< Nehemiah 5 >

1 Nísinsin yìí àwọn ènìyàn àti àwọn ìyàwó wọn kígbe ńlá sókè sí àwọn Júù arákùnrin wọn.
و قوم و زنان ایشان، بر برادران یهود خودفریاد عظیمی برآوردند.۱
2 Àwọn kan ń wí pé, “Àwa àti àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wa pọ̀; kí àwa kí ó le è jẹ, kí a sì wà láààyè, a gbọdọ̀ rí oúnjẹ.”
و بعضی ازایشان گفتند که «ما و پسران و دختران ما بسیاریم. پس گندم بگیریم تا بخوریم و زنده بمانیم.»۲
3 Àwọn mìíràn wí pé, “Àwa ti fi oko wa ọgbà àjàrà wa àti ilé wa dógò kí àwa kí ó lè rí oúnjẹ ní àkókò ìyàn.”
وبعضی گفتند: «مزرعه‌ها و تاکستانها و خانه های خود را گرو می‌دهیم تا به‌سبب قحط، گندم بگیریم.»۳
4 Síbẹ̀ àwọn mìíràn wí pé, “Àwa ní láti yá owó láti san ìṣákọ́lẹ̀ fún ọba lórí àwọn oko wa àti àwọn ọgbà àjàrà wa.
و بعضی گفتند که «نقره را به عوض مزرعه‌ها و تاکستانهای خود برای جزیه پادشاه قرض گرفتیم.۴
5 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a jẹ́ ẹran-ara kan àti ẹ̀jẹ̀ kan gẹ́gẹ́ bí àwọn ará ìlú wa tí àwọn ọmọkùnrin wa sì dára bí í tiwọn, síbẹ̀ àwa ní láti fi àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wa sí oko ẹrú. Díẹ̀ nínú àwọn ọmọbìnrin wa ti wà lóko ẹrú náà, ṣùgbọ́n àwa kò ní agbára, nítorí àwọn oko àti ọgbà àjàrà wa ti di ti ẹlòmíràn.”
و حال جسد ما مثل جسدهای برادران ماست و پسران ما مثل پسران ایشان واینک ما پسران و دختران خود را به بندگی می‌سپاریم و بعضی از دختران ما کنیز شده‌اند ودر دست ما هیچ استطاعتی نیست زیرا که مزرعه‌ها و تاکستانهای ما از آن دیگران شده است.»۵
6 Èmi bínú gidigidi nígbà tí mo gbọ́ igbe wọn àti àwọn ẹ̀sùn wọ̀nyí.
پس چون فریاد ایشان و این سخنان را شنیدم بسیار غضبناک شدم.۶
7 Mo rò wọ́n wò ní ọkàn mi mo sì fi ẹ̀sùn kan ọlọ́lá àti àwọn ìjòyè. Mo sọ fún wọn pé, ẹ̀yin ń gba owó èlé lọ́wọ́ àwọn ará ìlú u yín! Nítorí náà mo pe àpéjọ ńlá láti bá wọn wí.
و با دل خود مشورت کرده، بزرگان و سروران را عتاب نمودم و به ایشان گفتم: «شما هر کس از برادر خود ربا می‌گیرید!» وجماعتی عظیم به ضد ایشان جمع نمودم.۷
8 Mo sì wí fún wọn pé, “Níbi tí àwa ní agbára mọ, àwa ti ra àwọn Júù arákùnrin wa tí a ti tà fún àwọn tí kì í ṣe Júù padà. Nísinsin yìí ẹ̀yìn ń ta àwọn arákùnrin yín, tí àwa sì tún ní láti rà wọ́n padà!” Wọ́n dákẹ́, nítorí wọn kò rí ohunkóhun sọ.
و به ایشان گفتم: «ما برادران یهود خود را که به امت هافروخته شده‌اند، حتی المقدور فدیه کرده‌ایم. وآیا شما برادران خود را می‌فروشید و آیا می‌شودکه ایشان به ما فروخته شوند؟» پس خاموش شده، جوابی نیافتند.۸
9 Nítorí náà, mo tẹ̀síwájú pé, “Ohun tí ẹ̀ ń ṣe kò dára. Kò ha yẹ kí ẹ máa rìn nínú ìbẹ̀rù Ọlọ́run bí, láti yẹra fún ẹ̀gàn àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn tí í ṣe ọ̀tá wa?
و گفتم: «کاری که شما می‌کنید خوب نیست، آیا نمی باید شما به‌سبب ملامت امت هایی که دشمن ما می‌باشند، در ترس خدای ما سلوک نمایید؟۹
10 Èmi àti àwọn arákùnrin mi àti àwọn ènìyàn mi, pẹ̀lú ń yá àwọn ènìyàn lówó àti oúnjẹ. Ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí a dáwọ́ owó èlé gbígbà yìí dúró!
و نیز من و برادران و بندگانم نقره و غله به ایشان قرض داده‌ایم. پس سزاواراست که این ربا را ترک نماییم.۱۰
11 Ẹ fún wọn ní oko wọn, ọgbà àjàrà wọn, ọgbà olifi wọn àti ilé e wọn pẹ̀lú owó èlé tí ẹ ti gbà lọ́wọ́ wọn ìdá ọgọ́rùn-ún owó, oúnjẹ, wáìnì tuntun àti òróró tí ẹ ti gbà lọ́wọ́ wọn padà kíákíá.”
و الان امروزمزرعه‌ها و تاکستانها و باغات زیتون و خانه های ایشان و صد یک از نقره و غله و عصیر انگور وروغن که بر ایشان نهاده‌اید به ایشان رد کنید.»۱۱
12 Wọ́n wí pé, “Àwa yóò dá a padà. Àwa kì yóò sì béèrè ohunkóhun lọ́wọ́ wọn mọ́. Àwa yóò ṣe bí o ti wí.” Nígbà náà mo pe àwọn àlùfáà, mo sì mú kí àwọn ọlọ́lá àti àwọn ìjòyè búra láti jẹ́ kí wọ́n ṣe ohun tí wọ́n ti ṣe ìlérí.
پس جواب دادند که «رد خواهیم کرد و ازایشان مطالبه نخواهیم نمود و چنانکه تو فرمودی به عمل خواهیم آورد.» آنگاه کاهنان را خوانده، به ایشان قسم دادم که بروفق این کلام رفتارنمایند.۱۲
13 Mo sì gbọn ìṣẹ́tí aṣọ mi, mo wí pé, “Báyìí ni kí Ọlọ́run gbọn olúkúlùkù ènìyàn tí kò bá pa ìlérí yìí mọ́ jáde kúrò ní ilẹ̀ ìní i rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni kí a gbọn irú ẹni bẹ́ẹ̀ jáde kí ó sì ṣófo!” Gbogbo ìjọ ènìyàn sì wí pé, “Àmín,” wọ́n sì fi ìyìn fún Olúwa. Àwọn ènìyàn náà sì ṣe bí wọ́n ti ṣe ìlérí.
پس دامن خود را تکانیده گفتم: «خداهر کس را که این کلام را ثابت ننماید، از خانه وکسبش چنین بتکاند و به این قسم تکانیده و خالی بشود.» پس تمامی جماعت گفتند آمین وخداوند را تسبیح خواندند و قوم برحسب این کلام عمل نمودند.۱۳
14 Síwájú sí í, láti ogún ọdún ọba Artasasta, nígbà tí a ti yàn mí láti jẹ́ baálẹ̀ wọn ní ilẹ̀ Juda, títí di ọdún kejìlélọ́gbọ̀n ìjọba rẹ̀—ọdún méjìlá, èmi àti àwọn arákùnrin mi kò jẹ oúnjẹ baálẹ̀.
و نیز از روزی که به والی بودن زمین یهوه مامور شدم، یعنی از سال بیستم تا سال سی و دوم ارتحشستا پادشاه، که دوازده سال بود من وبرادرانم وظیفه والیگری را نخوردیم.۱۴
15 Ṣùgbọ́n àwọn baálẹ̀ ìṣáájú—tí ó ti wà ṣáájú mi—gbe àjàgà wúwo lé àwọn ènìyàn lórí yàtọ̀ fún oúnjẹ àti wáìnì wọ́n sì tún gba ogójì ṣékélì fàdákà lọ́wọ́ wọn. Kódà àwọn ìránṣẹ́ wọn tún jẹ gàba lórí wọn. Ṣùgbọ́n èmi kò ṣe bẹ́ẹ̀ nítorí ìbẹ̀rù Ọlọ́run.
اماوالیان اول که قبل از من بودند بر قوم بار سنگین نهاده، علاوه بر چهل مثقال نقره، نان و شراب نیزاز ایشان می‌گرفتند و خادمان ایشان بر قوم حکمرانی می‌کردند. لیکن من به‌سبب ترس خداچنین نکردم.۱۵
16 Dípò bẹ́ẹ̀, mo fi ara mi jì fún iṣẹ́ lórí odi yìí. Gbogbo àwọn ènìyàn mi péjọ síbẹ̀ fún iṣẹ́ náà; a kò sì gba ilẹ̀ kankan.
و من نیز در ساختن حصارمشغول می‌بودم و هیچ مزرعه نخریدیم و همه بندگان من در آنجا به‌کار جمع بودند.۱۶
17 Síwájú sí í, àádọ́jọ àwọn Júù àti àwọn ìjòyè jẹun lórí tábìlì mi, àti pẹ̀lú àwọn tí wọ́n wá bá wa láti àwọn orílẹ̀-èdè tí ó yí wa ká.
و صد وپنجاه نفر از یهودیان و سروران، سوای آنانی که ازامت های مجاور ما نزد ما می‌آمدند، بر سفره من خوراک می‌خوردند.۱۷
18 Ní ọjọ́ kọ̀ọ̀kan ni a máa ń pèsè màlúù kan, ààyò àgùntàn mẹ́fà àti adìyẹ fún mi àti lẹ́ẹ̀kan ní ọjọ́ mẹ́wàá ni wọ́n máa ń pèsè onírúurú wáìnì tí ó pọ̀ fún mi. Fún gbogbo èyí, èmi kò béèrè oúnjẹ baálẹ̀, nítorí ohun ti a ń béèrè lọ́wọ́ àwọn ènìyàn wọ̀nyí pọ̀ jọjọ.
و آنچه برای هر روز مهیامی شد، یک گاو و شش گوسفند پرواری می‌بود ومرغها نیز برای من حاضر می‌کردند و هر ده روز مقداری کثیر از هر گونه شراب. اما معهذا وظیفه والیگری را نطلبیدم زیرا که بندگی سخت بر این قوم می‌بود.۱۸
19 Rántí mi, Ọlọ́run mi, fún rere, nítorí fún gbogbo ohun tí mo ti ṣe fún àwọn ènìyàn yìí.
‌ای خدایم موافق هر‌آنچه به این قوم عمل نمودم مرا به نیکویی یاد آور.۱۹

< Nehemiah 5 >