< Nehemiah 1 >

1 Ọ̀rọ̀ Nehemiah ọmọ Hakaliah. Ní oṣù Kisleu ní ogún ọdún (ìjọba Ahaswerusi ọba Persia) nígbà tí mo wà ní ààfin Susa,
Récits de Néhémias, fils d'Helcias. Au mois de chaseleu, en la vingtième année, j'étais à Suse, résidence royale.
2 Hanani, ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin mi wá láti Juda pẹ̀lú àwọn ọkùnrin kan, mo sì béèrè lọ́wọ́ wọn nípa àwọn Júù tí ó ṣẹ́kù tí wọn kò kó ní ìgbèkùn, àti nípa Jerusalẹmu.
Et Anani, l'un de mes frères, vint, lui et des hommes de Juda, et je les questionnai, tant sur ceux qui étaient demeurés de la captivité et vivaient encore, que sur Jérusalem.
3 Wọ́n sọ fún mi pé, “Àwọn tí ó kù tí a kó ní ìgbèkùn tí wọ́n sì padà sí agbègbè ìjọba wà nínú wàhálà púpọ̀ àti ẹ̀gàn. Odi Jerusalẹmu ti wó lulẹ̀ a sì ti fi iná sun ẹnu ibodè rẹ̀.”
Et ils me dirent: Ceux qui sont demeurés, et qui ont été laissés de la captivité, sont dans la terre promise en grande détresse et opprobre; les murs de Jérusalem ont été abattus, et ses portes brûlées par le feu.
4 Nígbà tí mo gbọ́ àwọn nǹkan wọ̀nyí, mo jókòó mo sì sọkún. Mo ṣọ̀fọ̀, mo gbààwẹ̀, mo sì gbàdúrà fún ọjọ́ díẹ̀ níwájú Ọlọ́run ọ̀run.
Or, quand j'eus ouï de telles paroles, je m'assis et pleurai, et, pendant plusieurs jours, me lamentai, et j'étais jeûnant et priant devant le Dieu du ciel.
5 Nígbà náà ni mo wí pé: “Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run, Ọlọ́run tí ó tóbi tí ó sì ní ẹ̀rù, tí ó ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ pẹ̀lú wọn tí ó fẹ́ ẹ tí wọ́n sì ń pa àṣẹ mọ́.
Et je dis: Que cela ne soit, je vous prie, Seigneur Dieu du ciel, Dieu fort, grand et redoutable qui gardez votre alliance et votre miséricorde à ceux qui vous aiment et observent vos commandements.
6 Jẹ́ kí etí rẹ kí ó ṣí sílẹ̀, kí ojú ù rẹ kí ó sì ṣí sílẹ̀ láti gbọ́ àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ ń gbà ní iwájú rẹ ní ọ̀sán àti ní òru fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ènìyàn Israẹli. Mo jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àwa ọmọ Israẹli àti tèmi àti ti ilé baba mi, tí a ti ṣẹ̀ sí ọ.
Que votre oreille soit attentive, que vos yeux s'ouvrent, afin d'ouïr l'oraison de votre serviteur que je fais maintenant devant vous, nuit et jour, pour vos serviteurs les enfants d'Israël; et je me confesse pour les péchés des enfants d'Israël, en lesquels nous avons péché contre vous. Moi et la maison de mon père avons péché.
7 Àwa ti ṣe búburú sí ọ. A kò sì pa àṣẹ ìlànà àti òfin tí ìwọ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ mọ́.
Nous avons rompu l'alliance; nous n'avons point gardé les commandements, les jugements et les ordonnances que vous avez intimés à Moïse, votre serviteur.
8 “Rántí ìlànà tí o fún Mose ìránṣẹ́ rẹ, wí pé, ‘Bí ìwọ bá jẹ́ aláìṣòótọ́, èmi yóò fọ́n yín ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè.
Souvenez-vous de la parole que vous avez intimée à Moïse, votre serviteur, disant: Si vous manquez à notre alliance, je vous disperserai parmi les nations.
9 Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá yípadà sí mi, tí ẹ bá sì pa àṣẹ mi mọ́, nígbà náà bí àwọn ènìyàn yín tí a kó ní ìgbèkùn tilẹ̀ wà ní jìnnà réré ìpẹ̀kun ọ̀run, èmi yóò kó wọn jọ láti ibẹ̀, èmi yóò sì mú wọn wá, sí ibi tí èmi ti yàn bí i ibùgbé fún orúkọ mi.’
Et si vous revenez à moi, si vous gardez mes commandements, si vous les pratiquez, quand vous seriez disséminés jusqu'aux lieux où la terre touche le ciel, je vous en ramènerai, je vous réunirai en la terre que j'ai choisie pour que mon nom y réside.
10 “Àwọn ni ìránṣẹ́ rẹ àti ènìyàn rẹ àwọn tí ìwọ rà padà pẹ̀lú agbára ńlá rẹ àti ọwọ́ agbára ńlá rẹ.
Et voici vos serviteurs et votre peuple que vous avez rachetés par votre toute-puissance et votre forte main.
11 Olúwa, jẹ́ kí etí rẹ ṣí sílẹ̀ sí àdúrà ìránṣẹ́ rẹ yìí, àti sí àdúrà àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí wọ́n ní inú dídùn láti bọ̀wọ̀ fún orúkọ rẹ. Fún ìránṣẹ́ rẹ ní àṣeyọrí lónìí kí o sì síjú àánú wò ó níwájú ọkùnrin yìí.” Nítorí tí mo jẹ́ agbọ́tí ọba nígbà náà.
Qu'ils ne demeurent pas ainsi, Seigneur; mais que votre oreille soit attentive à l'oraison de votre serviteur et à celle de vos serviteurs qui veulent craindre votre nom. Soyez-lui propice aujourd'hui à votre serviteur; faites qu'il trouve miséricorde devant les hommes; or, j'étais échanson du roi.

< Nehemiah 1 >