< Nehemiah 5 >

1 Nísinsin yìí àwọn ènìyàn àti àwọn ìyàwó wọn kígbe ńlá sókè sí àwọn Júù arákùnrin wọn.
U qaƣda halayiⱪ wǝ ularning hotunliri ɵz ⱪerindaxliri bolƣan Yǝⱨudalar üstidin xikayǝt ⱪilip ⱪattiⱪ dad-pǝryad kɵtürüxti.
2 Àwọn kan ń wí pé, “Àwa àti àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wa pọ̀; kí àwa kí ó le è jẹ, kí a sì wà láààyè, a gbọdọ̀ rí oúnjẹ.”
Bǝzilǝr: — Biz wǝ oƣul-ⱪizlirimizning jan sanimiz kɵp, kün kǝqüriximiz üqün toyƣudǝk axliⱪ almisaⱪ bolmaydu, deyixti.
3 Àwọn mìíràn wí pé, “Àwa ti fi oko wa ọgbà àjàrà wa àti ilé wa dógò kí àwa kí ó lè rí oúnjẹ ní àkókò ìyàn.”
Yǝnǝ bǝzilǝr: — Biz aqarqiliⱪta ⱪalƣan waⱪtimizda axliⱪ elip yǝymiz dǝp etizlirimiz, üzümzarliⱪlirimizni wǝ ɵylirimizni rǝnigǝ berixkǝ mǝjbur bolduⱪ, deyixti.
4 Síbẹ̀ àwọn mìíràn wí pé, “Àwa ní láti yá owó láti san ìṣákọ́lẹ̀ fún ọba lórí àwọn oko wa àti àwọn ọgbà àjàrà wa.
Wǝ yǝnǝ bǝzilǝr: — Padixaⱨning etizlirimiz wǝ üzümzarliⱪlirimiz üstigǝ salƣan baj-seliⱪni tapxuruxⱪa pul ⱪǝrz alduⱪ.
5 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a jẹ́ ẹran-ara kan àti ẹ̀jẹ̀ kan gẹ́gẹ́ bí àwọn ará ìlú wa tí àwọn ọmọkùnrin wa sì dára bí í tiwọn, síbẹ̀ àwa ní láti fi àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wa sí oko ẹrú. Díẹ̀ nínú àwọn ọmọbìnrin wa ti wà lóko ẹrú náà, ṣùgbọ́n àwa kò ní agbára, nítorí àwọn oko àti ọgbà àjàrà wa ti di ti ẹlòmíràn.”
Gǝrqǝ bǝdǝnlirimiz ⱪerindaxlirimizning bǝdǝnlirigǝ, pǝrzǝntlirimiz ularning pǝrzǝntlirigǝ ohxax bolsimu, lekin oƣul-ⱪizlirimizni ⱪul-dedǝk boluxⱪa tapxurmay amalimiz bolmidi; ǝmǝliyǝttǝ ⱪizlirimizdin bǝziliri alliⱪaqan dedǝk bolupmu kǝtti; ularni bǝdǝl tɵlǝp ⱨɵrlükkǝ qiⱪirixⱪa ⱪurbimiz yǝtmidi, qünki bizning etizlar wǝ üzümzarliⱪlirimiz ⱨazir baxⱪilarning ⱪolididur, — deyixti.
6 Èmi bínú gidigidi nígbà tí mo gbọ́ igbe wọn àti àwọn ẹ̀sùn wọ̀nyí.
Mǝn ularning dad-pǝryadlirini wǝ eytⱪan bu gǝplirini angliƣandin keyin ⱪattiⱪ ƣǝzǝplǝndim.
7 Mo rò wọ́n wò ní ọkàn mi mo sì fi ẹ̀sùn kan ọlọ́lá àti àwọn ìjòyè. Mo sọ fún wọn pé, ẹ̀yin ń gba owó èlé lọ́wọ́ àwọn ará ìlú u yín! Nítorí náà mo pe àpéjọ ńlá láti bá wọn wí.
Kɵnglümdǝ birǝr ⱪur oyliniwalƣandin keyin, mɵtiwǝrlǝr bilǝn ǝmǝldarlarni ǝyiblǝp: — Silǝr ɵz ⱪerindaxliringlarƣa ⱪǝrz berip ulardin ɵsüm alidikǝnsilǝr-ⱨǝ! — dǝp tǝnbiⱨ bǝrdim. Andin ularning sǝwǝbidin qong bir yiƣin eqip
8 Mo sì wí fún wọn pé, “Níbi tí àwa ní agbára mọ, àwa ti ra àwọn Júù arákùnrin wa tí a ti tà fún àwọn tí kì í ṣe Júù padà. Nísinsin yìí ẹ̀yìn ń ta àwọn arákùnrin yín, tí àwa sì tún ní láti rà wọ́n padà!” Wọ́n dákẹ́, nítorí wọn kò rí ohunkóhun sọ.
ularni: — Biz küqimizning yetixiqǝ yat taipilǝrgǝ setiwetilgǝn ⱪerindiximiz Yǝⱨudalarni ⱪayturup setiwalduⱪ, lekin silǝr bizni ularni ⱪayturup setiwalsun dǝp ⱪerindaxliringlarni yǝnǝ setiwǝtmǝkqi boluwatamsilǝr? — dǝp ǝyibliwidim, ular dǝydiƣan gǝp tapalmay, xük turup ⱪaldi.
9 Nítorí náà, mo tẹ̀síwájú pé, “Ohun tí ẹ̀ ń ṣe kò dára. Kò ha yẹ kí ẹ máa rìn nínú ìbẹ̀rù Ọlọ́run bí, láti yẹra fún ẹ̀gàn àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn tí í ṣe ọ̀tá wa?
Andin mǝn ularƣa yǝnǝ: — Silǝrning bu ⱪilƣininglar ⱪamlaxmaptu. Silǝr düxmǝnlirimiz bolƣan taipilǝr aldida bizni aⱨanǝtkǝ ⱪaldurmay, Hudayimizning ⱪorⱪunqida mangsanglar bolmasmidi?
10 Èmi àti àwọn arákùnrin mi àti àwọn ènìyàn mi, pẹ̀lú ń yá àwọn ènìyàn lówó àti oúnjẹ. Ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí a dáwọ́ owó èlé gbígbà yìí dúró!
Mǝnmu, ⱪerindaxlirim wǝ hizmǝtkarlirim ularƣa pul wǝ axliⱪ ɵtnǝ berip turup ɵsüm alsaⱪ alattuⱪ! Silǝrdin ɵtünimǝn, mundaⱪ ɵsüm elixtin waz keqǝyli!
11 Ẹ fún wọn ní oko wọn, ọgbà àjàrà wọn, ọgbà olifi wọn àti ilé e wọn pẹ̀lú owó èlé tí ẹ ti gbà lọ́wọ́ wọn ìdá ọgọ́rùn-ún owó, oúnjẹ, wáìnì tuntun àti òróró tí ẹ ti gbà lọ́wọ́ wọn padà kíákíá.”
Ɵtünüp ⱪalay, silǝr dǝl bügün ularning etizlirini, üzümzarliⱪ, zǝytunzarliⱪ wǝ ɵylirini ⱪayturup beringlar, wǝ xuningdǝk silǝr ulardin ündürüwalƣan pul, axliⱪ, yengi mǝy-xarab wǝ yengi zǝytun maylirining ɵsümini ularƣa ⱪayturup beringlar, dedim.
12 Wọ́n wí pé, “Àwa yóò dá a padà. Àwa kì yóò sì béèrè ohunkóhun lọ́wọ́ wọn mọ́. Àwa yóò ṣe bí o ti wí.” Nígbà náà mo pe àwọn àlùfáà, mo sì mú kí àwọn ọlọ́lá àti àwọn ìjòyè búra láti jẹ́ kí wọ́n ṣe ohun tí wọ́n ti ṣe ìlérí.
Ular: — Ⱪayturup berimiz, ǝmdi ulardin ⱨeq ɵsüm almaymiz; sili nemǝ desilǝ, biz xundaⱪ ⱪilimiz, deyixti. Mǝn kaⱨinlarni qaⱪirtip kelip, ularni bu wǝdǝ boyiqǝ xundaⱪ ijra ⱪilixⱪa ⱪǝsǝm iqküzdüm.
13 Mo sì gbọn ìṣẹ́tí aṣọ mi, mo wí pé, “Báyìí ni kí Ọlọ́run gbọn olúkúlùkù ènìyàn tí kò bá pa ìlérí yìí mọ́ jáde kúrò ní ilẹ̀ ìní i rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni kí a gbọn irú ẹni bẹ́ẹ̀ jáde kí ó sì ṣófo!” Gbogbo ìjọ ènìyàn sì wí pé, “Àmín,” wọ́n sì fi ìyìn fún Olúwa. Àwọn ènìyàn náà sì ṣe bí wọ́n ti ṣe ìlérí.
Mǝn tonumning pexini ⱪeⱪip turup: — Kim muxu wǝdini ada ⱪilmisa, Huda xu yol bilǝn uning ɵzini ɵz ɵyidin wǝ mal-mülkidin mǝⱨrum ⱪilip ⱪeⱪiwǝtsun! Xu yol bilǝn uning ⱨǝmmǝ nemisi ⱪuruⱪdilip ⱪalƣuqǝ ⱪeⱪiwetilsun! — dedim. Pütkül jamaǝt birdǝk: «Amin!» deyixti ⱨǝm Pǝrwǝrdigarƣa Ⱨǝmdusana oⱪuxti. Andin kɵpqilik xu wǝdisi boyiqǝ deginidǝk ⱪilixti.
14 Síwájú sí í, láti ogún ọdún ọba Artasasta, nígbà tí a ti yàn mí láti jẹ́ baálẹ̀ wọn ní ilẹ̀ Juda, títí di ọdún kejìlélọ́gbọ̀n ìjọba rẹ̀—ọdún méjìlá, èmi àti àwọn arákùnrin mi kò jẹ oúnjẹ baálẹ̀.
Xuningdǝk, Yǝⱨudiyǝ zeminida ularƣa waliy boluxⱪa tiklǝngǝn kündin buyan, yǝni padixaⱨ Artahxaxtaning yigirminqi yilidin ottuz ikkinqi yiliƣiqǝ bolƣan on ikki yil iqidǝ nǝ mǝn, nǝ mening uruⱪ-tuƣⱪanlirim waliyliⱪ nenini ⱨeq yemiduⱪ.
15 Ṣùgbọ́n àwọn baálẹ̀ ìṣáájú—tí ó ti wà ṣáájú mi—gbe àjàgà wúwo lé àwọn ènìyàn lórí yàtọ̀ fún oúnjẹ àti wáìnì wọ́n sì tún gba ogójì ṣékélì fàdákà lọ́wọ́ wọn. Kódà àwọn ìránṣẹ́ wọn tún jẹ gàba lórí wọn. Ṣùgbọ́n èmi kò ṣe bẹ́ẹ̀ nítorí ìbẹ̀rù Ọlọ́run.
Mǝndin ilgiri waliy bolƣanlar hǝlⱪⱪǝ eƣirqilik selip, ulardin [kündilik] axliⱪ, mǝy-xarab wǝ xuningdǝk ⱪiriⱪ xǝkǝl kümüx elip kǝlgǝnikǝn; ⱨǝtta ularning hizmǝtkarlirimu hǝlⱪning üstidin ⱨoⱪuⱪwazliⱪ ⱪilip kǝlgǝnikǝn. Lekin mǝn Hudadin ⱪorⱪidiƣinim üqün undaⱪ ⱪilmidim.
16 Dípò bẹ́ẹ̀, mo fi ara mi jì fún iṣẹ́ lórí odi yìí. Gbogbo àwọn ènìyàn mi péjọ síbẹ̀ fún iṣẹ́ náà; a kò sì gba ilẹ̀ kankan.
Mǝn dǝrwǝⱪǝ sepilning ⱪuruluxiƣila berilgǝqkǝ, biz ⱨǝtta birǝr etiznimu setiwalmiduⱪ; mening barliⱪ hizmǝtkarlirimmu ⱪuruluxta ixlǝxkǝ xu yǝrgǝ yiƣilatti.
17 Síwájú sí í, àádọ́jọ àwọn Júù àti àwọn ìjòyè jẹun lórí tábìlì mi, àti pẹ̀lú àwọn tí wọ́n wá bá wa láti àwọn orílẹ̀-èdè tí ó yí wa ká.
Ətrapimizdiki yat ǝllǝrdin bizning yenimizƣa kǝlgǝnlǝrdin bɵlǝk, mening bilǝn bir dastihanda ƣiza yǝydiƣanlar Yǝⱨudiylar wǝ ǝmǝldarlardin bir yüz ǝllik kixi idi.
18 Ní ọjọ́ kọ̀ọ̀kan ni a máa ń pèsè màlúù kan, ààyò àgùntàn mẹ́fà àti adìyẹ fún mi àti lẹ́ẹ̀kan ní ọjọ́ mẹ́wàá ni wọ́n máa ń pèsè onírúurú wáìnì tí ó pọ̀ fún mi. Fún gbogbo èyí, èmi kò béèrè oúnjẹ baálẹ̀, nítorí ohun ti a ń béèrè lọ́wọ́ àwọn ènìyàn wọ̀nyí pọ̀ jọjọ.
Ⱨǝrküni bir kala, hillanƣan altǝ ⱪoy tǝyyarlinatti, yǝnǝ manga bǝzi uqar ⱪuxlar tǝyyarlinatti; ⱨǝr on kündǝ bir ⱪetim ⱨǝrhil mol mǝy-xarab bilǝn tǝminlinǝtti. Xundaⱪ bolsimu mǝn yǝnila «waliy neni»ni tǝlǝp ⱪilmidim; qünki ⱪurulux Ixi hǝlⱪning üstidiki eƣir yük idi.
19 Rántí mi, Ọlọ́run mi, fún rere, nítorí fún gbogbo ohun tí mo ti ṣe fún àwọn ènìyàn yìí.
— Aⱨ Hudayim, mǝn muxu hǝlⱪ üqün ⱪilƣan barliⱪ iximni yad ǝtkǝysǝn, manga xapaǝt kɵrsǝtkǝysǝn!

< Nehemiah 5 >