o bá fun ìpè ìdágìrì, àwọn ẹ̀yà tó pa ibùdó sí ìhà ìlà-oòrùn ni yóò gbéra.
And when ye blow an alarm, the camps that lie eastward shall set forward.
6 Nígbà tí o bá fun ìpè ìdágìrì kejì, ibùdó tó wà ní ìhà gúúsù ni yóò gbéra. Ìpè ìdágìrì yìí ni yóò jẹ́ àmì fún gbígbéra.
And when ye blow an alarm the second time, the camps that lie southward shall set forward; they shall blow an alarm on their setting forward.
7 Nígbà tí o bá fẹ́ pe ìjọ ènìyàn jọ, fun fèrè nìkan, má ṣe fun ti ìdágìrì pẹ̀lú rẹ̀.
And when the congregation is to be gathered together, ye shall blow, but ye shall not blow an alarm:
8 “Àwọn ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ni kí ó máa fun fèrè. Èyí yóò jẹ́ ìlànà láéláé fún yín àti fún ìran tó ń bọ̀.
the sons of Aaron, the priests, shall blow with the trumpets; and they shall be to you for an everlasting statute throughout your generations.
9 Nígbà tí ẹ bá lọ jagun pẹ̀lú àwọn ọ̀tá tó ń ni yín lára ní ilẹ̀ yín, ẹ fun ìpè ìdágìrì pẹ̀lú fèrè. A ó sì rántí yín níwájú Olúwa, Ọlọ́run yín yóò sì gbà yín lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá yín.
And if ye go to war in your land against the enemy that oppresseth you, then ye shall blow an alarm with the trumpets; and ye shall be remembered before Jehovah your God, and ye shall be saved from your enemies.
10 Bẹ́ẹ̀ náà ni ní ọjọ́ ayọ̀ yín, ní gbogbo àjọ̀dún tí a yàn àti ní ìbẹ̀rẹ̀ oṣù yín, ni kí ẹ máa fun fèrè lórí ẹbọ sísun àti ọrẹ àlàáfíà yín, wọn yóò sì jẹ́ ìrántí fún yín níwájú Ọlọ́run. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.”
And in the day of your gladness, and in your set feasts, and in your new moons, ye shall blow with the trumpets over your burnt-offerings and over your sacrifices of peace-offering; and they shall be to you for a memorial before your God: I am Jehovah your God.
11 Ní ogúnjọ́ oṣù kejì, ní ọdún kejì ni ìkùùkuu kúrò lórí tabanaku ẹ̀rí.
And it came to pass in the second year, in the second month, on the twentieth of the month, that the cloud was taken up from off the tabernacle of the testimony.
12 Àwọn ọmọ Israẹli sì gbéra kúrò ní aginjù Sinai wọ́n sì rin ìrìnàjò wọn káàkiri títí tí ìkùùkuu fi dúró sí aginjù Parani.
And the children of Israel set forward according to their journeys out of the wilderness of Sinai; and the cloud stood still in the wilderness of Paran.
13 Wọ́n gbéra nígbà àkọ́kọ́ yìí nípa àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose.
And they first took their journey, according to the commandment of Jehovah through Moses.
14 Àwọn ìpín ti ibùdó Juda ló kọ́kọ́ gbéra tẹ̀lé wọn lábẹ́ ogun wọn Nahiṣoni ọmọ Amminadabu ni ọ̀gágun wọn.
The standard of the camp of the children of Judah set forward first according to their hosts, and over his host was Nahshon the son of Amminadab;
15 Netaneli ọmọ Suari ni ọ̀gágun ti ẹ̀yà Isakari;
and over the host of the tribe of the children of Issachar was Nethaneel the son of Zuar;
16 Eliabu ọmọ Heloni ni ọ̀gágun ni ìpín ti ẹ̀yà Sebuluni.
and over the host of the tribe of the children of Zebulun was Eliab the son of Helon.
17 Nígbà náà ni wọ́n sọ tabanaku kalẹ̀ àwọn ọmọ Gerṣoni àti Merari tó gbé àgọ́ sì gbéra.
And the tabernacle was taken down; and the sons of Gershon and the sons of Merari set forward bearing the tabernacle.
18 Àwọn ìpín ti ibùdó ti Reubeni ló gbéra tẹ̀lé wọn, lábẹ́ ọ̀págun wọn. Elisuri ọmọ Ṣedeuri ni ọ̀gágun wọn.
And the standard of the camp of Reuben set forward according to their hosts, and over his host was Elizur the son of Shedeur;
19 Ṣelumieli ọmọ Suriṣaddai ni ọ̀gágun ti ẹ̀yà Simeoni.
and over the host of the tribe of the children of Simeon was Shelumiel the son of Zurishaddai;
20 Eliasafu ọmọ Deueli ni ọ̀gágun ìpín ti ẹ̀yà Gadi.
and over the host of the tribe of the children of Gad was Eliasaph the son of Deuel.
21 Nígbà náà ni àwọn ọmọ Kohati tí ń ru ohun mímọ́ náà gbéra. Àwọn ti àkọ́kọ́ yóò sì ti gbé tabanaku dúró kí wọn tó dé.
And the Kohathites set forward bearing the sanctuary: and [the others] set up the tabernacle whilst they came.
22 Àwọn ìpín tó wà ní ibùdó Efraimu ló tún kàn lábẹ́ ọ̀págun wọn. Eliṣama ọmọ Ammihudu ni ọ̀gágun wọn.
And the standard of the camp of the children of Ephraim set forward according to their hosts, and over his host was Elishama the son of Ammihud;
23 Gamalieli ọmọ Pedasuri ni ọ̀gágun ìpín ti ẹ̀yà Manase.
and over the host of the tribe of the children of Manasseh was Gamaliel the son of Pedahzur;
24 Abidani ọmọ Gideoni ni ọ̀gágun ìpín ti ẹ̀yà Benjamini.
and over the host of the tribe of the children of Benjamin was Abidan the son of Gideoni.
25 Lákòótan, àwọn ọmọ-ogun tó ń mójútó ẹ̀yìn ló tún kàn, àwọn ni ìpín ti ibùdó Dani lábẹ́ ọ̀págun wọn. Ahieseri ọmọ Ammiṣaddai ni ọ̀gágun wọn.
And the standard of the camp of the children of Dan set forward, the rear-guard of all the camps according to their hosts, and over his host was Ahiezer the son of Ammishaddai;
26 Pagieli ọmọ Okanri ni ìpín ti ẹ̀yà Aṣeri,
and over the host of the tribe of the children of Asher was Pagiel the son of Ocran;
27 Ahira ọmọ Enani ni ọ̀gágun ti ẹ̀yà Naftali.
and over the host of the tribe of the children of Naphtali was Ahira the son of Enan.
28 Báyìí ni àwọn ọmọ Israẹli ṣe tò jáde gẹ́gẹ́ bí ogun nígbà tí wọ́n bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn.
These were the settings forward of the children of Israel according to their hosts: so did they set forward.
29 Mose sì sọ fún Hobabu ọmọ Reueli ará Midiani tí í ṣe àna rẹ̀ pé, “A ń gbéra láti lọ sí ibi tí Olúwa sọ pé, ‘Èmi ó fi fún un yín.’ Bá wa lọ, àwa ó ṣe ọ́ dáradára nítorí pé Olúwa ti ṣèlérí ohun rere fún Israẹli.”
And Moses said to Hobab, the son of Reuel the Midianite, Moses' father-in-law, We are journeying to the place of which Jehovah said, I will give it unto you: come with us, and we will do thee good; for Jehovah has spoken good concerning Israel.
30 Ó sì dáhùn pé, “Rárá, èmi kò ní bá yín lọ, mò ń padà lọ sí ilẹ̀ mi àti sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn mi.”
And he said to him, I will not go; but to mine own land, and to my kindred will I go.
31 Mose sì sọ pé, “Jọ̀wọ́ ma fi wá sílẹ̀, ìwọ mọ ibi tí a lè pa ibùdó sí nínú aginjù, ìwọ yóò sì jẹ́ ojú fún wa.
And he said, Leave me not, I pray thee, because thou knowest where we are to encamp in the wilderness, and thou wilt be to us for eyes.
32 Bí o bá bá wa lọ, a ó sì pín fún ọ nínú ohun rere yówù tí Olúwa bá fún wa.”
And it shall be, if thou come with us, that whatever good Jehovah doeth unto us, so will we do to thee.
33 Wọ́n sì gbéra láti orí òkè Olúwa ní ìrìn ọjọ́ mẹ́ta. Àpótí ẹ̀rí Olúwa ń lọ níwájú wọn fún gbogbo ọjọ́ mẹ́ta yìí láti wá ibi ìsinmi fún wọn.
And they set forward from the mountain of Jehovah [and went] three days' journey; and the ark of the covenant of Jehovah went before them in the three days' journey, to search out a resting-place for them.
34 Ìkùùkuu Olúwa wà lórí wọn lọ́sàn nígbà tí wọ́n gbéra kúrò ní ibùdó.
And the cloud of Jehovah was over them by day when they set forward out of the camp.
35 Nígbàkígbà tí àpótí ẹ̀rí bá gbéra Mose yóò sì wí pé, “Dìde, Olúwa! Kí a tú àwọn ọ̀tá rẹ ká, kí àwọn tí ó kórìíra rẹ sì sálọ níwájú rẹ.”
And it came to pass when the ark set forward, that Moses said, Rise up, Jehovah, and let thine enemies be scattered; And let them that hate thee flee before thy face.
36 Nígbàkígbà tí àpótí ẹ̀rí bá sinmi yóò wí pé, “Padà, Olúwa, sọ́dọ̀ àwọn àìmoye ẹgbẹẹgbẹ̀rún Israẹli.”
And when it rested, he said, Return, Jehovah, unto the myriads of the thousands of Israel.

< Numbers 10 >