< Nehemiah 9 >
1 Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kan náà, àwọn ọmọ Israẹli péjọpọ̀, wọ́n gbààwẹ̀, wọ́n wọ aṣọ ọ̀fọ̀, wọ́n sì da eruku sórí ara wọn.
Or, au vingt-quatrième jour de ce mois, les enfants d’Israël s’assemblèrent dans le jeûne, dans des sacs, et ayant de la terre sur eux.
2 Àwọn ọkùnrin Israẹli sì ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò nínú gbogbo àwọn àjèjì. Wọ́n dúró ní ààyè e wọn, wọ́n sì ń jẹ́wọ́ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ ẹ wọn àti iṣẹ́ búburú àwọn baba wọn.
Et la race des enfants d’Israël fut séparée de tout fils étranger; et ils se tinrent debout, et ils confessaient leurs péchés et les iniquités de leurs pères.
3 Wọ́n dúró sí ibi tí wọ́n wà, wọ́n sì fi ìdámẹ́rin ọjọ́ kà nínú ìwé òfin Olúwa Ọlọ́run wọn, wọ́n sì tún fi ìdámẹ́rin mìíràn ní ìjẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àti ní sí sin Olúwa Ọlọ́run wọn.
Ainsi ils se levèrent pour se tenir debout, ils lurent dans le volume de la loi du Seigneur leur Dieu quatre fois dans le jour, et quatre fois ils confessaient leurs péchés et adoraient le Seigneur leur Dieu.
4 Nígbà náà ni Jeṣua, àti Bani, Kadmieli, Ṣebaniah, Bunni, Ṣerebiah, Bani àti Kenaani gòkè dúró lórí àwọn àtẹ̀gùn àwọn ọmọ Lefi, wọ́n sì fi ohùn rara kígbe sí Olúwa Ọlọ́run wọn.
Or sur l’estrade des Lévites se levèrent Josué, Bani, Cedmihel, Sabania, Bonni, Sarébias, Bani et Chanani, et ils crièrent avec une voix forte vers le Seigneur leur Dieu.
5 Nígbà náà ni àwọn ọmọ Lefi: Jeṣua, Kadmieli, Bani, Haṣbneiah, Ṣerebiah, Hodiah, Ṣebaniah àti Petahiah—wí pé, “Ẹ dìde ẹ fi ìyìn fún Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó wà láé àti láéláé.” “Ìbùkún ni fún orúkọ rẹ tí ó ní ògo, kí ó sì di gbígbéga ju gbogbo ìbùkún àti ìyìn lọ.
Et les Lévites Josué, Cedmihel, Bonni, Hasebnia, Sérébia, Odaïa, Sebnia, Phathahia, dirent: Levez-vous; bénissez le Seigneur votre Dieu depuis l’éternité jusqu’à l’éternité; qu’ils bénissent donc le nom sublime de votre gloire en toute bénédiction et louange.
6 Ìwọ nìkan ni Olúwa. Ìwọ ni ó dá ọ̀run, àní àwọn ọ̀run tí ó ga jù pẹ̀lú gbogbo ogun wọn, ayé àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀, òkun, àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀. Ìwọ sì pa gbogbo wọn mọ́ láàyè, ogun ọ̀run sì ń sìn ọ́.
C’est vous-même, Seigneur, vous seul qui avez fait le ciel, et le ciel des cieux, et toute leur milice; la terre, et tout ce qui est en elle; les mers, et tout ce qui est en elles; et c’est vous qui vivifiez toutes choses, et l’armée du ciel vous adore.
7 “Ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run, tí ó yan Abramu tí ó sì mú u jáde láti Uri ti Kaldea, tí ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Abrahamu.
C’est vous-même, Seigneur Dieu, qui avez choisi Abram, qui l’avez retiré du feu des Chaldéens, et qui lui avez donné le nom d’Abraham.
8 Ìwọ sì rí í pé ọkàn rẹ̀ jẹ́ olóòtítọ́ sí ọ, ìwọ sì dá májẹ̀mú pẹ̀lú u rẹ̀ láti fi ilẹ̀ àwọn ará a Kenaani, Hiti, Amori, Peresi, Jebusi àti Girgaṣi fún irú àwọn ọmọ rẹ̀. Ìwọ ti pa ìpinnu rẹ̀ mọ́ nítorí tí ìwọ jẹ́ olódodo.
Et vous avez trouvé son cœur fidèle devant vous, et vous avez fait avec lui alliance pour lui donner la terre du Chananéen, de l’Héthéen, de l’Amorrhéen, du Phérézéen, du Jébuséen et du Gergéséen, pour la donner à sa postérité; et vous avez accompli vos paroles, parce que vous êtes juste.
9 “Ìwọ rí ìpọ́njú àwọn baba ńlá wa ní Ejibiti; ìwọ gbọ́ igbe ẹkún wọn ní Òkun Pupa.
Et vous avez vu l’affliction de nos pères en Égypte, et vous avez entendu leur cri sur la mer Rouge.
10 Ìwọ rán iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu sí Farao, sí gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀ àti sí gbogbo ènìyàn ilẹ̀ ẹ rẹ̀, nítorí ìwọ mọ ìwà ìgbéraga tí àwọn ará Ejibiti hù sí wọn. Ìwọ ra orúkọ fún ara à rẹ, èyí tí ó sì wà títí di òní yìí.
Et vous avez fait éclater des signes et des merveilles sur Pharaon, et sur tous ses serviteurs, et sur tout le peuple de ce pays; car vous avez connu qu’ils avaient agi insolemment contre eux, et vous vous êtes fait un nom comme il est encore en ce jour.
11 Ìwọ pín òkun níwájú wọn, nítorí kí wọn lè kọjá ní ìyàngbẹ ilẹ̀, ṣùgbọ́n ìwọ sọ àwọn tí ń lépa wọn sínú ibú, bí òkúta sínú omi ńlá.
Et vous avez divisé la mer devant eux, et ils ont passé au milieu de la mer à sec; et ceux qui les poursuivaient, vous les avez jetés au fond, comme une pierre dans de grandes eaux.
12 Ní ọ̀sán ìwọ darí i wọn pẹ̀lú ọ̀wọn àwọsánmọ̀ àti ní òru ni ìwọ darí i wọn pẹ̀lú ọ̀wọn iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ ní ọ̀nà tí wọn yóò gbà.
Et dans une colonne de nuée, vous avez été leur guide pendant le jour, et dans une colonne de feu pendant la nuit, afin que leur apparût la voie dans laquelle ils entraient.
13 “Ìwọ sọ̀kalẹ̀ wá sí orí òkè Sinai; ìwọ bá wọn sọ̀rọ̀ láti ọ̀run. Ìwọ fún wọn ní ìlànà àti àwọn òfin tí ó jẹ́ òdodo tí ó sì tọ́ àti ìlànà tí ó dára.
Vous êtes descendu aussi sur la montagne de Sinaï, et vous avez parlé avec eux du haut du ciel; et vous leur avez donné des ordonnances justes et une loi de vérité, des cérémonies et des bons préceptes.
14 Ìwọ mú ọjọ́ ìsinmi rẹ mímọ́ di mí mọ̀ fún wọn, o sì fún wọn ní àwọn ìlànà, àwọn àṣẹ àti àwọn òfin láti ọwọ́ Mose ìránṣẹ́ rẹ.
Et vous leur avez montré votre sabbat sanctifié, et vous leur avez prescrit et des commandements et des cérémonies, et une loi, par l’entremise de Moïse, votre serviteur.
15 Ìwọ fún wọn ní oúnjẹ láti ọ̀run wá nígbà tí ebi ń pa wọ́n àti nígbà òǹgbẹ, o fún wọn ní omi láti inú àpáta; o sì sọ fún wọn pé, kí wọ́n lọ láti lọ gba ilẹ̀ náà tí ìwọ ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ láti fi fún wọn nípa ìgbọ́wọ́sókè.
Vous leur avez donné aussi un pain du ciel dans leur faim, et vous avez fait jaillir de l’eau d’une pierre pour eux, lorsqu’ils avaient soif; et vous leur avez dit qu’ils entreraient, pour la posséder, dans la terre sur laquelle vous avez levé la main, jurant que vous la leur donneriez.
16 “Ṣùgbọ́n àwọn, baba ńlá wa, wọ́n ṣe ìgbéraga, wọ́n sì ṣe agídí, wọn kò sì tẹríba fún àwọn ìlànà rẹ.
Mais eux et nos pères ont agi insolemment; ils ont rendu leur cou inflexible, et ils n’ont pas écouté vos commandements.
17 Wọ́n kọ̀ láti fetísílẹ̀, wọ́n sì kùnà láti rántí iṣẹ́ ìyanu tí ìwọ ṣe ní àárín wọn. Wọ́n ṣe agídí, nínú ìṣọ̀tẹ̀ wọn, wọ́n yan olórí láti padà sí oko ẹrú wọn. Ṣùgbọ́n ìwọ Ọlọ́run tí ó ń dáríjì, olóore-ọ̀fẹ́ àti aláàánú, ó lọ́ra láti bínú, ó sì pọ̀ ní ìfẹ́. Nítorí náà ìwọ kò sì kọ̀ wọ́n sílẹ̀,
Et ils n’ont pas voulu entendre, et ils ne se sont pas souvenus de vos merveilles que vous aviez faites pour eux; ils ont même rendu leur cou inflexible; et ils ont établi un chef, pour retourner à leur servitude comme par rébellion. Mais vous, Dieu propice, clément et miséricordieux, ayant de la longanimité et une abondante miséricorde, vous ne les avez point abandonnés,
18 nítòótọ́ nígbà tí wọ́n ṣe ẹgbọrọ màlúù dídá, tí wọ́n sì wí pé, ‘Èyí ni Ọlọ́run rẹ tí ó mú ọ gòkè láti Ejibiti wá; tàbí nígbà tí wọ́n sọ ọ̀rọ̀-òdì tí ó burú jàì’.
Lors même qu’ils se firent un veau jeté en fonte, et qu’ils dirent: C’est là votre Dieu qui vous a tirés de l’Egypte, et qu’ils firent de grands blasphèmes.
19 “Nítorí àánú ńlá rẹ, ìwọ kò kọ̀ wọ́n sílẹ̀ ní aginjù. Ní ọ̀sán ọ̀wọn ìkùùkuu kò kúrò ní ọ̀dọ̀ wọn láti ṣe amọ̀nà an wọn, tàbí ọ̀wọ́n iná láti tàn sí wọn ní òru ní ọ̀nà tí wọn yóò rìn.
Mais vous, dans vos miséricordes sans nombre, vous ne les avez point abandonnés dans le désert; la colonne de nuée ne se retira point d’eux pendant le jour pour les conduire dans leur voie, ni la colonne de feu pendant la nuit pour leur montrer le chemin par lequel ils devaient marcher.
20 Ìwọ fi ẹ̀mí rere rẹ fún wọn láti kọ́ wọn. Ìwọ kò dá manna rẹ dúró ní ẹnu wọn, ó sì fún wọn ní omi fún òǹgbẹ.
Et vous leur avez donné votre bon esprit pour les enseigner, vous n’avez pas retiré votre manne de leur bouche, et vous leur avez donné de l’eau dans leur soif.
21 Fún ogójì ọdún ni ìwọ fi bọ́ wọn ní aginjù; wọn kò ṣe aláìní ohunkóhun, aṣọ wọn kò gbó bẹ́ẹ̀ ni ẹsẹ̀ wọn kò wú.
Pendant quarante ans vous les avez nourris dans le désert, et rien ne leur a manqué: leurs vêtements ne vieillirent pas, et leurs pieds ne furent pas déchirés.
22 “Ìwọ fi àwọn ìjọba àti àwọn orílẹ̀-èdè fún wọn, ó sì fi gbogbo ilẹ̀ náà fún wọ́n. Wọ́n sì gba ilẹ̀ ọba Sihoni ará a Heṣboni àti ilẹ̀ Ogu ọba Baṣani.
Et vous leur avez donné des royaumes et des peuples, et vous leur avez distribué des lots, et ils possédèrent la terre de Séhon, et la terre du roi d’Hésébon, et la terre d’Og, roi de Basan.
23 Ìwọ ti mú àwọn ọmọ wọn pọ̀ bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, ó sì mú wọn wá sí ilẹ̀ tí o ti sọ fún àwọn baba wọn pé kí wọn wọ̀, kí wọn sì jogún un rẹ̀.
Et vous avez multiplié leurs fils comme les étoiles du ciel, et vous les avez conduits dans la terre dont vous aviez dit à leurs pères qu’ils y entreraient et la posséderaient.
24 Àwọn ọkùnrin wọn wọ inú rẹ̀, wọ́n sì gbà ilẹ̀ náà. Ìwọ sì tẹ orí àwọn ará a Kenaani, tí ń gbé inú ilẹ̀ náà ba níwájú wọn; ó fi àwọn ará a Kenaani lé wọn lọ́wọ́ pẹ̀lú àwọn ọba wọn àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà kí wọn ṣe wọn bí ó ti wù wọ́n.
Et les fils sont venus, et ils ont possédé la terre; et vous avez humilié devant eux les habitants de cette terre, les Chananéens, et vous les avez livrés en leur main, eux et leurs rois, et les peuples de cette terre, pour qu’ils leur fissent comme il leur plairait.
25 Wọ́n gba àwọn ìlú olódi àti ilẹ̀ ọlọ́ràá; wọ́n gba àwọn ilé tí ó kún fún onírúurú gbogbo nǹkan rere, àwọn kànga tí a ti gbẹ́, àwọn ọgbà àjàrà, àwọn ọgbà olifi àti àwọn igi eléso ní ọ̀pọ̀lọpọ̀. Wọ́n jẹ, wọ́n yó, wọ́n sì sanra dáradára; wọ́n sì yọ̀ nínú oore ńlá rẹ.
C’est pourquoi ils prirent des villes fortifiées et une terre fertile, et ils possédèrent des maisons pleines de toute sorte de biens, des citernes faites par d’autres, des vignes, des plants d’oliviers, et beaucoup d’arbres portant des fruits; et ils ont mangé et ils ont été rassasiés, et ils se sont engraissés, et ils ont abondé en délices par votre grande bonté.
26 “Ṣùgbọ́n wọ́n ṣe àìgbọ́ràn, wọ́n sì ṣọ̀tẹ̀ sí ọ; wọ́n gbàgbé òfin rẹ. Wọ́n pa àwọn wòlíì rẹ, tí o fi gbà wọn ni ìyànjú pé kí wọn yí padà sí ọ; wọ́n sì se ọ̀rọ̀-òdì tí ó burú jàì.
Mais ils vous ont provoqué au courroux; ils se sont retirés de vous; ils ont rejeté votre loi derrière eux, tué vos prophètes qui les conjuraient de revenir à vous, et ils ont fait de grands blasphèmes.
27 Nítorí náà, ìwọ fi wọ́n lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́, àwọn tí ó ni wọ́n lára. Ṣùgbọ́n nígbà tí a ni wọ́n lára wọ́n kígbe sí ọ. Ìwọ gbọ́ wọn láti ọ̀run wá àti nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ àánú rẹ, ìwọ fún wọn ní olùgbàlà, tí ó gbà wọ́n lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn.
Et vous les avez livrés à la main de leurs ennemis, qui les ont opprimés. Et dans le temps de leur tribulation, ils ont crié vers vous, et vous les avez entendus du ciel; et, selon vos miséricordes sans nombre, vous leur avez donné des sauveurs pour les sauver de la main de leurs ennemis.
28 “Ṣùgbọ́n bí wọ́n bá ti wà nínú ìsinmi, wọn a sì túnṣe búburú lójú rẹ. Nígbà náà ni ìwọ kọ̀ wọ́n sílẹ̀ ṣọ́wọ́ àwọn ọ̀tá kí wọ́n lè jẹ ọba lórí wọn. Nígbà tí wọ́n bá sì tún kígbe sí ọ, ìwọ a gbọ́ láti ọ̀run wá, àti nínú àánú rẹ ni ìwọ gbà láti ìgbà dé ìgbà.
Et, lorsqu’ils ont été en repos, ils ont de nouveau fait le mal en votre présence; et vous les avez délaissés dans la main de leurs ennemis, qui s’en sont rendus maîtres; ils se sont ensuite tournés vers vous et ont crié vers vous, et vous les avez exaucés du ciel, et vous les avez délivrés dans vos miséricordes, en bien des temps divers.
29 “Ìwọ kìlọ̀ fún wọn láti padà sínú òfin rẹ, ṣùgbọ́n wọ́n hu ìwà ìgbéraga, wọ́n sì ṣe àìgbọ́ràn si àṣẹ rẹ. Wọ́n ṣẹ̀ sí ìlànà rẹ, nípa èyí tí ènìyàn yóò yè tí wọ́n bá pa wọ́n mọ́. Nínú agídí ọkàn wọ́n kọ ẹ̀yìn sí ọ, wọ́n jẹ́ olórí kunkun wọn kò sì fẹ́ gbọ́.
De plus, vous les avez pressés de venir à votre loi; mais ils ont agi insolemment; ils n’ont pas écouté vos commandements, et ils ont péché contre vos ordonnances dans lesquelles l’homme qui les pratiquera, trouvera la vie; mais ils ont tourné l’épaule en arrière; ils ont rendu leur cou inflexible, et n’ont pas écouté.
30 Fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún ni ìwọ fi ní sùúrù pẹ̀lú wọn. Nípa ẹ̀mí rẹ ni ìwọ kìlọ̀ fún wọn nípasẹ̀ àwọn wòlíì. Síbẹ̀ wọn kò fi etí sílẹ̀, nítorí náà ni ìwọ ṣe fi wọ́n lé àwọn aládùúgbò wọn lọ́wọ́.
Vous les avez attendus pendant bien des années, et vous les avez pressés par votre esprit, par l’entremise de vos prophètes; mais ils n’ont pas écouté, et vous les avez livrés en la main des peuples de la terre.
31 Ṣùgbọ́n nínú ọ̀pọ̀ àánú rẹ, ìwọ kò mú òpin bá wọn tàbí kọ̀ wọ́n sílẹ̀, nítorí ìwọ ni Ọlọ́run olóore-ọ̀fẹ́ àti aláàánú.
Mais, dans vos miséricordes innombrables, vous ne les avez point exterminés ni abandonnés, parce que vous êtes un Dieu de miséricorde et de clémence.
32 “Ǹjẹ́ nítorí náà, Ọlọ́run wa, Ọlọ́run tí ó tóbi, tí ó lágbára, tí ó sì ní ẹ̀rù, ẹni tí ó pa májẹ̀mú ìfẹ́ mọ́, má ṣe jẹ́ gbogbo ìnira yìí dàbí ohun kékeré ní ojú rẹ—ìnira tí ó ti wá sórí wa, sórí àwọn ọba wa àti àwọn olórí wa, sórí àwọn àlùfáà wa àti àwọn wòlíì, sórí àwọn baba wa àti sórí gbogbo ènìyàn rẹ̀, láti àwọn ọjọ́ àwọn ọba Asiria wá títí di òní.
Maintenant donc, notre Dieu, le grand, le fort, le terrible, qui gardez l’alliance et la miséricorde, ne détournez point de votre face tout le mal qui nous a accablés, nous, nos rois, nos princes, nos prêtres, nos prophètes, nos pères, et tout votre peuple, depuis les jours du roi d’Assur jusqu’à ce jour.
33 Ìwọ jẹ́ olódodo nínú ohun gbogbo tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí wa; ìwọ sì ti ṣe òtítọ́, nígbà tí a bá ṣe búburú.
Pour vous, vous êtes juste dans tout ce qui vous est venu sur nous; car vous avez accompli la vérité, mais nous, nous avons agi avec impiété.
34 Àwọn ọba wa, àwọn olórí wa, àwọn àlùfáà wa, àti àwọn baba wa kò tẹ̀lé òfin rẹ; wọn kò fetísílẹ̀ sí àṣẹ rẹ tàbí àwọn ìkìlọ̀ tí ìwọ fún wọn.
Nos rois, nos princes, nos prêtres et nos pères n’ont pas pratiqué votre loi, et n’ont pas écouté vos commandements et vos décrets que vous leur avez intimés.
35 Àní nígbà tí wọ́n wà nínú ìjọba wọn, tí wọ́n ń gbádùn oore ńlá tí ìwọ fi fún wọn, ní ilẹ̀ tí ó tóbi tí ó sì lọ́ràá, wọn kò sìn ọ́ tàbí padà kúrò nínú àwọn ọ̀nà búburú wọn.
Et même au milieu de leurs royaumes, et malgré la grande bonté que vous leur avez témoignée, et dans la terre très étendue et fertile que vous leur avez livrée, ils ne vous ont pas servi, et ils ne sont pas revenus de leurs inclinations très mauvaises.
36 “Ṣùgbọ́n wò ó, àwa jẹ́ ẹrú lónìí, àwa jẹ́ ẹrú ní ilẹ̀ tí ìwọ fún àwọn baba ńlá wa, nítorí kí wọn bá máa jẹ èso rẹ̀ àti ìre mìíràn tí ó mú jáde.
Voilà que nous-mêmes aujourd’hui nous sommes esclaves, ainsi que la terre que vous aviez donnée à vos pères, afin qu’ils en mangeassent le pain et qu’ils jouissent des biens qui sont en elles, et nous-mêmes, nous sommes esclaves dans cette terre.
37 Nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìkórè rẹ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ọba tí ó fi ṣe olórí wa. Wọ́n ń ṣe àkóso lórí wa àti lórí ẹran wa bí ó ti wù wọ́n, àwa sì wà nínú ìpọ́njú ńlá.
Et ses fruits se multiplient pour les rois que vous avez placés sur nous à cause de nos péchés, et ils dominent sur nos corps et sur nos bêtes, selon leur volonté, et nous sommes dans une grande tribulation.
38 “Nítorí gbogbo èyí, a ń ṣe àdéhùn tí ó fẹsẹ̀múlẹ̀, a sì kọ ọ́ sínú ìwé, àwọn olórí ọmọ Lefi àwọn àlùfáà sì fi èdìdì dì í.”
À cause donc de toutes ces choses, nous-mêmes nous faisons une alliance, nous l’écrivons, et nos princes, nos Lévites et nos prêtres la signent.