< Nehemiah 4 >

1 Nígbà tí Sanballati gbọ́ pé àwa ń tún odi náà mọ, ó bínú, ó sì bínú púpọ̀. Ó fi àwọn ará Júù ṣe ẹlẹ́yà,
Dar s-a întâmplat că, atunci când Sanbalat a auzit că noi am construit zidul, s-a înfuriat și s-a aprins mult și a batjocorit pe iudei.
2 ó sọ níwájú àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ àti níwájú àwọn ọmọ-ogun Samaria pé, “Kí ni àwọn aláìlera Júù wọ̀nyí ń ṣe yìí? Ṣé wọn yóò mú odi wọn padà ni? Ṣé wọn yóò rú ẹbọ ni? Ṣé wọn yóò parí i rẹ̀ lóòjọ́ ni bí? Ṣé wọ́n lè mú òkúta tí a ti sun láti inú òkìtì padà bọ̀ sípò tí ó jóná bí wọ́n ṣe wà?”
Și a vorbit înaintea fraților săi și a armatei Samariei și a spus: Ce fac acești iudei slabi? Se vor întări ei? Vor sacrifica ei? Vor termina ei într-o zi? Vor reînvia ei pietrele din grămezile de moloz care sunt arse?
3 Tobiah ará Ammoni, ẹni tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, wí pé, “Ohun tí wọ́n ń mọ—bí kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ lásán bá gùn ún sókè, yóò fọ́ odi òkúta wọn lulẹ̀!”
Și Tobia amonitul era lângă el și a spus: Ceea ce ei construiesc dacă doar o vulpe s-ar urca, ar dărâma zidul lor de piatră.
4 Gbọ́ ti wa, Ọlọ́run wa, nítorí àwa di ẹni ẹ̀gàn. Dá ẹ̀gàn wọn padà sórí ara wọn. Kí o sì fi wọ́n fún ìkógun ní ilẹ̀ ìgbèkùn.
Auzi, Dumnezeul nostru, pentru că suntem disprețuiți; și întoarce ocara lor asupra capului lor și dă-i ca pradă în țara captivității;
5 Má ṣe bo ẹ̀bi wọn tàbí wẹ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wọn nù kúrò níwájú rẹ, nítorí wọ́n mú ọ bínú níwájú àwọn ọ̀mọ̀lé.
Și nu acoperi nelegiuirea lor și să nu fie șters păcatul lor dinaintea ta, pentru că ei te-au provocat la mânie înaintea celor care construiesc.
6 Bẹ́ẹ̀ ni àwa mọ odi náà títí gbogbo rẹ̀ fi dé ìdajì gíga rẹ̀, nítorí àwọn ènìyàn ṣiṣẹ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn an wọn.
Astfel am construit noi zidul; și tot zidul a fost îmbinat până la jumătatea lui, pentru că poporul avea inimă să muncească.
7 Ṣùgbọ́n nígbà tí Sanballati, Tobiah, àwọn ará Arabia, ará Ammoni, àti àwọn ènìyàn Aṣdodu gbọ́ pé àtúnṣe odi Jerusalẹmu ti ga dé òkè àti pé a ti mọ àwọn ibi tí ó yá dí, inú bí wọn gidigidi.
Dar s-a întâmplat, când au auzit Sanbalat și Tobia și arabii și amoniții și asdodiții că zidurile Ierusalimului erau ridicate și că spărturile începeau să fie astupate, că s-au înfuriat foarte tare,
8 Gbogbo wọn jọ gbìmọ̀ pọ̀ láti wá bá Jerusalẹmu jà àti láti dìde wàhálà sí í.
Și au uneltit toți împreună să vină și să lupte împotriva Ierusalimului și să îl împiedice.
9 Ṣùgbọ́n àwa gbàdúrà sí Ọlọ́run wa, a sì yan olùṣọ́ ọ̀sán àti ti òru láti kojú ìhàlẹ̀ yìí.
Totuși noi ne-am făcut rugăciunea către Dumnezeul nostru și am pus o gardă împotriva lor zi și noapte, din cauza lor.
10 Lákòókò yìí, àwọn ènìyàn Juda wí pé, “Agbára àwọn òṣìṣẹ́ ti dínkù, àlàpà púpọ̀ ni ó wà tó bẹ́ẹ̀ tí àwa kò fi le è mọ odi náà.”
Și Iuda a spus: Puterea purtătorilor de poveri este slăbită și este mult moloz; astfel încât nu suntem în stare să construim zidul.
11 Bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn ọ̀tá wa wí pé, “Kí wọn tó mọ̀ tàbí kí wọn tó rí wa, àwa yóò ti dé àárín wọn, a ó sì pa wọ́n, a ó sì dá iṣẹ́ náà dúró.”
Și potrivnicii noștri au spus: Nu vor ști, nici nu vor vedea, până vom ajunge în mijlocul lor și îi vom ucide și vom face ca lucrarea să înceteze.
12 Nígbà náà ni àwọn Júù tí ó ń gbé ní ẹ̀gbẹ́ wọn wá sọ fún wa ní ìgbà mẹ́wàá pé, “Ibikíbi tí ẹ̀yin bá padà sí, wọn yóò kọlù wá.”
Și s-a întâmplat că, atunci când iudeii, care locuiau lângă ei, au venit, ne-au spus de zece ori: Oriunde vă veți întoarce, ei vor fi peste voi.
13 Nítorí náà mo dá ènìyàn díẹ̀ dúró níbi tí ó rẹlẹ̀ jù lẹ́yìn odi ní ibi gbangba, mo fi wọ́n síbẹ̀ nípa àwọn ìdílé wọn, pẹ̀lú àwọn idà wọn, àwọn ọ̀kọ̀ wọn àti àwọn ọrun wọn.
De aceea am pus în locurile mai de jos în spatele zidului și în locurile mai înalte, chiar eu am așezat poporul după familiile lor cu săbiile lor, cu sulițele lor și cu arcurile lor.
14 Lẹ́yìn ìgbà tí mo wo àwọn nǹkan yíká, mo dìde mo sì wí fún àwọn ọlọ́lá àwọn ìjòyè àti àwọn ènìyàn tókù pé, “Ẹ má ṣe bẹ̀rù u wọn. Ẹ rántí Olúwa, ẹni tí ó tóbi, tí ó sì ní ẹ̀rù, kí ẹ sì jà fún àwọn arákùnrin yín, àwọn ọmọkùnrin yín, àwọn ọmọbìnrin yín, àwọn ìyàwó yín àti àwọn ilé yín.”
Și m-am uitat și m-am ridicat și am spus nobililor și conducătorilor și restului poporului: Nu vă temeți de ei; amintiți-vă de DOMNUL, care este mare și înfricoșător, și luptați pentru frații voștri, fiii voștri și fiicele voastre, soțiile voastre și casele voastre.
15 Nígbà tí àwọn ọ̀tá wa gbọ́ pé àwa ti mọ èrò wọn àti wí pé Ọlọ́run ti bà á jẹ́, gbogbo wa padà sí ibi odi, ẹnìkọ̀ọ̀kan sí ibi iṣẹ́ tirẹ̀.
Și s-a întâmplat, când dușmanii noștri au auzit că ni s-a făcut cunoscut și că Dumnezeu făcuse sfatul lor de nimic, că noi ne-am întors cu toții la zid, fiecare la lucrarea sa.
16 Láti ọjọ́ náà lọ, ìdajì àwọn ènìyàn ń ṣe iṣẹ́ náà, nígbà tí àwọn ìdajì tókù múra pẹ̀lú ọ̀kọ̀, asà, ọrun àti ìhámọ́ra. Àwọn ìjòyè sì pín ara wọn sẹ́yìn gbogbo ènìyàn Juda.
Și s-a întâmplat, de atunci înainte, că jumătate din servitorii mei lucrau în lucrare și cealaltă jumătate din ei purtau deopotrivă sulițele, scuturile și arcurile și armurile; și conducătorii erau în spatele întregii case a lui Iuda.
17 Àwọn ẹni tí ó ń mọ odi. Àwọn tí ń ru àwọn ohun èlò ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú ọwọ́ kan, wọ́n sì fi ọwọ́ kejì di ohun ìjà mú,
Cei care construiau zidul și cei care purtau poveri, cu cei care încărcau, fiecare cu o mână lucra în lucrare și cu cealaltă ținea o armă.
18 olúkúlùkù àwọn ọ̀mọ̀lé fi idà wọn sí ẹ̀gbẹ́ wọn bí wọ́n ṣe ń ṣiṣẹ́. Ṣùgbọ́n ọkùnrin tí ń fọn ìpè dúró pẹ̀lú mi.
Deoarece cei care construiau, fiecare își avea sabia lui încinsă la șold și astfel construia. Și cel care suna din trâmbiță era lângă mine.
19 Nígbà náà ni mo sọ fún àwọn ọlọ́lá, àwọn ìjòyè àti àwọn ènìyàn tókù pé, “Iṣẹ́ náà fẹ̀ ó sì pọ̀, a sì ti jìnnà sí ara wa púpọ̀ lórí odi.
Și am spus nobililor și conducătorilor și restului poporului: Lucrarea este mare și întinsă și noi suntem împrăștiați pe zid, departe unul de altul.
20 Níbikíbi tí ẹ bá ti gbọ́ ohùn ìpè, ẹ da ara pọ̀ mọ́ wa níbẹ̀. Ọlọ́run wa yóò jà fún wa!”
Oriunde veți auzi sunetul trâmbiței, să vă adunați într-acolo la noi; Dumnezeul nostru va lupta pentru noi.
21 Bẹ́ẹ̀ ni àwa ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú àwọn ìdajì ènìyàn tí ó di ọ̀kọ̀ mú, láti òwúrọ̀ kùtùkùtù títí di ìgbà tí ìràwọ̀ yóò fi yọ.
Astfel noi munceam în lucrare; și jumătate din ei purtau sulițele de la ridicarea dimineții până când stelele apăreau.
22 Ní ìgbà náà mo tún sọ fún àwọn ènìyàn pé, “Jẹ́ kí olúkúlùkù ènìyàn àti olùrànlọ́wọ́ rẹ̀ dúró ní Jerusalẹmu ní òru, nítorí kí wọn le jẹ́ ẹ̀ṣọ́ fún wa ní òru, kí wọn sì le ṣe iṣẹ́ ní ọ̀sán.”
Tot astfel în acel timp am spus poporului: Fiecare cu servitorul său să găzduiască în Ierusalim, ca noaptea să ne fie gardă, și ziua să muncească.
23 Bẹ́ẹ̀ ni èmi àti àwọn arákùnrin mi àti àwọn ènìyàn mi àti àwọn ẹ̀ṣọ́ tí ó wà pẹ̀lú mi kò bọ́ aṣọ wa, olúkúlùkù wa ní ohun ìjà tirẹ̀, kódà nígbà tí wọ́n bá ń lọ pọn omi.
Astfel nici eu, nici frații mei, nici servitorii mei, nici bărbații de gardă care mă urmau, niciunul dintre noi nu ne-am dezbrăcat de hainele noastre, fiecare se dezbrăca doar pentru spălare.

< Nehemiah 4 >