< Nehemiah 7 >

1 Lẹ́yìn ìgbà tí a tún odi mọ tán tí mo sì ri àwọn ìlẹ̀kùn sí ààyè wọn, a sì yan àwọn aṣọ́bodè, àwọn akọrin àti àwọn Lefi.
And it came to pass, when the wall was built, and I had set up the doors, and the porters and the singers and the Levites were appointed,
2 Mo fún Hanani arákùnrin mi pẹ̀lú Hananiah olórí ilé ìṣọ́ ní àṣẹ lórí Jerusalẹmu, nítorí tí ó jẹ́ ènìyàn olóòtítọ́, ó sì bẹ̀rù Ọlọ́run jù bí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ti ṣe lọ.
that I gave charge to Ananias my brother, and Ananias the ruler of the palace, over Jerusalem: for he was a true man, and one that feared God beyond many.
3 Mo sọ fún wọn pé, “A kò gbọdọ̀ ṣí ìlẹ̀kùn Jerusalẹmu títí oòrùn yóò fi mú. Nígbà tí àwọn aṣọ́bodè bá sì wà lẹ́nu iṣẹ́, jẹ́ kí wọn ti ìlẹ̀kùn kí wọn sì há wọn. Bákan náà, yàn nínú àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́. Àwọn mìíràn níbi tí a pín wọn sí àti àwọn mìíràn ní tòsí ilé e wọn.”
And I said to them, The gates of Jerusalem shall not be opened till sunrise; and while they are still watching, let the doors be shut, and bolted; and set watches of them that dwell in Jerusalem, [every] man at his post, and [every] man over against his house.
4 Ìlú náà tóbi ó sì ní ààyè, ṣùgbọ́n ènìyàn inú rẹ̀ kéré, a kò sì tí ì tún àwọn ilé inú rẹ̀ kọ́.
Now the city [was] wide and large; and the people [were] few in it, and the houses were not built.
5 Nígbà náà ni Ọlọ́run mi fi sí mi ní ọkàn láti kó àwọn ọlọ́lá, àwọn ìjòyè, àti àwọn ènìyàn jọ fún ìforúkọsílẹ̀ ní ìdílé ìdílé. Mo rí ìwé àkọsílẹ̀ ìtàn ìran àwọn tí ó kọ́ gòkè padà wá láti ìgbèkùn. Èyí ni ohun tí mo rí tí a kọ sínú ìwé náà.
And God put [it] into my heart, and I gathered the nobles, and the rulers, and the people, into companies: and I found a register of the company that came up first, and I found written in it as follows:
6 Èyí ni àwọn ènìyàn agbègbè náà tí wọ́n sọ̀kalẹ̀ wá láti ìgbèkùn, àwọn tí Nebukadnessari ọba Babeli ti kó ní ìgbèkùn (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú u rẹ̀.
Now these [are] the children of the country, that came up from captivity, of the number which Nabuchodonosor king of Babylon carried away, and they returned to Jerusalem and to Juda, [every] man to his city;
7 Wọ́n jọ rìn wá pẹ̀lú u Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Asariah, Raamiah, Nahamani, Mordekai, Bilṣani, Misperi, Bigfai, Nehumu, àti Baanah). Àkọsílẹ̀ orúkọ àwọn ọkùnrin Israẹli,
with Zorobabel, and Jesus, and Neemia, Azaria, and Reelma, Naemani, Mardochaeus, Balsan, Maspharath, Esdra, Boguia, Inaum, Baana, Masphar, men of the people of Israel.
8 àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
The children of Phoros, two thousand and one hundred and seventy-two.
9 Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
The children of Saphatia, three hundred and seventy-two.
10 Arah jẹ́ ẹgbẹ̀tàléláàádọ́ta ó lé méjì
The children of Era, six hundred and fifty-two.
11 Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìnlá ó lé méjìdínlógún
The children of Phaath Moab, with the children of Jesus and Joab, two thousand and six hundred and eighteen.
12 Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
The children of Aelam, a thousand and two hundred and fifty-four.
13 Sattu jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
The children of Zathuia, eight hundred and forty-five.
14 Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
The children of Zacchu, seven hundred and sixty.
15 Binnui jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́jọ
The children of Banui, six hundred and forty-eight.
16 Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé méjìdínlọ́gbọ̀n
The children of Bebi, six hundred and twenty-eight.
17 Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó dín méjìdínlọ́gọ́rin
The children of Asgad, two thousand and three hundred and twenty-two.
18 Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méje
The children of Adonicam, six hundred and sixty-seven.
19 Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́tàdínláàádọ́rin
The children of Bagoi, two thousand and sixty-seven.
20 Adini jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé márùn-ún
The children of Edin, six hundred and fifty-five.
21 Ateri (láti ipasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́rùn-ún
The children of Ater, [the son] of Ezekias, ninety-eight.
22 Haṣumu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó ó lé mẹ́jọ
The children of Esam, three hundred and twenty-eight.
23 Besai jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó ó lé mẹ́rin
The children of Besei, three hundred and twenty-four.
24 Harifu jẹ́ méjìléláàádọ́fà
The children of Ariph, a hundred and twelve: the children of Asen, two hundred and twenty-three.
25 Gibeoni jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
The children of Gabaon, ninety-five.
26 Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu àti Netofa jẹ́ igba ó dín méjìlélógún
The children of Baethalem, a hundred and twenty-three: the children of Atopha, fifty-six.
27 Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
The children of Anathoth, a hundred and twenty-eight.
28 Beti-Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
The men of Bethasmoth, forty-two.
29 Kiriati-Jearimu, Kefira, àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
The men of Cariatharim, Caphira, and Beroth, seven hundred and forty-three.
30 Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
The men of Arama and Gabaa, six hundred and twenty.
31 Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
The men of Machemas, a hundred and twenty-two.
32 Beteli àti Ai jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
The men of Baethel and Ai, a hundred and twenty-three.
33 Nebo mìíràn jẹ́ méjìléláàádọ́ta
The men of Nabia, a hundred an fifty-two.
34 Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
The men of Elamaar, one thousand and two hundred and fifty-two.
35 Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó
The children of Eram, three hundred and twenty.
36 Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún.
The children of Jericho, three hundred and forty-five.
37 Lodi, Hadidi, àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé ọ̀kan
The children of Lodadid and Ono, seven hundred and twenty-one.
38 Senaa jẹ́ ẹgbàajì ó dín àádọ́rin.
The children of Sanana, three thousand and nine hundred and thirty.
39 Àwọn àlùfáà: àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
The priests; the sons of Jodae, [pertaining] to the house of Jesus, nine hundred and seventy-three.
40 Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
The children of Emmer, one thousand and fifty-two.
41 Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
The children of Phaseur, one thousand and two hundred and forty-seven.
42 Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
The children of Eram, a thousand and seventeen.
43 Àwọn ọmọ Lefi: àwọn ọmọ Jeṣua (láti ipasẹ̀ Kadmieli, láti ipasẹ̀ Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
The Levites; the children of Jesus the son of Cadmiel, with the children of Uduia, seventy-four.
44 Àwọn akọrin: àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádọ́jọ.
The singers; the children of Asaph, a hundred and forty-eight.
45 Àwọn aṣọ́nà: àwọn ọmọ Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita, àti Ṣobai jẹ́ méjìdínlógóje.
The porters; the children of Salum, the children of Ater, the children of Telmon, the children of Acub, the children of Atita, the children of Sabi, a hundred and thirty-eight.
46 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ Siha, Hasufa, Tabboati,
The Nathinim; the children of Sea, the children of Aspha, the children of Tabaoth,
47 Kerosi, Sia, Padoni,
the children of Kiras, the children of Asuia, the children of Phadon,
48 Lebana, Hagaba, Ṣalmai,
the children of Labana, the children of Agaba, the children of Selmei,
49 Hanani, Giddeli, Gahari,
the children of Anan, the children of Gadel, the children of Gaar,
50 Reaiah, Resini, Nekoda,
the children of Raaia, the children of Rasson, the children of Necoda,
51 Gassamu, Ussa, Pasea,
the children of Gezam, the children of Ozi, the children of Phese,
52 Besai, Mehuni, Nefisimu,
the children of Besi, the children of Meinon, the children of Nephosasi,
53 Bakbu, Hakufa, Harhuri,
the children of Bacbuc, the children of Achipha, the children of Arur,
54 Basluti, Mehida, Harṣa,
the children of Basaloth, the children of Mida, the children of Adasan,
55 Barkosi, Sisera, Tema,
the children of Barcue, the children of Sisarath, the children of Thema,
56 Nesia, àti Hatifa.
the children of Nisia, the children of Atipha.
57 Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni: àwọn ọmọ Sotai, Sofereti; Perida,
The children of the servants of Solomon; the children of Sutei, the children of Sapharat, the children of Pherida,
58 Jaala, Darkoni, Giddeli,
the children of Jelel, the children of Dorcon, the children of Gadael,
59 Ṣefatia, Hattili, Pokereti-Haṣṣebaimu, àti Amoni.
the children of Saphatia, the children of Ettel, the children of Phacarath, the children of Sabaim, the children of Emim.
60 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
All the Nathinim, and children of the servants of Solomon, [were] three hundred and ninety-two.
61 Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
And these went up from Thelmeleth, Thelaresa, Charub, Eron, Jemer: but they could not declare the houses of their families, or their seed, whether they were of Israel.
62 Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
The children of Dalaia, the children of Tobia, the children of Necoda, six hundred and forty-two.
63 Lára àwọn àlùfáà ni: àwọn ọmọ Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi, ẹni tí a ń fi orúkọ yìí pè).
And of the priests; the children of Ebia, the children of Acos, the children of Berzelli, for they took wives of the daughters of Berzelli the Galaadite, and they were called by their name.
64 Àwọn wọ̀nyí wá àkọsílẹ̀ orúkọ ìran wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí í níbẹ̀, fún ìdí èyí, a yọ wọ́n kúrò nínú àwọn tí ń ṣiṣẹ́ àlùfáà gẹ́gẹ́ bí aláìmọ́.
These sought the pedigree of their company, and it was not found, and they were removed [as polluted] from the priesthood.
65 Baálẹ̀ sọ fún wọn nítorí náà pé wọn kò gbọdọ̀ kópa nínú jíjẹ oúnjẹ mímọ́ títí tí àlùfáà tí yóò wá tí ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu yóò fi dé.
And the Athersastha said, that they should not eat of the most holy things, until a priest should stand up to give light.
66 Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó,
And all the congregation was about forty-two thousand and three hundred and sixty,
67 yàtọ̀ sí àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin tí wọ́n jẹ́ ẹgbẹ̀ta dín lẹ́gbàárin ó dín ẹ̀tàlélọ́gọ́ta; wọ́n sì tún ní àwọn akọrin ọkùnrin àti obìnrin tí wọ́n jẹ́ òjìlúgba ó lé márùn-ún.
besides their menservants and their maidservants: these were seven thousand and three hundred and thirty seven: and the singing-men and singing-women, two hundred and forty-five.
68 Ẹṣin wọn jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin, ìbákasẹ wọn jẹ́ òjìlúgba ó dín márùn-ún;
69 ìbákasẹ wọn jẹ́ òjìlénírinwó ó dín márùn-ún; kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọ́n jẹ́ ẹgbẹ̀rìnlélọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
Two thousand and seven hundred asses.
70 Díẹ̀ lára àwọn olórí ìdílé náà kópa nínú ṣíṣe iṣẹ́ náà. Baálẹ̀ fún ilé ìṣúra ní ẹgbẹ̀rún dariki wúrà, àádọ́ta àwo koto àti ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀ta lé mẹ́wàá ẹ̀wù fún àwọn àlùfáà.
And part of the heads of families gave into the treasury to Neemias for the work a thousand pieces of gold, fifty bowls, and thirty priests' [garments].
71 Díẹ̀ lára àwọn olórí ìdílé fún ilé ìṣúra ní ogún ẹgbẹ̀rún dariki wúrà àti ẹgbọ̀kànlá mina fàdákà.
And [some] of the heads of families gave into the treasuries of the work, twenty thousand pieces of gold, and two thousand and three hundred pounds of silver.
72 Àròpọ̀ gbogbo ohun tí àwọn ènìyàn tókù fi sílẹ̀ jẹ́ ogún ẹgbẹ̀rún dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún méjì mina fàdákà àti ẹẹ́tàdínláàdọ́rin ẹ̀wù fún àwọn àlùfáà.
And the rest of the people gave twenty thousand pieces of gold, and two thousand and two hundred pounds of silver, and sixty-seven priests' [garments].
73 Àwọn àlùfáà, àwọn Lefi, àwọn aṣọ́bodè, àwọn akọrin, àwọn ènìyàn díẹ̀, àwọn ìránṣẹ́ ilé Ọlọ́run, àti gbogbo ènìyàn Israẹli wà ní ìlú wọn. Nígbà tí ó di oṣù keje, tí àwọn ọmọ Israẹli sì ti wà nínú ìlú u wọn,
And the priests, and Levites, and porters, and singers, and [some] of the people, and the Nathinim, and all Israel, lived in their cities.

< Nehemiah 7 >