< Nehemiah 7 >

1 Lẹ́yìn ìgbà tí a tún odi mọ tán tí mo sì ri àwọn ìlẹ̀kùn sí ààyè wọn, a sì yan àwọn aṣọ́bodè, àwọn akọrin àti àwọn Lefi.
And it was just when it had been rebuilt the wall and I had set up the doors and they had been appointed the gatekeepers and the singers and the Levites.
2 Mo fún Hanani arákùnrin mi pẹ̀lú Hananiah olórí ilé ìṣọ́ ní àṣẹ lórí Jerusalẹmu, nítorí tí ó jẹ́ ènìyàn olóòtítọ́, ó sì bẹ̀rù Ọlọ́run jù bí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ti ṣe lọ.
And I appointed Hanani brother my and Hananiah [the] commander of the citadel over Jerusalem for he [was] like a man of faithfulness and fearing God more than many [people].
3 Mo sọ fún wọn pé, “A kò gbọdọ̀ ṣí ìlẹ̀kùn Jerusalẹmu títí oòrùn yóò fi mú. Nígbà tí àwọn aṣọ́bodè bá sì wà lẹ́nu iṣẹ́, jẹ́ kí wọn ti ìlẹ̀kùn kí wọn sì há wọn. Bákan náà, yàn nínú àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́. Àwọn mìíràn níbi tí a pín wọn sí àti àwọn mìíràn ní tòsí ilé e wọn.”
(And I said *Q(K)*) to them not they will be opened [the] gates of Jerusalem until is hot the sun and until they [are] standing guard let them shut the doors and bolt [them] and appoint guards of [the] inhabitants of Jerusalem someone at guard post his and someone before house his.
4 Ìlú náà tóbi ó sì ní ààyè, ṣùgbọ́n ènìyàn inú rẹ̀ kéré, a kò sì tí ì tún àwọn ilé inú rẹ̀ kọ́.
And the city [was] broad of both hands and large and the people [were] few in [the] midst of it and not houses [were] rebuilt.
5 Nígbà náà ni Ọlọ́run mi fi sí mi ní ọkàn láti kó àwọn ọlọ́lá, àwọn ìjòyè, àti àwọn ènìyàn jọ fún ìforúkọsílẹ̀ ní ìdílé ìdílé. Mo rí ìwé àkọsílẹ̀ ìtàn ìran àwọn tí ó kọ́ gòkè padà wá láti ìgbèkùn. Èyí ni ohun tí mo rí tí a kọ sínú ìwé náà.
And he put God my into heart my and I assembled! the nobles and the officials and the people to have themselves enrolled and I found [the] document of the genealogy the [ones who] came up at the first and I found [was] written in it.
6 Èyí ni àwọn ènìyàn agbègbè náà tí wọ́n sọ̀kalẹ̀ wá láti ìgbèkùn, àwọn tí Nebukadnessari ọba Babeli ti kó ní ìgbèkùn (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú u rẹ̀.
These - [are] [the] children of the province who came up from [the] captivity of the exile[s] whom he had taken into exile Nebuchadnezzar [the] king of Babylon and they returned to Jerusalem and to Judah each one to own city his.
7 Wọ́n jọ rìn wá pẹ̀lú u Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Asariah, Raamiah, Nahamani, Mordekai, Bilṣani, Misperi, Bigfai, Nehumu, àti Baanah). Àkọsílẹ̀ orúkọ àwọn ọkùnrin Israẹli,
Who came with Zerubbabel Jeshua Nehemiah Azariah Raamiah Nahamani Mordecai Bilshan Mispereth Bigvai Nehum Baanah [the] number of [the] men of [the] people of Israel.
8 àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
[the] descendants of Parosh two thousand one hundred and seventy and two.
9 Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
[the] descendants of Shephatiah three hundred seventy and two.
10 Arah jẹ́ ẹgbẹ̀tàléláàádọ́ta ó lé méjì
[the] descendants of Arah six hundred fifty and two.
11 Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìnlá ó lé méjìdínlógún
[the] descendants of Pahath-Moab of [the] descendants of Jeshua and Joab two thousand and eight hundred eight-teen.
12 Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
[the] descendants of Elam one thousand two hundred fifty and four.
13 Sattu jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
[the] descendants of Zattu eight hundred forty and five.
14 Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
[the] descendants of Zaccai seven hundred and sixty.
15 Binnui jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́jọ
[the] descendants of Binnui six hundred forty and eight.
16 Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé méjìdínlọ́gbọ̀n
[the] descendants of Bebai six hundred twenty and eight.
17 Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó dín méjìdínlọ́gọ́rin
[the] descendants of Azgad two thousand three hundred twenty and two.
18 Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méje
[the] descendants of Adonikam six hundred sixty and seven.
19 Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́tàdínláàádọ́rin
[the] descendants of Bigvai two thousand sixty and seven.
20 Adini jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé márùn-ún
[the] descendants of Adin six hundred fifty and five.
21 Ateri (láti ipasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́rùn-ún
[the] descendants of Ater of Hezekiah ninety and eight.
22 Haṣumu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó ó lé mẹ́jọ
[the] descendants of Hashum three hundred twenty and eight.
23 Besai jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó ó lé mẹ́rin
[the] descendants of Bezai three hundred twenty and four.
24 Harifu jẹ́ méjìléláàádọ́fà
[the] descendants of Hariph one hundred two [plus] ten.
25 Gibeoni jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
[the] descendants of Gibeon ninety and five.
26 Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu àti Netofa jẹ́ igba ó dín méjìlélógún
[the] men of Beth-lehem and Netophah one hundred eighty and eight.
27 Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
[the] men of Anathoth one hundred twenty and eight.
28 Beti-Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
[the] men of Beth Azmaveth forty and two.
29 Kiriati-Jearimu, Kefira, àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
[the] men of Kiriath Jearim Kephirah and Beeroth seven hundred forty and three.
30 Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
[the] men of Ramah and Geba six hundred twenty and one.
31 Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
[the] men of Micmash one hundred and twenty and two.
32 Beteli àti Ai jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
[the] men of Beth-el and Ai one hundred twenty and three.
33 Nebo mìíràn jẹ́ méjìléláàádọ́ta
[the] men of Nebo [the] other fifty and two.
34 Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
[the] descendants of Elam [the] other one thousand two hundred fifty and four.
35 Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó
[the] descendants of Harim three hundred and twenty.
36 Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún.
[the] descendants of Jericho three hundred forty and five.
37 Lodi, Hadidi, àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé ọ̀kan
[the] descendants of Lod Hadid and Ono seven hundred and twenty and one.
38 Senaa jẹ́ ẹgbàajì ó dín àádọ́rin.
[the] descendants of Senaah three thousand nine hundred and thirty.
39 Àwọn àlùfáà: àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
The priests [the] descendants of Jedaiah of [the] house of Jeshua nine hundred seventy and three.
40 Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
[the] descendants of Immer one thousand fifty and two.
41 Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
[the] descendants of Pashhur one thousand two hundred forty and seven.
42 Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
[the] descendants of Harim one thousand seven-teen.
43 Àwọn ọmọ Lefi: àwọn ọmọ Jeṣua (láti ipasẹ̀ Kadmieli, láti ipasẹ̀ Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
The Levites [the] descendants of Jeshua of Kadmiel of [the] descendants of Hodaviah seventy and four.
44 Àwọn akọrin: àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádọ́jọ.
The singers [the] descendants of Asaph one hundred forty and eight.
45 Àwọn aṣọ́nà: àwọn ọmọ Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita, àti Ṣobai jẹ́ méjìdínlógóje.
The gatekeepers [the] descendants of Shallum [the] descendants of Ater [the] descendants of Talmon [the] descendants of Akkub [the] descendants of Hatita [the] descendants of Shobai one hundred thirty and eight.
46 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ Siha, Hasufa, Tabboati,
The temple servants [the] descendants of Ziha [the] descendants of Hasupha [the] descendants of Tabbaoth.
47 Kerosi, Sia, Padoni,
[the] descendants of Keros [the] descendants of Sia [the] descendants of Padon.
48 Lebana, Hagaba, Ṣalmai,
[the] descendants of Lebanah [the] descendants of Hagabah [the] descendants of Shalmai.
49 Hanani, Giddeli, Gahari,
[the] descendants of Hanan [the] descendants of Giddel [the] descendants of Gahar.
50 Reaiah, Resini, Nekoda,
[the] descendants of Reaiah [the] descendants of Rezin [the] descendants of Nekoda.
51 Gassamu, Ussa, Pasea,
[the] descendants of Gazzam [the] descendants of Uzzah [the] descendants of Paseah.
52 Besai, Mehuni, Nefisimu,
[the] descendants of Besai [the] descendants of Meunim [the] descendants of (Nephissim. *Q(K)*)
53 Bakbu, Hakufa, Harhuri,
[the] descendants of Bakbuk [the] descendants of Hakupha [the] descendants of Harhur.
54 Basluti, Mehida, Harṣa,
[the] descendants of Bazluth [the] descendants of Mehida [the] descendants of Harsha.
55 Barkosi, Sisera, Tema,
[the] descendants of Barkos [the] descendants of Sisera [the] descendants of Temah.
56 Nesia, àti Hatifa.
[the] descendants of Neziah [the] descendants of Hatipha.
57 Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni: àwọn ọmọ Sotai, Sofereti; Perida,
[the] descendants of [the] servants of Solomon [the] descendants of Sotai [the] descendants of Sophereth [the] descendants of Perida.
58 Jaala, Darkoni, Giddeli,
[the] descendants of Jaala [the] descendants of Darkon [the] descendants of Giddel.
59 Ṣefatia, Hattili, Pokereti-Haṣṣebaimu, àti Amoni.
[the] descendants of Shephatiah [the] descendants of Hattil [the] descendants of Pokereth-Hazzebaim [the] descendants of Amon.
60 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
All the temple servants and [the] descendants of [the] servants of Solomon three hundred ninety and two.
61 Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
And these [are] the [ones who] came up from Tel Melah Tel Harsha Kerub Addon and Immer and not they were able to declare [the] house of ancestors their and offspring their if [were] from Israel they.
62 Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
[the] descendants of Delaiah [the] descendants of Tobiah [the] descendants of Nekoda six hundred and forty and two.
63 Lára àwọn àlùfáà ni: àwọn ọmọ Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi, ẹni tí a ń fi orúkọ yìí pè).
And of the priests [the] descendants of Hobaiah [the] descendants of Hakkoz [the] descendants of Barzillai who he had taken one of [the] daughters of Barzillai the Gileadite wife and he was called on name their.
64 Àwọn wọ̀nyí wá àkọsílẹ̀ orúkọ ìran wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí í níbẹ̀, fún ìdí èyí, a yọ wọ́n kúrò nínú àwọn tí ń ṣiṣẹ́ àlùfáà gẹ́gẹ́ bí aláìmọ́.
These they sought document their who had had themselves enrolled and not it was found and they were defiled from the priesthood.
65 Baálẹ̀ sọ fún wọn nítorí náà pé wọn kò gbọdọ̀ kópa nínú jíjẹ oúnjẹ mímọ́ títí tí àlùfáà tí yóò wá tí ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu yóò fi dé.
And he said the governor to them that not they will eat any of [the] holy thing of the holy things until will arise the priest to Urim and Thummim.
66 Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó,
All the assembly as one four ten thousand two thousand three hundred and sixty.
67 yàtọ̀ sí àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin tí wọ́n jẹ́ ẹgbẹ̀ta dín lẹ́gbàárin ó dín ẹ̀tàlélọ́gọ́ta; wọ́n sì tún ní àwọn akọrin ọkùnrin àti obìnrin tí wọ́n jẹ́ òjìlúgba ó lé márùn-ún.
Besides male servants their and female servants their these [were] seven thousand three hundred thirty and seven and [belonged] to them male singers and female singers two hundred
68 Ẹṣin wọn jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin, ìbákasẹ wọn jẹ́ òjìlúgba ó dín márùn-ún;
(horses their seven hundred thirty and six mules their two hundred *R*) and forty and five.
69 ìbákasẹ wọn jẹ́ òjìlénírinwó ó dín márùn-ún; kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọ́n jẹ́ ẹgbẹ̀rìnlélọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
Camels four hundred thirty and five. Donkeys six thousand seven hundred and twenty.
70 Díẹ̀ lára àwọn olórí ìdílé náà kópa nínú ṣíṣe iṣẹ́ náà. Baálẹ̀ fún ilé ìṣúra ní ẹgbẹ̀rún dariki wúrà, àádọ́ta àwo koto àti ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀ta lé mẹ́wàá ẹ̀wù fún àwọn àlùfáà.
And some of [the] end of [the] leaders of the fathers they gave for the work the governor he gave to the treasury gold drachmas one thousand bowls fifty garments of priests thirty and five hundred.
71 Díẹ̀ lára àwọn olórí ìdílé fún ilé ìṣúra ní ogún ẹgbẹ̀rún dariki wúrà àti ẹgbọ̀kànlá mina fàdákà.
And some of [the] leaders of the fathers they gave to [the] treasury of the work gold drachmas two ten thousands and silver minas two thousand and two hundred.
72 Àròpọ̀ gbogbo ohun tí àwọn ènìyàn tókù fi sílẹ̀ jẹ́ ogún ẹgbẹ̀rún dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún méjì mina fàdákà àti ẹẹ́tàdínláàdọ́rin ẹ̀wù fún àwọn àlùfáà.
And [that] which they gave [the] remainder of the people [was] gold drachmas two ten thousand and silver minas two thousand and tunics of priests sixty and seven.
73 Àwọn àlùfáà, àwọn Lefi, àwọn aṣọ́bodè, àwọn akọrin, àwọn ènìyàn díẹ̀, àwọn ìránṣẹ́ ilé Ọlọ́run, àti gbogbo ènìyàn Israẹli wà ní ìlú wọn. Nígbà tí ó di oṣù keje, tí àwọn ọmọ Israẹli sì ti wà nínú ìlú u wọn,
And they dwelt the priests and the Levites and the gatekeepers and the singers and some of the people and the temple servants and all Israel in own cities their and it arrived the month seventh and [the] people of Israel [were] in cities their.

< Nehemiah 7 >