< Nehemiah 7 >

1 Lẹ́yìn ìgbà tí a tún odi mọ tán tí mo sì ri àwọn ìlẹ̀kùn sí ààyè wọn, a sì yan àwọn aṣọ́bodè, àwọn akọrin àti àwọn Lefi.
Y fue, que como el muro fue edificado, y asenté las puertas, y fueron señalados porteros, y cantores, y Levitas,
2 Mo fún Hanani arákùnrin mi pẹ̀lú Hananiah olórí ilé ìṣọ́ ní àṣẹ lórí Jerusalẹmu, nítorí tí ó jẹ́ ènìyàn olóòtítọ́, ó sì bẹ̀rù Ọlọ́run jù bí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ti ṣe lọ.
Mandé a Janani mi hermano, y a Jananías príncipe del palacio en Jerusalem: porque este era, como varón de verdad y temeroso de Dios, sobre muchos:
3 Mo sọ fún wọn pé, “A kò gbọdọ̀ ṣí ìlẹ̀kùn Jerusalẹmu títí oòrùn yóò fi mú. Nígbà tí àwọn aṣọ́bodè bá sì wà lẹ́nu iṣẹ́, jẹ́ kí wọn ti ìlẹ̀kùn kí wọn sì há wọn. Bákan náà, yàn nínú àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́. Àwọn mìíràn níbi tí a pín wọn sí àti àwọn mìíràn ní tòsí ilé e wọn.”
Y díjeles: No se abran las puertas de Jerusalem hasta que el sol caliente: y aun ellos presentes, cierren las puertas, y atrancád. Y señalé guardias de los moradores de Jerusalem, cada uno en su guardia, y cada uno delante de su casa.
4 Ìlú náà tóbi ó sì ní ààyè, ṣùgbọ́n ènìyàn inú rẹ̀ kéré, a kò sì tí ì tún àwọn ilé inú rẹ̀ kọ́.
Y la ciudad era ancha de espacio y grande, y poco pueblo dentro de ella; que no había aun casas edificadas.
5 Nígbà náà ni Ọlọ́run mi fi sí mi ní ọkàn láti kó àwọn ọlọ́lá, àwọn ìjòyè, àti àwọn ènìyàn jọ fún ìforúkọsílẹ̀ ní ìdílé ìdílé. Mo rí ìwé àkọsílẹ̀ ìtàn ìran àwọn tí ó kọ́ gòkè padà wá láti ìgbèkùn. Èyí ni ohun tí mo rí tí a kọ sínú ìwé náà.
Mas puso Dios en mi corazón que juntase los principales, y los magistrados, y el pueblo, para que fuesen empadronados por el orden de los linajes; y hallé el libro de la genealogía de los que habían subido antes, y hallé escrito en él:
6 Èyí ni àwọn ènìyàn agbègbè náà tí wọ́n sọ̀kalẹ̀ wá láti ìgbèkùn, àwọn tí Nebukadnessari ọba Babeli ti kó ní ìgbèkùn (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú u rẹ̀.
Estos son los hijos de la provincia, que subieron de la cautividad de la transmigración, que hizo pasar Nabucodonosor rey de Babilonia, los cuales volvieron a Jerusalem y a Judá, cada uno a su ciudad.
7 Wọ́n jọ rìn wá pẹ̀lú u Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Asariah, Raamiah, Nahamani, Mordekai, Bilṣani, Misperi, Bigfai, Nehumu, àti Baanah). Àkọsílẹ̀ orúkọ àwọn ọkùnrin Israẹli,
Los cuales vinieron con Zorobabel, Jesuá, Nehemías, Azarías, Raamías, Nahamani, Mardoqueo, Bilsán, Misperet, Biguai, Nehum, Baana. La cuenta de los varones del pueblo de Israel:
8 àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
Los hijos de Faros, dos mil y ciento y setenta y dos.
9 Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
Los hijos de Safatías, trescientos y setenta y dos.
10 Arah jẹ́ ẹgbẹ̀tàléláàádọ́ta ó lé méjì
Los hijos de Area, seiscientos y cincuenta y dos.
11 Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìnlá ó lé méjìdínlógún
Los hijos de Pahat-moab, de los hijos de Jesuá, y de Joab, dos mil y ochocientos y diez y ocho.
12 Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
Los hijos de Elam, mil y doscientos y cincuenta y cuatro.
13 Sattu jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
Los hijos de Zattu, ochocientos y cuarenta y cinco.
14 Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
Los hijos de Zecai, setecientos y sesenta.
15 Binnui jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́jọ
Los hijos de Binui, seiscientos y cuarenta y ocho.
16 Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé méjìdínlọ́gbọ̀n
Los hijos de Bebai, seiscientos y veinte y ocho.
17 Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó dín méjìdínlọ́gọ́rin
Los hijos de Azgad, dos mil y seiscientos y veinte y dos.
18 Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méje
Los hijos de Adonicam, seiscientos y sesenta y siete.
19 Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́tàdínláàádọ́rin
Los hijos de Biguai, dos mil y sesenta y siete.
20 Adini jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé márùn-ún
Los hijos de Addín, seiscientos y cincuenta y cinco.
21 Ateri (láti ipasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́rùn-ún
Los hijos de Ater, de Ezequías, noventa y ocho.
22 Haṣumu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó ó lé mẹ́jọ
Los hijos de Hasum, trescientos y veinte y ocho.
23 Besai jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó ó lé mẹ́rin
Los hijos de Besaí, trescientos y veinte y cuatro.
24 Harifu jẹ́ méjìléláàádọ́fà
Los hijos de Harif, ciento y doce.
25 Gibeoni jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
Los hijos de Gabaón, noventa y cinco.
26 Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu àti Netofa jẹ́ igba ó dín méjìlélógún
Los varones de Belén y de Netofa, ciento y ochenta y ocho.
27 Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
Los varones de Anatot, ciento y veinte y ocho.
28 Beti-Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
Los varones de Bet-azmavet, cuarenta y dos.
29 Kiriati-Jearimu, Kefira, àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
Los varones de Cariat-jarim, Quefira y Beerot, setecientos y cuarenta y tres.
30 Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
Los varones de Rama y de Gabaa, seiscientos y veinte y uno.
31 Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
Los varones de Macmas, ciento y veinte y dos.
32 Beteli àti Ai jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
Los varones de Bet-el y de Ai, ciento y veinte y tres.
33 Nebo mìíràn jẹ́ méjìléláàádọ́ta
Los varones de la otra Nebo, cincuenta y dos.
34 Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
Los hijos de la otra Elam, mil y doscientos y cincuenta y cuatro.
35 Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó
Los hijos de Harim, trescientos y veinte.
36 Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún.
Los hijos de Jericó, trescientos y cuarenta y cinco.
37 Lodi, Hadidi, àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé ọ̀kan
Los hijos de Lod, Hadid, y de Ono, siete cientos y veinte y uno.
38 Senaa jẹ́ ẹgbàajì ó dín àádọ́rin.
Los hijos de Senaa, tres mil y novecientos y treinta.
39 Àwọn àlùfáà: àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
Sacerdotes: Los hijos de Jedaias de la casa de Jesuá, novecientos y setenta y tres.
40 Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
Los hijos de Immer, mil y cincuenta y dos.
41 Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
Los hijos de Fasur, mil y doscientos y cuarenta y siete.
42 Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
Los hijos de Harim, mil y diez y siete.
43 Àwọn ọmọ Lefi: àwọn ọmọ Jeṣua (láti ipasẹ̀ Kadmieli, láti ipasẹ̀ Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
Levitas: Los hijos de Jesuá, de Cadmiel, de los hijos de Odvia, setenta y cuatro.
44 Àwọn akọrin: àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádọ́jọ.
Cantores: Los hijos de Asaf, ciento y cuarenta y ocho.
45 Àwọn aṣọ́nà: àwọn ọmọ Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita, àti Ṣobai jẹ́ méjìdínlógóje.
Porteros: Los hijos de Sellum, los hijos de Ater, los hijos de Talmón, los hijos de Accub, los hijos de Hatita, los hijos de Sobai, ciento y treinta y ocho.
46 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ Siha, Hasufa, Tabboati,
Natineos: Los hijos de Siha, los hijos de Hasufa, los hijos de Tabaot,
47 Kerosi, Sia, Padoni,
Los hijos de Ceros, los hijos de Sea, los hijos de Padón,
48 Lebana, Hagaba, Ṣalmai,
Los hijos de Lebana, los hijos de Hagaba, los hijos de Salmai,
49 Hanani, Giddeli, Gahari,
Los hijos de Hanán, los hijos de Giddel, los hijos de Gahar,
50 Reaiah, Resini, Nekoda,
Los hijos de Reaia, los hijos de Resín, los hijos de Necoda,
51 Gassamu, Ussa, Pasea,
Los hijos de Gazzam, los hijos de Uzza, los hijos de Fasea,
52 Besai, Mehuni, Nefisimu,
Los hijos de Besai, los hijos de Meunim, los hijos de Nefisesim,
53 Bakbu, Hakufa, Harhuri,
Los hijos de Bacbuc, los hijos de Hacufa, los hijos de Harur,
54 Basluti, Mehida, Harṣa,
Los hijos de Baslit, los hijos de Mehida, los hijos de Harsa,
55 Barkosi, Sisera, Tema,
Los hijos de Barcos, los hijos de Sísera, los hijos de Tama,
56 Nesia, àti Hatifa.
Los hijos de Nesia, los hijos de Hatifa.
57 Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni: àwọn ọmọ Sotai, Sofereti; Perida,
Los hijos de los siervos de Salomón: los hijos de Sotai, los hijos de Soforet, los hijos de Perida,
58 Jaala, Darkoni, Giddeli,
Los hijos de Jaala, los hijos de Darcón, los hijos de Giddel,
59 Ṣefatia, Hattili, Pokereti-Haṣṣebaimu, àti Amoni.
Los hijos de Safatías, los hijos de Hatil, los hijos de Poqueret de Hasbaim, los hijos de Amón.
60 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
Todos los Natineos, e hijos de los siervos de Salomón, trescientos y noventa y dos.
61 Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
Y estos son los que subieron de Tel-mela, Tel-harsa, Querub, Addón, e Immer, los cuales no pudieron mostrar la casa de sus padres, y su linaje, si eran de Israel:
62 Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
Los hijos de Delaia, los hijos de Tobías, los hijos de Necoda, seiscientos y cuarenta y dos.
63 Lára àwọn àlùfáà ni: àwọn ọmọ Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi, ẹni tí a ń fi orúkọ yìí pè).
Y de los sacerdotes: los hijos de Hobaias, los hijos de Haccos, los hijos de Berzellai, que tomó mujer de las hijas de Berzellai Galaadita, y se llamó del nombre de ellas.
64 Àwọn wọ̀nyí wá àkọsílẹ̀ orúkọ ìran wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí í níbẹ̀, fún ìdí èyí, a yọ wọ́n kúrò nínú àwọn tí ń ṣiṣẹ́ àlùfáà gẹ́gẹ́ bí aláìmọ́.
Estos buscaron su escritura de genealogías, y no fueron hallados, y fueron echados del sacerdocio.
65 Baálẹ̀ sọ fún wọn nítorí náà pé wọn kò gbọdọ̀ kópa nínú jíjẹ oúnjẹ mímọ́ títí tí àlùfáà tí yóò wá tí ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu yóò fi dé.
Y díjoles el Tirsata, que no comiesen de la santidad de las santidades, hasta que hubiese sacerdote con Urim y Tumim.
66 Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó,
Toda la congregación como un varón, fueron cuarenta y dos mil y trescientos y sesenta,
67 yàtọ̀ sí àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin tí wọ́n jẹ́ ẹgbẹ̀ta dín lẹ́gbàárin ó dín ẹ̀tàlélọ́gọ́ta; wọ́n sì tún ní àwọn akọrin ọkùnrin àti obìnrin tí wọ́n jẹ́ òjìlúgba ó lé márùn-ún.
Sin sus siervos y siervas, los cuales eran siete mil y trescientos y treinta y siete: y entre ellos había cantores y cantoras, doscientos y cuarenta y cinco.
68 Ẹṣin wọn jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin, ìbákasẹ wọn jẹ́ òjìlúgba ó dín márùn-ún;
Sus caballos, siete cientos y treinta y seis: sus mulos, doscientos y cuarenta y cinco:
69 ìbákasẹ wọn jẹ́ òjìlénírinwó ó dín márùn-ún; kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọ́n jẹ́ ẹgbẹ̀rìnlélọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
Camellos, cuatrocientos y treinta y cinco: asnos, seis mil y siete cientos y veinte.
70 Díẹ̀ lára àwọn olórí ìdílé náà kópa nínú ṣíṣe iṣẹ́ náà. Baálẹ̀ fún ilé ìṣúra ní ẹgbẹ̀rún dariki wúrà, àádọ́ta àwo koto àti ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀ta lé mẹ́wàá ẹ̀wù fún àwọn àlùfáà.
Y algunos de los príncipes de las familias dieron para la obra: el Tirsata dio para el tesoro mil dracmas de oro; tazones cincuenta; vestimentos sacerdotales quinientos y treinta.
71 Díẹ̀ lára àwọn olórí ìdílé fún ilé ìṣúra ní ogún ẹgbẹ̀rún dariki wúrà àti ẹgbọ̀kànlá mina fàdákà.
Y de los príncipes de las familias dieron para el tesoro de la obra veinte mil dracmas de oro, y dos mil y doscientas libras de plata.
72 Àròpọ̀ gbogbo ohun tí àwọn ènìyàn tókù fi sílẹ̀ jẹ́ ogún ẹgbẹ̀rún dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún méjì mina fàdákà àti ẹẹ́tàdínláàdọ́rin ẹ̀wù fún àwọn àlùfáà.
Y lo que dio el resto del pueblo fue veinte mil dracmas de oro, y dos mil libras de plata, y vestiduras sacerdotales sesenta y siete.
73 Àwọn àlùfáà, àwọn Lefi, àwọn aṣọ́bodè, àwọn akọrin, àwọn ènìyàn díẹ̀, àwọn ìránṣẹ́ ilé Ọlọ́run, àti gbogbo ènìyàn Israẹli wà ní ìlú wọn. Nígbà tí ó di oṣù keje, tí àwọn ọmọ Israẹli sì ti wà nínú ìlú u wọn,
Y habitaron los sacerdotes y los Levitas, y los porteros, y los cantores, y los del pueblo, y los Natineos, y todo Israel, en sus ciudades: y venido el mes séptimo, los hijos de Israel estaban en sus ciudades.

< Nehemiah 7 >