< Nehemiah 6 >

1 Nígbà tí Sanballati, Tobiah Geṣemu ará Arabia àti àwọn ọ̀tá wa tókù gbọ́ pé, mo ti tún odi náà mọ, kò sì sí àlàfo kankan tí ó ṣẹ́kù nínú rẹ̀—bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi kò ì tí ì ri àwọn ìlẹ̀kùn ibodè ní àkókò náà.
Kwasekusithi oSanibhalathi loTobiya loGeshema umArabhiya lezinye izitha zethu sezizwile ukuthi ngiwakhile umduli lokuthi kakusalanga sikhala kuwo, lanxa kuze kube yilesosikhathi ngangingamisanga izivalo emasangweni,
2 Sanballati àti Geṣemu rán iṣẹ́ yìí sí mi pé, “Wá jẹ́ kí a jọ pàdé pọ̀ nínú ọ̀kan lára àwọn ìletò ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Ono.” Ṣùgbọ́n wọ́n ń gbèrò láti ṣe mí ní ibi;
oSanibhalathi loGeshema bathuma kimi besithi: Woza sihlangane ndawonye emizini emagcekeni eOno. Kodwa babecabange ukwenza okubi kimi.
3 bẹ́ẹ̀ ni mo rán oníṣẹ́ padà pẹ̀lú èsì yìí pé, “Èmi ń ṣe iṣẹ́ ńlá kan, èmi kò le è sọ̀kalẹ̀ wá. Èéṣe tí iṣẹ́ náà yóò fi dúró, nígbà tí mo bá fi í sílẹ̀ tí mo sì sọ̀kalẹ̀ tọ̀ yín wá?”
Ngasengithuma izithunywa kubo ngisithi: Ngenza umsebenzi omkhulu, ngakho kangilakho ukwehla. Kungani umsebenzi uzakuma, ngiwutshiye, ngehlele kini?
4 Wọ́n rán iṣẹ́ náà sí mi nígbà mẹ́rin ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀, mo sì fún wọn ní èsì bákan náà fún ìgbà kọ̀ọ̀kan.
Basebethuma kimi kane ngaleyondlela, ngabaphendula ngaleyondlela.
5 Ní ìgbà karùn-ún, Sanballati rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sí mi pẹ̀lú irú iṣẹ́ kan náà, lẹ́tà kan tí a kò fi sínú àpò ìwé wà ní ọwọ́ rẹ̀
Ngakho uSanibhalathi wathuma kimi inceku yakhe ngaleyondlela ngokwesihlanu ilencwadi evulekileyo esandleni sayo.
6 tí a kọ sínú un rẹ̀ pé, “A ròyìn rẹ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, Geṣemu sì sọ pé, òtítọ́ ni, pé ìwọ àti àwọn Júù ń gbèrò láti ṣọ̀tẹ̀, nítorí náà ni ẹ ṣe ń mọ odi. Síwájú sí i, gẹ́gẹ́ bí ìròyìn yìí, ìwọ sì ń gbèrò láti di ọba wọn
Kwakubhalwe kuyo ukuthi: Kuzwakele ezizweni, loGashimu uthi: Wena lamaJuda linakana ukuhlamuka; ngenxa yalokho wakha umduli, ukuze wena ube yinkosi yabo, njengalamazwi.
7 àti pé ó ti yan àwọn wòlíì kí wọn lè kéde nípa rẹ̀ ní Jerusalẹmu: ‘Ọba kan wà ní Juda!’ Nísinsin yìí, ìròyìn yìí yóò padà sí ọ̀dọ̀ ọba; nítorí náà wá, jẹ́ kí a bá ara wa sọ̀rọ̀.”
Futhi umisile labaprofethi ukuze bamemezele ngawe eJerusalema, besithi: Kukhona inkosi koJuda. Khathesi-ke kuzazwakala enkosini njengalamazwi. Ngakho-ke woza, sicebisane.
8 Mo dá èsì yìí padà sí i pé, “Kò sí ohun kan nínú irú ohun tí ìwọ sọ tí ó ṣẹlẹ̀; ìwọ kàn rò wọ́n ní orí ara rẹ ni.”
Ngasengithuma kuye ngisithi: Kazikho izinto ezinjengalezo ozitshoyo, kodwa uyazibumba zivela enhliziyweni yakho.
9 Gbogbo wọn múra láti dẹ́rùbà wá, wọ́n ń rò ó wí pé, “Ọwọ́ wọn kò ní ran iṣẹ́ náà, àti wí pé wọn kò ní parí rẹ̀.” Ṣùgbọ́n mo gbàdúrà pé, “Nísinsin yìí Ọlọ́run fi agbára fún ọwọ́ mi.”
Ngoba bonke basethusa besithi: Izandla zabo zizadangala emsebenzini, ukuthi ungenziwa. Ngakho-ke qinisa izandla zami.
10 Ní ọjọ́ kan mo lọ sí ilé Ṣemaiah ọmọ Delaiah, ọmọ Mehetabeeli, ẹni tí a há mọ́ sínú ilé rẹ̀. Ó wí pé, “Jẹ́ kí a pàdé ní ilé Ọlọ́run nínú tẹmpili, kí o sì jẹ́ kí a pa àwọn ìlẹ̀kùn tẹmpili dé, nítorí àwọn ènìyàn ń bọ̀ láti pa ọ́, ní òru ni wọn yóò wá láti pa ọ́.”
Mina sengingenile endlini kaShemaya indodana kaDelaya indodana kaMehethabheli owayezivalele, wasesithi: Asihlangane endlini kaNkulunkulu phakathi kwethempeli, sivale iminyango yethempeli, ngoba bayeza ukukubulala, yebo, bayeza ebusuku ukukubulala.
11 Ṣùgbọ́n mo wí pé, “Ǹjẹ́ ó yẹ kí irú ènìyàn bí èmi sálọ? Tàbí kí ènìyàn bí èmi sálọ sínú tẹmpili láti gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là? Èmi kò ní lọ!”
Kodwa ngathi: Kambe umuntu onjengami angabaleka? Pho, nguwuphi umuntu onjengami ongangena ethempelini aphile? Kangiyikungena.
12 Èmi wòye pé Ọlọ́run kò rán an, ṣùgbọ́n ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí mi nítorí Tobiah àti Sanballati ti bẹ̀ ẹ́ ní ọ̀wẹ̀.
Ngasenginanzelela, khangela-ke, uNkulunkulu wayengamthumanga, kodwa wakhuluma isiprofetho esimelene lami ngoba oTobiya loSanibhalathi babemqhatshile.
13 Wọ́n bẹ̀ ẹ́ ní ọ̀wẹ̀ láti dẹ́rùbà mí nítorí kí èmi lè dẹ́ṣẹ̀ nípa ṣíṣe èyí, kí wọn lè bà mí lórúkọ jẹ́, kí n sì di ẹni ẹ̀gàn.
Ngakho wayeqhatshiwe ukuze ngesabe, ngenze njalo, ngone, ukuze babe lebizo elibi ngami, ukuze bangigcone.
14 A! Ọlọ́run mi, rántí Tobiah àti Sanballati, nítorí ohun tí wọ́n ti ṣe; kí o sì tún rántí Noadiah wòlíì obìnrin àti àwọn wòlíì tókù tí wọ́n ń gbèrò láti dẹ́rùbà mí.
Khumbula, Nkulunkulu wami, uTobiya loSanibhalathi njengokwale imisebenzi yakhe, njalo loNowadiya umprofethikazi labanye abaprofethi ababengethusa.
15 Bẹ́ẹ̀ ni a parí odi náà ní ọjọ́ kẹẹdọ́gbọ̀n oṣù Eluli, láàrín ọjọ́ méjìléláàádọ́ta.
Waphela-ke umduli ngolwamatshumi amabili lanhlanu kaEluli ngensuku ezingamatshumi amahlanu lambili.
16 Nígbà tí àwọn ọ̀tá wa gbọ́ èyí, gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó yí wa ká bẹ̀rù jìnnìjìnnì sì mú wọn, nítorí wọ́n wòye pé iṣẹ́ yìí di ṣíṣe pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Ọlọ́run wa.
Kwasekusithi zonke izitha zethu zisizwa, lazo zonke izizwe ezisizingelezeleyo zibona, zawa kakhulu emehlweni azo; ngoba zananzelela ukuthi lumsebenzi wenziwe nguNkulunkulu wethu.
17 Bákan náà, ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ọlọ́lá Juda ń kọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ lẹ́tà ránṣẹ́ sí Tobiah, èsì láti ọ̀dọ̀ Tobiah sì ń wá sí ọ̀dọ̀ wọn.
Njalo ngalezonsuku izikhulu zakoJuda zandisa incwadi zazo eziya kuTobiya, lezikaTobiya zeza kuzo.
18 Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn Juda ti mulẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, nítorí tí ó jẹ́ àna Ṣekaniah ọmọ Arah (Sanballati fẹ́ ọmọ Ṣekaniah), ọmọ rẹ̀ Jehohanani sì tún fẹ́ ọmọbìnrin Meṣullamu ọmọ Berekiah.
Ngoba abanengi koJuda babefungile kuye ngoba wayengumkhwenyana kaShekaniya indodana kaAra, loJehohanani indodana yakhe wayethethe indodakazi kaMeshulamu indodana kaBerekiya.
19 Síwájú sí í, wọ́n túbọ̀ ń ròyìn iṣẹ́ rere rẹ̀ fún mi, wọ́n sì ń sọ ohun tí mo sọ fún un. Tobiah sì ń kọ àwọn lẹ́tà ránṣẹ́ sí mi láti dẹ́rùbà mí.
Njalo babekhuluma izenzo zakhe ezinhle phambi kwami, lamazwi ami bewakhuphela kuye. UTobiya wathumela incwadi zokungethusa.

< Nehemiah 6 >