< Nehemiah 8 >

1 gbogbo àwọn ènìyàn kó ara wọn jọ bí ẹnìkan ní gbangba ìta níwájú ibodè omi. Wọ́n sọ fún Esra akọ̀wé pé kí ó gbé ìwé òfin Mose jáde, èyí tí Olúwa ti pàṣẹ fún Israẹli.
Og alt folket samlet sig som en mann på plassen foran Vannporten; og de bad Esras, den skriftlærde, om å hente boken med Mose lov, som Herren hadde gitt Israel.
2 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù keje ni àlùfáà Esra gbé ìwé òfin jáde ní iwájú ìjọ ènìyàn, èyí tí ó jẹ́ àpapọ̀ ọkùnrin àti obìnrin àti gbogbo àwọn ènìyàn tí wọ́n le è gbọ́ ọ ní àgbọ́yé.
Og presten Esras bar loven frem for menigheten, både for menn og kvinner og alle som kunde forstå hvad de hørte; det var den første dag i den syvende måned.
3 Ó kà á sókè láti òwúrọ̀ títí di ọ̀sán bí ó ti kọjú sí ìta ní iwájú ibodè omi ní ojú u gbogbo ọkùnrin, obìnrin àti àwọn ènìyàn tókù tí òye le è yé tí wọ́n wà níbẹ̀. Gbogbo ènìyàn sì fetísílẹ̀ sí ìwé òfin náà pẹ̀lú ìfarabalẹ̀.
Og han leste op av den midt for plassen foran Vannporten fra tidlig morgen til midt på dagen - for mennene og kvinnene og dem som kunde forstå; og alt folket lyttet til lovbokens ord.
4 Akọ̀wé Esra dìde dúró lórí i pẹpẹ ìdúrólé tí a fi igi kàn fún ètò yìí. Ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ọ̀tún ni Mattitiah, Ṣema, Anaiah, Uriah, Hilkiah àti Maaseiah gbé dúró sí, ní ẹ̀gbẹ́ òsì rẹ̀ ní Pedaiah, Misaeli, Malkiah, Haṣumu, Haṣabadana, Sekariah àti Meṣullamu dúró sí.
Esras, den skriftlærde, stod på en forhøining av tre, som var blitt reist til dette, og ved siden av ham stod Mattitja, Sema, Anaja, Uria, Hilkia og Ma'aseja til høire for ham, og til venstre for ham Pedaja, Misael, Malkia, Hasum, Hasbaddana, Sakarja og Mesullam.
5 Esra ṣí ìwé náà, gbogbo ènìyàn sì le rí í nítorí ó dúró níbi tí ó ga ju gbogbo ènìyàn lọ; bí ó sì ti ṣí ìwé náà, gbogbo ènìyàn dìde dúró.
Og Esras åpnet boken for alt folkets øine; for han stod høiere enn alt folket; og da han åpnet den, reiste alt folket sig.
6 Esra yin Olúwa, Ọlọ́run alágbára; gbogbo ènìyàn gbé ọwọ́ wọn sókè, wọ́n sì wí pé, “Àmín! Àmín!” Nígbà náà ni wọ́n wólẹ̀ wọ́n sì sin Olúwa ní ìdojúbolẹ̀.
Esras lovet Herren, den store Gud, og alt folket svarte med opløftede hender: Amen, amen, og de bøide sig og kastet sig ned for Herren med ansiktet til jorden.
7 Àwọn Lefi—Jeṣua, Bani, Ṣerebiah, Jamini, Akkubu, Ṣabbetai, Hodiah, Maaseiah, Kelita, Asariah, Josabadi, Hanani àti Pelaiah—kọ́ wọn ni òfin náà bí àwọn ènìyàn ṣe wà ní ìdúró síbẹ̀.
Og Josva, Bani, Serebja, Jamin, Akkub, Sabbetai, Hodia, Ma'aseja, Kelita, Asarja, Josabad, Hanan, Pelaja og de andre levitter utla loven for folket, mens folket blev stående på sin plass.
8 Wọ́n kà láti inú ìwé òfin Ọlọ́run, wọ́n túmọ̀ rẹ̀, wọ́n ṣe àlàyé kí ohun tí wọ́n kà bá à le yé àwọn ènìyàn yékéyéké.
De leste op av boken - av Guds lov - de tolket og utla den for folket, så de skjønte det som blev lest.
9 Nígbà náà ni Nehemiah tí ó jẹ́ baálẹ̀, Esra àlùfáà àti akọ̀wé, àti àwọn Lefi tí wọ́n ń kọ́ àwọn ènìyàn wí fún gbogbo wọn pé, “Ọjọ́ yìí jẹ́ ọjọ́ mímọ́ fún Olúwa Ọlọ́run yín. Ẹ má ṣe ṣọ̀fọ̀ tàbí sọkún,” nítorí gbogbo àwọn ènìyàn ti ń sọkún bí wọ́n ti ń tẹ́tí sí ọ̀rọ̀ inú òfin náà.
Og stattholderen Nehemias og presten Esras, den skriftlærde, og levittene som lærte folket, sa til alt folket: Denne dag er helliget Herren eders Gud, sørg ikke og gråt ikke! For alt folket gråt da de hørte lovens ord.
10 Nehemiah wí pé, “Ẹ lọ kí ẹ gbádùn oúnjẹ tí ẹ yàn láàyò kí ẹ sì mú ohun dídùn, kí ẹ sì mú díẹ̀ ránṣẹ́ sí àwọn tí kò ní. Ọjọ́ yìí, mímọ́ ni fún Olúwa wa. Ẹ má ṣe banújẹ́, nítorí ayọ̀ Olúwa ni agbára yín.”
Så sa han til dem: Gå nu og et fete retter og drikk søte drikker og send gaver derav til dem for hvem intet er tillaget, for dagen er helliget vår Herre, og sørg ikke, for glede i Herren er eders styrke!
11 Àwọn ọmọ Lefi mú kí gbogbo ènìyàn dákẹ́ jẹ́, wọ́n wí pé, “Ẹ dákẹ́, nítorí mímọ́ ni ọjọ́ yìí. Ẹ má ṣe banújẹ́.”
Også levittene søkte å få alt folket til å holde sig rolig og sa: Vær stille, for dagen er hellig; sørg ikke!
12 Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn lọ láti jẹ àti láti mu, wọ́n sì fi ìpín oúnjẹ ránṣẹ́, wọ́n sì ṣe àjọyọ̀ pẹ̀lú ayọ̀ ńlá, nítorí báyìí àwọn òfin tí a sọ di mímọ́ fun wọn ti yé wọn.
Da gikk alt folket bort og åt og drakk og sendte gaver omkring og holdt en stor gledesfest; for de hadde forstått det som var blitt talt til dem.
13 Ní ọjọ́ kejì oṣù náà, àwọn olórí, gbogbo ìdílé, àti àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, péjọ sọ́dọ̀ Esra akọ̀wé, wọ́n fi ara balẹ̀ láti fetí sí àwọn ọ̀rọ̀ òfin.
Dagen efter samlet alt folkets familiehoder, prestene og levittene sig hos Esras, den skriftlærde, for å få nærmere rede på lovens ord.
14 Wọ́n ri ní àkọsílẹ̀ nínú ìwé òfin, èyí tí Olúwa ti pa ní àṣẹ nípasẹ̀ Mose, kí àwọn ọmọ Israẹli gbé inú àgọ́ ní àkókò àjọ àgọ́ oṣù keje
De fant da skrevet i loven - den lov som Herren hadde gitt ved Moses - at Israels barn skulde bo i løvhytter på festen i den syvende måned,
15 àti kí wọn kéde ọ̀rọ̀ yìí, kí wọn sì tàn án kálẹ̀ ní gbogbo ìlú wọn àti ní Jerusalẹmu: “Ẹ jáde lọ sí ìlú olókè, kí ẹ mú àwọn ẹ̀ka inú olifi àti ẹ̀ka igi olifi igbó, àti láti inú maritili, àwọn imọ̀ ọ̀pẹ àti àwọn igi tí ó léwé dáradára wá, láti ṣe àgọ́”—gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́.
og at de skulde kunngjøre og la utrope i alle sine byer og i Jerusalem: Gå ut på fjellene og hent løv av oljetrær og av ville oljetrær og av myrter og av palmer og av andre løvrike trær og gjør løvhytter, som foreskrevet er.
16 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn jáde lọ, wọ́n sì mú àwọn ẹ̀ka wá, wọ́n sì kọ́ àgọ́ fún ara wọn sí orí òrùlé ara wọn, ní àgbàlá wọn àti ní àgbàlá ilé Ọlọ́run àti ní ìta gbangba lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹnu ibodè omi àti èyí tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹnu ibodè Efraimu.
Da gikk folket ut og hentet løv, og de gjorde sig løvhytter, hver på sitt tak og på sine tun og likeledes i forgårdene til Guds hus og på plassen ved Vannporten og på plassen ved Efra'im-porten.
17 Gbogbo ìjọ ènìyàn tí wọ́n padà láti ìgbèkùn kọ́ àgọ́, wọ́n sì ń gbé inú wọn. Láti ọjọ́ Jeṣua ọmọ Nuni títí di ọjọ́ náà, àwọn ọmọ Israẹli kò tí ì ṣe àjọyọ̀ ọ rẹ̀ bí irú èyí. Ayọ̀ ọ wọn sì pọ̀.
Og hele menigheten, de som var kommet tilbake fra fangenskapet, gjorde løvhytter og bodde i dem; for fra Josvas, Nuns sønns dager like til denne dag hadde Israels barn ikke gjort dette. Og der var en overmåte stor glede.
18 Esra kà nínú ìwé òfin Ọlọ́run, bí ọjọ́ ṣe ń gorí ọjọ́, láti ọjọ́ kìn-ín-ní dé ọjọ́ ìkẹyìn. Wọ́n ṣe àjọyọ̀ àjọ náà fún ọjọ́ méje, ní ọjọ́ kẹjọ wọ́n ní àpéjọ, ní ìbámu pẹ̀lú òfin.
Dag efter dag leste de op av Guds lovbok, fra den første dag til den siste; de holdt høitid i syv dager og på den åttende dag en festlig sammenkomst, som påbudt var.

< Nehemiah 8 >