< Nehemiah 8 >

1 gbogbo àwọn ènìyàn kó ara wọn jọ bí ẹnìkan ní gbangba ìta níwájú ibodè omi. Wọ́n sọ fún Esra akọ̀wé pé kí ó gbé ìwé òfin Mose jáde, èyí tí Olúwa ti pàṣẹ fún Israẹli.
Et à l'approche du septième mois, comme les enfants d'Israël étaient dans leurs villes, tout le peuple se rassembla comme un seul homme dans la place qui est devant la Porte de l'Eau. Et ils dirent à Esdras, le Scribe, d'apporter le livre de la Loi de Moïse, prescrite par l'Éternel à Israël.
2 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù keje ni àlùfáà Esra gbé ìwé òfin jáde ní iwájú ìjọ ènìyàn, èyí tí ó jẹ́ àpapọ̀ ọkùnrin àti obìnrin àti gbogbo àwọn ènìyàn tí wọ́n le è gbọ́ ọ ní àgbọ́yé.
Et le Prêtre Esdras apporta la Loi devant l'Assemblée composée d'hommes et de femmes et de tous ceux qui étaient capables de l'entendre, le premier jour du septième mois.
3 Ó kà á sókè láti òwúrọ̀ títí di ọ̀sán bí ó ti kọjú sí ìta ní iwájú ibodè omi ní ojú u gbogbo ọkùnrin, obìnrin àti àwọn ènìyàn tókù tí òye le è yé tí wọ́n wà níbẹ̀. Gbogbo ènìyàn sì fetísílẹ̀ sí ìwé òfin náà pẹ̀lú ìfarabalẹ̀.
Et il en fit la lecture en face de la Place qui est devant la Porte de l'Eau, depuis l'aube jusqu'à midi, en présence des hommes et des femmes et de tous ceux qui étaient capables d'entendre. Et les oreilles de tout le peuple se dirigeaient vers le livre de la Loi.
4 Akọ̀wé Esra dìde dúró lórí i pẹpẹ ìdúrólé tí a fi igi kàn fún ètò yìí. Ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ọ̀tún ni Mattitiah, Ṣema, Anaiah, Uriah, Hilkiah àti Maaseiah gbé dúró sí, ní ẹ̀gbẹ́ òsì rẹ̀ ní Pedaiah, Misaeli, Malkiah, Haṣumu, Haṣabadana, Sekariah àti Meṣullamu dúró sí.
Et Esdras, le Scribe, se tenait sur une estrade en bois qu'on avait faite pour cet objet. Et à côté de lui se tenaient Matthithia et Sema et Anaïa et Uri et Hilkia et Maaseïa à sa droite; et à sa gauche étaient Pedaïa et Misaël et Malchiia et Hasum et Hasbaddana, Zacharie, Mesullam.
5 Esra ṣí ìwé náà, gbogbo ènìyàn sì le rí í nítorí ó dúró níbi tí ó ga ju gbogbo ènìyàn lọ; bí ó sì ti ṣí ìwé náà, gbogbo ènìyàn dìde dúró.
Et Esdras ouvrit le volume devant les yeux de tout le peuple, car il était placé plus haut que tout le peuple; et quand il l'ouvrit, tout le peuple se leva.
6 Esra yin Olúwa, Ọlọ́run alágbára; gbogbo ènìyàn gbé ọwọ́ wọn sókè, wọ́n sì wí pé, “Àmín! Àmín!” Nígbà náà ni wọ́n wólẹ̀ wọ́n sì sin Olúwa ní ìdojúbolẹ̀.
Et Esdras bénit l'Éternel, le Grand Dieu, et tout le peuple répondit: Ainsi soit-il! Ainsi soit-il! en élevant leurs mains, et ils s'inclinèrent et se prosternèrent devant l'Éternel la face contre terre.
7 Àwọn Lefi—Jeṣua, Bani, Ṣerebiah, Jamini, Akkubu, Ṣabbetai, Hodiah, Maaseiah, Kelita, Asariah, Josabadi, Hanani àti Pelaiah—kọ́ wọn ni òfin náà bí àwọn ènìyàn ṣe wà ní ìdúró síbẹ̀.
Et Jésuah et Bani et Sérébia, Jamin, Accub, Sabthaï, Hodia, Maaseïa, Kelita, Azaria, Jozabad, Hanan, Pelaïa et les Lévites interprétaient la Loi au peuple, et le peuple restait en place.
8 Wọ́n kà láti inú ìwé òfin Ọlọ́run, wọ́n túmọ̀ rẹ̀, wọ́n ṣe àlàyé kí ohun tí wọ́n kà bá à le yé àwọn ènìyàn yékéyéké.
Et ils lurent dans le livre de la Loi de Dieu distinctement et indiquaient le sens, et expliquaient en faisant lecture.
9 Nígbà náà ni Nehemiah tí ó jẹ́ baálẹ̀, Esra àlùfáà àti akọ̀wé, àti àwọn Lefi tí wọ́n ń kọ́ àwọn ènìyàn wí fún gbogbo wọn pé, “Ọjọ́ yìí jẹ́ ọjọ́ mímọ́ fún Olúwa Ọlọ́run yín. Ẹ má ṣe ṣọ̀fọ̀ tàbí sọkún,” nítorí gbogbo àwọn ènìyàn ti ń sọkún bí wọ́n ti ń tẹ́tí sí ọ̀rọ̀ inú òfin náà.
Et Néhémie, le Thirsatha, et le Prêtre Esdras, le Scribe, et les Lévites qui enseignaient le peuple, dirent à tout le peuple: Ce jour est consacré à l'Éternel, votre Dieu. Ne soyez ni dans le deuil ni dans les larmes! (car tout le peuple pleurait en écoutant les paroles de la Loi.)
10 Nehemiah wí pé, “Ẹ lọ kí ẹ gbádùn oúnjẹ tí ẹ yàn láàyò kí ẹ sì mú ohun dídùn, kí ẹ sì mú díẹ̀ ránṣẹ́ sí àwọn tí kò ní. Ọjọ́ yìí, mímọ́ ni fún Olúwa wa. Ẹ má ṣe banújẹ́, nítorí ayọ̀ Olúwa ni agbára yín.”
Et il leur dit: Allez, faites chère grasse et buvez des boissons douces, et envoyez des parts à ceux qui n'ont rien d'apprêté, car ce jour est consacré à notre Seigneur. Et ne vous tourmentez pas, — car la joie que vous donne l'Éternel, doit être votre réconfort.
11 Àwọn ọmọ Lefi mú kí gbogbo ènìyàn dákẹ́ jẹ́, wọ́n wí pé, “Ẹ dákẹ́, nítorí mímọ́ ni ọjọ́ yìí. Ẹ má ṣe banújẹ́.”
Et les Lévites calmèrent tout le peuple et dirent: Silence! car le jour est Saint! et ne vous tourmentez pas!
12 Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn lọ láti jẹ àti láti mu, wọ́n sì fi ìpín oúnjẹ ránṣẹ́, wọ́n sì ṣe àjọyọ̀ pẹ̀lú ayọ̀ ńlá, nítorí báyìí àwọn òfin tí a sọ di mímọ́ fun wọn ti yé wọn.
Là-dessus tout le peuple s'en alla manger et boire et envoyer des portions et faire une grande réjouissance. Car ils avaient compris les paroles dont il leur avait été donné connaissance.
13 Ní ọjọ́ kejì oṣù náà, àwọn olórí, gbogbo ìdílé, àti àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, péjọ sọ́dọ̀ Esra akọ̀wé, wọ́n fi ara balẹ̀ láti fetí sí àwọn ọ̀rọ̀ òfin.
Et le second jour s'assemblèrent les chefs des maisons patriarcales de tout le peuple, les Prêtres et les Lévites, auprès d'Esdras, le Scribe, pour étudier les paroles de la Loi.
14 Wọ́n ri ní àkọsílẹ̀ nínú ìwé òfin, èyí tí Olúwa ti pa ní àṣẹ nípasẹ̀ Mose, kí àwọn ọmọ Israẹli gbé inú àgọ́ ní àkókò àjọ àgọ́ oṣù keje
Et ils trouvèrent consigné dans la Loi, que l'Éternel avait prescrite par l'organe de Moïse: que les enfants d'Israël devaient se loger dans des huttes, à la fête du septième mois,
15 àti kí wọn kéde ọ̀rọ̀ yìí, kí wọn sì tàn án kálẹ̀ ní gbogbo ìlú wọn àti ní Jerusalẹmu: “Ẹ jáde lọ sí ìlú olókè, kí ẹ mú àwọn ẹ̀ka inú olifi àti ẹ̀ka igi olifi igbó, àti láti inú maritili, àwọn imọ̀ ọ̀pẹ àti àwọn igi tí ó léwé dáradára wá, láti ṣe àgọ́”—gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́.
et qu'ils devaient publier et faire circuler dans toutes leurs villes et à Jérusalem cet appel: Allez à la montagne et en rapportez des rameaux d'olivier à huile et des rameaux d'olivier sauvage, et des rameaux de myrte et des branches de palmier et des branches d'arbres touffus pour en faire des loges, comme c'est écrit.
16 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn jáde lọ, wọ́n sì mú àwọn ẹ̀ka wá, wọ́n sì kọ́ àgọ́ fún ara wọn sí orí òrùlé ara wọn, ní àgbàlá wọn àti ní àgbàlá ilé Ọlọ́run àti ní ìta gbangba lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹnu ibodè omi àti èyí tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹnu ibodè Efraimu.
Et le peuple sortit et en rapporta, et ils se firent des loges, chacun sur sa terrasse, et dans leurs cours et dans les cours de la Maison de Dieu, et dans la Place de la Porte de l'Eau, et dans la Place de la Porte d'Éphraïm.
17 Gbogbo ìjọ ènìyàn tí wọ́n padà láti ìgbèkùn kọ́ àgọ́, wọ́n sì ń gbé inú wọn. Láti ọjọ́ Jeṣua ọmọ Nuni títí di ọjọ́ náà, àwọn ọmọ Israẹli kò tí ì ṣe àjọyọ̀ ọ rẹ̀ bí irú èyí. Ayọ̀ ọ wọn sì pọ̀.
Et toute l'Assemblée de ceux qui étaient revenus de la captivité, fit des loges, et habita dans des loges. Car depuis l'époque de Josué, fils de Nun, jusqu'à ce jour, les enfants d'Israël n'avaient rien fait de pareil, et ce fut une très grande réjouissance.
18 Esra kà nínú ìwé òfin Ọlọ́run, bí ọjọ́ ṣe ń gorí ọjọ́, láti ọjọ́ kìn-ín-ní dé ọjọ́ ìkẹyìn. Wọ́n ṣe àjọyọ̀ àjọ náà fún ọjọ́ méje, ní ọjọ́ kẹjọ wọ́n ní àpéjọ, ní ìbámu pẹ̀lú òfin.
Et on lut dans le livre de la Loi de Dieu chaque jour, du premier au dernier jour. Et ils firent la fête pendant sept jours, et le huitième jour eut lieu la Grande Convocation selon l'usage.

< Nehemiah 8 >