< Nehemiah 1 >

1 Ọ̀rọ̀ Nehemiah ọmọ Hakaliah. Ní oṣù Kisleu ní ogún ọdún (ìjọba Ahaswerusi ọba Persia) nígbà tí mo wà ní ààfin Susa,
Słowa Nehemijasza, syna Hachalijaszowego. I stało się miesiąca Chyslew, roku dwudziestego (Aswerusa króla) gdym był na zamku w Susan,
2 Hanani, ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin mi wá láti Juda pẹ̀lú àwọn ọkùnrin kan, mo sì béèrè lọ́wọ́ wọn nípa àwọn Júù tí ó ṣẹ́kù tí wọn kò kó ní ìgbèkùn, àti nípa Jerusalẹmu.
Że przyszedł Chanani, jeden z braci moich, a z nim niektórzy mężowie z Judy, którychem się pytał o Żydów, którzy pozostali i wyszli z więzienia, i o Jeruzalem.
3 Wọ́n sọ fún mi pé, “Àwọn tí ó kù tí a kó ní ìgbèkùn tí wọ́n sì padà sí agbègbè ìjọba wà nínú wàhálà púpọ̀ àti ẹ̀gàn. Odi Jerusalẹmu ti wó lulẹ̀ a sì ti fi iná sun ẹnu ibodè rẹ̀.”
I odpowiedzieli mi: Te ostatki, które pozostały z więzienia tam w onej krainie, są w wielkiem utrapieniu, i w zelżywości: nadto mur Jeruzalemski rozwalony jest, i bramy jego spalone są ogniem.
4 Nígbà tí mo gbọ́ àwọn nǹkan wọ̀nyí, mo jókòó mo sì sọkún. Mo ṣọ̀fọ̀, mo gbààwẹ̀, mo sì gbàdúrà fún ọjọ́ díẹ̀ níwájú Ọlọ́run ọ̀run.
A gdym usłyszał te słowa, siadłszy płakałem i narzekałem przez kilka dni, poszcząc i modląc się przed obliczem Boga niebieskiego.
5 Nígbà náà ni mo wí pé: “Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run, Ọlọ́run tí ó tóbi tí ó sì ní ẹ̀rù, tí ó ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ pẹ̀lú wọn tí ó fẹ́ ẹ tí wọ́n sì ń pa àṣẹ mọ́.
I rzekłem; Proszę Panie, Boże niebieski, mocny, wielki i straszny! który strzeżesz umowy, i miłosierdzia z tymi, którzy cię miłują, i strzegą przykazania twego.
6 Jẹ́ kí etí rẹ kí ó ṣí sílẹ̀, kí ojú ù rẹ kí ó sì ṣí sílẹ̀ láti gbọ́ àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ ń gbà ní iwájú rẹ ní ọ̀sán àti ní òru fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ènìyàn Israẹli. Mo jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àwa ọmọ Israẹli àti tèmi àti ti ilé baba mi, tí a ti ṣẹ̀ sí ọ.
Niech będzie proszę ucho twoje nakłonione, a oczy twoje otworzone, abyś usłyszał modlitwę sługi twego, którą się ja dziś modlę przed tobą we dnie i w nocy za synami Izraelskimi, sługami twymi, i wyznaję grzechy synów Izraelskich, któremiśmy zgrzes zyli przeciw tobie; i ja i dom ojca mego zgrzeszyliśmy.
7 Àwa ti ṣe búburú sí ọ. A kò sì pa àṣẹ ìlànà àti òfin tí ìwọ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ mọ́.
Srodześmy wystąpili przeciwko tobie, i nie przestrzegaliśmy przykazań, i ustaw, i sądów, któreś przykazał Mojżeszowi, słudze twemu.
8 “Rántí ìlànà tí o fún Mose ìránṣẹ́ rẹ, wí pé, ‘Bí ìwọ bá jẹ́ aláìṣòótọ́, èmi yóò fọ́n yín ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè.
Wspomnij proszę na słowo, któreś przykazał Mojżeszowi, słudze twemu, mówiąc: Jeżli wy wystąpicie, tedy Ja was rozproszę między narody;
9 Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá yípadà sí mi, tí ẹ bá sì pa àṣẹ mi mọ́, nígbà náà bí àwọn ènìyàn yín tí a kó ní ìgbèkùn tilẹ̀ wà ní jìnnà réré ìpẹ̀kun ọ̀run, èmi yóò kó wọn jọ láti ibẹ̀, èmi yóò sì mú wọn wá, sí ibi tí èmi ti yàn bí i ibùgbé fún orúkọ mi.’
Ale jeżli się nawrócicie do mnie, a strzedz będziecie przykazań moich, i czynić je, choćbyście byli wygnani na kraj świata, tedy i stamtąd was zgromadzę, i przyprowadzę was na miejsce, którem obrał, aby tam przebywało imię moje.
10 “Àwọn ni ìránṣẹ́ rẹ àti ènìyàn rẹ àwọn tí ìwọ rà padà pẹ̀lú agbára ńlá rẹ àti ọwọ́ agbára ńlá rẹ.
Wszak oni są słudzy twoi, i lud twój, któryś odkupił mocą twoją wielką, i ręką twą silną.
11 Olúwa, jẹ́ kí etí rẹ ṣí sílẹ̀ sí àdúrà ìránṣẹ́ rẹ yìí, àti sí àdúrà àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí wọ́n ní inú dídùn láti bọ̀wọ̀ fún orúkọ rẹ. Fún ìránṣẹ́ rẹ ní àṣeyọrí lónìí kí o sì síjú àánú wò ó níwájú ọkùnrin yìí.” Nítorí tí mo jẹ́ agbọ́tí ọba nígbà náà.
Proszę o Panie! niech teraz będzie ucho twoje nakłonione ku modlitwie sługi twego i ku modlitwie sług twoich, którzy mają wolę bać się imienia twego; a zdarz dziś, proszę, słudze twemu, i spraw mu miłosierdzie przed tym mężem. A jam był podczaszym królewskim.

< Nehemiah 1 >