< Nehemiah 7 >

1 Lẹ́yìn ìgbà tí a tún odi mọ tán tí mo sì ri àwọn ìlẹ̀kùn sí ààyè wọn, a sì yan àwọn aṣọ́bodè, àwọn akọrin àti àwọn Lefi.
Or, après que la muraille fut rebâtie, et que j'eus mis les portes, et qu'on eut fait une revue des chantres et des Lévites;
2 Mo fún Hanani arákùnrin mi pẹ̀lú Hananiah olórí ilé ìṣọ́ ní àṣẹ lórí Jerusalẹmu, nítorí tí ó jẹ́ ènìyàn olóòtítọ́, ó sì bẹ̀rù Ọlọ́run jù bí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ti ṣe lọ.
Je commandai à Hanani mon frère, et à Hanania capitaine de la forteresse de Jérusalem; car il était tel qu'un homme fidèle [doit] être, et il craignait Dieu plus que plusieurs [autres];
3 Mo sọ fún wọn pé, “A kò gbọdọ̀ ṣí ìlẹ̀kùn Jerusalẹmu títí oòrùn yóò fi mú. Nígbà tí àwọn aṣọ́bodè bá sì wà lẹ́nu iṣẹ́, jẹ́ kí wọn ti ìlẹ̀kùn kí wọn sì há wọn. Bákan náà, yàn nínú àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́. Àwọn mìíràn níbi tí a pín wọn sí àti àwọn mìíràn ní tòsí ilé e wọn.”
Et je leur dis: Que les portes de Jérusalem ne s'ouvrent point jusqu'à la chaleur du soleil; et quand ceux qui se tiendront [là] auront fermé les portes, examinez-[les]: et qu'on pose des gardes d'entre les habitants de Jérusalem, chacun selon sa garde, et chacun vis-à-vis de sa maison.
4 Ìlú náà tóbi ó sì ní ààyè, ṣùgbọ́n ènìyàn inú rẹ̀ kéré, a kò sì tí ì tún àwọn ilé inú rẹ̀ kọ́.
Or la ville était spacieuse et grande, mais il y avait peu de peuple, et ses maisons n'étaient point bâties.
5 Nígbà náà ni Ọlọ́run mi fi sí mi ní ọkàn láti kó àwọn ọlọ́lá, àwọn ìjòyè, àti àwọn ènìyàn jọ fún ìforúkọsílẹ̀ ní ìdílé ìdílé. Mo rí ìwé àkọsílẹ̀ ìtàn ìran àwọn tí ó kọ́ gòkè padà wá láti ìgbèkùn. Èyí ni ohun tí mo rí tí a kọ sínú ìwé náà.
Et mon Dieu me mit au cœur d'assembler les principaux et les magistrats, et le peuple, pour en faire le dénombrement selon leurs généalogies; et je trouvai le registre du dénombrement selon les généalogies de ceux qui étaient montés la première fois; et j'y trouvai ainsi écrit:
6 Èyí ni àwọn ènìyàn agbègbè náà tí wọ́n sọ̀kalẹ̀ wá láti ìgbèkùn, àwọn tí Nebukadnessari ọba Babeli ti kó ní ìgbèkùn (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú u rẹ̀.
Ce sont ici ceux de la Province qui remontèrent de la captivité, d'entre ceux qui avaient été transportés, lesquels Nébuchadnetsar Roi de Babylone avait transportés, et qui retournèrent à Jérusalem et en Judée, chacun en sa ville;
7 Wọ́n jọ rìn wá pẹ̀lú u Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Asariah, Raamiah, Nahamani, Mordekai, Bilṣani, Misperi, Bigfai, Nehumu, àti Baanah). Àkọsílẹ̀ orúkọ àwọn ọkùnrin Israẹli,
Qui vinrent avec Zorobabel, Jésuah, Néhémie, Hazaria, Rahamia, Nahamani, Mardochée, Bisan, Mitspéreth, Begvaï, Néhum, et Bahana; le nombre, [dis-je], des hommes du peuple d'Israël [est tel.]
8 àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
Les enfants de Parhos, deux mille cent soixante et douze.
9 Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
Les enfants de Séphatia, trois cent soixante et douze.
10 Arah jẹ́ ẹgbẹ̀tàléláàádọ́ta ó lé méjì
Les enfants d'Arah, six cent cinquante-deux.
11 Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìnlá ó lé méjìdínlógún
Les enfants de Pahath-Moab, des enfants de Jésuah et de Joab, deux mille huit cent dix-huit.
12 Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
Les enfants de Hélam, mille deux cent cinquante-quatre.
13 Sattu jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
Les enfants de Zattu, huit cent quarante-cinq.
14 Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
Les enfants de Zaccaï, sept cent soixante.
15 Binnui jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́jọ
Les enfants de Binnui, six cent quarante-huit.
16 Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé méjìdínlọ́gbọ̀n
Les enfants de Bébaï, six cent vingt-huit.
17 Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó dín méjìdínlọ́gọ́rin
Les enfants de Hazgad, deux mille trois cent vingt-deux.
18 Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méje
Les enfants d'Adonikam, six cent soixante-sept.
19 Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́tàdínláàádọ́rin
Les enfants de Bigvaï, deux mille soixante-sept.
20 Adini jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé márùn-ún
Les enfants de Hadin, six cent cinquante-cinq.
21 Ateri (láti ipasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́rùn-ún
Les enfants d'Ater, [issu] d'Ezéchias, quatre-vingt-dix-huit.
22 Haṣumu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó ó lé mẹ́jọ
Les enfants de Hasum, trois cent vingt-huit.
23 Besai jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó ó lé mẹ́rin
Les enfants de Betsaï, trois cent vingt-quatre.
24 Harifu jẹ́ méjìléláàádọ́fà
Les enfants de Harib, cent douze.
25 Gibeoni jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
Les enfants de Gabaon, quatre-vingt-quinze.
26 Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu àti Netofa jẹ́ igba ó dín méjìlélógún
Les gens de Bethléhem et de Nétopha, cent quatre-vingt-huit.
27 Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
Les gens d'Hanathoth, cent vingt-huit.
28 Beti-Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
Les gens de Beth-Hazmaveth, quarante-deux.
29 Kiriati-Jearimu, Kefira, àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
Les gens de Kiriath-Jéharim, de Képhira et de Béeroth, sept cent quarante-trois.
30 Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
Les gens de Rama et de Guébah, six cent vingt et un.
31 Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
Les gens de Micmas, cent vingt-deux.
32 Beteli àti Ai jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
Les gens de Béthel, et de Haï, cent vingt-trois.
33 Nebo mìíràn jẹ́ méjìléláàádọ́ta
Les gens de l'autre Nébo, cinquante-deux.
34 Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
Les enfants d'un autre Hélam, mille deux cent cinquante-quatre.
35 Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó
Les enfants de Harim, trois cent vingt.
36 Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún.
Les enfants de Jéricho, trois cent quarante-cinq.
37 Lodi, Hadidi, àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé ọ̀kan
Les enfants de Lod, de Hadid et d'Ono, sept cent vingt et un.
38 Senaa jẹ́ ẹgbàajì ó dín àádọ́rin.
Les enfants de Sénaa, trois mille neuf cent trente.
39 Àwọn àlùfáà: àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
Des Sacrificateurs: Les enfants de Jédahia, de la maison de Jésuah, neuf cent soixante et treize.
40 Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
Les enfants d'Immer, mille cinquante-deux.
41 Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
Les enfants de Pashur, mille deux cent quarante-sept.
42 Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
Les enfants de Harim, mille dix-sept.
43 Àwọn ọmọ Lefi: àwọn ọmọ Jeṣua (láti ipasẹ̀ Kadmieli, láti ipasẹ̀ Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
Des Lévites: Les enfants de Jésuah et de Kadmiel, d'entre les enfants de Hodeva, soixante quatorze.
44 Àwọn akọrin: àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádọ́jọ.
Des chantres: Les enfants d'Asaph, cent quarante-huit.
45 Àwọn aṣọ́nà: àwọn ọmọ Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita, àti Ṣobai jẹ́ méjìdínlógóje.
Des portiers: Les enfants de Sallum, les enfants d'Ater, les enfants de Talmon, les enfants d'Hakkub, les enfantsde Hattita, les enfants de Sobaï, cent trente-huit.
46 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ Siha, Hasufa, Tabboati,
Des Néthiniens: Les enfants de Tsiha, les enfants de Hasupha, les enfants de Tabbahoth,
47 Kerosi, Sia, Padoni,
Les enfants de Kéros, les enfants de Siha, les enfants de Padon,
48 Lebana, Hagaba, Ṣalmai,
Les enfants de Lebana, les enfants de Hagaba, les enfants de Salmaï,
49 Hanani, Giddeli, Gahari,
Les enfants de Hanan, les enfants de Guiddel, les enfants de Gahar,
50 Reaiah, Resini, Nekoda,
Les enfants de Réaja, les enfants de Retsin, les enfants de Nékoda,
51 Gassamu, Ussa, Pasea,
Les enfants de Gazam, les enfants de Huza, les enfants de Paséah,
52 Besai, Mehuni, Nefisimu,
Les enfants de Bésaï, les enfants de Méhunim, les enfants de Néphisésim,
53 Bakbu, Hakufa, Harhuri,
Les enfants de Bakbuk, les enfants de Hakupha, les enfants de Harhur,
54 Basluti, Mehida, Harṣa,
Les enfants de Batslith, les enfants de Méhida, les enfants de Harsa,
55 Barkosi, Sisera, Tema,
Les enfants de Barkos, les enfants de Sisra, les enfants de Témah,
56 Nesia, àti Hatifa.
Les enfants de Netsiah, les enfants de Hatipha.
57 Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni: àwọn ọmọ Sotai, Sofereti; Perida,
Des enfants des serviteurs de Salomon: Les enfants de Sotaï, les enfants de Sophéreth, les enfants de Périda,
58 Jaala, Darkoni, Giddeli,
Les enfants de Jahala, les enfants de Darkon, les enfants de Guiddel,
59 Ṣefatia, Hattili, Pokereti-Haṣṣebaimu, àti Amoni.
Les enfants de Séphatia, les enfants de Hattil, les enfants de Pockereth-Hatsébajim, les enfants d'Amon.
60 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
Tous les Néthiniens, et les enfants des serviteurs de Salomon, étaient trois cent quatre-vingt-douze.
61 Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
Or ce sont ici ceux qui montèrent de Telmelah, de Tel-Harsa, de Kérub, d'Addon et d'Immer, lesquels ne purent montrer la maison de leurs pères, ni leur race, [pour savoir] s'ils étaient d'Israël.
62 Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
Les enfants de Délaja, les enfants de Tobija, les enfants de Nékoda, six cent quarante-deux.
63 Lára àwọn àlùfáà ni: àwọn ọmọ Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi, ẹni tí a ń fi orúkọ yìí pè).
Et des Sacrificateurs: Les enfants de Habaja, les enfants de Kots, les enfants de Barzillaï, qui prit pour femme une des filles de Barzillaï Galaadite, et qui fut appelé de leur nom.
64 Àwọn wọ̀nyí wá àkọsílẹ̀ orúkọ ìran wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí í níbẹ̀, fún ìdí èyí, a yọ wọ́n kúrò nínú àwọn tí ń ṣiṣẹ́ àlùfáà gẹ́gẹ́ bí aláìmọ́.
Ils cherchèrent leur registre en recherchant leur généalogie, mais ils n'y furent point trouvés; c'est pourquoi ils furent exclus de la Sacrificature.
65 Baálẹ̀ sọ fún wọn nítorí náà pé wọn kò gbọdọ̀ kópa nínú jíjẹ oúnjẹ mímọ́ títí tí àlùfáà tí yóò wá tí ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu yóò fi dé.
Et Attirsatha leur dit; qu'ils ne mangeassent point des choses très-saintes, jusqu'à ce que le Sacrificateur assistât avec l'Urim et le Thummim.
66 Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó,
Toute l'assemblée réunie était de quarante-deux mille trois cent soixante;
67 yàtọ̀ sí àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin tí wọ́n jẹ́ ẹgbẹ̀ta dín lẹ́gbàárin ó dín ẹ̀tàlélọ́gọ́ta; wọ́n sì tún ní àwọn akọrin ọkùnrin àti obìnrin tí wọ́n jẹ́ òjìlúgba ó lé márùn-ún.
Sans leurs serviteurs et leurs servantes, qui étaient sept mille trois cent trente-sept; et ils avaient deux cent quarante-cinq chantres ou chanteuses.
68 Ẹṣin wọn jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin, ìbákasẹ wọn jẹ́ òjìlúgba ó dín márùn-ún;
Ils avaient sept cent trente-six chevaux, deux cent quarante-cinq mulets;
69 ìbákasẹ wọn jẹ́ òjìlénírinwó ó dín márùn-ún; kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọ́n jẹ́ ẹgbẹ̀rìnlélọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
Quatre cent trente-cinq chameaux, et six mille sept cent vingt ânes.
70 Díẹ̀ lára àwọn olórí ìdílé náà kópa nínú ṣíṣe iṣẹ́ náà. Baálẹ̀ fún ilé ìṣúra ní ẹgbẹ̀rún dariki wúrà, àádọ́ta àwo koto àti ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀ta lé mẹ́wàá ẹ̀wù fún àwọn àlùfáà.
Or quelques-uns des Chefs des pères contribuèrent pour l'ouvrage. Attirsatha donna au trésor mille drachmes d'or, cinquante bassins, cinq cent trente robes de Sacrificateurs.
71 Díẹ̀ lára àwọn olórí ìdílé fún ilé ìṣúra ní ogún ẹgbẹ̀rún dariki wúrà àti ẹgbọ̀kànlá mina fàdákà.
Et quelques autres d'entre les Chefs des pères donnèrent pour le trésor de l'ouvrage, vingt mille drachmes d'or, et deux mille deux cent mines d'argent.
72 Àròpọ̀ gbogbo ohun tí àwọn ènìyàn tókù fi sílẹ̀ jẹ́ ogún ẹgbẹ̀rún dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún méjì mina fàdákà àti ẹẹ́tàdínláàdọ́rin ẹ̀wù fún àwọn àlùfáà.
Et ce que le reste du peuple donna, fut vingt mille drachmes d'or, et deux mille mines d'argent, et soixante-sept robes de Sacrificateurs.
73 Àwọn àlùfáà, àwọn Lefi, àwọn aṣọ́bodè, àwọn akọrin, àwọn ènìyàn díẹ̀, àwọn ìránṣẹ́ ilé Ọlọ́run, àti gbogbo ènìyàn Israẹli wà ní ìlú wọn. Nígbà tí ó di oṣù keje, tí àwọn ọmọ Israẹli sì ti wà nínú ìlú u wọn,
Et ainsi les Sacrificateurs, les Lévites, les portiers, les chantres, quelques-uns du peuple, les Néthiniens, et tous ceux d'Israël habitèrent dans leurs villes; de sorte que quand le septième mois approcha, les enfants d'Israël étaient dans leurs villes.

< Nehemiah 7 >