< Nehemiah 1 >

1 Ọ̀rọ̀ Nehemiah ọmọ Hakaliah. Ní oṣù Kisleu ní ogún ọdún (ìjọba Ahaswerusi ọba Persia) nígbà tí mo wà ní ààfin Susa,
Paroles de Néhémie, fils de Hacalia. Au mois de Chislev de la vingtième année, comme je me trouvais dans le palais de Suse,
2 Hanani, ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin mi wá láti Juda pẹ̀lú àwọn ọkùnrin kan, mo sì béèrè lọ́wọ́ wọn nípa àwọn Júù tí ó ṣẹ́kù tí wọn kò kó ní ìgbèkùn, àti nípa Jerusalẹmu.
Hanani, l'un de mes frères, arriva, lui et quelques hommes de Juda, et je les interrogeai sur les Juifs qui s'étaient échappés, sur ceux qui restaient de la captivité, et sur Jérusalem.
3 Wọ́n sọ fún mi pé, “Àwọn tí ó kù tí a kó ní ìgbèkùn tí wọ́n sì padà sí agbègbè ìjọba wà nínú wàhálà púpọ̀ àti ẹ̀gàn. Odi Jerusalẹmu ti wó lulẹ̀ a sì ti fi iná sun ẹnu ibodè rẹ̀.”
Ils me répondirent: « Les restes de la captivité qui sont restés dans la province sont dans une grande détresse et dans l'opprobre. La muraille de Jérusalem est aussi détruite, et ses portes sont brûlées par le feu. »
4 Nígbà tí mo gbọ́ àwọn nǹkan wọ̀nyí, mo jókòó mo sì sọkún. Mo ṣọ̀fọ̀, mo gbààwẹ̀, mo sì gbàdúrà fún ọjọ́ díẹ̀ níwájú Ọlọ́run ọ̀run.
Lorsque j'entendis ces paroles, je m'assis et je pleurai, et je fus en deuil pendant plusieurs jours; Je jeûnai et je priai devant le Dieu des cieux,
5 Nígbà náà ni mo wí pé: “Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run, Ọlọ́run tí ó tóbi tí ó sì ní ẹ̀rù, tí ó ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ pẹ̀lú wọn tí ó fẹ́ ẹ tí wọ́n sì ń pa àṣẹ mọ́.
et je dis: « Je t'en supplie, Yahvé, le Dieu des cieux, le Dieu grand et redoutable qui garde l'alliance et la bonté envers ceux qui l'aiment et qui gardent ses commandements,
6 Jẹ́ kí etí rẹ kí ó ṣí sílẹ̀, kí ojú ù rẹ kí ó sì ṣí sílẹ̀ láti gbọ́ àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ ń gbà ní iwájú rẹ ní ọ̀sán àti ní òru fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ènìyàn Israẹli. Mo jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àwa ọmọ Israẹli àti tèmi àti ti ilé baba mi, tí a ti ṣẹ̀ sí ọ.
que ton oreille soit attentive et tes yeux ouverts, afin que tu puisses écouter la prière de ton serviteur que je fais devant toi en ce moment, jour et nuit, pour les enfants d'Israël, tes serviteurs, tandis que je confesse les péchés des enfants d'Israël que nous avons commis contre toi. Oui, moi et la maison de mon père avons péché.
7 Àwa ti ṣe búburú sí ọ. A kò sì pa àṣẹ ìlànà àti òfin tí ìwọ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ mọ́.
Nous nous sommes montrés très corrompus envers toi, et nous n'avons pas observé les commandements, les lois et les ordonnances que tu avais prescrits à ton serviteur Moïse.
8 “Rántí ìlànà tí o fún Mose ìránṣẹ́ rẹ, wí pé, ‘Bí ìwọ bá jẹ́ aláìṣòótọ́, èmi yóò fọ́n yín ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè.
« Souviens-toi, je t'en prie, de la parole que tu as donnée à Moïse, ton serviteur, en disant: « Si vous commettez une infidélité, je vous disperserai parmi les peuples;
9 Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá yípadà sí mi, tí ẹ bá sì pa àṣẹ mi mọ́, nígbà náà bí àwọn ènìyàn yín tí a kó ní ìgbèkùn tilẹ̀ wà ní jìnnà réré ìpẹ̀kun ọ̀run, èmi yóò kó wọn jọ láti ibẹ̀, èmi yóò sì mú wọn wá, sí ibi tí èmi ti yàn bí i ibùgbé fún orúkọ mi.’
mais si vous revenez à moi, si vous gardez mes commandements et si vous les mettez en pratique, quand vos exilés seraient à l'extrémité des cieux, je les rassemblerai de là et je les amènerai dans le lieu que j'ai choisi, pour y faire résider mon nom ».
10 “Àwọn ni ìránṣẹ́ rẹ àti ènìyàn rẹ àwọn tí ìwọ rà padà pẹ̀lú agbára ńlá rẹ àti ọwọ́ agbára ńlá rẹ.
« Voici tes serviteurs et ton peuple, que tu as rachetés par ta grande puissance et par ta main forte.
11 Olúwa, jẹ́ kí etí rẹ ṣí sílẹ̀ sí àdúrà ìránṣẹ́ rẹ yìí, àti sí àdúrà àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí wọ́n ní inú dídùn láti bọ̀wọ̀ fún orúkọ rẹ. Fún ìránṣẹ́ rẹ ní àṣeyọrí lónìí kí o sì síjú àánú wò ó níwájú ọkùnrin yìí.” Nítorí tí mo jẹ́ agbọ́tí ọba nígbà náà.
Seigneur, je t'en prie, que ton oreille soit maintenant attentive à la prière de ton serviteur, et à la prière de tes serviteurs qui aiment à craindre ton nom; fais prospérer aujourd'hui ton serviteur, et accorde-lui la miséricorde aux yeux de cet homme. » J'étais le porteur de coupe du roi.

< Nehemiah 1 >