< Nehemiah 9 >

1 Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kan náà, àwọn ọmọ Israẹli péjọpọ̀, wọ́n gbààwẹ̀, wọ́n wọ aṣọ ọ̀fọ̀, wọ́n sì da eruku sórí ara wọn.
Un tā paša mēneša divdesmit ceturtā dienā Israēla bērni sapulcējās, gavēdami un maisos un ar zemi uz galvām.
2 Àwọn ọkùnrin Israẹli sì ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò nínú gbogbo àwọn àjèjì. Wọ́n dúró ní ààyè e wọn, wọ́n sì ń jẹ́wọ́ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ ẹ wọn àti iṣẹ́ búburú àwọn baba wọn.
Un Israēla dzimums šķīrās no visiem svešiniekiem, un tie stāvēja un sūdzēja savus grēkus un savu tēvu noziegumus.
3 Wọ́n dúró sí ibi tí wọ́n wà, wọ́n sì fi ìdámẹ́rin ọjọ́ kà nínú ìwé òfin Olúwa Ọlọ́run wọn, wọ́n sì tún fi ìdámẹ́rin mìíràn ní ìjẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àti ní sí sin Olúwa Ọlọ́run wọn.
Un tie cēlās no savas vietas un vienu cēlienu tie lasīja Tā Kunga, sava Dieva, bauslības grāmatā, un vienu cēlienu tie sūdzēja (savus grēkus) un pielūdza To Kungu, savu Dievu.
4 Nígbà náà ni Jeṣua, àti Bani, Kadmieli, Ṣebaniah, Bunni, Ṣerebiah, Bani àti Kenaani gòkè dúró lórí àwọn àtẹ̀gùn àwọn ọmọ Lefi, wọ́n sì fi ohùn rara kígbe sí Olúwa Ọlọ́run wọn.
Un augstā levitu vietā stāvēja: Ješuūs un Banus, Kadmiēls, Šebanija, Bunus, Šerebija, Banus un Kenanus, un sauca ar stipru balsi uz To Kungu, savu Dievu.
5 Nígbà náà ni àwọn ọmọ Lefi: Jeṣua, Kadmieli, Bani, Haṣbneiah, Ṣerebiah, Hodiah, Ṣebaniah àti Petahiah—wí pé, “Ẹ dìde ẹ fi ìyìn fún Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó wà láé àti láéláé.” “Ìbùkún ni fún orúkọ rẹ tí ó ní ògo, kí ó sì di gbígbéga ju gbogbo ìbùkún àti ìyìn lọ.
Un tad sacīja tie leviti Ješuūs un Kadmiēls, Banus, Azabenija, Šerebija, Hodija, Šebanija, Petahja: ceļaties, teiciet To Kungu, savu Dievu, mūžīgi mūžam. Un lai slavēts top Tavas godības vārds, kas ir augstāks pār visu slavu un teikšanu.
6 Ìwọ nìkan ni Olúwa. Ìwọ ni ó dá ọ̀run, àní àwọn ọ̀run tí ó ga jù pẹ̀lú gbogbo ogun wọn, ayé àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀, òkun, àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀. Ìwọ sì pa gbogbo wọn mọ́ láàyè, ogun ọ̀run sì ń sìn ọ́.
Tu esi tas vienīgais Kungs, Tu esi darījis debesis un debesu debesis un visu viņu spēku, zemi un visu, kas zemes virsū, jūru un visu, kas iekš tās, un Tu dari šo visu dzīvu un debesu spēks klanās Tavā priekšā.
7 “Ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run, tí ó yan Abramu tí ó sì mú u jáde láti Uri ti Kaldea, tí ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Abrahamu.
Tu esi Tas Kungs un Dievs, kas Ābramu izredzējis un viņu izvedis no Ura Kaldejā un viņam devis vārdu Ābrahāmu.
8 Ìwọ sì rí í pé ọkàn rẹ̀ jẹ́ olóòtítọ́ sí ọ, ìwọ sì dá májẹ̀mú pẹ̀lú u rẹ̀ láti fi ilẹ̀ àwọn ará a Kenaani, Hiti, Amori, Peresi, Jebusi àti Girgaṣi fún irú àwọn ọmọ rẹ̀. Ìwọ ti pa ìpinnu rẹ̀ mọ́ nítorí tí ìwọ jẹ́ olódodo.
Un Tu viņa sirdi esi atradis uzticīgu Sava vaiga priekšā, un ar viņu esi cēlis derību, viņam dot Kanaāniešu, Hetiešu, Amoriešu un Fereziešu un Jebusiešu un Ģirgoziešu zemi, to dot viņa dzimumam; un Tu Savu vārdu stipri esi turējis, tāpēc ka Tu esi taisns.
9 “Ìwọ rí ìpọ́njú àwọn baba ńlá wa ní Ejibiti; ìwọ gbọ́ igbe ẹkún wọn ní Òkun Pupa.
Un Tu esi redzējis mūsu tēvu bēdas Ēģiptes zemē un viņu brēkšanu klausījis pie Niedru jūras,
10 Ìwọ rán iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu sí Farao, sí gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀ àti sí gbogbo ènìyàn ilẹ̀ ẹ rẹ̀, nítorí ìwọ mọ ìwà ìgbéraga tí àwọn ará Ejibiti hù sí wọn. Ìwọ ra orúkọ fún ara à rẹ, èyí tí ó sì wà títí di òní yìí.
Un esi zīmes un brīnumus darījis pie Faraona un pie visiem viņa kalpiem un pie visiem viņa zemes ļaudīm. Jo Tu zināji, ka tie pret tiem bijuši pārgalvīgi, un Tu Sev esi darījis slavu, tā kā šodien.
11 Ìwọ pín òkun níwájú wọn, nítorí kí wọn lè kọjá ní ìyàngbẹ ilẹ̀, ṣùgbọ́n ìwọ sọ àwọn tí ń lépa wọn sínú ibú, bí òkúta sínú omi ńlá.
Un jūru Tu esi dalījis viņu priekšā, ka tie pa jūras vidu ir gājuši sausumā; un kas viņiem pakaļ dzinās, tos Tu esi iemetis dziļumos, tā kā akmeni stipros ūdeņos.
12 Ní ọ̀sán ìwọ darí i wọn pẹ̀lú ọ̀wọn àwọsánmọ̀ àti ní òru ni ìwọ darí i wọn pẹ̀lú ọ̀wọn iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ ní ọ̀nà tí wọn yóò gbà.
Un dienā Tu tos esi vadījis ar padebeša stabu un naktī ar uguns stabu, viņiem gaišu darīdams ceļu, kur tiem bija jāiet.
13 “Ìwọ sọ̀kalẹ̀ wá sí orí òkè Sinai; ìwọ bá wọn sọ̀rọ̀ láti ọ̀run. Ìwọ fún wọn ní ìlànà àti àwọn òfin tí ó jẹ́ òdodo tí ó sì tọ́ àti ìlànà tí ó dára.
Un Tu esi nolaidies uz Sinaī kalnu un no debesīm ar tiem runājis un tiem devis taisnas tiesas, īstenu bauslību, labus likumus un baušļus.
14 Ìwọ mú ọjọ́ ìsinmi rẹ mímọ́ di mí mọ̀ fún wọn, o sì fún wọn ní àwọn ìlànà, àwọn àṣẹ àti àwọn òfin láti ọwọ́ Mose ìránṣẹ́ rẹ.
Un savu svēto dusas dienu Tu tiem esi darījis zināmu, un baušļus un iestādījumus un bauslību tiem esi pavēlējis caur Mozu, Savu kalpu.
15 Ìwọ fún wọn ní oúnjẹ láti ọ̀run wá nígbà tí ebi ń pa wọ́n àti nígbà òǹgbẹ, o fún wọn ní omi láti inú àpáta; o sì sọ fún wọn pé, kí wọ́n lọ láti lọ gba ilẹ̀ náà tí ìwọ ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ láti fi fún wọn nípa ìgbọ́wọ́sókè.
Un maizi Tu tiem esi devis no debesīm, kad tie bija izsalkuši, un ūdeni tiem izvedis no klints, kad tie bija izslāpuši, un esi uz tiem sacījis, lai ieiet un iemanto to zemi, pār ko Tu Savu roku pacēli, viņiem to dot.
16 “Ṣùgbọ́n àwọn, baba ńlá wa, wọ́n ṣe ìgbéraga, wọ́n sì ṣe agídí, wọn kò sì tẹríba fún àwọn ìlànà rẹ.
Bet šie, mūsu tēvi, turējušies pārgalvīgi un viņu kakls palika stīvs, un tie nav klausījuši Taviem baušļiem,
17 Wọ́n kọ̀ láti fetísílẹ̀, wọ́n sì kùnà láti rántí iṣẹ́ ìyanu tí ìwọ ṣe ní àárín wọn. Wọ́n ṣe agídí, nínú ìṣọ̀tẹ̀ wọn, wọ́n yan olórí láti padà sí oko ẹrú wọn. Ṣùgbọ́n ìwọ Ọlọ́run tí ó ń dáríjì, olóore-ọ̀fẹ́ àti aláàánú, ó lọ́ra láti bínú, ó sì pọ̀ ní ìfẹ́. Nítorí náà ìwọ kò sì kọ̀ wọ́n sílẹ̀,
Un ir liegušies klausīt un nav pieminējuši Tavus brīnumus, ko Tu tiem esi darījis, bet tie palikuši stūrgalvīgi un cēluši virsnieku, iet atpakaļ uz savu kalpošanu, dumpinieki būdami. Bet Tu Dievs žēlotājs, žēlīgs un sirdsžēlīgs, lēnprātīgs un no lielas žēlastības, Tu tos neesi atstājis.
18 nítòótọ́ nígbà tí wọ́n ṣe ẹgbọrọ màlúù dídá, tí wọ́n sì wí pé, ‘Èyí ni Ọlọ́run rẹ tí ó mú ọ gòkè láti Ejibiti wá; tàbí nígbà tí wọ́n sọ ọ̀rọ̀-òdì tí ó burú jàì’.
Jebšu tie arī taisīja lietu teļu un sacīja: šis ir tavs dievs, kas tevi izvedis no Ēģiptes zemes, - un tevi gauži kaitināja,
19 “Nítorí àánú ńlá rẹ, ìwọ kò kọ̀ wọ́n sílẹ̀ ní aginjù. Ní ọ̀sán ọ̀wọn ìkùùkuu kò kúrò ní ọ̀dọ̀ wọn láti ṣe amọ̀nà an wọn, tàbí ọ̀wọ́n iná láti tàn sí wọn ní òru ní ọ̀nà tí wọn yóò rìn.
Tomēr pēc Savas lielās sirdsžēlastības Tu tos neesi atstājis tuksnesī, tas padebeša stabs neatstājās no tiem dienā, tos vezdams pa ceļu, nedz tas uguns stabs naktī, tiem spīdēdams uz ceļa, kur tie gāja.
20 Ìwọ fi ẹ̀mí rere rẹ fún wọn láti kọ́ wọn. Ìwọ kò dá manna rẹ dúró ní ẹnu wọn, ó sì fún wọn ní omi fún òǹgbẹ.
Un Tu esi devis Savu labo Garu, tos pamācīt, un to mannu Tu neesi atrāvis no viņu mutes, un tiem ūdeni esi devis, kad tie bija izslāpuši.
21 Fún ogójì ọdún ni ìwọ fi bọ́ wọn ní aginjù; wọn kò ṣe aláìní ohunkóhun, aṣọ wọn kò gbó bẹ́ẹ̀ ni ẹsẹ̀ wọn kò wú.
Tā Tu tos tuksnesī esi uzturējis četrdesmit gadus, tiem nekāds trūkums nav bijis, viņu drēbes nav palikušas vecas un viņu kājas nav uztūkušas.
22 “Ìwọ fi àwọn ìjọba àti àwọn orílẹ̀-èdè fún wọn, ó sì fi gbogbo ilẹ̀ náà fún wọ́n. Wọ́n sì gba ilẹ̀ ọba Sihoni ará a Heṣboni àti ilẹ̀ Ogu ọba Baṣani.
Un Tu tiem esi devis ķēniņu valstis un ļaudis, un tos esi nošķīris šurp un turp. Tā tie ir iemantojuši Sihona zemi un Hešbonas ķēniņa zemi un Basanas ķēniņa Oga zemi.
23 Ìwọ ti mú àwọn ọmọ wọn pọ̀ bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, ó sì mú wọn wá sí ilẹ̀ tí o ti sọ fún àwọn baba wọn pé kí wọn wọ̀, kí wọn sì jogún un rẹ̀.
Un viņu bērnus Tu esi vairojis kā debess zvaigznes un tos ievedis tai zemē, par ko Tu viņu tēviem esi sacījis, ka tie ieies, to iemantot.
24 Àwọn ọkùnrin wọn wọ inú rẹ̀, wọ́n sì gbà ilẹ̀ náà. Ìwọ sì tẹ orí àwọn ará a Kenaani, tí ń gbé inú ilẹ̀ náà ba níwájú wọn; ó fi àwọn ará a Kenaani lé wọn lọ́wọ́ pẹ̀lú àwọn ọba wọn àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà kí wọn ṣe wọn bí ó ti wù wọ́n.
Tā tie bērni tur ir iegājuši un to zemi iemantojuši, un Tu esi pazemojis tās zemes iedzīvotājus, tos Kanaāniešus, viņu priekšā un nodevis viņu rokās viņu ķēniņus un tās zemes ļaudis, lai ar tiem dara pēc sava prāta.
25 Wọ́n gba àwọn ìlú olódi àti ilẹ̀ ọlọ́ràá; wọ́n gba àwọn ilé tí ó kún fún onírúurú gbogbo nǹkan rere, àwọn kànga tí a ti gbẹ́, àwọn ọgbà àjàrà, àwọn ọgbà olifi àti àwọn igi eléso ní ọ̀pọ̀lọpọ̀. Wọ́n jẹ, wọ́n yó, wọ́n sì sanra dáradára; wọ́n sì yọ̀ nínú oore ńlá rẹ.
Un tie ir uzņēmuši stipras pilsētas un treknu zemi un iemantojuši namus, visāda labuma pilnus, izcirstas akas, vīna dārzus un eļļas dārzus un daudz augļu kokus, un tie ir ēduši un paēduši un tauki palikuši, un ir priecājušies caur Tavu lielo labdarīšanu.
26 “Ṣùgbọ́n wọ́n ṣe àìgbọ́ràn, wọ́n sì ṣọ̀tẹ̀ sí ọ; wọ́n gbàgbé òfin rẹ. Wọ́n pa àwọn wòlíì rẹ, tí o fi gbà wọn ni ìyànjú pé kí wọn yí padà sí ọ; wọ́n sì se ọ̀rọ̀-òdì tí ó burú jàì.
Bet tie ir palikuši pārgalvīgi un Tev turējušies pretī un atmetuši Tavu bauslību un nokāvuši Tavus praviešus, kas pret tiem liecināja, lai pie Tevis atgriežas, un tie ir padarījuši lielas apkaitināšanas.
27 Nítorí náà, ìwọ fi wọ́n lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́, àwọn tí ó ni wọ́n lára. Ṣùgbọ́n nígbà tí a ni wọ́n lára wọ́n kígbe sí ọ. Ìwọ gbọ́ wọn láti ọ̀run wá àti nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ àánú rẹ, ìwọ fún wọn ní olùgbàlà, tí ó gbà wọ́n lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn.
Tāpēc Tu tos esi devis viņu naidnieku rokā, kas tos spaidījuši. Bet tiem savu spaidu laikā uz Tevi brēcot, Tu esi dzirdējis no debesīm un pēc Savas lielās apžēlošanas Tu tiem esi devis pestītājus, kas tos izpestīja no viņu naidnieku rokas.
28 “Ṣùgbọ́n bí wọ́n bá ti wà nínú ìsinmi, wọn a sì túnṣe búburú lójú rẹ. Nígbà náà ni ìwọ kọ̀ wọ́n sílẹ̀ ṣọ́wọ́ àwọn ọ̀tá kí wọ́n lè jẹ ọba lórí wọn. Nígbà tí wọ́n bá sì tún kígbe sí ọ, ìwọ a gbọ́ láti ọ̀run wá, àti nínú àánú rẹ ni ìwọ gbà láti ìgbà dé ìgbà.
Bet kad tiem bija miers, tad tie atkal darīja ļaunu Tava vaiga priekšā; tā Tu tos atstāji viņu ienaidnieku rokā, un tie pār viņiem valdīja. Kad tie nu atgriezās un uz Tevi brēca, tad Tu tos esi klausījis no debesīm un tos dažu reizi izpestījis pēc Savas lielās apžēlošanas.
29 “Ìwọ kìlọ̀ fún wọn láti padà sínú òfin rẹ, ṣùgbọ́n wọ́n hu ìwà ìgbéraga, wọ́n sì ṣe àìgbọ́ràn si àṣẹ rẹ. Wọ́n ṣẹ̀ sí ìlànà rẹ, nípa èyí tí ènìyàn yóò yè tí wọ́n bá pa wọ́n mọ́. Nínú agídí ọkàn wọ́n kọ ẹ̀yìn sí ọ, wọ́n jẹ́ olórí kunkun wọn kò sì fẹ́ gbọ́.
Un Tu tiem esi devis liecību, lai tie atgriežas pie Tavas bauslības. Bet tie bija pārgalvīgi un neklausīja Taviem baušļiem un grēkoja pret Tavām tiesām, ko cilvēkam būs darīt, lai caur to dzīvo, un tie Tev griezuši muguru un savu kaklu darījuši stīvu un nav klausījuši.
30 Fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún ni ìwọ fi ní sùúrù pẹ̀lú wọn. Nípa ẹ̀mí rẹ ni ìwọ kìlọ̀ fún wọn nípasẹ̀ àwọn wòlíì. Síbẹ̀ wọn kò fi etí sílẹ̀, nítorí náà ni ìwọ ṣe fi wọ́n lé àwọn aládùúgbò wọn lọ́wọ́.
Un Tu uz tiem esi gaidījis daudz gadus un tiem liecinājis caur Savu Garu, caur Saviem praviešiem: bet tie neatgrieza savas ausis. Tāpēc Tu tos esi nodevis pasaules tautu rokā.
31 Ṣùgbọ́n nínú ọ̀pọ̀ àánú rẹ, ìwọ kò mú òpin bá wọn tàbí kọ̀ wọ́n sílẹ̀, nítorí ìwọ ni Ọlọ́run olóore-ọ̀fẹ́ àti aláàánú.
Tomēr pēc Savas lielās apžēlošanas Tu tos neesi pavisam iznīcinājis nedz tos atstājis; jo Tu esi žēlīgs un sirdsžēlīgs Dievs.
32 “Ǹjẹ́ nítorí náà, Ọlọ́run wa, Ọlọ́run tí ó tóbi, tí ó lágbára, tí ó sì ní ẹ̀rù, ẹni tí ó pa májẹ̀mú ìfẹ́ mọ́, má ṣe jẹ́ gbogbo ìnira yìí dàbí ohun kékeré ní ojú rẹ—ìnira tí ó ti wá sórí wa, sórí àwọn ọba wa àti àwọn olórí wa, sórí àwọn àlùfáà wa àti àwọn wòlíì, sórí àwọn baba wa àti sórí gbogbo ènìyàn rẹ̀, láti àwọn ọjọ́ àwọn ọba Asiria wá títí di òní.
Un nu mūsu Dievs, Tu stiprais, lielais, varenais un bijājamais Dievs, kas tur derību un sirds žēlastību, - lai Tev nešķiet maza visa šī grūtība, kas mums uzgājusi mūsu ķēniņiem, mūsu lielkungiem un mūsu priesteriem un mūsu praviešiem un mūsu tēviem un visiem Taviem ļaudīm, no Asīrijas ķēniņa laika līdz šai dienai.
33 Ìwọ jẹ́ olódodo nínú ohun gbogbo tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí wa; ìwọ sì ti ṣe òtítọ́, nígbà tí a bá ṣe búburú.
Tomēr Tu esi taisns iekš visa, kas mums uznācis, jo Tu esi uzticīgi darījis; bet mēs esam darījuši bezdievīgi.
34 Àwọn ọba wa, àwọn olórí wa, àwọn àlùfáà wa, àti àwọn baba wa kò tẹ̀lé òfin rẹ; wọn kò fetísílẹ̀ sí àṣẹ rẹ tàbí àwọn ìkìlọ̀ tí ìwọ fún wọn.
Un mūsu ķēniņi, mūsu lielkungi, mūsu priesteri un mūsu tēvi nav turējuši Tavu bauslību un nav vērā ņēmuši Tavas pavēles un Tavas liecības, ko Tu tiem liecinājis.
35 Àní nígbà tí wọ́n wà nínú ìjọba wọn, tí wọ́n ń gbádùn oore ńlá tí ìwọ fi fún wọn, ní ilẹ̀ tí ó tóbi tí ó sì lọ́ràá, wọn kò sìn ọ́ tàbí padà kúrò nínú àwọn ọ̀nà búburú wọn.
Jo tie Tev nav kalpojuši savā valstī un iekš Tava lielā labuma, ko Tu tiem biji devis, un tai plašā treknā zemē, ko Tu priekš viņiem biji nolicis, un nav atgriezušies no saviem ļauniem darbiem.
36 “Ṣùgbọ́n wò ó, àwa jẹ́ ẹrú lónìí, àwa jẹ́ ẹrú ní ilẹ̀ tí ìwọ fún àwọn baba ńlá wa, nítorí kí wọn bá máa jẹ èso rẹ̀ àti ìre mìíràn tí ó mú jáde.
Redzi, mēs šodien esam kalpi; arī tai zemē, ko Tu mūsu tēviem esi devis, viņas augļus un viņas labumu ēst, - redzi, iekš tās mēs esam kalpi.
37 Nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìkórè rẹ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ọba tí ó fi ṣe olórí wa. Wọ́n ń ṣe àkóso lórí wa àti lórí ẹran wa bí ó ti wù wọ́n, àwa sì wà nínú ìpọ́njú ńlá.
Un viņas augļi vairojās priekš tiem ķēniņiem, ko Tu pār mums esi iecēlis mūsu grēku dēļ, un tie valda pār mūsu miesām un pār mūsu lopiem pēc savas patikšanas. Tā mēs esam lielās bēdās.
38 “Nítorí gbogbo èyí, a ń ṣe àdéhùn tí ó fẹsẹ̀múlẹ̀, a sì kọ ọ́ sínú ìwé, àwọn olórí ọmọ Lefi àwọn àlùfáà sì fi èdìdì dì í.”
Un pēc visa tā mēs cēlām taisnu derību un to uzrakstījām; un mūsu lielkungi, mūsu leviti un mūsu priesteri to apzieģelēja.

< Nehemiah 9 >