< Nehemiah 8 >

1 gbogbo àwọn ènìyàn kó ara wọn jọ bí ẹnìkan ní gbangba ìta níwájú ibodè omi. Wọ́n sọ fún Esra akọ̀wé pé kí ó gbé ìwé òfin Mose jáde, èyí tí Olúwa ti pàṣẹ fún Israẹli.
Kaminawk boih angzoh o moe, tui khongkha hmaa ih loklam ah amkhueng o; Angraeng mah Israel caanawk khaeah paek ih, Mosi ih kaalok cabu to sinh hanah ca tarikkung Ezra khaeah thuih pae o baktih toengah,
2 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù keje ni àlùfáà Esra gbé ìwé òfin jáde ní iwájú ìjọ ènìyàn, èyí tí ó jẹ́ àpapọ̀ ọkùnrin àti obìnrin àti gbogbo àwọn ènìyàn tí wọ́n le è gbọ́ ọ ní àgbọ́yé.
khrah sarihto amtong tangsuekhaih niah, qaima Ezra mah kaalok to nongpa nongpatanawk hoi lok thaikop kaminawk boih hmaa ah sin pae.
3 Ó kà á sókè láti òwúrọ̀ títí di ọ̀sán bí ó ti kọjú sí ìta ní iwájú ibodè omi ní ojú u gbogbo ọkùnrin, obìnrin àti àwọn ènìyàn tókù tí òye le è yé tí wọ́n wà níbẹ̀. Gbogbo ènìyàn sì fetísílẹ̀ sí ìwé òfin náà pẹ̀lú ìfarabalẹ̀.
Lok thaikop, nongpa hoi nongpatanawk hmaa ah akhawnbang hoi athun karoek to, tuipuek khongkha hmaa ih loklam ah a kroek pae; kaminawk boih mah kaalok cabu thung ih lok to palung tang hoi tahngaih pae o.
4 Akọ̀wé Esra dìde dúró lórí i pẹpẹ ìdúrólé tí a fi igi kàn fún ètò yìí. Ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ọ̀tún ni Mattitiah, Ṣema, Anaiah, Uriah, Hilkiah àti Maaseiah gbé dúró sí, ní ẹ̀gbẹ́ òsì rẹ̀ ní Pedaiah, Misaeli, Malkiah, Haṣumu, Haṣabadana, Sekariah àti Meṣullamu dúró sí.
Ca tarikkung Ezara loe nihcae mah thing hoi sak o ih hmaicam nuiah angdoet; a bantang bangah Mattithiah, Shema, Anaiah, Urijah, Hilkiah hoi Maaseiah cae angdoet o moe, banqoi bangah Pedaiah, Mishael, Malkhiah, Hashum, Hashbadana, Zekhariah hoi Meshullam cae to angdoet o.
5 Esra ṣí ìwé náà, gbogbo ènìyàn sì le rí í nítorí ó dúró níbi tí ó ga ju gbogbo ènìyàn lọ; bí ó sì ti ṣí ìwé náà, gbogbo ènìyàn dìde dúró.
Kaminawk mah anih hnuk o thai hanah, Ezra loe minawk pong sang kue ah angdoet, anih mah minawk hmaa ah cabu to paongh naah, kaminawk boih angdoet o.
6 Esra yin Olúwa, Ọlọ́run alágbára; gbogbo ènìyàn gbé ọwọ́ wọn sókè, wọ́n sì wí pé, “Àmín! Àmín!” Nígbà náà ni wọ́n wólẹ̀ wọ́n sì sin Olúwa ní ìdojúbolẹ̀.
Ezra mah kalen koek Sithaw, Angraeng to tahamhoihaih paek. To naah kaminawk boih ban payangh o moe, Amen! Amen! tiah pathim o: Mikhmai long ah akuep o moe, Angraeng to a bok o.
7 Àwọn Lefi—Jeṣua, Bani, Ṣerebiah, Jamini, Akkubu, Ṣabbetai, Hodiah, Maaseiah, Kelita, Asariah, Josabadi, Hanani àti Pelaiah—kọ́ wọn ni òfin náà bí àwọn ènìyàn ṣe wà ní ìdúró síbẹ̀.
Jeshua, Bani, Sherebiah, Jamin, Akkub, Shabbethai, Hodijah, Maaseiah, Kelita, Azariah, Jozabad, Hanan, Pelaiah hoi Levinawk mah, kaminawk angmacae ahmuen ah angdoet o naah, kaalok panoek o thaih hanah abomh o.
8 Wọ́n kà láti inú ìwé òfin Ọlọ́run, wọ́n túmọ̀ rẹ̀, wọ́n ṣe àlàyé kí ohun tí wọ́n kà bá à le yé àwọn ènìyàn yékéyéké.
Nihcae mah Sithaw ih kaalok to kroek pae o, kroek o ih lok to a thaih o kop hanah, a thuih koehhaih lokhlong to kaminawk hanah kamtueng ah leh pae o.
9 Nígbà náà ni Nehemiah tí ó jẹ́ baálẹ̀, Esra àlùfáà àti akọ̀wé, àti àwọn Lefi tí wọ́n ń kọ́ àwọn ènìyàn wí fún gbogbo wọn pé, “Ọjọ́ yìí jẹ́ ọjọ́ mímọ́ fún Olúwa Ọlọ́run yín. Ẹ má ṣe ṣọ̀fọ̀ tàbí sọkún,” nítorí gbogbo àwọn ènìyàn ti ń sọkún bí wọ́n ti ń tẹ́tí sí ọ̀rọ̀ inú òfin náà.
Kaminawk mah kaalok to thaih o naah, qah o pongah, prae ukkung Nehemiah, ca tarikkung hoi qaima Ezra, patukkung, Levinawk mah, kaminawk boih khaeah, Vaihni loe Angraeng na Sithaw han ciimcaihaih niah oh; palungsae o sak hmah loe, qah o hmah, tiah naa o.
10 Nehemiah wí pé, “Ẹ lọ kí ẹ gbádùn oúnjẹ tí ẹ yàn láàyò kí ẹ sì mú ohun dídùn, kí ẹ sì mú díẹ̀ ránṣẹ́ sí àwọn tí kò ní. Ọjọ́ yìí, mímọ́ ni fún Olúwa wa. Ẹ má ṣe banújẹ́, nítorí ayọ̀ Olúwa ni agbára yín.”
Nehemiah mah, Caeh oh loe, caaknaek kahoih to caa oh, kaluep tui to nae oh; caaknaek tawn ai kaminawk han doeh paek oh; vaihni loe aicae Angraeng hanah ciimcaihaih niah oh; palungsae o hmah, Angraeng anghoehaih loe nangcae thacakhaih ah oh, tiah a naa.
11 Àwọn ọmọ Lefi mú kí gbogbo ènìyàn dákẹ́ jẹ́, wọ́n wí pé, “Ẹ dákẹ́, nítorí mímọ́ ni ọjọ́ yìí. Ẹ má ṣe banújẹ́.”
Levinawk mah, Vaihni loe kaciim niah oh pongah, om o duem ah, palungsae o hmah, tiah a naa.
12 Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn lọ láti jẹ àti láti mu, wọ́n sì fi ìpín oúnjẹ ránṣẹ́, wọ́n sì ṣe àjọyọ̀ pẹ̀lú ayọ̀ ńlá, nítorí báyìí àwọn òfin tí a sọ di mímọ́ fun wọn ti yé wọn.
Nihcae khaeah thuih pae ih lok to thaikop o pongah, kaminawk boih mah caak naek o, caaknaek tawn ai kaminawk han doeh caaknaek to paek o moe, kanawm ah poih to sak o.
13 Ní ọjọ́ kejì oṣù náà, àwọn olórí, gbogbo ìdílé, àti àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, péjọ sọ́dọ̀ Esra akọ̀wé, wọ́n fi ara balẹ̀ láti fetí sí àwọn ọ̀rọ̀ òfin.
Ni hnetto haih naah loe, kaalok amtuk hanah, acaeng ukkungnawk, qaimanawk hoi Levinawk boih ca tarikkung Ezra khaeah amkhueng o.
14 Wọ́n ri ní àkọsílẹ̀ nínú ìwé òfin, èyí tí Olúwa ti pa ní àṣẹ nípasẹ̀ Mose, kí àwọn ọmọ Israẹli gbé inú àgọ́ ní àkókò àjọ àgọ́ oṣù keje
To naah Israelnawk loe khrah sarihto haih poih sak naah impoem tetta thungah oh han angaih, tiah Angraeng mah Mosi khaeah paek ih kaalok cabu thungah tarik ih lok to a hnuk o.
15 àti kí wọn kéde ọ̀rọ̀ yìí, kí wọn sì tàn án kálẹ̀ ní gbogbo ìlú wọn àti ní Jerusalẹmu: “Ẹ jáde lọ sí ìlú olókè, kí ẹ mú àwọn ẹ̀ka inú olifi àti ẹ̀ka igi olifi igbó, àti láti inú maritili, àwọn imọ̀ ọ̀pẹ àti àwọn igi tí ó léwé dáradára wá, láti ṣe àgọ́”—gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́.
To lok to thaih o naah, cabu thung ih lok baktih toengah, impoem ta sak hanah, mae nuiah caeh oh loe, olive thing tanghang, hmaica thing tanghang, myrtle thing tanghang, ungsikung baktih kaom thing tanghangnawk hoi aqam kathah thing tanghangnawk to sin oh, tiah Jerusalem hoi angmacae ih vangpuinawk boih ah taphong o.
16 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn jáde lọ, wọ́n sì mú àwọn ẹ̀ka wá, wọ́n sì kọ́ àgọ́ fún ara wọn sí orí òrùlé ara wọn, ní àgbàlá wọn àti ní àgbàlá ilé Ọlọ́run àti ní ìta gbangba lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹnu ibodè omi àti èyí tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹnu ibodè Efraimu.
To pongah kaminawk loe caeh o moe, thing tanghangnawk to sin o; imphu nuiah maw, to tih ai boeh loe angmacae im longhma, Sithaw im longhma, tuipuek khongkha longhma hoi Ephraim khongkha longhmaa ah impoem ta to a sak o.
17 Gbogbo ìjọ ènìyàn tí wọ́n padà láti ìgbèkùn kọ́ àgọ́, wọ́n sì ń gbé inú wọn. Láti ọjọ́ Jeṣua ọmọ Nuni títí di ọjọ́ náà, àwọn ọmọ Israẹli kò tí ì ṣe àjọyọ̀ ọ rẹ̀ bí irú èyí. Ayọ̀ ọ wọn sì pọ̀.
Misong hoi amlaem let kaminawk boih, impoem ta to sak o moe, a thungah anghnut o; Nun capa Joshua ih adungh hoi kamtong vaihni ni khoek to Israel caanawk mah to tiah sah o vai ai vop. Nihcae loe paroeai anghoehaih tawnh o.
18 Esra kà nínú ìwé òfin Ọlọ́run, bí ọjọ́ ṣe ń gorí ọjọ́, láti ọjọ́ kìn-ín-ní dé ọjọ́ ìkẹyìn. Wọ́n ṣe àjọyọ̀ àjọ náà fún ọjọ́ méje, ní ọjọ́ kẹjọ wọ́n ní àpéjọ, ní ìbámu pẹ̀lú òfin.
Amtong tangsuekhaih ni hoi boenghaih ni khoek to nito pacoeng nito, Ezara mah Sithaw ih kaalok to kroek pae. Nihcae mah to poih to ni sarihto thung patoh o; ni tazetto naah loe, angmacae khosakhaih atawk baktiah, nawnto amkhuenghaih to a sak o.

< Nehemiah 8 >