< Nehemiah 9 >

1 Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kan náà, àwọn ọmọ Israẹli péjọpọ̀, wọ́n gbààwẹ̀, wọ́n wọ aṣọ ọ̀fọ̀, wọ́n sì da eruku sórí ara wọn.
Forsothe in the foure and twentithe dai of this monethe, the sones of Israel camen togidere in fastyng,
2 Àwọn ọkùnrin Israẹli sì ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò nínú gbogbo àwọn àjèjì. Wọ́n dúró ní ààyè e wọn, wọ́n sì ń jẹ́wọ́ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ ẹ wọn àti iṣẹ́ búburú àwọn baba wọn.
and in sackis, and `erthe was on hem. And the seed of the sones of Israel was departid fro ech alien sone. And thei stoden bifor the Lord, and knoulechiden her synnes, and the wickidnessis of her fadris.
3 Wọ́n dúró sí ibi tí wọ́n wà, wọ́n sì fi ìdámẹ́rin ọjọ́ kà nínú ìwé òfin Olúwa Ọlọ́run wọn, wọ́n sì tún fi ìdámẹ́rin mìíràn ní ìjẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àti ní sí sin Olúwa Ọlọ́run wọn.
And thei risiden togidere to stonde; and thei redden in the book of the lawe of `her Lord God fouresithis in the dai, and fouresithis in the niyt; thei knoulechiden, and herieden `her Lord God.
4 Nígbà náà ni Jeṣua, àti Bani, Kadmieli, Ṣebaniah, Bunni, Ṣerebiah, Bani àti Kenaani gòkè dúró lórí àwọn àtẹ̀gùn àwọn ọmọ Lefi, wọ́n sì fi ohùn rara kígbe sí Olúwa Ọlọ́run wọn.
Forsothe `thei risiden on the degree, of dekenes, Jesuy, and Bany, Cedynyel, Remmy, Abany, Sarabie, Bany, and Chanany.
5 Nígbà náà ni àwọn ọmọ Lefi: Jeṣua, Kadmieli, Bani, Haṣbneiah, Ṣerebiah, Hodiah, Ṣebaniah àti Petahiah—wí pé, “Ẹ dìde ẹ fi ìyìn fún Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó wà láé àti láéláé.” “Ìbùkún ni fún orúkọ rẹ tí ó ní ògo, kí ó sì di gbígbéga ju gbogbo ìbùkún àti ìyìn lọ.
And the dekenes crieden with grete vois to her Lord God. And Jesue, and Cedyniel, Bonny, Assebie, Serebie, Arabie, Odaie, Sebua, and Facaia, seiden, Rise ye, and blesse ye `youre Lord God fro without bigynnyng and til in to with outen ende; and blesse thei the hiye name of thi glorie in al blessyng and preysyng.
6 Ìwọ nìkan ni Olúwa. Ìwọ ni ó dá ọ̀run, àní àwọn ọ̀run tí ó ga jù pẹ̀lú gbogbo ogun wọn, ayé àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀, òkun, àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀. Ìwọ sì pa gbogbo wọn mọ́ láàyè, ogun ọ̀run sì ń sìn ọ́.
And Esdras seide, Thou thi silf, Lord, art aloone; thou madist heuene and the heuene of heuenes, and al the oost of tho heuenes; thou madist the erthe and alle thingis that ben there ynne; `thou madist the sees and alle thingis that ben in tho; and thou quikenyst alle these thingis; and the oost of heuene worschipith thee.
7 “Ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run, tí ó yan Abramu tí ó sì mú u jáde láti Uri ti Kaldea, tí ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Abrahamu.
Thou thi silf art the Lord God, that chesidist Abram, and leddist hym out of the fier of Caldeis, and settidist his name Abraham;
8 Ìwọ sì rí í pé ọkàn rẹ̀ jẹ́ olóòtítọ́ sí ọ, ìwọ sì dá májẹ̀mú pẹ̀lú u rẹ̀ láti fi ilẹ̀ àwọn ará a Kenaani, Hiti, Amori, Peresi, Jebusi àti Girgaṣi fún irú àwọn ọmọ rẹ̀. Ìwọ ti pa ìpinnu rẹ̀ mọ́ nítorí tí ìwọ jẹ́ olódodo.
and foundist his herte feithful bifor thee, and thou hast smyte with hym a boond of pees, that thou woldist yyue to hym the lond of Cananei, of Ethei, of Euey, and of Ammorrei, and of Pherezei, and of Jebuzei, and of Gergesei, that thou woldist yyue it to his seed; and thou hast fillid thi wordis, for thou art iust.
9 “Ìwọ rí ìpọ́njú àwọn baba ńlá wa ní Ejibiti; ìwọ gbọ́ igbe ẹkún wọn ní Òkun Pupa.
And thou hast seyn the turment of oure fadris in Egipt, and thou herdist the cry of hem on the reed see.
10 Ìwọ rán iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu sí Farao, sí gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀ àti sí gbogbo ènìyàn ilẹ̀ ẹ rẹ̀, nítorí ìwọ mọ ìwà ìgbéraga tí àwọn ará Ejibiti hù sí wọn. Ìwọ ra orúkọ fún ara à rẹ, èyí tí ó sì wà títí di òní yìí.
And thou hast youe signes and grete wondris in Farao, and in alle hise seruauntis, and in al the puple of that lond; for thou knowist, that thei diden proudli ayens oure fadris; and thou madist to thee a name, as also in this dai.
11 Ìwọ pín òkun níwájú wọn, nítorí kí wọn lè kọjá ní ìyàngbẹ ilẹ̀, ṣùgbọ́n ìwọ sọ àwọn tí ń lépa wọn sínú ibú, bí òkúta sínú omi ńlá.
And thou departidist the see bifor hem, and thei passiden thorou the `myddis of the see in the drie place; forsothe thou castidist doun the pursueris of hem into depthe, as a stoon in strong watris.
12 Ní ọ̀sán ìwọ darí i wọn pẹ̀lú ọ̀wọn àwọsánmọ̀ àti ní òru ni ìwọ darí i wọn pẹ̀lú ọ̀wọn iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ ní ọ̀nà tí wọn yóò gbà.
And in a piler of cloude thou were the ledere of hem bi dai, and in a piler of fier bi nyyt, that the weie, bi which thei entriden, schulde appere to hem.
13 “Ìwọ sọ̀kalẹ̀ wá sí orí òkè Sinai; ìwọ bá wọn sọ̀rọ̀ láti ọ̀run. Ìwọ fún wọn ní ìlànà àti àwọn òfin tí ó jẹ́ òdodo tí ó sì tọ́ àti ìlànà tí ó dára.
Also thou camest doun at the hil of Synai, and spakist with hem fro heuene, and thou yauest to hem riytful domes, and the lawe of trewthe, cerymonyes, and goode comaundementis.
14 Ìwọ mú ọjọ́ ìsinmi rẹ mímọ́ di mí mọ̀ fún wọn, o sì fún wọn ní àwọn ìlànà, àwọn àṣẹ àti àwọn òfin láti ọwọ́ Mose ìránṣẹ́ rẹ.
And thou schewidist to hem an halewid sabat; and thou comaundidist `to hem comaundementis, and cerymonyes, and lawe, in the hond of Moises, thi seruaunt.
15 Ìwọ fún wọn ní oúnjẹ láti ọ̀run wá nígbà tí ebi ń pa wọ́n àti nígbà òǹgbẹ, o fún wọn ní omi láti inú àpáta; o sì sọ fún wọn pé, kí wọ́n lọ láti lọ gba ilẹ̀ náà tí ìwọ ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ láti fi fún wọn nípa ìgbọ́wọ́sókè.
Also thou yauest to hem breed fro heuene in her hungur; and thou leddist out of the stoon watir to hem thirstinge; and thou seidist to hem, that thei schulden entre, and haue in possessioun the lond, on which lond thou reisidist thin hond, that thou schuldist yyue it to hem.
16 “Ṣùgbọ́n àwọn, baba ńlá wa, wọ́n ṣe ìgbéraga, wọ́n sì ṣe agídí, wọn kò sì tẹríba fún àwọn ìlànà rẹ.
But `thei and oure fadris diden proudli, and maden hard her nollis, and herden not thi comaundementis.
17 Wọ́n kọ̀ láti fetísílẹ̀, wọ́n sì kùnà láti rántí iṣẹ́ ìyanu tí ìwọ ṣe ní àárín wọn. Wọ́n ṣe agídí, nínú ìṣọ̀tẹ̀ wọn, wọ́n yan olórí láti padà sí oko ẹrú wọn. Ṣùgbọ́n ìwọ Ọlọ́run tí ó ń dáríjì, olóore-ọ̀fẹ́ àti aláàánú, ó lọ́ra láti bínú, ó sì pọ̀ ní ìfẹ́. Nítorí náà ìwọ kò sì kọ̀ wọ́n sílẹ̀,
And thei nolden here; and thei hadden not mynde of thi merueils, which thou haddist do to hem; and thei maden hard her nollis; and thei yauen the heed, that thei `weren al turned to her seruage as bi strijf; but thou art God helpful, meke, and merciful, abidynge longe, `ether pacient, and of myche merciful doyng, and forsokist not hem;
18 nítòótọ́ nígbà tí wọ́n ṣe ẹgbọrọ màlúù dídá, tí wọ́n sì wí pé, ‘Èyí ni Ọlọ́run rẹ tí ó mú ọ gòkè láti Ejibiti wá; tàbí nígbà tí wọ́n sọ ọ̀rọ̀-òdì tí ó burú jàì’.
and sotheli whanne thei hadden maad to hem a yotun calf, as bi strijf, and hadden seid, This is thi God, that `ledde thee out of Egipt, and thei diden grete blasfemyes.
19 “Nítorí àánú ńlá rẹ, ìwọ kò kọ̀ wọ́n sílẹ̀ ní aginjù. Ní ọ̀sán ọ̀wọn ìkùùkuu kò kúrò ní ọ̀dọ̀ wọn láti ṣe amọ̀nà an wọn, tàbí ọ̀wọ́n iná láti tàn sí wọn ní òru ní ọ̀nà tí wọn yóò rìn.
But thou in thi many mercyes leftist not hem in deseert; for a piler of cloude yede not awei fro hem bi the dai, that it schulde lede hem in to the weie; and a piler of fier yede not awei `fro hem bi nyyt, that it schulde schewe to hem the weie, bi which thei schulden entre.
20 Ìwọ fi ẹ̀mí rere rẹ fún wọn láti kọ́ wọn. Ìwọ kò dá manna rẹ dúró ní ẹnu wọn, ó sì fún wọn ní omi fún òǹgbẹ.
And thou yauest to hem thi good Spirit, that tauyte hem; and thou forbedist not thin aungels mete fro her mouth, and thou yauest to hem water in thirst.
21 Fún ogójì ọdún ni ìwọ fi bọ́ wọn ní aginjù; wọn kò ṣe aláìní ohunkóhun, aṣọ wọn kò gbó bẹ́ẹ̀ ni ẹsẹ̀ wọn kò wú.
Fourti yeer thou feddist hem in deseert, and no thing failide to hem; her clothis wexiden not elde, and her feet weren not hirt.
22 “Ìwọ fi àwọn ìjọba àti àwọn orílẹ̀-èdè fún wọn, ó sì fi gbogbo ilẹ̀ náà fún wọ́n. Wọ́n sì gba ilẹ̀ ọba Sihoni ará a Heṣboni àti ilẹ̀ Ogu ọba Baṣani.
And thou yauest to hem rewmes, and puplis; and thou departidist lottis, `ether eritagis, to hem, and thei hadden in possessioun the lond of Seon, and the lond of the kyng of Esebon, and the lond of Og, kyng of Basan.
23 Ìwọ ti mú àwọn ọmọ wọn pọ̀ bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, ó sì mú wọn wá sí ilẹ̀ tí o ti sọ fún àwọn baba wọn pé kí wọn wọ̀, kí wọn sì jogún un rẹ̀.
And thou multipliedist the sones of hem, as the sterris of heuene; and thou brouytist hem to the lond, of which thou seidist to her fadris, that thei schulden entre, and holde it in possessioun.
24 Àwọn ọkùnrin wọn wọ inú rẹ̀, wọ́n sì gbà ilẹ̀ náà. Ìwọ sì tẹ orí àwọn ará a Kenaani, tí ń gbé inú ilẹ̀ náà ba níwájú wọn; ó fi àwọn ará a Kenaani lé wọn lọ́wọ́ pẹ̀lú àwọn ọba wọn àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà kí wọn ṣe wọn bí ó ti wù wọ́n.
And the sones of Israel camen, and hadden the lond in possessioun; and bifor hem thou madist low the dwellers of the lond, Cananeis; and thou yauest hem in to the hondis of the sones of Israel, and the kyngis of hem, and the puplis of the lond, that thei diden to hem, as it pleside hem.
25 Wọ́n gba àwọn ìlú olódi àti ilẹ̀ ọlọ́ràá; wọ́n gba àwọn ilé tí ó kún fún onírúurú gbogbo nǹkan rere, àwọn kànga tí a ti gbẹ́, àwọn ọgbà àjàrà, àwọn ọgbà olifi àti àwọn igi eléso ní ọ̀pọ̀lọpọ̀. Wọ́n jẹ, wọ́n yó, wọ́n sì sanra dáradára; wọ́n sì yọ̀ nínú oore ńlá rẹ.
And thei token citees maad strong, and fat erthe; and thei hadden in possessioun housis fulle of alle goodis, cisternes maad of othere men, vineris, and places of olyues, and many apple trees. And thei eeten, and weren fillid, and weren maad fat; and hadden plentee of ritchessis `in thi greet goodnesse.
26 “Ṣùgbọ́n wọ́n ṣe àìgbọ́ràn, wọ́n sì ṣọ̀tẹ̀ sí ọ; wọ́n gbàgbé òfin rẹ. Wọ́n pa àwọn wòlíì rẹ, tí o fi gbà wọn ni ìyànjú pé kí wọn yí padà sí ọ; wọ́n sì se ọ̀rọ̀-òdì tí ó burú jàì.
Sotheli thei terriden thee to wrathfulnesse, and yeden awei fro thee, and castiden awei thi lawe bihynde her backis; and thei killiden thi prophetis, that witnessiden to hem, that thei schulden turne ayen to thee; and thei diden grete blasfemyes.
27 Nítorí náà, ìwọ fi wọ́n lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́, àwọn tí ó ni wọ́n lára. Ṣùgbọ́n nígbà tí a ni wọ́n lára wọ́n kígbe sí ọ. Ìwọ gbọ́ wọn láti ọ̀run wá àti nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ àánú rẹ, ìwọ fún wọn ní olùgbàlà, tí ó gbà wọ́n lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn.
And thou yauest hem in to the hond of her enemyes; and thei turmentiden hem; and in the tyme of her tribulacioun thei crieden to thee; and thou herdist them fro heuyn, and bi thi many merciful doyngis thou yauest hem sauyours, that sauyden hem fro the hond of her enemyes.
28 “Ṣùgbọ́n bí wọ́n bá ti wà nínú ìsinmi, wọn a sì túnṣe búburú lójú rẹ. Nígbà náà ni ìwọ kọ̀ wọ́n sílẹ̀ ṣọ́wọ́ àwọn ọ̀tá kí wọ́n lè jẹ ọba lórí wọn. Nígbà tí wọ́n bá sì tún kígbe sí ọ, ìwọ a gbọ́ láti ọ̀run wá, àti nínú àánú rẹ ni ìwọ gbà láti ìgbà dé ìgbà.
And whanne thei hadden restid, thei turneden ayen to do yuel in thi siyt; and thou forsokist hem in the hond of her enemyes, and enemyes hadden hem in possessioun; and thei weren conuertid, and thei crieden to thee; forsothe thou herdist hem fro heuene, and delyueridist hem `in thi mercies in many tymes.
29 “Ìwọ kìlọ̀ fún wọn láti padà sínú òfin rẹ, ṣùgbọ́n wọ́n hu ìwà ìgbéraga, wọ́n sì ṣe àìgbọ́ràn si àṣẹ rẹ. Wọ́n ṣẹ̀ sí ìlànà rẹ, nípa èyí tí ènìyàn yóò yè tí wọ́n bá pa wọ́n mọ́. Nínú agídí ọkàn wọ́n kọ ẹ̀yìn sí ọ, wọ́n jẹ́ olórí kunkun wọn kò sì fẹ́ gbọ́.
And thou witnessidist to hem, that thei schulden turne ayen to thi lawe; but thei diden proudli, and herden not thin heestis, and synneden in thi domes, whiche a man that schal do schal lyue in tho; and thei yauen the schuldre goynge awei, and thei maden hard her nol.
30 Fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún ni ìwọ fi ní sùúrù pẹ̀lú wọn. Nípa ẹ̀mí rẹ ni ìwọ kìlọ̀ fún wọn nípasẹ̀ àwọn wòlíì. Síbẹ̀ wọn kò fi etí sílẹ̀, nítorí náà ni ìwọ ṣe fi wọ́n lé àwọn aládùúgbò wọn lọ́wọ́.
And thou drowist along many yeeris on hem, and thou witnessidist to hem in thi Spirit bi the hond of thi prophetis; and thei herden not; and thou yauest hem in to the hond of the puplis of londis.
31 Ṣùgbọ́n nínú ọ̀pọ̀ àánú rẹ, ìwọ kò mú òpin bá wọn tàbí kọ̀ wọ́n sílẹ̀, nítorí ìwọ ni Ọlọ́run olóore-ọ̀fẹ́ àti aláàánú.
But in thi mercies ful manye thou madist not hem in to wastyng, nethir thou forsokist hem; for thou art God of merciful doynges, and meke.
32 “Ǹjẹ́ nítorí náà, Ọlọ́run wa, Ọlọ́run tí ó tóbi, tí ó lágbára, tí ó sì ní ẹ̀rù, ẹni tí ó pa májẹ̀mú ìfẹ́ mọ́, má ṣe jẹ́ gbogbo ìnira yìí dàbí ohun kékeré ní ojú rẹ—ìnira tí ó ti wá sórí wa, sórí àwọn ọba wa àti àwọn olórí wa, sórí àwọn àlùfáà wa àti àwọn wòlíì, sórí àwọn baba wa àti sórí gbogbo ènìyàn rẹ̀, láti àwọn ọjọ́ àwọn ọba Asiria wá títí di òní.
Now therfor, oure Lord God, greet God, strong, and ferdful, kepynge couenaunt and merci, turne thou not awei thi face in al the trauel that foond vs, oure kyngis, and oure princes, and oure fadris, and oure preestis, and oure profetis, and al thi puple, fro the daies of kyng Assur til to this dai.
33 Ìwọ jẹ́ olódodo nínú ohun gbogbo tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí wa; ìwọ sì ti ṣe òtítọ́, nígbà tí a bá ṣe búburú.
And thou art iust in alle thingis, that camen on vs, for thou didist trewthe to vs; but we han do wickidli.
34 Àwọn ọba wa, àwọn olórí wa, àwọn àlùfáà wa, àti àwọn baba wa kò tẹ̀lé òfin rẹ; wọn kò fetísílẹ̀ sí àṣẹ rẹ tàbí àwọn ìkìlọ̀ tí ìwọ fún wọn.
Oure kyngis, and oure princes, oure prestis, and fadris `diden not thi lawe; and thei perseyueden not thin heestis and witnessyngis, whiche thou witnessidist in hem.
35 Àní nígbà tí wọ́n wà nínú ìjọba wọn, tí wọ́n ń gbádùn oore ńlá tí ìwọ fi fún wọn, ní ilẹ̀ tí ó tóbi tí ó sì lọ́ràá, wọn kò sìn ọ́ tàbí padà kúrò nínú àwọn ọ̀nà búburú wọn.
And thei in her good rewmes, and in thi myche goodnesse, which thou yauest to hem, and in the largest lond and fat, whych thou haddist youe in the siyt of hem, serueden not thee, nether turneden ayen fro her werste studies.
36 “Ṣùgbọ́n wò ó, àwa jẹ́ ẹrú lónìí, àwa jẹ́ ẹrú ní ilẹ̀ tí ìwọ fún àwọn baba ńlá wa, nítorí kí wọn bá máa jẹ èso rẹ̀ àti ìre mìíràn tí ó mú jáde.
Lo! we `vs silf ben thrallis to dai; and the lond which thou yauest to oure fadris, that thei schulden ete the breed therof, and the goodis that ben therof, `is thral; and we `vs silf ben thrallis, `ethir boonde men, in that lond.
37 Nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìkórè rẹ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ọba tí ó fi ṣe olórí wa. Wọ́n ń ṣe àkóso lórí wa àti lórí ẹran wa bí ó ti wù wọ́n, àwa sì wà nínú ìpọ́njú ńlá.
And the fruytis therof ben multiplied to kyngis, whiche thou hast set on vs for oure synnes; and thei ben lordis of oure bodies, and of oure beestis, bi her wille, and we ben in greet tribulacioun.
38 “Nítorí gbogbo èyí, a ń ṣe àdéhùn tí ó fẹsẹ̀múlẹ̀, a sì kọ ọ́ sínú ìwé, àwọn olórí ọmọ Lefi àwọn àlùfáà sì fi èdìdì dì í.”
Therfor on alle these thingis we `vs silf smyten and writen boond of pees, and oure princes, oure dekenes, and oure prestis aseelen.

< Nehemiah 9 >