< Nehemiah 1 >

1 Ọ̀rọ̀ Nehemiah ọmọ Hakaliah. Ní oṣù Kisleu ní ogún ọdún (ìjọba Ahaswerusi ọba Persia) nígbà tí mo wà ní ààfin Susa,
Slova Nehemiáše syna Chachaliášova. I stalo se měsíce Kislev léta dvadcátého, když jsem byl na hradě Susan,
2 Hanani, ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin mi wá láti Juda pẹ̀lú àwọn ọkùnrin kan, mo sì béèrè lọ́wọ́ wọn nípa àwọn Júù tí ó ṣẹ́kù tí wọn kò kó ní ìgbèkùn, àti nípa Jerusalẹmu.
Že přišel Chanani, jeden z bratří mých, s některými muži z Judstva. Kterýchžto vzeptal jsem se na Židy, na ostatky pozůstalé z zajetí a na Jeruzalém.
3 Wọ́n sọ fún mi pé, “Àwọn tí ó kù tí a kó ní ìgbèkùn tí wọ́n sì padà sí agbègbè ìjọba wà nínú wàhálà púpọ̀ àti ẹ̀gàn. Odi Jerusalẹmu ti wó lulẹ̀ a sì ti fi iná sun ẹnu ibodè rẹ̀.”
I řekli mi: Ostatkové ti, kteříž pozůstali z zajetí tam v té krajině, jsou u velikém nátisku a v pohanění, nadto i zed Jeruzalémská rozbořena jest, a brány jeho ohněm zkaženy.
4 Nígbà tí mo gbọ́ àwọn nǹkan wọ̀nyí, mo jókòó mo sì sọkún. Mo ṣọ̀fọ̀, mo gbààwẹ̀, mo sì gbàdúrà fún ọjọ́ díẹ̀ níwájú Ọlọ́run ọ̀run.
Kterážto slova když jsem uslyšel, sedna plakal jsem a kvílil za několik dní, a postil jsem se, i modlil před Bohem nebeským.
5 Nígbà náà ni mo wí pé: “Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run, Ọlọ́run tí ó tóbi tí ó sì ní ẹ̀rù, tí ó ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ pẹ̀lú wọn tí ó fẹ́ ẹ tí wọ́n sì ń pa àṣẹ mọ́.
A řekl jsem: Prosím, Hospodine Bože nebeský, silný, veliký a hrozný, ostříhající smlouvy a milosrdenství těm, jenž tě milují, a ostříhají přikázaní tvých,
6 Jẹ́ kí etí rẹ kí ó ṣí sílẹ̀, kí ojú ù rẹ kí ó sì ṣí sílẹ̀ láti gbọ́ àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ ń gbà ní iwájú rẹ ní ọ̀sán àti ní òru fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ènìyàn Israẹli. Mo jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àwa ọmọ Israẹli àti tèmi àti ti ilé baba mi, tí a ti ṣẹ̀ sí ọ.
Budiž, prosím, ucho tvé nakloněné, a oči tvé otevřené, abys slyšel modlitbu služebníka svého, kterouž já se modlím před tebou nyní dnem i nocí za syny Izraelské, služebníky tvé, a vyznávám hříchy synů Izraelských, jimiž jsme hřešili proti tobě. Já také i dům otce mého hřešili jsme.
7 Àwa ti ṣe búburú sí ọ. A kò sì pa àṣẹ ìlànà àti òfin tí ìwọ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ mọ́.
Zpronevěřili jsme se tobě, a neostříhali jsme přikázaní a ustanovení a soudů, kteréž jsi vydal skrze Mojžíše služebníka svého.
8 “Rántí ìlànà tí o fún Mose ìránṣẹ́ rẹ, wí pé, ‘Bí ìwọ bá jẹ́ aláìṣòótọ́, èmi yóò fọ́n yín ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè.
Budiž pamětliv, prosím, na slovo, kteréž jsi přikázal Mojžíšovi služebníku svému, řka: Vy přestoupíte, já pak rozptýlím vás mezi národy.
9 Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá yípadà sí mi, tí ẹ bá sì pa àṣẹ mi mọ́, nígbà náà bí àwọn ènìyàn yín tí a kó ní ìgbèkùn tilẹ̀ wà ní jìnnà réré ìpẹ̀kun ọ̀run, èmi yóò kó wọn jọ láti ibẹ̀, èmi yóò sì mú wọn wá, sí ibi tí èmi ti yàn bí i ibùgbé fún orúkọ mi.’
Ale když se obrátíte ke mně, a budete ostříhati přikázaní mých, a plniti je, by pak někteří z vás až na kraj světa zahnáni byli, i odtud shromáždím je, a přivedu je zase na místo, kteréž jsem vyvolil, aby tam přebývalo jméno mé.
10 “Àwọn ni ìránṣẹ́ rẹ àti ènìyàn rẹ àwọn tí ìwọ rà padà pẹ̀lú agbára ńlá rẹ àti ọwọ́ agbára ńlá rẹ.
Však tito jsou služebníci tvoji a lid tvůj, kteréž jsi vykoupil mocí svou převelikou, a rukou svou přesilnou.
11 Olúwa, jẹ́ kí etí rẹ ṣí sílẹ̀ sí àdúrà ìránṣẹ́ rẹ yìí, àti sí àdúrà àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí wọ́n ní inú dídùn láti bọ̀wọ̀ fún orúkọ rẹ. Fún ìránṣẹ́ rẹ ní àṣeyọrí lónìí kí o sì síjú àánú wò ó níwájú ọkùnrin yìí.” Nítorí tí mo jẹ́ agbọ́tí ọba nígbà náà.
Prosím, ó Hospodine, nechť jest nakloněné ucho tvé k modlitbě služebníka tvého, a k modlitbě služebníků tvých, kteříž žádají báti se jména tvého, a dej šťastný prospěch, prosím, služebníku svému dnes, nakloně k němu lítostí člověka toho. Já pak byl jsem šeňkéřem královským.

< Nehemiah 1 >