< Nehemiah 6 >

1 Nígbà tí Sanballati, Tobiah Geṣemu ará Arabia àti àwọn ọ̀tá wa tókù gbọ́ pé, mo ti tún odi náà mọ, kò sì sí àlàfo kankan tí ó ṣẹ́kù nínú rẹ̀—bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi kò ì tí ì ri àwọn ìlẹ̀kùn ibodè ní àkókò náà.
Lorsque la nouvelle parvint à Sanballat, à Tobia, à Ghéchem, l’Arabe, et à nos autres ennemis, que j’avais reconstruit la muraille et qu’il n’y restait aucune brèche, (toutefois jusqu’à ce moment je n’avais pas fixé les battants aux portes),
2 Sanballati àti Geṣemu rán iṣẹ́ yìí sí mi pé, “Wá jẹ́ kí a jọ pàdé pọ̀ nínú ọ̀kan lára àwọn ìletò ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Ono.” Ṣùgbọ́n wọ́n ń gbèrò láti ṣe mí ní ibi;
Sanballat et Ghéchem m’envoyèrent dire: "Viens, nous allons conférer ensemble à Kefirim, dans la vallée d’Ono." Ils avaient l’intention de me faire du mal.
3 bẹ́ẹ̀ ni mo rán oníṣẹ́ padà pẹ̀lú èsì yìí pé, “Èmi ń ṣe iṣẹ́ ńlá kan, èmi kò le è sọ̀kalẹ̀ wá. Èéṣe tí iṣẹ́ náà yóò fi dúró, nígbà tí mo bá fi í sílẹ̀ tí mo sì sọ̀kalẹ̀ tọ̀ yín wá?”
Mais je leur expédiai des messagers et leur fis dire: "Je suis occupé à un grand ouvrage et ne puis y descendre. Pourquoi laisserai-je s’arrêter le travail en l’abandonnant, pour me rendre auprès de vous?"
4 Wọ́n rán iṣẹ́ náà sí mi nígbà mẹ́rin ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀, mo sì fún wọn ní èsì bákan náà fún ìgbà kọ̀ọ̀kan.
A quatre reprises, ils me firent transmettre la même proposition, et je leur donnai la même réponse.
5 Ní ìgbà karùn-ún, Sanballati rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sí mi pẹ̀lú irú iṣẹ́ kan náà, lẹ́tà kan tí a kò fi sínú àpò ìwé wà ní ọwọ́ rẹ̀
Sanballat m’adressa la même invitation une cinquième fois par son valet, qui portait en sa main une lettre ouverte,
6 tí a kọ sínú un rẹ̀ pé, “A ròyìn rẹ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, Geṣemu sì sọ pé, òtítọ́ ni, pé ìwọ àti àwọn Júù ń gbèrò láti ṣọ̀tẹ̀, nítorí náà ni ẹ ṣe ń mọ odi. Síwájú sí i, gẹ́gẹ́ bí ìròyìn yìí, ìwọ sì ń gbèrò láti di ọba wọn
contenant ces mots: "Le bruit s’est répandu parmi les peuples, et Gachmou le confirme, que toi et les Judéens, vous pensez vous révolter; dans ce but, tu rebâtirais la muraille, et tu songerais à devenir leur roi, d’après ce qui se dit.
7 àti pé ó ti yan àwọn wòlíì kí wọn lè kéde nípa rẹ̀ ní Jerusalẹmu: ‘Ọba kan wà ní Juda!’ Nísinsin yìí, ìròyìn yìí yóò padà sí ọ̀dọ̀ ọba; nítorí náà wá, jẹ́ kí a bá ara wa sọ̀rọ̀.”
Tu aurais aussi suscité des prophètes chargés de te proclamer à Jérusalem "roi de Juda". Or, de tels bruits peuvent arriver jusqu’au roi: viens donc et concertons-nous ensemble."
8 Mo dá èsì yìí padà sí i pé, “Kò sí ohun kan nínú irú ohun tí ìwọ sọ tí ó ṣẹlẹ̀; ìwọ kàn rò wọ́n ní orí ara rẹ ni.”
Je renvoyai vers lui pour lui faire dire: "Il n’y a rien de vrai dans tous ces faits que tu allègues, c’est ton imagination qui les a inventés."
9 Gbogbo wọn múra láti dẹ́rùbà wá, wọ́n ń rò ó wí pé, “Ọwọ́ wọn kò ní ran iṣẹ́ náà, àti wí pé wọn kò ní parí rẹ̀.” Ṣùgbọ́n mo gbàdúrà pé, “Nísinsin yìí Ọlọ́run fi agbára fún ọwọ́ mi.”
Car tous ces gens cherchaient à nous intimider, se disant: "Leurs mains se relâcheront dans le travail, et il ne s’exécutera pas." Or, toi ô Seigneur, soutiens mes bras!
10 Ní ọjọ́ kan mo lọ sí ilé Ṣemaiah ọmọ Delaiah, ọmọ Mehetabeeli, ẹni tí a há mọ́ sínú ilé rẹ̀. Ó wí pé, “Jẹ́ kí a pàdé ní ilé Ọlọ́run nínú tẹmpili, kí o sì jẹ́ kí a pa àwọn ìlẹ̀kùn tẹmpili dé, nítorí àwọn ènìyàn ń bọ̀ láti pa ọ́, ní òru ni wọn yóò wá láti pa ọ́.”
Je me rendis dans la maison de Chemaïa, fils de Delaïa, fils de Mehétabel, qui était enfermé chez lui. Il me dit: "Allons de concert dans la maison de Dieu, au fond du sanctuaire, et fermons les portes du sanctuaire, car ils vont venir te tuer; c’est dans la nuit qu’on viendra te mettre à mort."
11 Ṣùgbọ́n mo wí pé, “Ǹjẹ́ ó yẹ kí irú ènìyàn bí èmi sálọ? Tàbí kí ènìyàn bí èmi sálọ sínú tẹmpili láti gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là? Èmi kò ní lọ!”
Je répondis: "Est-ce qu’un homme comme moi doit s’enfuir? Et quel est mon pareil qui oserait entrer dans le sanctuaire et qui resterait en vie? Je n’irai point."
12 Èmi wòye pé Ọlọ́run kò rán an, ṣùgbọ́n ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí mi nítorí Tobiah àti Sanballati ti bẹ̀ ẹ́ ní ọ̀wẹ̀.
Je reconnus par là que ce n’était pas Dieu qui l’avait envoyé, mais qu’il avait prononcé une prophétie à mon sujet, Tobia et Sanballat l’ayant soudoyé.
13 Wọ́n bẹ̀ ẹ́ ní ọ̀wẹ̀ láti dẹ́rùbà mí nítorí kí èmi lè dẹ́ṣẹ̀ nípa ṣíṣe èyí, kí wọn lè bà mí lórúkọ jẹ́, kí n sì di ẹni ẹ̀gàn.
En effet, il avait été soudoyé pour que, prenant peur, j’agisse selon son conseil et me rendisse coupable; cela leur aurait servi à me faire une mauvaise réputation et à me couvrir d’opprobre.
14 A! Ọlọ́run mi, rántí Tobiah àti Sanballati, nítorí ohun tí wọ́n ti ṣe; kí o sì tún rántí Noadiah wòlíì obìnrin àti àwọn wòlíì tókù tí wọ́n ń gbèrò láti dẹ́rùbà mí.
Tiens compte, ô mon Dieu, à Tobia et à Sanballat de tels agissements; tiens compte aussi à la prophétesse Noadia et aux autres prophètes de ce qu’ils cherchaient à m’intimider.
15 Bẹ́ẹ̀ ni a parí odi náà ní ọjọ́ kẹẹdọ́gbọ̀n oṣù Eluli, láàrín ọjọ́ méjìléláàádọ́ta.
La muraille fut achevée le vingt-cinquième jour du mois d’Eloul, au bout de cinquante-deux jours.
16 Nígbà tí àwọn ọ̀tá wa gbọ́ èyí, gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó yí wa ká bẹ̀rù jìnnìjìnnì sì mú wọn, nítorí wọ́n wòye pé iṣẹ́ yìí di ṣíṣe pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Ọlọ́run wa.
Lorsque nos ennemis en furent tous instruits, toutes les nations qui nous entouraient prirent peur et se sentirent bien diminuées à leurs propres yeux; elles reconnurent que c’était grâce à notre Dieu que cette entreprise avait été menée à bonne fin.
17 Bákan náà, ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ọlọ́lá Juda ń kọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ lẹ́tà ránṣẹ́ sí Tobiah, èsì láti ọ̀dọ̀ Tobiah sì ń wá sí ọ̀dọ̀ wọn.
En ce même temps, les nobles de Juda multipliaient leurs lettres à l’adresse de Tobia, et celui-ci leur en faisait parvenir de son côté.
18 Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn Juda ti mulẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, nítorí tí ó jẹ́ àna Ṣekaniah ọmọ Arah (Sanballati fẹ́ ọmọ Ṣekaniah), ọmọ rẹ̀ Jehohanani sì tún fẹ́ ọmọbìnrin Meṣullamu ọmọ Berekiah.
Beaucoup de gens de Juda, en effet, lui étaient affiliés par un pacte, car il était le gendre de Chekhania, fils d’Arah, et son fils Johanan avait épousé la fille de Mechoullam, fils de Bérékhia.
19 Síwájú sí í, wọ́n túbọ̀ ń ròyìn iṣẹ́ rere rẹ̀ fún mi, wọ́n sì ń sọ ohun tí mo sọ fún un. Tobiah sì ń kọ àwọn lẹ́tà ránṣẹ́ sí mi láti dẹ́rùbà mí.
Ils vantaient aussi ses mérites devant moi et lui rapportaient mes paroles; Tobia, lui, envoyait des lettres pour m’intimider.

< Nehemiah 6 >