< Nehemiah 8 >

1 gbogbo àwọn ènìyàn kó ara wọn jọ bí ẹnìkan ní gbangba ìta níwájú ibodè omi. Wọ́n sọ fún Esra akọ̀wé pé kí ó gbé ìwé òfin Mose jáde, èyí tí Olúwa ti pàṣẹ fún Israẹli.
När sjunde månaden nalkades och Israels barn voro bosatta i sina städer, församlade sig folket, alla såsom en man, på den öppna platsen framför Vattenporten; och de bådo Esra, den skriftlärde, att hämta fram Moses lagbok, den som HERREN hade givit åt Israel.
2 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù keje ni àlùfáà Esra gbé ìwé òfin jáde ní iwájú ìjọ ènìyàn, èyí tí ó jẹ́ àpapọ̀ ọkùnrin àti obìnrin àti gbogbo àwọn ènìyàn tí wọ́n le è gbọ́ ọ ní àgbọ́yé.
Då framlade prästen Esra lagen för församlingen, för både män och kvinnor, alla som kunde förstå vad de hörde; detta var på första dagen i sjunde månaden.
3 Ó kà á sókè láti òwúrọ̀ títí di ọ̀sán bí ó ti kọjú sí ìta ní iwájú ibodè omi ní ojú u gbogbo ọkùnrin, obìnrin àti àwọn ènìyàn tókù tí òye le è yé tí wọ́n wà níbẹ̀. Gbogbo ènìyàn sì fetísílẹ̀ sí ìwé òfin náà pẹ̀lú ìfarabalẹ̀.
Och han föreläste därur vid den öppna platsen framför Vattenporten, från dagningen till middagen, för män och kvinnor, dem som kunde förstå det; och allt folket lyssnade till lagboken.
4 Akọ̀wé Esra dìde dúró lórí i pẹpẹ ìdúrólé tí a fi igi kàn fún ètò yìí. Ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ọ̀tún ni Mattitiah, Ṣema, Anaiah, Uriah, Hilkiah àti Maaseiah gbé dúró sí, ní ẹ̀gbẹ́ òsì rẹ̀ ní Pedaiah, Misaeli, Malkiah, Haṣumu, Haṣabadana, Sekariah àti Meṣullamu dúró sí.
Och Esra, den skriftlärde, stod på en hög träställning som man hade gjort för det ändamålet; och bredvid honom stodo Mattitja, Sema, Anaja, Uria, Hilkia och Maaseja på hans högra sida, och till vänster om honom Pedaja, Misael, Malkia, Hasum, Hasbaddana, Sakarja och Mesullam.
5 Esra ṣí ìwé náà, gbogbo ènìyàn sì le rí í nítorí ó dúró níbi tí ó ga ju gbogbo ènìyàn lọ; bí ó sì ti ṣí ìwé náà, gbogbo ènìyàn dìde dúró.
Och Esra öppnade boken, så att allt folket såg det, ty han stod högre än allt folket; och när han öppnade den, stod allt folket upp.
6 Esra yin Olúwa, Ọlọ́run alágbára; gbogbo ènìyàn gbé ọwọ́ wọn sókè, wọ́n sì wí pé, “Àmín! Àmín!” Nígbà náà ni wọ́n wólẹ̀ wọ́n sì sin Olúwa ní ìdojúbolẹ̀.
Och Esra lovade den store HERREN Gud, och allt folket svarade: "Amen, Amen", med uppräckta händer; och de böjde sig ned och tillbådo HERREN med ansiktet mot jorden.
7 Àwọn Lefi—Jeṣua, Bani, Ṣerebiah, Jamini, Akkubu, Ṣabbetai, Hodiah, Maaseiah, Kelita, Asariah, Josabadi, Hanani àti Pelaiah—kọ́ wọn ni òfin náà bí àwọn ènìyàn ṣe wà ní ìdúró síbẹ̀.
Och Jesua, Bani, Serebja, Jamin, Ackub, Sabbetai, Hodia, Maaseja, Kelita, Asarja, Josabad, Hanan, Pelaja och de andra leviterna undervisade folket i lagen, medan folket stod där, var och en på sin plats.
8 Wọ́n kà láti inú ìwé òfin Ọlọ́run, wọ́n túmọ̀ rẹ̀, wọ́n ṣe àlàyé kí ohun tí wọ́n kà bá à le yé àwọn ènìyàn yékéyéké.
Och de föreläste tydligt ur boken, ur Guds lag; och de utlade meningen, så att man förstod det som lästes.
9 Nígbà náà ni Nehemiah tí ó jẹ́ baálẹ̀, Esra àlùfáà àti akọ̀wé, àti àwọn Lefi tí wọ́n ń kọ́ àwọn ènìyàn wí fún gbogbo wọn pé, “Ọjọ́ yìí jẹ́ ọjọ́ mímọ́ fún Olúwa Ọlọ́run yín. Ẹ má ṣe ṣọ̀fọ̀ tàbí sọkún,” nítorí gbogbo àwọn ènìyàn ti ń sọkún bí wọ́n ti ń tẹ́tí sí ọ̀rọ̀ inú òfin náà.
Och Nehemja, han som var ståthållare, och prästen Esra, den skriftlärde, och leviterna, som undervisade folket, sade till allt folket: "Denna dag är helgad åt HERREN, eder Gud; sörjen icke och gråten icke." Ty allt folket grät, när de hörde lagens ord.
10 Nehemiah wí pé, “Ẹ lọ kí ẹ gbádùn oúnjẹ tí ẹ yàn láàyò kí ẹ sì mú ohun dídùn, kí ẹ sì mú díẹ̀ ránṣẹ́ sí àwọn tí kò ní. Ọjọ́ yìí, mímọ́ ni fún Olúwa wa. Ẹ má ṣe banújẹ́, nítorí ayọ̀ Olúwa ni agbára yín.”
Och han sade ytterligare till dem: "Gån bort och äten eder bästa mat och dricken edert sötaste vin, och sänden omkring gåvor därav till dem som icke hava något tillrett åt sig, ty denna dag är helgad åt vår Herre. Och varen icke bedrövade, ty fröjd i HERREN är eder starkhet."
11 Àwọn ọmọ Lefi mú kí gbogbo ènìyàn dákẹ́ jẹ́, wọ́n wí pé, “Ẹ dákẹ́, nítorí mímọ́ ni ọjọ́ yìí. Ẹ má ṣe banújẹ́.”
Också leviterna lugnade allt folket och sade: "Varen stilla, ty dagen är helig; varen icke bedrövade."
12 Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn lọ láti jẹ àti láti mu, wọ́n sì fi ìpín oúnjẹ ránṣẹ́, wọ́n sì ṣe àjọyọ̀ pẹ̀lú ayọ̀ ńlá, nítorí báyìí àwọn òfin tí a sọ di mímọ́ fun wọn ti yé wọn.
Och allt folket gick bort och åt och drack; de sände ock omkring gåvor av den mat de hade tillagat och gjorde sig mycket glada; ty de hade aktat på det som man hade kungjort för dem.
13 Ní ọjọ́ kejì oṣù náà, àwọn olórí, gbogbo ìdílé, àti àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, péjọ sọ́dọ̀ Esra akọ̀wé, wọ́n fi ara balẹ̀ láti fetí sí àwọn ọ̀rọ̀ òfin.
Dagen därefter församlade sig huvudmännen för hela folkets familjer, så ock prästerna och leviterna, till Esra, den skriftlärde, för att giva närmare akt på lagens ord.
14 Wọ́n ri ní àkọsílẹ̀ nínú ìwé òfin, èyí tí Olúwa ti pa ní àṣẹ nípasẹ̀ Mose, kí àwọn ọmọ Israẹli gbé inú àgọ́ ní àkókò àjọ àgọ́ oṣù keje
Och de funno skrivet i lagen att HERREN genom Mose hade bjudit att Israels barn skulle bo i lövhyddor under högtiden i sjunde månaden,
15 àti kí wọn kéde ọ̀rọ̀ yìí, kí wọn sì tàn án kálẹ̀ ní gbogbo ìlú wọn àti ní Jerusalẹmu: “Ẹ jáde lọ sí ìlú olókè, kí ẹ mú àwọn ẹ̀ka inú olifi àti ẹ̀ka igi olifi igbó, àti láti inú maritili, àwọn imọ̀ ọ̀pẹ àti àwọn igi tí ó léwé dáradára wá, láti ṣe àgọ́”—gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́.
och att man skulle kungöra och låta utropa i alla deras städer och i Jerusalem och säga: "Gån ut på bergen och hämten löv av olivträd, planterade eller vilda, och löv av myrten, palmträd och andra lummiga träd, och gören lövhyddor, såsom det är föreskrivet."
16 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn jáde lọ, wọ́n sì mú àwọn ẹ̀ka wá, wọ́n sì kọ́ àgọ́ fún ara wọn sí orí òrùlé ara wọn, ní àgbàlá wọn àti ní àgbàlá ilé Ọlọ́run àti ní ìta gbangba lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹnu ibodè omi àti èyí tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹnu ibodè Efraimu.
Då gick folket ut och hämtade sådant och gjorde sig hyddor på tak och på gårdar, var och en åt sig, så ock på gårdarna till Guds hus och på den öppna platsen vid Vattenporten och på den öppna platsen vid Efraimsporten.
17 Gbogbo ìjọ ènìyàn tí wọ́n padà láti ìgbèkùn kọ́ àgọ́, wọ́n sì ń gbé inú wọn. Láti ọjọ́ Jeṣua ọmọ Nuni títí di ọjọ́ náà, àwọn ọmọ Israẹli kò tí ì ṣe àjọyọ̀ ọ rẹ̀ bí irú èyí. Ayọ̀ ọ wọn sì pọ̀.
Och hela församlingen, så många som hade kommit tillbaka ifrån fångenskapen, gjorde sig lövhyddor och bodde i dessa hyddor. Ty från Jesuas, Nuns sons, dagar ända till den dagen hade Israels barn icke gjort så. Och där rådde mycket stor glädje.
18 Esra kà nínú ìwé òfin Ọlọ́run, bí ọjọ́ ṣe ń gorí ọjọ́, láti ọjọ́ kìn-ín-ní dé ọjọ́ ìkẹyìn. Wọ́n ṣe àjọyọ̀ àjọ náà fún ọjọ́ méje, ní ọjọ́ kẹjọ wọ́n ní àpéjọ, ní ìbámu pẹ̀lú òfin.
Och man föreläste ur Guds lagbok var dag, från den första dagen till den sista. Och de höllo högtid i sju dagar, och på åttonde dagen hölls en högtidsförsamling på föreskrivet sätt.

< Nehemiah 8 >