< Nehemiah 7 >
1 Lẹ́yìn ìgbà tí a tún odi mọ tán tí mo sì ri àwọn ìlẹ̀kùn sí ààyè wọn, a sì yan àwọn aṣọ́bodè, àwọn akọrin àti àwọn Lefi.
Lorsque la muraille fut construite, que j'eus dressé les portes et que les gardiens des portes, les chantres et les lévites furent désignés,
2 Mo fún Hanani arákùnrin mi pẹ̀lú Hananiah olórí ilé ìṣọ́ ní àṣẹ lórí Jerusalẹmu, nítorí tí ó jẹ́ ènìyàn olóòtítọ́, ó sì bẹ̀rù Ọlọ́run jù bí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ti ṣe lọ.
je confiai à mon frère Hanani et à Hanania, gouverneur de la forteresse, la responsabilité de Jérusalem, car c'était un homme fidèle et qui craignait Dieu plus que quiconque.
3 Mo sọ fún wọn pé, “A kò gbọdọ̀ ṣí ìlẹ̀kùn Jerusalẹmu títí oòrùn yóò fi mú. Nígbà tí àwọn aṣọ́bodè bá sì wà lẹ́nu iṣẹ́, jẹ́ kí wọn ti ìlẹ̀kùn kí wọn sì há wọn. Bákan náà, yàn nínú àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́. Àwọn mìíràn níbi tí a pín wọn sí àti àwọn mìíràn ní tòsí ilé e wọn.”
Je leur dis: « Qu'on n'ouvre pas les portes de Jérusalem avant que le soleil soit chaud; et pendant qu'ils montent la garde, qu'ils ferment les portes, et vous les barrez; et établissez des tours de garde des habitants de Jérusalem, chacun dans son tour de garde, chacun près de sa maison. »
4 Ìlú náà tóbi ó sì ní ààyè, ṣùgbọ́n ènìyàn inú rẹ̀ kéré, a kò sì tí ì tún àwọn ilé inú rẹ̀ kọ́.
Or la ville était large et grande; mais le peuple y était peu nombreux, et les maisons n'étaient pas bâties.
5 Nígbà náà ni Ọlọ́run mi fi sí mi ní ọkàn láti kó àwọn ọlọ́lá, àwọn ìjòyè, àti àwọn ènìyàn jọ fún ìforúkọsílẹ̀ ní ìdílé ìdílé. Mo rí ìwé àkọsílẹ̀ ìtàn ìran àwọn tí ó kọ́ gòkè padà wá láti ìgbèkùn. Èyí ni ohun tí mo rí tí a kọ sínú ìwé náà.
Mon Dieu a mis dans mon cœur de rassembler les nobles, les chefs et le peuple, afin de les classer par généalogie. J'ai trouvé le livre de la généalogie de ceux qui étaient montés les premiers, et j'y ai trouvé ceci écrit:
6 Èyí ni àwọn ènìyàn agbègbè náà tí wọ́n sọ̀kalẹ̀ wá láti ìgbèkùn, àwọn tí Nebukadnessari ọba Babeli ti kó ní ìgbèkùn (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú u rẹ̀.
Ce sont les fils de la province qui sont sortis de la captivité de ceux que Nebucadnetsar, roi de Babylone, avait emmenés, et qui sont revenus à Jérusalem et en Juda, chacun dans sa ville.
7 Wọ́n jọ rìn wá pẹ̀lú u Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Asariah, Raamiah, Nahamani, Mordekai, Bilṣani, Misperi, Bigfai, Nehumu, àti Baanah). Àkọsílẹ̀ orúkọ àwọn ọkùnrin Israẹli,
Ils sont venus avec Zorobabel, Josué, Néhémie, Azaria, Raamia, Nahamani, Mardochée, Bilshan, Mispereth, Bigvaï, Nehum et Baana. Le nombre d'hommes du peuple d'Israël:
8 àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
Fils de Parosh: deux mille cent soixante-douze.
9 Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
Fils de Shephatia: trois cent soixante-douze.
10 Arah jẹ́ ẹgbẹ̀tàléláàádọ́ta ó lé méjì
Fils d'Arach: six cent cinquante-deux.
11 Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìnlá ó lé méjìdínlógún
Fils de Pahathmoab, des fils de Josué et de Joab: deux mille huit cent dix-huit.
12 Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
Fils d'Élam: mille deux cent cinquante-quatre.
13 Sattu jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
Fils de Zattu: huit cent quarante-cinq.
14 Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
Fils de Zaccaï: sept cent soixante.
15 Binnui jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́jọ
Fils de Binnui: six cent quarante-huit.
16 Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé méjìdínlọ́gbọ̀n
Fils de Bébaï: six cent vingt-huit.
17 Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó dín méjìdínlọ́gọ́rin
Fils d'Azgad: deux mille trois cent vingt-deux.
18 Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méje
Fils d'Adonikam: six cent soixante-sept.
19 Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́tàdínláàádọ́rin
Fils de Bigvai: deux mille soixante-sept.
20 Adini jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé márùn-ún
Fils d'Adin: six cent cinquante-cinq.
21 Ateri (láti ipasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́rùn-ún
Fils d'Ater: d'Ézéchias, quatre-vingt-dix-huit.
22 Haṣumu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó ó lé mẹ́jọ
Fils de Haschum: trois cent vingt-huit.
23 Besai jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó ó lé mẹ́rin
Fils de Betsaï: trois cent vingt-quatre.
24 Harifu jẹ́ méjìléláàádọ́fà
Fils de Hariph: cent douze.
25 Gibeoni jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
Fils de Gabaon: quatre-vingt-quinze.
26 Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu àti Netofa jẹ́ igba ó dín méjìlélógún
Hommes de Bethléem et de Netopha: cent quatre-vingt-huit.
27 Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
Hommes d'Anathoth: cent vingt-huit.
28 Beti-Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
Les hommes de Beth Azmaveth: quarante-deux.
29 Kiriati-Jearimu, Kefira, àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
Hommes de Kiriath Jearim, de Chephira et de Beeroth: sept cent quarante-trois.
30 Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
- Les hommes de Rama et de Guéba: six cent vingt et un.
31 Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
Hommes de Michmas: cent vingt-deux.
32 Beteli àti Ai jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
Hommes de Béthel et d'Aï: cent vingt-trois.
33 Nebo mìíràn jẹ́ méjìléláàádọ́ta
Les hommes de l'autre Nebo: cinquante-deux.
34 Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
Fils de l'autre Elam: mille deux cent cinquante-quatre.
35 Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó
Fils de Harim: trois cent vingt.
36 Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún.
Fils de Jéricho: trois cent quarante-cinq.
37 Lodi, Hadidi, àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé ọ̀kan
Fils de Lod, Hadid et Ono: sept cent vingt et un.
38 Senaa jẹ́ ẹgbàajì ó dín àádọ́rin.
Fils de Senaah: trois mille neuf cent trente.
39 Àwọn àlùfáà: àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
Les sacrificateurs: Les fils de Jedaiah, de la maison de Jeshua: neuf cent soixante-treize.
40 Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
Fils d'Immer: mille cinquante-deux.
41 Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
Fils de Pashhur: mille deux cent quarante-sept.
42 Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
Fils de Harim: mille dix-sept.
43 Àwọn ọmọ Lefi: àwọn ọmọ Jeṣua (láti ipasẹ̀ Kadmieli, láti ipasẹ̀ Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
Lévites: les fils de Jéshua, de Kadmiel, des fils de Hodeva: soixante-quatorze.
44 Àwọn akọrin: àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádọ́jọ.
Chantres: les fils d'Asaph, cent quarante-huit.
45 Àwọn aṣọ́nà: àwọn ọmọ Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita, àti Ṣobai jẹ́ méjìdínlógóje.
Gardiens: les fils de Shallum, les fils d'Ater, les fils de Talmon, les fils d'Akkub, les fils de Hatita, les fils de Shobai: cent trente-huit.
46 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ Siha, Hasufa, Tabboati,
Les serviteurs du temple: les enfants de Ziha, les enfants de Hasupha, les enfants de Tabbaoth,
les enfants de Keros, les enfants de Sia, les enfants de Padon,
48 Lebana, Hagaba, Ṣalmai,
les enfants de Lebana, les enfants de Hagaba, les enfants de Salmai,
49 Hanani, Giddeli, Gahari,
les enfants de Hanan, les enfants de Giddel, les enfants de Gahar,
50 Reaiah, Resini, Nekoda,
les enfants de Reaiah, les enfants de Rezin, les enfants de Nekoda,
les enfants de Gazzam, les fils de Uzza, les fils de Paseah,
52 Besai, Mehuni, Nefisimu,
les fils de Besai, les fils de Meunim, les fils de Nephushesim,
53 Bakbu, Hakufa, Harhuri,
les fils de Bakbuk, les fils de Hakupha, les fils de Harhur,
54 Basluti, Mehida, Harṣa,
les fils de Bazlith, les fils de Mehida, les fils de Harsha,
55 Barkosi, Sisera, Tema,
les fils de Barkos, les fils de Sisera, les fils de Temah,
les fils de Neziah, et les fils de Hatipha.
57 Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni: àwọn ọmọ Sotai, Sofereti; Perida,
Fils des serviteurs de Salomon: les fils de Sotai, les fils de Sophereth, les fils de Perida,
58 Jaala, Darkoni, Giddeli,
les fils de Jaala, les fils de Darkon, les fils de Giddel,
59 Ṣefatia, Hattili, Pokereti-Haṣṣebaimu, àti Amoni.
les fils de Shephatia, les fils de Hattil, les fils de Pochereth Hazzebaim, et les fils d'Amon.
60 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
Tous les serviteurs du temple et les fils des serviteurs de Salomon étaient au nombre de trois cent quatre-vingt-douze.
61 Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
Voici ceux qui montèrent de Tel Melah, de Tel Harsha, de Cherub, d'Addon et d'Immer; mais ils ne purent montrer les maisons de leurs pères, ni leurs descendants, pour savoir s'ils étaient d'Israël:
62 Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
Fils de Delaja, fils de Tobija, fils de Nekoda: six cent quarante-deux.
63 Lára àwọn àlùfáà ni: àwọn ọmọ Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi, ẹni tí a ń fi orúkọ yìí pè).
Parmi les sacrificateurs: les fils de Hobaia, les fils de Hakkoz, les fils de Barzillai, qui prit une femme parmi les filles de Barzillai, le Galaadite, et fut appelé de leur nom.
64 Àwọn wọ̀nyí wá àkọsílẹ̀ orúkọ ìran wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí í níbẹ̀, fún ìdí èyí, a yọ wọ́n kúrò nínú àwọn tí ń ṣiṣẹ́ àlùfáà gẹ́gẹ́ bí aláìmọ́.
Ceux-ci ont cherché leurs documents généalogiques, mais ne les ont pas trouvés. Ils furent donc considérés comme disqualifiés et retirés de la prêtrise.
65 Baálẹ̀ sọ fún wọn nítorí náà pé wọn kò gbọdọ̀ kópa nínú jíjẹ oúnjẹ mímọ́ títí tí àlùfáà tí yóò wá tí ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu yóò fi dé.
Le gouverneur leur dit de ne pas manger des choses les plus saintes jusqu'à ce qu'un prêtre se lève pour faire le service avec l'Urim et le Thummim.
66 Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó,
Toute l'assemblée était de quarante-deux mille trois cent soixante personnes,
67 yàtọ̀ sí àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin tí wọ́n jẹ́ ẹgbẹ̀ta dín lẹ́gbàárin ó dín ẹ̀tàlélọ́gọ́ta; wọ́n sì tún ní àwọn akọrin ọkùnrin àti obìnrin tí wọ́n jẹ́ òjìlúgba ó lé márùn-ún.
sans compter leurs serviteurs et leurs servantes, au nombre de sept mille trois cent trente-sept. Ils avaient deux cent quarante-cinq chanteurs et chanteuses.
68 Ẹṣin wọn jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin, ìbákasẹ wọn jẹ́ òjìlúgba ó dín márùn-ún;
Leurs chevaux étaient au nombre de sept cent trente-six; leurs mulets, deux cent quarante-cinq;
69 ìbákasẹ wọn jẹ́ òjìlénírinwó ó dín márùn-ún; kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọ́n jẹ́ ẹgbẹ̀rìnlélọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
leurs chameaux, quatre cent trente-cinq; leurs ânes, six mille sept cent vingt.
70 Díẹ̀ lára àwọn olórí ìdílé náà kópa nínú ṣíṣe iṣẹ́ náà. Baálẹ̀ fún ilé ìṣúra ní ẹgbẹ̀rún dariki wúrà, àádọ́ta àwo koto àti ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀ta lé mẹ́wàá ẹ̀wù fún àwọn àlùfáà.
Quelques-uns, parmi les chefs de famille, contribuèrent à l'œuvre. Le gouverneur donna au trésor mille dariques d'or, cinquante bassins, et cinq cent trente vêtements de prêtres.
71 Díẹ̀ lára àwọn olórí ìdílé fún ilé ìṣúra ní ogún ẹgbẹ̀rún dariki wúrà àti ẹgbọ̀kànlá mina fàdákà.
Des chefs de famille donnèrent au trésor de l'œuvre vingt mille dariques d'or et deux mille deux cents mines d'argent.
72 Àròpọ̀ gbogbo ohun tí àwọn ènìyàn tókù fi sílẹ̀ jẹ́ ogún ẹgbẹ̀rún dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún méjì mina fàdákà àti ẹẹ́tàdínláàdọ́rin ẹ̀wù fún àwọn àlùfáà.
Le reste du peuple donna vingt mille dariques d'or, plus deux mille mines d'argent, et soixante-sept vêtements sacerdotaux.
73 Àwọn àlùfáà, àwọn Lefi, àwọn aṣọ́bodè, àwọn akọrin, àwọn ènìyàn díẹ̀, àwọn ìránṣẹ́ ilé Ọlọ́run, àti gbogbo ènìyàn Israẹli wà ní ìlú wọn. Nígbà tí ó di oṣù keje, tí àwọn ọmọ Israẹli sì ti wà nínú ìlú u wọn,
Ainsi, les prêtres, les lévites, les portiers, les chantres, une partie du peuple, les serviteurs du temple et tout Israël habitaient dans leurs villes. Lorsque le septième mois fut arrivé, les enfants d'Israël étaient dans leurs villes.