< Nehemiah 1 >

1 Ọ̀rọ̀ Nehemiah ọmọ Hakaliah. Ní oṣù Kisleu ní ogún ọdún (ìjọba Ahaswerusi ọba Persia) nígbà tí mo wà ní ààfin Susa,
Cuvintele lui Neemia, fiul lui Hacalia. Și s-a întâmplat în luna Chisleu, în anul al douăzecilea, când eram în palatul Susa,
2 Hanani, ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin mi wá láti Juda pẹ̀lú àwọn ọkùnrin kan, mo sì béèrè lọ́wọ́ wọn nípa àwọn Júù tí ó ṣẹ́kù tí wọn kò kó ní ìgbèkùn, àti nípa Jerusalẹmu.
Că Hanani, unul dintre frații mei, a venit, el și anumiți bărbați din Iuda; și i-am întrebat referitor la iudeii care scăpaseră, care rămăseseră din captivitate și referitor la Ierusalim.
3 Wọ́n sọ fún mi pé, “Àwọn tí ó kù tí a kó ní ìgbèkùn tí wọ́n sì padà sí agbègbè ìjọba wà nínú wàhálà púpọ̀ àti ẹ̀gàn. Odi Jerusalẹmu ti wó lulẹ̀ a sì ti fi iná sun ẹnu ibodè rẹ̀.”
Și ei mi-au spus: Rămășița care a rămas din captivitate acolo în provincie este în mare necaz și ocară; zidul Ierusalimului de asemenea este dărâmat și porțile lui sunt arse cu foc.
4 Nígbà tí mo gbọ́ àwọn nǹkan wọ̀nyí, mo jókòó mo sì sọkún. Mo ṣọ̀fọ̀, mo gbààwẹ̀, mo sì gbàdúrà fún ọjọ́ díẹ̀ níwájú Ọlọ́run ọ̀run.
Și s-a întâmplat, după ce am auzit aceste cuvinte, că am șezut jos și am plâns și am jelit câteva zile și am postit și m-am rugat înaintea Dumnezeului cerului,
5 Nígbà náà ni mo wí pé: “Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run, Ọlọ́run tí ó tóbi tí ó sì ní ẹ̀rù, tí ó ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ pẹ̀lú wọn tí ó fẹ́ ẹ tí wọ́n sì ń pa àṣẹ mọ́.
Și am spus: Te implor, DOAMNE Dumnezeul cerului, Dumnezeul cel mare și înfricoșător, care ține legământul și mila față de cei care îl iubesc și păzesc poruncile lui;
6 Jẹ́ kí etí rẹ kí ó ṣí sílẹ̀, kí ojú ù rẹ kí ó sì ṣí sílẹ̀ láti gbọ́ àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ ń gbà ní iwájú rẹ ní ọ̀sán àti ní òru fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ènìyàn Israẹli. Mo jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àwa ọmọ Israẹli àti tèmi àti ti ilé baba mi, tí a ti ṣẹ̀ sí ọ.
Să fie acum urechea ta atentă și ochii tăi deschiși, ca să auzi rugăciunea servitorului tău, cu care mă rog înaintea ta acum, zi și noapte, pentru copiii lui Israel, servitorii tăi, și mărturisesc păcatele copiilor lui Israel, pe care noi le-am păcătuit împotriva ta; deopotrivă eu și casa tatălui meu am păcătuit.
7 Àwa ti ṣe búburú sí ọ. A kò sì pa àṣẹ ìlànà àti òfin tí ìwọ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ mọ́.
Ne-am purtat foarte corupt împotriva ta și nu am păzit poruncile, nici statutele, nici judecățile, pe care le-ai poruncit servitorului tău Moise.
8 “Rántí ìlànà tí o fún Mose ìránṣẹ́ rẹ, wí pé, ‘Bí ìwọ bá jẹ́ aláìṣòótọ́, èmi yóò fọ́n yín ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè.
Amintește-ți, te implor, de cuvântul pe care l-ai poruncit servitorului tău Moise, spunând: Dacă încălcați legea, vă voi împrăștia printre națiuni;
9 Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá yípadà sí mi, tí ẹ bá sì pa àṣẹ mi mọ́, nígbà náà bí àwọn ènìyàn yín tí a kó ní ìgbèkùn tilẹ̀ wà ní jìnnà réré ìpẹ̀kun ọ̀run, èmi yóò kó wọn jọ láti ibẹ̀, èmi yóò sì mú wọn wá, sí ibi tí èmi ti yàn bí i ibùgbé fún orúkọ mi.’
Dar dacă vă întoarceți la mine și păziți poruncile mele și le faceți; chiar dacă ar fi dintre voi aruncați până la marginea cea mai îndepărtată a cerului, totuși îi voi aduna de acolo și îi voi aduce în locul pe care l-am ales pentru a pune numele meu acolo.
10 “Àwọn ni ìránṣẹ́ rẹ àti ènìyàn rẹ àwọn tí ìwọ rà padà pẹ̀lú agbára ńlá rẹ àti ọwọ́ agbára ńlá rẹ.
Și aceștia sunt servitorii tăi și poporul tău, pe care l-ai răscumpărat prin marea ta putere și prin mâna ta cea tare.
11 Olúwa, jẹ́ kí etí rẹ ṣí sílẹ̀ sí àdúrà ìránṣẹ́ rẹ yìí, àti sí àdúrà àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí wọ́n ní inú dídùn láti bọ̀wọ̀ fún orúkọ rẹ. Fún ìránṣẹ́ rẹ ní àṣeyọrí lónìí kí o sì síjú àánú wò ó níwájú ọkùnrin yìí.” Nítorí tí mo jẹ́ agbọ́tí ọba nígbà náà.
DOAMNE, te implor, să fie acum urechea ta atentă la rugăciunea servitorului tău și la rugăciunea servitorilor tăi, care doresc să se teamă de numele tău; și fă, te rog, să prospere servitorul tău în această zi și dăruiește-i milă înaintea ochilor acestui bărbat. Pentru că eu am fost paharnicul împăratului.

< Nehemiah 1 >