< Nehemiah 8 >

1 gbogbo àwọn ènìyàn kó ara wọn jọ bí ẹnìkan ní gbangba ìta níwájú ibodè omi. Wọ́n sọ fún Esra akọ̀wé pé kí ó gbé ìwé òfin Mose jáde, èyí tí Olúwa ti pàṣẹ fún Israẹli.
Då nu sjunde månaden kom, och Israels barn voro i sina städer, församlade sig allt folket, såsom en man, på breda gatone inför vattuporten, och sade till Esra den skriftlärda, att han skulle hemta fram Mose lagbok, som Herren Israel budit hade.
2 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù keje ni àlùfáà Esra gbé ìwé òfin jáde ní iwájú ìjọ ènìyàn, èyí tí ó jẹ́ àpapọ̀ ọkùnrin àti obìnrin àti gbogbo àwọn ènìyàn tí wọ́n le è gbọ́ ọ ní àgbọ́yé.
Och Esra Presten hemtade fram lagen inför menighetena, både män och qvinnor, och för alla dem som det förstå kunde, på första dagen i sjunde månadenom;
3 Ó kà á sókè láti òwúrọ̀ títí di ọ̀sán bí ó ti kọjú sí ìta ní iwájú ibodè omi ní ojú u gbogbo ọkùnrin, obìnrin àti àwọn ènìyàn tókù tí òye le è yé tí wọ́n wà níbẹ̀. Gbogbo ènìyàn sì fetísílẹ̀ sí ìwé òfin náà pẹ̀lú ìfarabalẹ̀.
Och las deruti, på breda gatone, som för vattuporten är, allt ifrå morgonlysningen intill middag, för män och qvinnor, och för dem som det förstå kunde; och hela folkens öron voro vänd till lagbokena.
4 Akọ̀wé Esra dìde dúró lórí i pẹpẹ ìdúrólé tí a fi igi kàn fún ètò yìí. Ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ọ̀tún ni Mattitiah, Ṣema, Anaiah, Uriah, Hilkiah àti Maaseiah gbé dúró sí, ní ẹ̀gbẹ́ òsì rẹ̀ ní Pedaiah, Misaeli, Malkiah, Haṣumu, Haṣabadana, Sekariah àti Meṣullamu dúró sí.
Och Esra den Skriftlärde stod uppå en hög trästol, den de till predikan gjort hade; och när honom stodo Mattithia, Sema, Anaja, Uria, Hilkia och Maaseja, på hans högra sido; och på hans venstra Pedaja, Misael, Malchija, Hasum, Hasbadana, Zacharia och Mesullam.
5 Esra ṣí ìwé náà, gbogbo ènìyàn sì le rí í nítorí ó dúró níbi tí ó ga ju gbogbo ènìyàn lọ; bí ó sì ti ṣí ìwé náà, gbogbo ènìyàn dìde dúró.
Och Esra lät upp bokena för hela folket; förty han stod högt öfver allt folket; och då han upplät henne, stod allt folket.
6 Esra yin Olúwa, Ọlọ́run alágbára; gbogbo ènìyàn gbé ọwọ́ wọn sókè, wọ́n sì wí pé, “Àmín! Àmín!” Nígbà náà ni wọ́n wólẹ̀ wọ́n sì sin Olúwa ní ìdojúbolẹ̀.
Och Esra lofvade Herran den stora Guden; och allt folket svarade: Amen, Amen, med uppräckta händer; och bugade sig, och tillbådo Herran med ansigtet ned på jordena.
7 Àwọn Lefi—Jeṣua, Bani, Ṣerebiah, Jamini, Akkubu, Ṣabbetai, Hodiah, Maaseiah, Kelita, Asariah, Josabadi, Hanani àti Pelaiah—kọ́ wọn ni òfin náà bí àwọn ènìyàn ṣe wà ní ìdúró síbẹ̀.
Och Jesua, Bani, Serebia, Jamin, Akkub, Sabbethai, Hodija, Maaseja, Kelita, Asaria, Josabad, Hanan, Pelaja, och Leviterna, beställde att folket gaf akt uppå lagen; och folket stod uppå sitt rum.
8 Wọ́n kà láti inú ìwé òfin Ọlọ́run, wọ́n túmọ̀ rẹ̀, wọ́n ṣe àlàyé kí ohun tí wọ́n kà bá à le yé àwọn ènìyàn yékéyéké.
Och de läste uti Guds lagbok klarliga och förståndeliga, så att man förstod, då läset vardt.
9 Nígbà náà ni Nehemiah tí ó jẹ́ baálẹ̀, Esra àlùfáà àti akọ̀wé, àti àwọn Lefi tí wọ́n ń kọ́ àwọn ènìyàn wí fún gbogbo wọn pé, “Ọjọ́ yìí jẹ́ ọjọ́ mímọ́ fún Olúwa Ọlọ́run yín. Ẹ má ṣe ṣọ̀fọ̀ tàbí sọkún,” nítorí gbogbo àwọn ènìyàn ti ń sọkún bí wọ́n ti ń tẹ́tí sí ọ̀rọ̀ inú òfin náà.
Och Nehemia, hvilken är Thirsatha, och Esra Presten, den Skriftlärde, och Leviterna, som folket höllo till att akta på, sade till allt folket: Denne dagen är helig Herranom edrom Gud; derföre sörjer intet, och gråter icke; ty allt folket gret, då de hörde lagsens ord.
10 Nehemiah wí pé, “Ẹ lọ kí ẹ gbádùn oúnjẹ tí ẹ yàn láàyò kí ẹ sì mú ohun dídùn, kí ẹ sì mú díẹ̀ ránṣẹ́ sí àwọn tí kò ní. Ọjọ́ yìí, mímọ́ ni fún Olúwa wa. Ẹ má ṣe banújẹ́, nítorí ayọ̀ Olúwa ni agbára yín.”
Derföre sade han till dem: Går bort, och äter det feta, och dricker det söta, och sänder dem ock delar, som intet för sig tillredt hafva; förty denne dagen är helig vårom Herra. Derföre bekymrer eder icke; ty fröjd i Herranom är edor starkhet.
11 Àwọn ọmọ Lefi mú kí gbogbo ènìyàn dákẹ́ jẹ́, wọ́n wí pé, “Ẹ dákẹ́, nítorí mímọ́ ni ọjọ́ yìí. Ẹ má ṣe banújẹ́.”
Och Leviterna stillade allt folket, och sade: Varer tyste, ty dagen är helig; bekymrens intet.
12 Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn lọ láti jẹ àti láti mu, wọ́n sì fi ìpín oúnjẹ ránṣẹ́, wọ́n sì ṣe àjọyọ̀ pẹ̀lú ayọ̀ ńlá, nítorí báyìí àwọn òfin tí a sọ di mímọ́ fun wọn ti yé wọn.
Och allt folket gick bort till att äta, dricka och del sända, och gjorde sig en stor glädje; förty de hade förståndit orden, som man dem förkunnat hade.
13 Ní ọjọ́ kejì oṣù náà, àwọn olórí, gbogbo ìdílé, àti àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, péjọ sọ́dọ̀ Esra akọ̀wé, wọ́n fi ara balẹ̀ láti fetí sí àwọn ọ̀rọ̀ òfin.
På annan dagen församlade sig öfversta fäderna ibland allt folket, och Presterna, och Leviterna, till Esra den Skriftlärda, att han skulle undervisa dem i lagsens ordom.
14 Wọ́n ri ní àkọsílẹ̀ nínú ìwé òfin, èyí tí Olúwa ti pa ní àṣẹ nípasẹ̀ Mose, kí àwọn ọmọ Israẹli gbé inú àgọ́ ní àkókò àjọ àgọ́ oṣù keje
Och de funno beskrifvet i lagen, att Herren genom Mose budit hade, att Israels barn skulle bo i löfhyddor, på den högtidene i sjunde månadenom.
15 àti kí wọn kéde ọ̀rọ̀ yìí, kí wọn sì tàn án kálẹ̀ ní gbogbo ìlú wọn àti ní Jerusalẹmu: “Ẹ jáde lọ sí ìlú olókè, kí ẹ mú àwọn ẹ̀ka inú olifi àti ẹ̀ka igi olifi igbó, àti láti inú maritili, àwọn imọ̀ ọ̀pẹ àti àwọn igi tí ó léwé dáradára wá, láti ṣe àgọ́”—gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́.
Och de läto det varda kunnigt, och utropadt i alla deras städer, och i Jerusalem, och sade: Går ut uppå berget, och hemter oljoqvistar, balsamqvistar, myrthenqvistar, palmqvistar och qvistar af tjockqvistadt trä, att man må göra löfhyddor, såsom skrifvet står.
16 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn jáde lọ, wọ́n sì mú àwọn ẹ̀ka wá, wọ́n sì kọ́ àgọ́ fún ara wọn sí orí òrùlé ara wọn, ní àgbàlá wọn àti ní àgbàlá ilé Ọlọ́run àti ní ìta gbangba lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹnu ibodè omi àti èyí tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹnu ibodè Efraimu.
Och folket gick ut, och hemtade, och gjorde sig löfhyddor, hvar uppå sitt tak, och i sina gårdar, och i Guds hus gårdar; och uppå den breda gatone vid vattuporten, och uppå den breda gatone vid Ephraims port.
17 Gbogbo ìjọ ènìyàn tí wọ́n padà láti ìgbèkùn kọ́ àgọ́, wọ́n sì ń gbé inú wọn. Láti ọjọ́ Jeṣua ọmọ Nuni títí di ọjọ́ náà, àwọn ọmọ Israẹli kò tí ì ṣe àjọyọ̀ ọ rẹ̀ bí irú èyí. Ayọ̀ ọ wọn sì pọ̀.
Och hela menigheten af dem, som af fängelset igenkomne voro, gjorde löfhyddor, och bodde deruti; ty Israels barn hade ifrå Josua, Nuns sons, tid, allt intill denna dag, intet så gjort; och var en ganska stor glädje.
18 Esra kà nínú ìwé òfin Ọlọ́run, bí ọjọ́ ṣe ń gorí ọjọ́, láti ọjọ́ kìn-ín-ní dé ọjọ́ ìkẹyìn. Wọ́n ṣe àjọyọ̀ àjọ náà fún ọjọ́ méje, ní ọjọ́ kẹjọ wọ́n ní àpéjọ, ní ìbámu pẹ̀lú òfin.
Och vardt hvar dag läset i Guds lagbok, ifrå första dagen allt intill den yttersta; och de höllo den högtiden i sju dagar; och på åttonde dagen församlingenes dag, såsom det borde sig.

< Nehemiah 8 >