< Nehemiah 7 >

1 Lẹ́yìn ìgbà tí a tún odi mọ tán tí mo sì ri àwọn ìlẹ̀kùn sí ààyè wọn, a sì yan àwọn aṣọ́bodè, àwọn akọrin àti àwọn Lefi.
And it comes to pass, when the wall has been built, that I set up the doors, and the gatekeepers are appointed, and the singers, and the Levites,
2 Mo fún Hanani arákùnrin mi pẹ̀lú Hananiah olórí ilé ìṣọ́ ní àṣẹ lórí Jerusalẹmu, nítorí tí ó jẹ́ ènìyàn olóòtítọ́, ó sì bẹ̀rù Ọlọ́run jù bí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ti ṣe lọ.
and I charge my brother Hanani, and Hananiah head of the palace, concerning Jerusalem—for he [is] as a man of truth, and fearing God above many—
3 Mo sọ fún wọn pé, “A kò gbọdọ̀ ṣí ìlẹ̀kùn Jerusalẹmu títí oòrùn yóò fi mú. Nígbà tí àwọn aṣọ́bodè bá sì wà lẹ́nu iṣẹ́, jẹ́ kí wọn ti ìlẹ̀kùn kí wọn sì há wọn. Bákan náà, yàn nínú àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́. Àwọn mìíràn níbi tí a pín wọn sí àti àwọn mìíràn ní tòsí ilé e wọn.”
and I say to them, “Do not let the gates of Jerusalem be opened until the heat of the sun, and while they are standing by let them shut the doors, and fasten, and appoint guards of the inhabitants of Jerusalem, each at his watch, and each in front of his house.”
4 Ìlú náà tóbi ó sì ní ààyè, ṣùgbọ́n ènìyàn inú rẹ̀ kéré, a kò sì tí ì tún àwọn ilé inú rẹ̀ kọ́.
And the city [is] broad on both sides, and great, and the people [are] few in its midst, and there are no houses built;
5 Nígbà náà ni Ọlọ́run mi fi sí mi ní ọkàn láti kó àwọn ọlọ́lá, àwọn ìjòyè, àti àwọn ènìyàn jọ fún ìforúkọsílẹ̀ ní ìdílé ìdílé. Mo rí ìwé àkọsílẹ̀ ìtàn ìran àwọn tí ó kọ́ gòkè padà wá láti ìgbèkùn. Èyí ni ohun tí mo rí tí a kọ sínú ìwé náà.
and my God puts it to my heart, and I gather the nobles, and the prefects, and the people, for the genealogy, and I find a scroll of the genealogy of those coming up at the beginning, and I find written in it:
6 Èyí ni àwọn ènìyàn agbègbè náà tí wọ́n sọ̀kalẹ̀ wá láti ìgbèkùn, àwọn tí Nebukadnessari ọba Babeli ti kó ní ìgbèkùn (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú u rẹ̀.
These [are] sons of the province, those coming up of the captives of the expulsion that Nebuchadnezzar king of Babylon removed—and they return to Jerusalem and to Judah, each to his city—
7 Wọ́n jọ rìn wá pẹ̀lú u Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Asariah, Raamiah, Nahamani, Mordekai, Bilṣani, Misperi, Bigfai, Nehumu, àti Baanah). Àkọsílẹ̀ orúkọ àwọn ọkùnrin Israẹli,
who are coming in with Zerubbabel, Jeshua, Nehemiah, Azariah, Raamiah, Nahamani, Mordecai, Bilshan, Mispereth, Bigvai, Nehum, Baanah. The number of the men of the people of Israel:
8 àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
sons of Parosh, two thousand one hundred and seventy-two;
9 Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
sons of Shephatiah, three hundred seventy-two;
10 Arah jẹ́ ẹgbẹ̀tàléláàádọ́ta ó lé méjì
sons of Arah, six hundred fifty-two;
11 Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìnlá ó lé méjìdínlógún
sons of Pahath-Moab, of the sons of Jeshua and Joab, two thousand and eight hundred [and] eighteen;
12 Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
sons of Elam, one thousand two hundred fifty-four;
13 Sattu jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
sons of Zattu, eight hundred forty-five;
14 Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
sons of Zaccai, seven hundred and sixty;
15 Binnui jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́jọ
sons of Binnui, six hundred forty-eight;
16 Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé méjìdínlọ́gbọ̀n
sons of Bebai, six hundred twenty-eight;
17 Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó dín méjìdínlọ́gọ́rin
sons of Azgad, two thousand three hundred twenty-two;
18 Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méje
sons of Adonikam, six hundred sixty-seven;
19 Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́tàdínláàádọ́rin
sons of Bigvai, two thousand sixty-seven;
20 Adini jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé márùn-ún
sons of Adin, six hundred fifty-five;
21 Ateri (láti ipasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́rùn-ún
sons of Ater of Hezekiah, ninety-eight;
22 Haṣumu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó ó lé mẹ́jọ
sons of Hashum, three hundred twenty-eight;
23 Besai jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó ó lé mẹ́rin
sons of Bezai, three hundred twenty-four;
24 Harifu jẹ́ méjìléláàádọ́fà
sons of Hariph, one hundred [and] twelve;
25 Gibeoni jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
sons of Gibeon, ninety-five;
26 Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu àti Netofa jẹ́ igba ó dín méjìlélógún
men of Beth-Lehem and Netophah, one hundred eighty-eight;
27 Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
men of Anathoth, one hundred twenty-eight;
28 Beti-Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
men of Beth-Azmaveth, forty-two;
29 Kiriati-Jearimu, Kefira, àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
men of Kirjath-Jearim, Chephirah, and Beeroth, seven hundred forty-three;
30 Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
men of Ramah and Gaba, six hundred twenty-one;
31 Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
men of Michmas, one hundred and twenty-two;
32 Beteli àti Ai jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
men of Bethel and Ai, one hundred twenty-three;
33 Nebo mìíràn jẹ́ méjìléláàádọ́ta
men of the other Nebo, fifty-two;
34 Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
sons of the other Elam, one thousand two hundred fifty-four;
35 Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó
sons of Harim, three hundred and twenty;
36 Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún.
sons of Jericho, three hundred forty-five;
37 Lodi, Hadidi, àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé ọ̀kan
sons of Lod, Hadid, and Ono, seven hundred and twenty-one;
38 Senaa jẹ́ ẹgbàajì ó dín àádọ́rin.
sons of Senaah, three thousand nine hundred and thirty.
39 Àwọn àlùfáà: àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
The priests: sons of Jedaiah, of the house of Jeshua, nine hundred seventy-three;
40 Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
sons of Immer, one thousand fifty-two;
41 Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
sons of Pashur, one thousand two hundred forty-seven;
42 Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
sons of Harim, one thousand and seventeen.
43 Àwọn ọmọ Lefi: àwọn ọmọ Jeṣua (láti ipasẹ̀ Kadmieli, láti ipasẹ̀ Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
The Levites: sons of Jeshua, of Kadmiel, of sons of Hodevah, seventy-four.
44 Àwọn akọrin: àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádọ́jọ.
The singers: sons of Asaph, one hundred forty-eight.
45 Àwọn aṣọ́nà: àwọn ọmọ Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita, àti Ṣobai jẹ́ méjìdínlógóje.
The gatekeepers: sons of Shallum, sons of Ater, sons of Talmon, sons of Akkub, sons of Hatita, sons of Shobai: one hundred thirty-eight.
46 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ Siha, Hasufa, Tabboati,
The Nethinim: sons of Ziha, sons of Hasupha, sons of Tabbaoth,
47 Kerosi, Sia, Padoni,
sons of Keros, sons of Sia, sons of Padon,
48 Lebana, Hagaba, Ṣalmai,
sons of Lebanah, sons of Hagaba, sons of Shalmai,
49 Hanani, Giddeli, Gahari,
sons of Hanan, sons of Giddel, sons of Gahar,
50 Reaiah, Resini, Nekoda,
sons of Reaiah, sons of Rezin, sons of Nekoda,
51 Gassamu, Ussa, Pasea,
sons of Gazzam, sons of Uzza, sons of Phaseah,
52 Besai, Mehuni, Nefisimu,
sons of Bezai, sons of Meunim, sons of Nephishesim,
53 Bakbu, Hakufa, Harhuri,
sons of Bakbuk, sons of Hakupha, sons of Harhur,
54 Basluti, Mehida, Harṣa,
sons of Bazlith, sons of Mehida, sons of Harsha,
55 Barkosi, Sisera, Tema,
sons of Barkos, sons of Sisera, sons of Tamah,
56 Nesia, àti Hatifa.
sons of Neziah, sons of Hatipha.
57 Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni: àwọn ọmọ Sotai, Sofereti; Perida,
Sons of the servants of Solomon: sons of Sotai, sons of Sophereth, sons of Perida,
58 Jaala, Darkoni, Giddeli,
sons of Jaala, sons of Darkon, sons of Giddel,
59 Ṣefatia, Hattili, Pokereti-Haṣṣebaimu, àti Amoni.
sons of Shephatiah, sons of Hattil, sons of Pochereth of Zebaim, sons of Amon.
60 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
All the Nethinim and the sons of the servants of Solomon [are] three hundred ninety-two.
61 Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
And these [are] those coming up from Tel-Melah, Tel-Harsha, Cherub, Addon, and Immer—and they have not been able to declare the house of their fathers, and their seed, whether they [are] of Israel—
62 Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
sons of Delaiah, sons of Tobiah, sons of Nekoda, six hundred forty-two.
63 Lára àwọn àlùfáà ni: àwọn ọmọ Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi, ẹni tí a ń fi orúkọ yìí pè).
And of the priests: sons of Habaiah, sons of Koz, sons of Barzillai (who has taken a wife from the daughters of Barzillai the Gileadite, and is called by their name).
64 Àwọn wọ̀nyí wá àkọsílẹ̀ orúkọ ìran wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí í níbẹ̀, fún ìdí èyí, a yọ wọ́n kúrò nínú àwọn tí ń ṣiṣẹ́ àlùfáà gẹ́gẹ́ bí aláìmọ́.
These have sought their register among those reckoning themselves by genealogy, and it has not been found, and they are redeemed from the priesthood,
65 Baálẹ̀ sọ fún wọn nítorí náà pé wọn kò gbọdọ̀ kópa nínú jíjẹ oúnjẹ mímọ́ títí tí àlùfáà tí yóò wá tí ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu yóò fi dé.
and the Tirshatha says to them that they do not eat of the most holy things until the standing up of the priest with [the] Lights and Perfections.
66 Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó,
All the assembly together [is] forty-two thousand three hundred and sixty,
67 yàtọ̀ sí àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin tí wọ́n jẹ́ ẹgbẹ̀ta dín lẹ́gbàárin ó dín ẹ̀tàlélọ́gọ́ta; wọ́n sì tún ní àwọn akọrin ọkùnrin àti obìnrin tí wọ́n jẹ́ òjìlúgba ó lé márùn-ún.
apart from their servants and their handmaids—these [are] seven thousand three hundred thirty-seven; and of them [are] male and female singers, two hundred forty-five.
68 Ẹṣin wọn jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin, ìbákasẹ wọn jẹ́ òjìlúgba ó dín márùn-ún;
Their horses [are] seven hundred thirty-six; their mules, two hundred [and] forty-five;
69 ìbákasẹ wọn jẹ́ òjìlénírinwó ó dín márùn-ún; kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọ́n jẹ́ ẹgbẹ̀rìnlélọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
camels, four hundred thirty-five; donkeys, six thousand seven hundred and twenty.
70 Díẹ̀ lára àwọn olórí ìdílé náà kópa nínú ṣíṣe iṣẹ́ náà. Baálẹ̀ fún ilé ìṣúra ní ẹgbẹ̀rún dariki wúrà, àádọ́ta àwo koto àti ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀ta lé mẹ́wàá ẹ̀wù fún àwọn àlùfáà.
And from the extremity of the heads of the fathers they have given to the work; the Tirshatha has given to the treasure, one thousand drams of gold, fifty bowls, five hundred and thirty priests’ coats.
71 Díẹ̀ lára àwọn olórí ìdílé fún ilé ìṣúra ní ogún ẹgbẹ̀rún dariki wúrà àti ẹgbọ̀kànlá mina fàdákà.
And of the heads of the fathers they have given to the treasure of the work, twenty thousand drams of gold, and two thousand and two hundred pounds of silver.
72 Àròpọ̀ gbogbo ohun tí àwọn ènìyàn tókù fi sílẹ̀ jẹ́ ogún ẹgbẹ̀rún dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún méjì mina fàdákà àti ẹẹ́tàdínláàdọ́rin ẹ̀wù fún àwọn àlùfáà.
And that which the rest of the people have given [is] twenty thousand drams of gold, and two thousand pounds of silver, and sixty-seven priests’ coats.
73 Àwọn àlùfáà, àwọn Lefi, àwọn aṣọ́bodè, àwọn akọrin, àwọn ènìyàn díẹ̀, àwọn ìránṣẹ́ ilé Ọlọ́run, àti gbogbo ènìyàn Israẹli wà ní ìlú wọn. Nígbà tí ó di oṣù keje, tí àwọn ọmọ Israẹli sì ti wà nínú ìlú u wọn,
And they dwell—the priests, and the Levites, and the gatekeepers, and the singers, and [some] of the people, and the Nethinim, and all Israel—in their cities, and the seventh month comes, and the sons of Israel [are] in their cities.

< Nehemiah 7 >