< Nehemiah 4 >

1 Nígbà tí Sanballati gbọ́ pé àwa ń tún odi náà mọ, ó bínú, ó sì bínú púpọ̀. Ó fi àwọn ará Júù ṣe ẹlẹ́yà,
Toda pripetilo se je, da ko je Sanbalát slišal, da smo gradili zid, da je bil besen in polastilo se ga je veliko ogorčenje in zasmehoval je Jude.
2 ó sọ níwájú àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ àti níwájú àwọn ọmọ-ogun Samaria pé, “Kí ni àwọn aláìlera Júù wọ̀nyí ń ṣe yìí? Ṣé wọn yóò mú odi wọn padà ni? Ṣé wọn yóò rú ẹbọ ni? Ṣé wọn yóò parí i rẹ̀ lóòjọ́ ni bí? Ṣé wọ́n lè mú òkúta tí a ti sun láti inú òkìtì padà bọ̀ sípò tí ó jóná bí wọ́n ṣe wà?”
Pred svojimi brati in vojsko Samarije je spregovoril ter rekel: »Kaj počno ti slabotni Judje? Mar se bodo utrdili? Mar bodo žrtvovali? Mar bodo končali v [enem] dnevu? Mar bodo oživili kamne iz kupov smeti, ki so požgane?«
3 Tobiah ará Ammoni, ẹni tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, wí pé, “Ohun tí wọ́n ń mọ—bí kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ lásán bá gùn ún sókè, yóò fọ́ odi òkúta wọn lulẹ̀!”
Torej Amónec Tobija je bil ob njem in rekel: »Celo to, kar so zgradili, če gre gor lisjak, bo torej porušil njihov kamniti zid.«
4 Gbọ́ ti wa, Ọlọ́run wa, nítorí àwa di ẹni ẹ̀gàn. Dá ẹ̀gàn wọn padà sórí ara wọn. Kí o sì fi wọ́n fún ìkógun ní ilẹ̀ ìgbèkùn.
Prisluhni, oh naš Bog, kajti mi smo prezirani. Obrni njihovo grajo na njihovo lastno glavo in jih daj za plen v deželi ujetništva
5 Má ṣe bo ẹ̀bi wọn tàbí wẹ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wọn nù kúrò níwájú rẹ, nítorí wọ́n mú ọ bínú níwájú àwọn ọ̀mọ̀lé.
in ne pokrij njihove krivičnosti in naj njihov greh ne bo izbrisan izpred tebe, kajti do jeze so te izzivali pred graditelji.
6 Bẹ́ẹ̀ ni àwa mọ odi náà títí gbogbo rẹ̀ fi dé ìdajì gíga rẹ̀, nítorí àwọn ènìyàn ṣiṣẹ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn an wọn.
Tako smo gradili obzidje in vse obzidje je bilo združeno skupaj do njegove polovice, kajti ljudstvo je imelo um, da dela.
7 Ṣùgbọ́n nígbà tí Sanballati, Tobiah, àwọn ará Arabia, ará Ammoni, àti àwọn ènìyàn Aṣdodu gbọ́ pé àtúnṣe odi Jerusalẹmu ti ga dé òkè àti pé a ti mọ àwọn ibi tí ó yá dí, inú bí wọn gidigidi.
Toda pripetilo se je, da ko so Sanbalát, Tobija, Arabci, Amónci in Ašdódčani slišali, da so bili zidovi Jeruzalema postavljeni in da so se vrzeli začele zapolnjevati, potem so bili zelo besni
8 Gbogbo wọn jọ gbìmọ̀ pọ̀ láti wá bá Jerusalẹmu jà àti láti dìde wàhálà sí í.
in vsi skupaj so skovali zaroto, da pridejo in se borijo zoper Jeruzalem in da to ovirajo.
9 Ṣùgbọ́n àwa gbàdúrà sí Ọlọ́run wa, a sì yan olùṣọ́ ọ̀sán àti ti òru láti kojú ìhàlẹ̀ yìí.
Kljub temu smo naredili svojo molitev k svojemu Bogu in podnevi ter ponoči zaradi njih postavili stražo.
10 Lákòókò yìí, àwọn ènìyàn Juda wí pé, “Agbára àwọn òṣìṣẹ́ ti dínkù, àlàpà púpọ̀ ni ó wà tó bẹ́ẹ̀ tí àwa kò fi le è mọ odi náà.”
Juda je rekel: »Moč nosilcev bremen je oslabela in tam je veliko smeti, tako, da nismo zmožni graditi obzidja.«
11 Bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn ọ̀tá wa wí pé, “Kí wọn tó mọ̀ tàbí kí wọn tó rí wa, àwa yóò ti dé àárín wọn, a ó sì pa wọ́n, a ó sì dá iṣẹ́ náà dúró.”
Naši nasprotniki pa so rekli: »Ne bodo vedeli niti videli, dokler ne pridemo v sredo mednje in jih pobijemo in povzročimo, da delo preneha.«
12 Nígbà náà ni àwọn Júù tí ó ń gbé ní ẹ̀gbẹ́ wọn wá sọ fún wa ní ìgbà mẹ́wàá pé, “Ibikíbi tí ẹ̀yin bá padà sí, wọn yóò kọlù wá.”
Pripetilo pa se je, ko so prišli Judje, ki so prebivali poleg njih, da so nam desetkrat rekli: »Iz vseh krajev, od koder se boste vrnili k nam, bodo oni nad vami.«
13 Nítorí náà mo dá ènìyàn díẹ̀ dúró níbi tí ó rẹlẹ̀ jù lẹ́yìn odi ní ibi gbangba, mo fi wọ́n síbẹ̀ nípa àwọn ìdílé wọn, pẹ̀lú àwọn idà wọn, àwọn ọ̀kọ̀ wọn àti àwọn ọrun wọn.
Zato sem postavil na nižjih mestih za obzidjem in na višjih mestih, sem celo postavil ljudstvo po njihovih družinah, z njihovimi meči, njihovimi sulicami in njihovimi loki.
14 Lẹ́yìn ìgbà tí mo wo àwọn nǹkan yíká, mo dìde mo sì wí fún àwọn ọlọ́lá àwọn ìjòyè àti àwọn ènìyàn tókù pé, “Ẹ má ṣe bẹ̀rù u wọn. Ẹ rántí Olúwa, ẹni tí ó tóbi, tí ó sì ní ẹ̀rù, kí ẹ sì jà fún àwọn arákùnrin yín, àwọn ọmọkùnrin yín, àwọn ọmọbìnrin yín, àwọn ìyàwó yín àti àwọn ilé yín.”
Pogledal sem, vstal in rekel plemičem, vladarjem in ostalemu ljudstvu: »Ne bojte se jih. Spominjajte se Gospoda, ki je velik in strašen in borite se za svoje brate, svoje sinove in svoje hčere, svoje žene in svoje hiše.«
15 Nígbà tí àwọn ọ̀tá wa gbọ́ pé àwa ti mọ èrò wọn àti wí pé Ọlọ́run ti bà á jẹ́, gbogbo wa padà sí ibi odi, ẹnìkọ̀ọ̀kan sí ibi iṣẹ́ tirẹ̀.
Pripetilo se je, ko so naši sovražniki slišali, da nam je bilo to znano in je Bog njihovo namero privedel v nič, da smo se vsi izmed nas vrnili k obzidju, vsak k svojemu delu.
16 Láti ọjọ́ náà lọ, ìdajì àwọn ènìyàn ń ṣe iṣẹ́ náà, nígbà tí àwọn ìdajì tókù múra pẹ̀lú ọ̀kọ̀, asà, ọrun àti ìhámọ́ra. Àwọn ìjòyè sì pín ara wọn sẹ́yìn gbogbo ènìyàn Juda.
Pripetilo se je od tega časa naprej, da je polovica mojih služabnikov delala na delu, druga polovica pa je držala sulice, ščite, loke in brezrokavne verižne srajce in vladarji so bili zadaj za vso Judovo hišo.
17 Àwọn ẹni tí ó ń mọ odi. Àwọn tí ń ru àwọn ohun èlò ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú ọwọ́ kan, wọ́n sì fi ọwọ́ kejì di ohun ìjà mú,
Tisti, ki so gradili na obzidju in tisti, ki so nosili bremena, s tistimi, ki so prenašali, vsak je z eno roko opravljal delo, z drugo roko pa je držal orožje.
18 olúkúlùkù àwọn ọ̀mọ̀lé fi idà wọn sí ẹ̀gbẹ́ wọn bí wọ́n ṣe ń ṣiṣẹ́. Ṣùgbọ́n ọkùnrin tí ń fọn ìpè dúró pẹ̀lú mi.
Kajti graditelji so gradili tako, da je imel vsakdo svoj meč opasan ob svoji strani. Tisti, ki je trobil na šofar, pa je bil poleg mene.
19 Nígbà náà ni mo sọ fún àwọn ọlọ́lá, àwọn ìjòyè àti àwọn ènìyàn tókù pé, “Iṣẹ́ náà fẹ̀ ó sì pọ̀, a sì ti jìnnà sí ara wa púpọ̀ lórí odi.
Rekel sem plemičem, vladarjem in ostalemu ljudstvu: »Delo je veliko in obsežno, mi pa smo na obzidju ločeni, eden daleč od drugega.
20 Níbikíbi tí ẹ bá ti gbọ́ ohùn ìpè, ẹ da ara pọ̀ mọ́ wa níbẹ̀. Ọlọ́run wa yóò jà fún wa!”
Na katerem mestu torej zaslišite glas šofarja, krenite tja k nam. Naš Bog se bo boril za nas.«
21 Bẹ́ẹ̀ ni àwa ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú àwọn ìdajì ènìyàn tí ó di ọ̀kọ̀ mú, láti òwúrọ̀ kùtùkùtù títí di ìgbà tí ìràwọ̀ yóò fi yọ.
Tako smo se trudili na delu. Polovica izmed njih je sulice držala od jutranjega vzhoda do pojavitve zvezd.
22 Ní ìgbà náà mo tún sọ fún àwọn ènìyàn pé, “Jẹ́ kí olúkúlùkù ènìyàn àti olùrànlọ́wọ́ rẹ̀ dúró ní Jerusalẹmu ní òru, nítorí kí wọn le jẹ́ ẹ̀ṣọ́ fún wa ní òru, kí wọn sì le ṣe iṣẹ́ ní ọ̀sán.”
Prav tako sem ljudstvu istočasno rekel: »Naj vsak s svojim služabnikom prenočuje znotraj Jeruzalema, da nam bodo ponoči lahko straža in se trudili podnevi.«
23 Bẹ́ẹ̀ ni èmi àti àwọn arákùnrin mi àti àwọn ènìyàn mi àti àwọn ẹ̀ṣọ́ tí ó wà pẹ̀lú mi kò bọ́ aṣọ wa, olúkúlùkù wa ní ohun ìjà tirẹ̀, kódà nígbà tí wọ́n bá ń lọ pọn omi.
Tako niti jaz, niti moji bratje, niti moji služabniki, niti ljudje na straži, ki so mi sledili, nihče izmed nas ni odložil svojih oblačil, razen, da jih je vsak slekel za pranje.

< Nehemiah 4 >