< Nehemiah 9 >

1 Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kan náà, àwọn ọmọ Israẹli péjọpọ̀, wọ́n gbààwẹ̀, wọ́n wọ aṣọ ọ̀fọ̀, wọ́n sì da eruku sórí ara wọn.
Or, le vingt-quatrième jour de ce mois, les enfants d'Israël s'assemblèrent en jeûnant, avec des sacs et des souillures sur eux.
2 Àwọn ọkùnrin Israẹli sì ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò nínú gbogbo àwọn àjèjì. Wọ́n dúró ní ààyè e wọn, wọ́n sì ń jẹ́wọ́ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ ẹ wọn àti iṣẹ́ búburú àwọn baba wọn.
Les descendants d'Israël se séparèrent de tous les étrangers et se tinrent debout pour confesser leurs péchés et les iniquités de leurs pères.
3 Wọ́n dúró sí ibi tí wọ́n wà, wọ́n sì fi ìdámẹ́rin ọjọ́ kà nínú ìwé òfin Olúwa Ọlọ́run wọn, wọ́n sì tún fi ìdámẹ́rin mìíràn ní ìjẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àti ní sí sin Olúwa Ọlọ́run wọn.
Ils se tinrent debout à leur place, et ils lurent dans le livre de la loi de l'Éternel, leur Dieu, un quart du jour; et un quart du jour, ils confessèrent et adorèrent l'Éternel, leur Dieu.
4 Nígbà náà ni Jeṣua, àti Bani, Kadmieli, Ṣebaniah, Bunni, Ṣerebiah, Bani àti Kenaani gòkè dúró lórí àwọn àtẹ̀gùn àwọn ọmọ Lefi, wọ́n sì fi ohùn rara kígbe sí Olúwa Ọlọ́run wọn.
Alors Jeshua, Bani, Kadmiel, Shebania, Bunni, Sherebia, Bani et Chenani, d'entre les Lévites, se levèrent sur l'escalier et crièrent d'une voix forte à l'Éternel, leur Dieu.
5 Nígbà náà ni àwọn ọmọ Lefi: Jeṣua, Kadmieli, Bani, Haṣbneiah, Ṣerebiah, Hodiah, Ṣebaniah àti Petahiah—wí pé, “Ẹ dìde ẹ fi ìyìn fún Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó wà láé àti láéláé.” “Ìbùkún ni fún orúkọ rẹ tí ó ní ògo, kí ó sì di gbígbéga ju gbogbo ìbùkún àti ìyìn lọ.
Alors les Lévites, Josué, Kadmiel, Bani, Haschabnéia, Shérébia, Hodia, Shebania et Pethahia, dirent: « Lève-toi et bénis Yahvé ton Dieu, d'éternité en éternité! Béni soit ton nom glorieux, qui s'élève au-dessus de toute bénédiction et de toute louange!
6 Ìwọ nìkan ni Olúwa. Ìwọ ni ó dá ọ̀run, àní àwọn ọ̀run tí ó ga jù pẹ̀lú gbogbo ogun wọn, ayé àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀, òkun, àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀. Ìwọ sì pa gbogbo wọn mọ́ láàyè, ogun ọ̀run sì ń sìn ọ́.
Tu es Yahvé, toi seul. Tu as fait les cieux, le ciel des cieux, avec toute leur armée, la terre et tout ce qui est sur elle, les mers et tout ce qui est en elles, et tu les préserves toutes. L'armée des cieux te vénère.
7 “Ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run, tí ó yan Abramu tí ó sì mú u jáde láti Uri ti Kaldea, tí ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Abrahamu.
Tu es Yahvé, le Dieu qui a choisi Abram, l'a fait sortir d'Ur des Chaldéens, lui a donné le nom d'Abraham,
8 Ìwọ sì rí í pé ọkàn rẹ̀ jẹ́ olóòtítọ́ sí ọ, ìwọ sì dá májẹ̀mú pẹ̀lú u rẹ̀ láti fi ilẹ̀ àwọn ará a Kenaani, Hiti, Amori, Peresi, Jebusi àti Girgaṣi fún irú àwọn ọmọ rẹ̀. Ìwọ ti pa ìpinnu rẹ̀ mọ́ nítorí tí ìwọ jẹ́ olódodo.
a trouvé son cœur fidèle devant toi, et a fait alliance avec lui pour donner le pays des Cananéens, des Héthiens, des Amoréens, des Phéréziens, des Jébusiens et des Guirgasiens, pour le donner à sa postérité, et tu as accompli tes paroles, car tu es juste.
9 “Ìwọ rí ìpọ́njú àwọn baba ńlá wa ní Ejibiti; ìwọ gbọ́ igbe ẹkún wọn ní Òkun Pupa.
« Tu as vu l'affliction de nos pères en Égypte, et tu as entendu leurs cris au bord de la mer Rouge,
10 Ìwọ rán iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu sí Farao, sí gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀ àti sí gbogbo ènìyàn ilẹ̀ ẹ rẹ̀, nítorí ìwọ mọ ìwà ìgbéraga tí àwọn ará Ejibiti hù sí wọn. Ìwọ ra orúkọ fún ara à rẹ, èyí tí ó sì wà títí di òní yìí.
et tu as fait des signes et des prodiges contre Pharaon, contre tous ses serviteurs et contre tout le peuple de son pays, car tu savais qu'ils s'enorgueillissaient d'eux, et tu t'es fait un nom, comme il en est aujourd'hui.
11 Ìwọ pín òkun níwájú wọn, nítorí kí wọn lè kọjá ní ìyàngbẹ ilẹ̀, ṣùgbọ́n ìwọ sọ àwọn tí ń lépa wọn sínú ibú, bí òkúta sínú omi ńlá.
Tu as fendu la mer devant eux, et ils ont traversé le milieu de la mer sur la terre ferme; tu as jeté leurs poursuivants dans les profondeurs, comme une pierre dans les grandes eaux.
12 Ní ọ̀sán ìwọ darí i wọn pẹ̀lú ọ̀wọn àwọsánmọ̀ àti ní òru ni ìwọ darí i wọn pẹ̀lú ọ̀wọn iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ ní ọ̀nà tí wọn yóò gbà.
Tu les conduisais de jour dans une colonne de nuée, et de nuit dans une colonne de feu, pour les éclairer dans la voie qu'ils devaient suivre.
13 “Ìwọ sọ̀kalẹ̀ wá sí orí òkè Sinai; ìwọ bá wọn sọ̀rọ̀ láti ọ̀run. Ìwọ fún wọn ní ìlànà àti àwọn òfin tí ó jẹ́ òdodo tí ó sì tọ́ àti ìlànà tí ó dára.
« Toi aussi, tu es descendu sur la montagne de Sinaï, tu leur as parlé du haut des cieux, tu leur as donné des ordonnances justes et des lois véritables, des statuts et des commandements bons,
14 Ìwọ mú ọjọ́ ìsinmi rẹ mímọ́ di mí mọ̀ fún wọn, o sì fún wọn ní àwọn ìlànà, àwọn àṣẹ àti àwọn òfin láti ọwọ́ Mose ìránṣẹ́ rẹ.
tu leur as fait connaître ton saint sabbat, et tu leur as prescrit des commandements, des statuts et une loi, par Moïse, ton serviteur,
15 Ìwọ fún wọn ní oúnjẹ láti ọ̀run wá nígbà tí ebi ń pa wọ́n àti nígbà òǹgbẹ, o fún wọn ní omi láti inú àpáta; o sì sọ fún wọn pé, kí wọ́n lọ láti lọ gba ilẹ̀ náà tí ìwọ ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ láti fi fún wọn nípa ìgbọ́wọ́sókè.
tu leur as donné du pain du ciel pour leur faim, tu as fait sortir de l'eau du rocher pour leur soif, et tu leur as ordonné d'entrer en possession du pays que tu avais juré de leur donner.
16 “Ṣùgbọ́n àwọn, baba ńlá wa, wọ́n ṣe ìgbéraga, wọ́n sì ṣe agídí, wọn kò sì tẹríba fún àwọn ìlànà rẹ.
« Mais eux et nos pères se sont conduits avec orgueil, ont endurci leur cou, n'ont pas écouté tes commandements,
17 Wọ́n kọ̀ láti fetísílẹ̀, wọ́n sì kùnà láti rántí iṣẹ́ ìyanu tí ìwọ ṣe ní àárín wọn. Wọ́n ṣe agídí, nínú ìṣọ̀tẹ̀ wọn, wọ́n yan olórí láti padà sí oko ẹrú wọn. Ṣùgbọ́n ìwọ Ọlọ́run tí ó ń dáríjì, olóore-ọ̀fẹ́ àti aláàánú, ó lọ́ra láti bínú, ó sì pọ̀ ní ìfẹ́. Nítorí náà ìwọ kò sì kọ̀ wọ́n sílẹ̀,
et ont refusé d'obéir. Ils ne se sont pas souvenus des merveilles que tu as accomplies au milieu d'eux, mais ils ont endurci leur cou et, dans leur rébellion, ils ont nommé un chef pour retourner dans leur servitude. Mais toi, tu es un Dieu prêt à pardonner, compatissant et miséricordieux, lent à la colère et riche en bonté, et tu ne les as pas abandonnés.
18 nítòótọ́ nígbà tí wọ́n ṣe ẹgbọrọ màlúù dídá, tí wọ́n sì wí pé, ‘Èyí ni Ọlọ́run rẹ tí ó mú ọ gòkè láti Ejibiti wá; tàbí nígbà tí wọ́n sọ ọ̀rọ̀-òdì tí ó burú jàì’.
Ils se sont fait un veau en bois, ils ont dit: « Voici ton Dieu, qui t'a fait monter d'Égypte », et ils ont commis d'affreux blasphèmes.
19 “Nítorí àánú ńlá rẹ, ìwọ kò kọ̀ wọ́n sílẹ̀ ní aginjù. Ní ọ̀sán ọ̀wọn ìkùùkuu kò kúrò ní ọ̀dọ̀ wọn láti ṣe amọ̀nà an wọn, tàbí ọ̀wọ́n iná láti tàn sí wọn ní òru ní ọ̀nà tí wọn yóò rìn.
Mais toi, dans ta grande bonté, tu ne les as pas abandonnés au désert. La colonne de nuée ne s'est pas éloignée d'eux pendant le jour, pour les conduire dans le chemin, ni la colonne de feu pendant la nuit, pour leur montrer la lumière et le chemin qu'ils devaient suivre.
20 Ìwọ fi ẹ̀mí rere rẹ fún wọn láti kọ́ wọn. Ìwọ kò dá manna rẹ dúró ní ẹnu wọn, ó sì fún wọn ní omi fún òǹgbẹ.
Tu as aussi donné ton bon Esprit pour les instruire, tu n'as pas retenu ta manne de leur bouche, et tu leur as donné de l'eau pour leur soif.
21 Fún ogójì ọdún ni ìwọ fi bọ́ wọn ní aginjù; wọn kò ṣe aláìní ohunkóhun, aṣọ wọn kò gbó bẹ́ẹ̀ ni ẹsẹ̀ wọn kò wú.
« Oui, pendant quarante ans, tu les as fait vivre dans le désert. Ils n'ont manqué de rien. Leurs vêtements n'ont pas vieilli, et leurs pieds n'ont pas enflé.
22 “Ìwọ fi àwọn ìjọba àti àwọn orílẹ̀-èdè fún wọn, ó sì fi gbogbo ilẹ̀ náà fún wọ́n. Wọ́n sì gba ilẹ̀ ọba Sihoni ará a Heṣboni àti ilẹ̀ Ogu ọba Baṣani.
Tu leur as donné des royaumes et des peuples, que tu leur as attribués selon leurs parts. Ils possédèrent le pays de Sihon, le pays du roi de Heshbon, et le pays d'Og, roi de Basan.
23 Ìwọ ti mú àwọn ọmọ wọn pọ̀ bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, ó sì mú wọn wá sí ilẹ̀ tí o ti sọ fún àwọn baba wọn pé kí wọn wọ̀, kí wọn sì jogún un rẹ̀.
Tu as aussi multiplié leurs enfants comme les étoiles du ciel, et tu les as fait entrer dans le pays dont tu avais dit à leurs pères qu'ils entreraient en possession.
24 Àwọn ọkùnrin wọn wọ inú rẹ̀, wọ́n sì gbà ilẹ̀ náà. Ìwọ sì tẹ orí àwọn ará a Kenaani, tí ń gbé inú ilẹ̀ náà ba níwájú wọn; ó fi àwọn ará a Kenaani lé wọn lọ́wọ́ pẹ̀lú àwọn ọba wọn àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà kí wọn ṣe wọn bí ó ti wù wọ́n.
« Les enfants entrèrent et prirent possession du pays; vous soumîtes devant eux les habitants du pays, les Cananéens, et vous les livrâtes entre leurs mains, avec leurs rois et les peuples du pays, pour qu'ils en fassent ce qu'ils voulaient.
25 Wọ́n gba àwọn ìlú olódi àti ilẹ̀ ọlọ́ràá; wọ́n gba àwọn ilé tí ó kún fún onírúurú gbogbo nǹkan rere, àwọn kànga tí a ti gbẹ́, àwọn ọgbà àjàrà, àwọn ọgbà olifi àti àwọn igi eléso ní ọ̀pọ̀lọpọ̀. Wọ́n jẹ, wọ́n yó, wọ́n sì sanra dáradára; wọ́n sì yọ̀ nínú oore ńlá rẹ.
Ils prirent des villes fortifiées et un pays riche, et possédèrent des maisons remplies de toutes sortes de biens, des citernes creusées, des vignes, des oliviers et des arbres fruitiers en abondance. Ils mangèrent, se rassasièrent, s'engraissèrent et se réjouirent de ta grande bonté.
26 “Ṣùgbọ́n wọ́n ṣe àìgbọ́ràn, wọ́n sì ṣọ̀tẹ̀ sí ọ; wọ́n gbàgbé òfin rẹ. Wọ́n pa àwọn wòlíì rẹ, tí o fi gbà wọn ni ìyànjú pé kí wọn yí padà sí ọ; wọ́n sì se ọ̀rọ̀-òdì tí ó burú jàì.
Cependant, ils ont été désobéissants et se sont révoltés contre toi, ils ont rejeté ta loi derrière leur dos, ils ont tué tes prophètes qui témoignaient contre eux pour les ramener à toi, et ils ont commis d'affreux blasphèmes.
27 Nítorí náà, ìwọ fi wọ́n lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́, àwọn tí ó ni wọ́n lára. Ṣùgbọ́n nígbà tí a ni wọ́n lára wọ́n kígbe sí ọ. Ìwọ gbọ́ wọn láti ọ̀run wá àti nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ àánú rẹ, ìwọ fún wọn ní olùgbàlà, tí ó gbà wọ́n lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn.
C'est pourquoi tu les as livrés entre les mains de leurs adversaires, qui les ont affligés. Au temps de leur détresse, quand ils criaient vers toi, tu as entendu du ciel; et selon tes multiples miséricordes, tu leur as donné des sauveurs qui les ont sauvés de la main de leurs adversaires.
28 “Ṣùgbọ́n bí wọ́n bá ti wà nínú ìsinmi, wọn a sì túnṣe búburú lójú rẹ. Nígbà náà ni ìwọ kọ̀ wọ́n sílẹ̀ ṣọ́wọ́ àwọn ọ̀tá kí wọ́n lè jẹ ọba lórí wọn. Nígbà tí wọ́n bá sì tún kígbe sí ọ, ìwọ a gbọ́ láti ọ̀run wá, àti nínú àánú rẹ ni ìwọ gbà láti ìgbà dé ìgbà.
Mais après leur repos, ils ont recommencé à faire le mal devant toi; tu les as donc laissés entre les mains de leurs ennemis, qui ont dominé sur eux; mais quand ils sont revenus et ont crié vers toi, tu as entendu du ciel; et plusieurs fois tu les as délivrés selon tes miséricordes,
29 “Ìwọ kìlọ̀ fún wọn láti padà sínú òfin rẹ, ṣùgbọ́n wọ́n hu ìwà ìgbéraga, wọ́n sì ṣe àìgbọ́ràn si àṣẹ rẹ. Wọ́n ṣẹ̀ sí ìlànà rẹ, nípa èyí tí ènìyàn yóò yè tí wọ́n bá pa wọ́n mọ́. Nínú agídí ọkàn wọ́n kọ ẹ̀yìn sí ọ, wọ́n jẹ́ olórí kunkun wọn kò sì fẹ́ gbọ́.
et tu as témoigné contre eux, afin de les ramener à ta loi. Mais ils se sont montrés arrogants, ils n'ont pas écouté tes commandements, ils ont péché contre tes ordonnances (que l'homme doit vivre en les pratiquant), ils ont tourné le dos, ils ont raidi leur cou, ils n'ont pas voulu entendre.
30 Fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún ni ìwọ fi ní sùúrù pẹ̀lú wọn. Nípa ẹ̀mí rẹ ni ìwọ kìlọ̀ fún wọn nípasẹ̀ àwọn wòlíì. Síbẹ̀ wọn kò fi etí sílẹ̀, nítorí náà ni ìwọ ṣe fi wọ́n lé àwọn aládùúgbò wọn lọ́wọ́.
Tu les as supportés pendant de longues années, et tu as témoigné contre eux par ton Esprit, par tes prophètes. Mais ils n'ont pas voulu écouter. C'est pourquoi tu les as livrés entre les mains des peuples de ces pays.
31 Ṣùgbọ́n nínú ọ̀pọ̀ àánú rẹ, ìwọ kò mú òpin bá wọn tàbí kọ̀ wọ́n sílẹ̀, nítorí ìwọ ni Ọlọ́run olóore-ọ̀fẹ́ àti aláàánú.
« Cependant, dans tes multiples miséricordes, tu n'as pas mis fin à leur existence et tu ne les as pas abandonnés, car tu es un Dieu plein de bonté et de miséricorde.
32 “Ǹjẹ́ nítorí náà, Ọlọ́run wa, Ọlọ́run tí ó tóbi, tí ó lágbára, tí ó sì ní ẹ̀rù, ẹni tí ó pa májẹ̀mú ìfẹ́ mọ́, má ṣe jẹ́ gbogbo ìnira yìí dàbí ohun kékeré ní ojú rẹ—ìnira tí ó ti wá sórí wa, sórí àwọn ọba wa àti àwọn olórí wa, sórí àwọn àlùfáà wa àti àwọn wòlíì, sórí àwọn baba wa àti sórí gbogbo ènìyàn rẹ̀, láti àwọn ọjọ́ àwọn ọba Asiria wá títí di òní.
Maintenant, notre Dieu, le Dieu grand, puissant et redoutable, qui garde l'alliance et la bonté, ne laisse pas paraître devant toi toutes les souffrances qui nous ont frappés, nos rois, nos princes, nos prêtres, nos prophètes, nos pères, et tout ton peuple, depuis le temps des rois d'Assyrie jusqu'à ce jour.
33 Ìwọ jẹ́ olódodo nínú ohun gbogbo tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí wa; ìwọ sì ti ṣe òtítọ́, nígbà tí a bá ṣe búburú.
Mais tu es juste dans tout ce qui nous est arrivé, car tu as agi avec justice, et nous avons agi avec méchanceté.
34 Àwọn ọba wa, àwọn olórí wa, àwọn àlùfáà wa, àti àwọn baba wa kò tẹ̀lé òfin rẹ; wọn kò fetísílẹ̀ sí àṣẹ rẹ tàbí àwọn ìkìlọ̀ tí ìwọ fún wọn.
Nos rois, nos princes, nos prêtres et nos pères n'ont pas gardé ta loi, et n'ont pas écouté tes commandements et tes témoignages, par lesquels tu leur rendais témoignage.
35 Àní nígbà tí wọ́n wà nínú ìjọba wọn, tí wọ́n ń gbádùn oore ńlá tí ìwọ fi fún wọn, ní ilẹ̀ tí ó tóbi tí ó sì lọ́ràá, wọn kò sìn ọ́ tàbí padà kúrò nínú àwọn ọ̀nà búburú wọn.
Car ils ne t'ont pas servi dans leur royaume, dans la grande bonté que tu leur as accordée, et dans le pays vaste et riche que tu as donné devant eux. Ils ne se sont pas détournés de leurs œuvres mauvaises.
36 “Ṣùgbọ́n wò ó, àwa jẹ́ ẹrú lónìí, àwa jẹ́ ẹrú ní ilẹ̀ tí ìwọ fún àwọn baba ńlá wa, nítorí kí wọn bá máa jẹ èso rẹ̀ àti ìre mìíràn tí ó mú jáde.
« Voici, nous sommes aujourd'hui des serviteurs, et quant au pays que tu as donné à nos pères pour qu'ils mangent de ses fruits et de ses biens, voici, nous y sommes des serviteurs.
37 Nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìkórè rẹ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ọba tí ó fi ṣe olórí wa. Wọ́n ń ṣe àkóso lórí wa àti lórí ẹran wa bí ó ti wù wọ́n, àwa sì wà nínú ìpọ́njú ńlá.
Elle donne beaucoup de produits aux rois que tu as établis sur nous à cause de nos péchés. Ils ont aussi le pouvoir sur nos corps et sur notre bétail, selon leur bon plaisir, et nous sommes dans une grande détresse.
38 “Nítorí gbogbo èyí, a ń ṣe àdéhùn tí ó fẹsẹ̀múlẹ̀, a sì kọ ọ́ sínú ìwé, àwọn olórí ọmọ Lefi àwọn àlùfáà sì fi èdìdì dì í.”
Mais pour tout cela, nous faisons une alliance sûre, nous l'écrivons, et nos chefs, nos lévites et nos prêtres la scellent. »

< Nehemiah 9 >