< Nehemiah 1 >

1 Ọ̀rọ̀ Nehemiah ọmọ Hakaliah. Ní oṣù Kisleu ní ogún ọdún (ìjọba Ahaswerusi ọba Persia) nígbà tí mo wà ní ààfin Susa,
O NA olelo a Nehemia ke keiki a Hakalia. I ka malama o Kiseleu, i ka iwakalua o ka makahiki, iloko no wau o Susana o ka pakaua;
2 Hanani, ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin mi wá láti Juda pẹ̀lú àwọn ọkùnrin kan, mo sì béèrè lọ́wọ́ wọn nípa àwọn Júù tí ó ṣẹ́kù tí wọn kò kó ní ìgbèkùn, àti nípa Jerusalẹmu.
A hiki mai la o Hanani, kekahi o na hoahanau o'u, oia a mo kekahi mau kanaka o ka Iuda; a ninau aku au ia lakou no ka poe o ka Iuda i pakele, ka poe i koe i ka lawe pio ana, a no Ierusalema no hoi.
3 Wọ́n sọ fún mi pé, “Àwọn tí ó kù tí a kó ní ìgbèkùn tí wọ́n sì padà sí agbègbè ìjọba wà nínú wàhálà púpọ̀ àti ẹ̀gàn. Odi Jerusalẹmu ti wó lulẹ̀ a sì ti fi iná sun ẹnu ibodè rẹ̀.”
A i mai la lakou ia'u, O ka poe i haaleleia malaila, ma ka mokuna, ka poe i koe i ka lawe pio ana, iloko no lakou o ka popilikia nui a me ka hoinoia mai; a o ka pa o Ierusalema, ua hoohioloia, a o na panipuka no hoi ona, ua pau i ke ahi.
4 Nígbà tí mo gbọ́ àwọn nǹkan wọ̀nyí, mo jókòó mo sì sọkún. Mo ṣọ̀fọ̀, mo gbààwẹ̀, mo sì gbàdúrà fún ọjọ́ díẹ̀ níwájú Ọlọ́run ọ̀run.
A i ko'u lohe ana i keia mau mea, noho no au ilalo, a uwe iho la, a kaniuhu no hoi i kekahi mau la, e hoopololi ana a e pule ana hoi imua o ke Akua o ka lani,
5 Nígbà náà ni mo wí pé: “Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run, Ọlọ́run tí ó tóbi tí ó sì ní ẹ̀rù, tí ó ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ pẹ̀lú wọn tí ó fẹ́ ẹ tí wọ́n sì ń pa àṣẹ mọ́.
A i aku la, Ke noi aku nei au ia oe, e Iehova ke Akua o ka lani, ke Akua nui hooweliweli, e malama ana i ka berita a i ke aloha no ka poe i aloha aku ia ia a malama hoi i kana mau kauoha;
6 Jẹ́ kí etí rẹ kí ó ṣí sílẹ̀, kí ojú ù rẹ kí ó sì ṣí sílẹ̀ láti gbọ́ àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ ń gbà ní iwájú rẹ ní ọ̀sán àti ní òru fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ènìyàn Israẹli. Mo jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àwa ọmọ Israẹli àti tèmi àti ti ilé baba mi, tí a ti ṣẹ̀ sí ọ.
E haliu mai no kou pepeiao, a e kaakaa kou mau maka i lohe oe i ka pule a kau kauwa, a'u e pule aku nei imua ou i keia la. i ke ao a me ka po, no na mamo a Iseraela, kau poe kauwa; e hai aku ana hoi i na hewa a na mamo a Iseraela a makou i hana hewa a aku ai ia oe; owau a me ko ka hale o ko'u makuakane, ua hana hewa no makou.
7 Àwa ti ṣe búburú sí ọ. A kò sì pa àṣẹ ìlànà àti òfin tí ìwọ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ mọ́.
Ua hana ino loa aku no makou ia oe, aole hoi i malama makou i na kauoha, a me na kanawai a me na olelo kupaa, au i kauoha mai ai ia Mose i kau kauwa.
8 “Rántí ìlànà tí o fún Mose ìránṣẹ́ rẹ, wí pé, ‘Bí ìwọ bá jẹ́ aláìṣòótọ́, èmi yóò fọ́n yín ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè.
Ke noi aku nei au ia oe o hoomanao oe i ka olelo au i kauoha mai ai ia Mose i kau kauwa, i mai la, A hana hewa oukou, e hoopuehu aku no au ia oukou iwaena o na lahuikanaka;
9 Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá yípadà sí mi, tí ẹ bá sì pa àṣẹ mi mọ́, nígbà náà bí àwọn ènìyàn yín tí a kó ní ìgbèkùn tilẹ̀ wà ní jìnnà réré ìpẹ̀kun ọ̀run, èmi yóò kó wọn jọ láti ibẹ̀, èmi yóò sì mú wọn wá, sí ibi tí èmi ti yàn bí i ibùgbé fún orúkọ mi.’
Aka, ina huli mai oukou ia'u, a malama i ka'u mau kauoha, a hana hoi ia; alaila ina i kipakuia kekahi o oukou ma ka palena o ka lani, e houluulu au ia lakou malaila mai, a e lawe mai ia lakou ma kahi a'u i wae ai e waiho i ko'u inoa malaila.
10 “Àwọn ni ìránṣẹ́ rẹ àti ènìyàn rẹ àwọn tí ìwọ rà padà pẹ̀lú agbára ńlá rẹ àti ọwọ́ agbára ńlá rẹ.
A, o lakou la, o kau poe kauwa no a me kou poe kanaka, au i hoopakele ai me kou mana nui, a me kou lima ikaika.
11 Olúwa, jẹ́ kí etí rẹ ṣí sílẹ̀ sí àdúrà ìránṣẹ́ rẹ yìí, àti sí àdúrà àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí wọ́n ní inú dídùn láti bọ̀wọ̀ fún orúkọ rẹ. Fún ìránṣẹ́ rẹ ní àṣeyọrí lónìí kí o sì síjú àánú wò ó níwájú ọkùnrin yìí.” Nítorí tí mo jẹ́ agbọ́tí ọba nígbà náà.
Ke noi aku nei au ia oe, e ka Haku e, e haliu mai kou pepeiao i ka pule a kau kauwa, a i ka pule a kau mau kauwa e makemake ana e makau i kou inoa; a e kokua mai oe i kau kauwa, i keia la, a haawi mai ia ia i ka lokomaikaiia mai imua o keia kanaka. No ka mea, owau ka mea lawe kiaha no ke alii.

< Nehemiah 1 >