< Nehemiah 7 >

1 Lẹ́yìn ìgbà tí a tún odi mọ tán tí mo sì ri àwọn ìlẹ̀kùn sí ààyè wọn, a sì yan àwọn aṣọ́bodè, àwọn akọrin àti àwọn Lefi.
Und es geschah, als die Mauer gebaut war, da setzte ich die Türflügel ein; und die Torhüter und die Sänger und die Leviten wurden bestellt.
2 Mo fún Hanani arákùnrin mi pẹ̀lú Hananiah olórí ilé ìṣọ́ ní àṣẹ lórí Jerusalẹmu, nítorí tí ó jẹ́ ènìyàn olóòtítọ́, ó sì bẹ̀rù Ọlọ́run jù bí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ti ṣe lọ.
Und ich beorderte über Jerusalem meinen Bruder Hanani und Hananja, den Obersten der Burg; denn er war ein sehr treuer Mann und gottesfürchtig vor vielen.
3 Mo sọ fún wọn pé, “A kò gbọdọ̀ ṣí ìlẹ̀kùn Jerusalẹmu títí oòrùn yóò fi mú. Nígbà tí àwọn aṣọ́bodè bá sì wà lẹ́nu iṣẹ́, jẹ́ kí wọn ti ìlẹ̀kùn kí wọn sì há wọn. Bákan náà, yàn nínú àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́. Àwọn mìíràn níbi tí a pín wọn sí àti àwọn mìíràn ní tòsí ilé e wọn.”
Und ich sprach zu ihnen: Die Tore Jerusalems sollen nicht eher geöffnet werden, als bis die Sonne heiß scheint; und während sie noch dastehen, soll man die Türflügel zumachen, und verschließet sie. Und ihr sollt Wachen aus den Bewohnern Jerusalems aufstellen, den einen auf seine Wache und den anderen vor sein Haus.
4 Ìlú náà tóbi ó sì ní ààyè, ṣùgbọ́n ènìyàn inú rẹ̀ kéré, a kò sì tí ì tún àwọn ilé inú rẹ̀ kọ́.
Die Stadt aber war geräumig und groß, und das Volk darin spärlich, und keine Häuser waren gebaut.
5 Nígbà náà ni Ọlọ́run mi fi sí mi ní ọkàn láti kó àwọn ọlọ́lá, àwọn ìjòyè, àti àwọn ènìyàn jọ fún ìforúkọsílẹ̀ ní ìdílé ìdílé. Mo rí ìwé àkọsílẹ̀ ìtàn ìran àwọn tí ó kọ́ gòkè padà wá láti ìgbèkùn. Èyí ni ohun tí mo rí tí a kọ sínú ìwé náà.
Und mein Gott gab mir ins Herz, die Edlen und die Vorsteher und das Volk zu versammeln, um sie nach den Geschlechtern zu verzeichnen. Und ich fand das Geschlechtsverzeichnis derer, die zuerst heraufgezogen waren, und fand darin geschrieben:
6 Èyí ni àwọn ènìyàn agbègbè náà tí wọ́n sọ̀kalẹ̀ wá láti ìgbèkùn, àwọn tí Nebukadnessari ọba Babeli ti kó ní ìgbèkùn (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú u rẹ̀.
Dies sind die Kinder der Landschaft Juda, welche aus der Gefangenschaft der Weggeführten, die Nebukadnezar, der König von Babel, weggeführt hatte, hinaufzogen, und die nach Jerusalem und Juda zurückkehrten, ein jeder in seine Stadt,
7 Wọ́n jọ rìn wá pẹ̀lú u Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Asariah, Raamiah, Nahamani, Mordekai, Bilṣani, Misperi, Bigfai, Nehumu, àti Baanah). Àkọsílẹ̀ orúkọ àwọn ọkùnrin Israẹli,
welche kamen mit Serubbabel, Jeschua, Nehemia, Asarja, Raamja, Nachamani, Mordokai, Bilschan, Mispereth, Bigwai, Nechum, Baana. Zahl der Männer des Volkes Israel:
8 àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
Die Söhne Parhosch', zweitausend einhundertzweiundsiebzig;
9 Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
die Söhne Schephatjas, dreihundertzweiundsiebzig;
10 Arah jẹ́ ẹgbẹ̀tàléláàádọ́ta ó lé méjì
die Söhne Arachs, sechshundertzweiundfünfzig;
11 Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìnlá ó lé méjìdínlógún
die Söhne Pachath-Moabs, von den Söhnen Jeschuas und Joabs, zweitausend achthundertachtzehn;
12 Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
die Söhne Elams, tausend zweihundertvierundfünfzig;
13 Sattu jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
die Söhne Sattus, achthundertfünfundvierzig;
14 Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
die Söhne Sakkais, siebenhundertsechzig;
15 Binnui jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́jọ
die Söhne Binnuis, sechshundertachtundvierzig;
16 Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé méjìdínlọ́gbọ̀n
die Söhne Bebais, sechshundertachtundzwanzig;
17 Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó dín méjìdínlọ́gọ́rin
die Söhne Asgads, zweitausend dreihundertzweiundzwanzig;
18 Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méje
die Söhne Adonikams, sechshundertsiebenundsechzig;
19 Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́tàdínláàádọ́rin
die Söhne Bigwais, zweitausend siebenundsechzig;
20 Adini jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé márùn-ún
die Söhne Adins, sechshundertfünfundfünfzig;
21 Ateri (láti ipasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́rùn-ún
die Söhne Aters, von Hiskia, achtundneunzig;
22 Haṣumu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó ó lé mẹ́jọ
die Söhne Haschums, dreihundertachtundzwanzig;
23 Besai jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó ó lé mẹ́rin
die Söhne Bezais, dreihundertvierundzwanzig;
24 Harifu jẹ́ méjìléláàádọ́fà
die Söhne Hariphs, hundertzwölf;
25 Gibeoni jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
die Söhne Gibeons, fünfundneunzig;
26 Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu àti Netofa jẹ́ igba ó dín méjìlélógún
die Männer von Bethlehem und Netopha, hundertachtundachtzig;
27 Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
die Männer von Anathoth, hundertachtundzwanzig;
28 Beti-Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
die Männer von Beth-Asmaweth, zweiundvierzig;
29 Kiriati-Jearimu, Kefira, àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
die Männer von Kirjath-Jearim, Kephira und Beeroth, siebenhundertdreiundvierzig;
30 Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
die Männer von Rama und Geba, sechshunderteinundzwanzig;
31 Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
die Männer von Mikmas, hundertzweiundzwanzig;
32 Beteli àti Ai jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
die Männer von Bethel und Ai, hundertdreiundzwanzig;
33 Nebo mìíràn jẹ́ méjìléláàádọ́ta
die Männer von dem anderen Nebo, zweiundfünfzig;
34 Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
die Söhne des anderen Elam, tausend zweihundertvierundfünfzig;
35 Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó
die Söhne Harims, dreihundertzwanzig;
36 Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún.
die Söhne Jerechos, dreihundertfünfundvierzig;
37 Lodi, Hadidi, àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé ọ̀kan
die Söhne Lods, Hadids und Onos, siebenhunderteinundzwanzig;
38 Senaa jẹ́ ẹgbàajì ó dín àádọ́rin.
die Söhne Senaas, dreitausend neunhundertdreißig.
39 Àwọn àlùfáà: àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
Die Priester: die Söhne Jedajas, vom Hause Jeschuas, neunhundertdreiundsiebzig;
40 Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
die Söhne Immers, tausend und zweiundfünfzig;
41 Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
die Söhne Paschchurs, tausend zweihundertsiebenundvierzig;
42 Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
die Söhne Harims, tausend und siebzehn.
43 Àwọn ọmọ Lefi: àwọn ọmọ Jeṣua (láti ipasẹ̀ Kadmieli, láti ipasẹ̀ Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
Die Leviten: die Söhne Jeschuas und Kadmiels, von den Söhnen Hodwas, vierundsiebzig. -
44 Àwọn akọrin: àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádọ́jọ.
Die Sänger: die Söhne Asaphs, hundertachtundvierzig. -
45 Àwọn aṣọ́nà: àwọn ọmọ Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita, àti Ṣobai jẹ́ méjìdínlógóje.
Die Torhüter: die Söhne Schallums, die Söhne Aters, die Söhne Talmons, die Söhne Akkubs, die Söhne Hatitas, die Söhne Schobais, hundertachtunddreißig.
46 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ Siha, Hasufa, Tabboati,
Die Nethinim: die Söhne Zichas, die Söhne Hasuphas, die Söhne Tabbaoths,
47 Kerosi, Sia, Padoni,
die Söhne Keros', die Söhne Sias, die Söhne Padons,
48 Lebana, Hagaba, Ṣalmai,
die Söhne Lebanas, die Söhne Hagabas, die Söhne Salmais,
49 Hanani, Giddeli, Gahari,
die Söhne Hanans, die Söhne Giddels, die Söhne Gachars,
50 Reaiah, Resini, Nekoda,
die Söhne Reajas, die Söhne Rezins, die Söhne Nekodas,
51 Gassamu, Ussa, Pasea,
die Söhne Gassams, die Söhne Ussas, die Söhne Paseachs,
52 Besai, Mehuni, Nefisimu,
die Söhne Besais, die Söhne der Meunim, die Söhne der Nephisim,
53 Bakbu, Hakufa, Harhuri,
die Söhne Bakbuks, die Söhne Hakuphas, die Söhne Harchurs,
54 Basluti, Mehida, Harṣa,
die Söhne Bazluths, die Söhne Mechidas, die Söhne Harschas,
55 Barkosi, Sisera, Tema,
die Söhne Barkos', die Söhne Siseras, die Söhne Tamachs,
56 Nesia, àti Hatifa.
die Söhne Neziachs, die Söhne Hatiphas.
57 Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni: àwọn ọmọ Sotai, Sofereti; Perida,
Die Söhne der Knechte Salomos: die Söhne Sotais, die Söhne Sophereths, die Söhne Peridas,
58 Jaala, Darkoni, Giddeli,
die Söhne Jaalas, die Söhne Darkons, die Söhne Giddels,
59 Ṣefatia, Hattili, Pokereti-Haṣṣebaimu, àti Amoni.
die Söhne Schephatjas, die Söhne Hattils, die Söhne Pokereths-Hazzebaim, die Söhne Amons.
60 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
Alle Nethinim und Söhne der Knechte Salomos: dreihundertzweiundneunzig.
61 Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
Und diese sind es, die aus Tel-Melach, Tel-Harscha, Kerub, Addon und Immer hinaufzogen; aber sie konnten ihr Vaterhaus und ihre Abkunft nicht angeben, ob sie aus Israel wären:
62 Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
die Söhne Delajas, die Söhne Tobijas, die Söhne Nekodas, sechshundertzweiundvierzig.
63 Lára àwọn àlùfáà ni: àwọn ọmọ Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi, ẹni tí a ń fi orúkọ yìí pè).
Und von den Priestern: die Söhne Habajas, die Söhne Hakkoz', die Söhne Barsillais, der ein Weib von den Töchtern Barsillais, des Gileaditers, genommen hatte und nach ihrem Namen genannt wurde.
64 Àwọn wọ̀nyí wá àkọsílẹ̀ orúkọ ìran wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí í níbẹ̀, fún ìdí èyí, a yọ wọ́n kúrò nínú àwọn tí ń ṣiṣẹ́ àlùfáà gẹ́gẹ́ bí aláìmọ́.
Diese suchten ihr Geschlechtsregisterverzeichnis, aber es wurde nicht gefunden; und sie wurden von dem Priestertum als unrein ausgeschlossen.
65 Baálẹ̀ sọ fún wọn nítorí náà pé wọn kò gbọdọ̀ kópa nínú jíjẹ oúnjẹ mímọ́ títí tí àlùfáà tí yóò wá tí ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu yóò fi dé.
Und der Tirsatha sprach zu ihnen, daß sie von dem Hochheiligen nicht essen dürften, bis ein Priester für die Urim und die Thummim aufstände.
66 Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó,
Die ganze Versammlung insgesamt war zweiundvierzigtausend dreihundertundsechzig,
67 yàtọ̀ sí àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin tí wọ́n jẹ́ ẹgbẹ̀ta dín lẹ́gbàárin ó dín ẹ̀tàlélọ́gọ́ta; wọ́n sì tún ní àwọn akọrin ọkùnrin àti obìnrin tí wọ́n jẹ́ òjìlúgba ó lé márùn-ún.
außer ihren Knechten und ihren Mägden; dieser waren siebentausend dreihundertsiebenunddreißig. Und sie hatten zweihundertfünfundvierzig Sänger und Sängerinnen.
68 Ẹṣin wọn jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin, ìbákasẹ wọn jẹ́ òjìlúgba ó dín márùn-ún;
Ihrer Rosse waren siebenhundertsechsunddreißig, ihrer Maultiere zweihundertfünfundvierzig,
69 ìbákasẹ wọn jẹ́ òjìlénírinwó ó dín márùn-ún; kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọ́n jẹ́ ẹgbẹ̀rìnlélọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
der Kamele vierhundertfünfunddreißig, der Esel sechstausend siebenhundertzwanzig.
70 Díẹ̀ lára àwọn olórí ìdílé náà kópa nínú ṣíṣe iṣẹ́ náà. Baálẹ̀ fún ilé ìṣúra ní ẹgbẹ̀rún dariki wúrà, àádọ́ta àwo koto àti ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀ta lé mẹ́wàá ẹ̀wù fún àwọn àlùfáà.
Und ein Teil der Häupter der Väter gab zum Werke. Der Tirsatha gab für den Schatz: an Gold tausend Dariken, fünfzig Sprengschalen, fünfhundertdreißig Priesterleibröcke.
71 Díẹ̀ lára àwọn olórí ìdílé fún ilé ìṣúra ní ogún ẹgbẹ̀rún dariki wúrà àti ẹgbọ̀kànlá mina fàdákà.
Und einige von den Häuptern der Väter gaben für den Schatz des Werkes: an Gold zwanzigtausend Dariken, und an Silber zweitausend zweihundert Minen.
72 Àròpọ̀ gbogbo ohun tí àwọn ènìyàn tókù fi sílẹ̀ jẹ́ ogún ẹgbẹ̀rún dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún méjì mina fàdákà àti ẹẹ́tàdínláàdọ́rin ẹ̀wù fún àwọn àlùfáà.
Und was das übrige Volk gab, war an Gold zwanzigtausend Dariken, und an Silber zweitausend Minen, und siebenundsechzig Priesterleibröcke.
73 Àwọn àlùfáà, àwọn Lefi, àwọn aṣọ́bodè, àwọn akọrin, àwọn ènìyàn díẹ̀, àwọn ìránṣẹ́ ilé Ọlọ́run, àti gbogbo ènìyàn Israẹli wà ní ìlú wọn. Nígbà tí ó di oṣù keje, tí àwọn ọmọ Israẹli sì ti wà nínú ìlú u wọn,
Und die Priester und die Leviten und die Torhüter und die Sänger und die aus dem Volke und die Nethinim und ganz Israel wohnten in ihren Städten.

< Nehemiah 7 >