< Numbers 1 >

1 Olúwa bá Mose sọ̀rọ̀ ní aginjù Sinai nínú àgọ́ àjọ ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kejì ní ọdún kejì tí àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, ó wí pé,
Egypt kho lamloh a coe phoeikah a kum bae, a hla bae hnin khat vaengah, Sinai khosoek kah tingtunnah dap ah BOEIPA loh Moses te a voek tih,
2 “Ka gbogbo àgbájọ ènìyàn Israẹli nípa ẹbí wọn, àti nípa ìdílé baba wọn, to orúkọ wọn olúkúlùkù ọkùnrin ní ọ̀kọ̀ọ̀kan.
“Israel ca rhaengpuei boeih hlangmi te amah huiko neh, a napa imkhui ah tongpa boeih kah ming tarhing neh a hlangmi te lo laeh.
3 Ìwọ àti Aaroni ni kí ẹ kà gbogbo ọmọkùnrin Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn láti ọmọ ogún ọdún sókè, àwọn tí ó tó lọ sójú ogun.
Kum kul ca lamloh a so, Israel khuikah caempuei la aka cet boeih te namah neh Aaron loh amah caempuei dong lamloh amih te cawh rhoi laeh.
4 Kí ẹ mú ọkùnrin kọ̀ọ̀kan láti inú olúkúlùkù ẹ̀yà kí ó sì wá pẹ̀lú yín, kí olúkúlùkù jẹ́ olórí ilé àwọn baba rẹ̀.
Amah a napa imkhui kah a lu hlang te koca pakhat lamloh hlang pakhat tah nangmih rhoi taengah om saeh.
5 “Orúkọ àwọn ọkùnrin tí yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ nìyí: “Láti ọ̀dọ̀ Reubeni, Elisuri ọmọ Ṣedeuri.
Te dongah he kah hlang ming aka om rhoek loh nangmih rhoi te m'pai puei saeh. Reuben ham Shedeur capa Elizur.
6 Láti ọ̀dọ̀ Simeoni, Ṣelumieli ọmọ Suriṣaddai.
Simeon ham te Zurishaddai capa Shelumiel.
7 Láti ọ̀dọ̀ Juda, Nahiṣoni ọmọ Amminadabu.
Judah ah Amminadab capa Nahshon.
8 Láti ọ̀dọ̀ Isakari, Netaneli ọmọ Suari.
Issakhar ah Zuar capa Nethanel.
9 Láti ọ̀dọ̀ Sebuluni, Eliabu ọmọ Heloni.
Zebulun ah Helon capa Eliab.
10 Láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Josẹfu: láti ọ̀dọ̀ Efraimu, Eliṣama ọmọ Ammihudu. Láti ọ̀dọ̀ Manase, Gamalieli ọmọ Pedasuri.
Joseph koca ah Ephraim kah Ammihud capa Elishama neh Manasseh kah Pedahzur capa Gamaliel.
11 Láti ọ̀dọ̀ Benjamini, Abidani ọmọ Gideoni.
Benjamin ah Gideoni capa Abidan.
12 Láti ọ̀dọ̀ Dani, Ahieseri ọmọ Ammiṣaddai.
Dan ah Ammishaddai capa Ahiezer.
13 Láti ọ̀dọ̀ Aṣeri, Pagieli ọmọ Okanri.
Asher ah Okran capa Pagiel.
14 Láti ọ̀dọ̀ Gadi, Eliasafu ọmọ Deueli.
Gad ah Deuel capa Eliasaph.
15 Láti ọ̀dọ̀ Naftali, Ahira ọmọ Enani.”
Naphtali ah Enan capa Ahira Enan saeh,” a ti nah.
16 Àwọn wọ̀nyí ni wọ́n yàn nínú àwùjọ ènìyàn, olórí àwọn ẹ̀yà baba wọn. Àwọn ni olórí àwọn ẹbí Israẹli.
He mingthang rhoek he rhaengpuei loh a napa rhoek koca kah khoboei neh Israel thawngkhat kah a lu la a khue uh.
17 Mose àti Aaroni mú àwọn ènìyàn tí a dárúkọ wọ̀nyí
Te phoeiah ming a phoei hlang rhoek te Moses neh Aaron loh a loh.
18 wọ́n sì pe gbogbo àwùjọ ènìyàn Israẹli jọ ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kejì. Àwọn ènìyàn sì dárúkọ baba ńlá wọn nípa ẹbí àti ìdílé wọn. Wọ́n sì ṣe àkọsílẹ̀ orúkọ àwọn ọmọkùnrin ní ọ̀kọ̀ọ̀kan láti ọmọ ogún ọdún sókè,
A hla bae kah hnin at ah tah rhaengpuei boeih te a tingtun sak. Te vaengah kum kul ca neh a so hang tah a hlangmi la amah huiko neh a napa rhoek imko tarhing la ming a khueh uh.
19 gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose. Bẹ́ẹ̀ náà ló ṣe kà wọ́n nínú aginjù Sinai.
BOEIPA loh Moses a uen bangla amih te Sinai khosoek ah a soep.
20 Láti ìran Reubeni tí í ṣe àkọ́bí Israẹli, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn, lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
Te vaengah Israel caming, Reuben koca kah a rhuirhong tah, a napa imkhui kah a huiko khaw, a hlangmi ming tarhing ah tongpa ca kum kul lamloh a so hang boeih neh caempuei la aka cet boeih te a tae uh.
21 Àwọn tí a kà ní ẹ̀yà Reubeni jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàlélógún ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
Amih Reuben koca te thawng sawmli thawng rhuk neh ya nga la a soep.
22 Láti ìran Simeoni, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè, tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n kà, wọ́n sì to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
Simeon koca kah a rhuirhong tah, a napa imkhui kah a huiko khaw, a hlangmi ming tarhing ah tongpa ca kum kul lamloh a so hang boeih neh caempuei la aka cet boeih te a soep uh.
23 Iye àwọn tí á kà nínú ẹ̀yà Simeoni jẹ́ ẹgbàá mọ́kàndínlọ́gbọ̀n ó lé ọ̀ọ́dúnrún.
Amih Simeon koca te thawng sawmnga thawng ko neh ya thum la a soep.
24 Láti ìran Gadi, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan, gẹ́gẹ́ bí ẹbí àti ìdílé wọn.
Gad koca kah a rhuirhong tah, a napa imkhui kah a huiko khaw, a ming tarhing ah kum kul ca lamloh a so hang neh caempuei la aka cet boeih te a tae uh.
25 Iye àwọn tí a kà nínú ẹ̀yà Gadi jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé àádọ́talélẹ́gbẹ̀jọ.
Amih Gad koca te thawng sawmli thawng nga neh ya rhuk sawmnga la a soep uh.
26 Láti ìran Juda, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè, tí wọ́n le lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
Judah koca kah a rhuirhong te, a napa imkhui kah a huiko khaw, a ming tarhing ah kum kul ca lamloh a so hang neh caempuei la aka cet boeih te a tae uh.
27 Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Juda jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlógójì ó lé ẹgbẹ̀ta.
Amih Judah koca te thawng sawmrhih thawng li neh ya rhuk la a soep uh.
28 Láti ìran Isakari, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n le lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
Issakhar koca kah a rhuirhong te, a napa imkhui kah a huiko khaw, a ming tarhing ah kum kul ca lamloh a so hang neh caempuei la aka cet boeih khaw,
29 Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Isakari jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlọ́gbọ̀n ó lé irinwó.
Amih Issakhar koca te thawng sawmnga thawng li neh ya li la a soep uh.
30 Láti ìran Sebuluni, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
Zebulun koca kah a rhuirhong te, a napa imkhui kah a huiko khaw, a ming tarhing ah kum kul ca lamloh a so hang neh caempuei la aka cet boeih khaw,
31 Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Sebuluni jẹ́ ẹgbàá méjìdínlọ́gbọ̀n ó lé egbèje.
Amih Zebulun koca te thawng sawmnga thawng rhih neh ya li la a soep uh.
32 Láti inú àwọn ọmọ Josẹfu. Láti ìran Efraimu, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọ́n jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
Joseph koca ah Ephraim koca kah a rhuirhong te, a napa imkhui kah a huiko khaw, a ming tarhing ah kum kul ca lamloh a so hang neh caempuei la aka cet boeih khaw,
33 Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Efraimu jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
Amih Ephraim koca te thawng sawmli neh ya nga la soep uh.
34 Láti ìran Manase, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè, tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
Manasseh koca kah a rhuirhong te, a napa imkhui kah a huiko khaw, a ming tarhing ah kum kul ca lamloh a so hang neh caempuei la aka cet boeih khaw,
35 Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Manase jẹ́ ẹgbàá ẹẹ́rìndínlógún ó lé igba.
Amih Manasseh koca te thawng sawmthum thawng hnih yahnih la a soep uh.
36 Láti ìran Benjamini, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
Benjamin koca kah a rhuirhong te, a napa imkhui kah a huiko dongkah, a ming tarhing ah kum kul ca lamloh a so hang neh caempuei la aka cet boeih khaw,
37 Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Benjamini jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlógún ó lé egbèje.
amih Benjamin koca te thawng sawmthum thawng nga ya li la a soep uh.
38 Láti ìran Dani, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ọmọ ogún ọdún sókè, tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
Dan koca kah a rhuirhong te, a napa imkhui kah a huiko dongkah, a ming tarhing ah kum kul ca lamloh a so hang neh caempuei la aka cet boeih khaw,
39 Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Dani jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélọ́gbọ̀n ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin.
amih Dan koca te thawng sawmrhuk thawng hnih neh ya rhih la a soep uh.
40 Láti ìran Aṣeri, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè, tí wọ́n le lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
Asher koca kah a rhuirhong te, a napa imkhui kah a huiko khaw, a ming tarhing ah kum kul ca lamloh a so hang neh caempuei la aka cet boeih khaw,
41 Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Aṣeri jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ.
amih Asher koca te thawng sawmli thawng khat neh ya nga la a soep uh.
42 Láti ìran Naftali, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún ó lé, tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
Naphtali koca kah a rhuirhong te, a napa rhoek imkhui kah a huiko khaw, a ming tarhing ah kum kul ca lamloh a so hang neh caempuei la aka cet boeih khaw,
43 Iye àwọn tí a kà nínú ẹ̀yà Naftali jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n ó lé egbèje.
amih Naphtali koca te thawng sawmnga thawng thum neh ya li la a soep uh.
44 Wọ̀nyí ni àwọn ènìyàn tí Mose àti Aaroni kà, pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ àwọn olórí méjìlá fún Israẹli, tí ẹnìkọ̀ọ̀kan ṣojú fún ìdílé rẹ̀.
He he aka soep rhoek loh a soep vaengah Moses neh Aaron khaw, Israel khoboei hlang hlai nit neh a napa rhoek imkhui pakhat lamkah hlang pakhat rhip om uh.
45 Gbogbo ọmọkùnrin Israẹli tó jẹ́ ọmọ ogún ọdún sókè, tó sì lè lọ sójú ogun ni wọ́n kà gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn.
Te dongah ni Israel ca rhoek loh a napa rhoek kah imkhui pakhat ah kum kul ca lamloh a so hang, Israel khuiah caempuei la aka cet boeih tah a soep la boeih om uh.
46 Àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ó lé egbèjìdínlógún dín làádọ́ta.
Te vaengkah a soep boeih te thawng ya rhuk neh thawng thum neh ya nga neh sawmnga lo uh.
47 A kò ka àwọn ìdílé ẹ̀yà Lefi mọ́ àwọn ìyókù.
Tedae Levi te tah a napa koca lamloh amih lakli ah ana soep uh thil pawh.
48 Nítorí Olúwa ti sọ fún Mose pé,
BOEIPA loh Moses te a voek tih,
49 “Ìwọ kò gbọdọ̀ ka ẹ̀yà Lefi, tàbí kí o kà wọ́n mọ́ àwọn ọmọ Israẹli.
“Levi koca bueng tah soep thil boel lamtah amih khuikah a lu te Israel ca khui la khuen boeh.
50 Dípò èyí yan àwọn ọmọ Lefi láti jẹ́ alábojútó àgọ́ ẹ̀rí, lórí gbogbo ohun èlò àti ohun gbogbo tó jẹ́ ti àgọ́ ẹ̀rí. Àwọn ni yóò máa gbé àgọ́ àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, wọn ó máa mójútó o, kí wọn ó sì máa pàgọ́ yí i ká.
Tedae namah loh Levi te laipainah dungtlungim so neh a hnopai cungkuem so neh a taengkah a cungkuem soah khueh. Amih loh dungtlungim neh a hnopai boeih te kawt uh saeh. Amih te thotat uh saeh lamtah dungtlungim taengah pin rhaeh uh saeh.
51 Ìgbàkígbà tí àgọ́ yóò bá tẹ̀síwájú, àwọn ọmọ Lefi ni yóò tú palẹ̀, nígbàkígbà tí a bá sì tún pa àgọ́, àwọn ọmọ Lefi náà ni yóò ṣe é. Àlejò tó bá súnmọ́ tòsí ibẹ̀, pípa ni kí ẹ pa á
Dungtlungim te khuen ham vaengah te te Levi rhoek loh suntlak puei saeh. Dungtlungim a rhaeh ham vaengah khaw te te Levi rhoek loh thoh uh saeh. Tedae hlangthawt loh a paan atah duek saeh.
52 kí àwọn ọmọ Israẹli pa àgọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn olúkúlùkù ní ibùdó tirẹ̀ lábẹ́ ọ̀págun tirẹ̀.
Israel ca khuikah hlang he amah kah rhaehhmuen ah rhaeh saeh lamtah hlang he amah caempuei kah a hnitai neh om saeh.
53 Àwọn ọmọ Lefi yóò jẹ́ alábojútó àti olùtọ́jú àgọ́ ẹ̀rí náà, kí ìbínú má ba à sí lára ìjọ àwọn ọmọ Israẹli; kí àwọn ọmọ Lefi sì máa ṣe ìtọ́jú àgọ́ ẹ̀rí náà.”
Te vaengah Levi rhoek tah laipainah dungtlungim kaepah rhaeh uh saeh. Te daengah ni thinhulnah loh Israel ca rhaengpuei soah a tlak pawt eh. Te dongah laipainah dungtlungim kah tuemkoi te Levi rhoek loh ngaithuen uh saeh.
54 Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe ohun gbogbo gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Israel ca rhoek loh a saii uh vaengah BOEIPA loh Moses a uen bangla a cungkuem te a saii uh.

< Numbers 1 >