< Nehemiah 4 >

1 Nígbà tí Sanballati gbọ́ pé àwa ń tún odi náà mọ, ó bínú, ó sì bínú púpọ̀. Ó fi àwọn ará Júù ṣe ẹlẹ́yà,
Kwathi uSanibhalathi esizwa ukuthi sasiwuvusa umduli, wazonda waze wagcwalelana. Wabahleka ulunya amaJuda,
2 ó sọ níwájú àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ àti níwájú àwọn ọmọ-ogun Samaria pé, “Kí ni àwọn aláìlera Júù wọ̀nyí ń ṣe yìí? Ṣé wọn yóò mú odi wọn padà ni? Ṣé wọn yóò rú ẹbọ ni? Ṣé wọn yóò parí i rẹ̀ lóòjọ́ ni bí? Ṣé wọ́n lè mú òkúta tí a ti sun láti inú òkìtì padà bọ̀ sípò tí ó jóná bí wọ́n ṣe wà?”
wasesithi phambi kwabakhula bakhe lebutho laseSamariya, “OkungamaJuda lokhu kuthi kwenzani kambe? Kungawuvusa umduli wakho na? Kuzayenza imihlatshelo na? Kuzawuqeda ngalanga linye? Kungakubuyisa na ukuphila ematsheni lawana azinqwaba zengcekeza etshe kanjeyana?”
3 Tobiah ará Ammoni, ẹni tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, wí pé, “Ohun tí wọ́n ń mọ—bí kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ lásán bá gùn ún sókè, yóò fọ́ odi òkúta wọn lulẹ̀!”
UThobhiya umʼAmoni, owayeseceleni kwakhe wathi, “Lokhu abakwakhayo, loba nje ikhanka lingakhwela phezu kwakho, lingawudiliza umduli wabo wamatshe!”
4 Gbọ́ ti wa, Ọlọ́run wa, nítorí àwa di ẹni ẹ̀gàn. Dá ẹ̀gàn wọn padà sórí ara wọn. Kí o sì fi wọ́n fún ìkógun ní ilẹ̀ ìgbèkùn.
Sizwe, Oh Nkulunkulu wethu, ngoba siyeyiswa. Phindisela kubo emakhanda izithuko zabo. Banikele babe yimpango elizweni lobugqili.
5 Má ṣe bo ẹ̀bi wọn tàbí wẹ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wọn nù kúrò níwájú rẹ, nítorí wọ́n mú ọ bínú níwájú àwọn ọ̀mọ̀lé.
Ungaligubuzeli icala labo kumbe wesule izono zabo emehlweni akho, ngoba bebehlambaza abakhi.
6 Bẹ́ẹ̀ ni àwa mọ odi náà títí gbogbo rẹ̀ fi dé ìdajì gíga rẹ̀, nítorí àwọn ènìyàn ṣiṣẹ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn an wọn.
Ngakho sawakha umduli wonke waze waphakama okufika ingxenye yobude bawo, ngoba abantu basebenza ngenhliziyo yabo yonke.
7 Ṣùgbọ́n nígbà tí Sanballati, Tobiah, àwọn ará Arabia, ará Ammoni, àti àwọn ènìyàn Aṣdodu gbọ́ pé àtúnṣe odi Jerusalẹmu ti ga dé òkè àti pé a ti mọ àwọn ibi tí ó yá dí, inú bí wọn gidigidi.
Kodwa kwathi ukuba uSanibhalathi, loThobhiya, lama-Arabhu, lama-Amoni lamadoda ase-Ashidodi besizwa ukuthi ukuvuselelwa kwemiduli yaseJerusalema kwasekuqhubekile njalo lezikhala zazivalwa bazonda kakhulu.
8 Gbogbo wọn jọ gbìmọ̀ pọ̀ láti wá bá Jerusalẹmu jà àti láti dìde wàhálà sí í.
Baceba ukuba beze bazohlasela iJerusalema bavuse uthuli kulo.
9 Ṣùgbọ́n àwa gbàdúrà sí Ọlọ́run wa, a sì yan olùṣọ́ ọ̀sán àti ti òru láti kojú ìhàlẹ̀ yìí.
Kodwa sakhuleka kuNkulunkulu wethu sabeka abalindi emini lebusuku ukuthi balindele lokhukuhlaselwa.
10 Lákòókò yìí, àwọn ènìyàn Juda wí pé, “Agbára àwọn òṣìṣẹ́ ti dínkù, àlàpà púpọ̀ ni ó wà tó bẹ́ẹ̀ tí àwa kò fi le è mọ odi náà.”
Kusenjalo, abantu bakoJuda bathi, “Amandla abasebenzi asededa, ikanti izibi zisezinengi okokuthi siyehluleka ukuqhubeka ngokwakha umduli.”
11 Bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn ọ̀tá wa wí pé, “Kí wọn tó mọ̀ tàbí kí wọn tó rí wa, àwa yóò ti dé àárín wọn, a ó sì pa wọ́n, a ó sì dá iṣẹ́ náà dúró.”
Izitha zethu lazo zathi, “Besalibele nje futhi bengakasiboni, bazaqabuka sesiphakathi kwabo sesibabulala siwuphethe lumsebenzi.”
12 Nígbà náà ni àwọn Júù tí ó ń gbé ní ẹ̀gbẹ́ wọn wá sọ fún wa ní ìgbà mẹ́wàá pé, “Ibikíbi tí ẹ̀yin bá padà sí, wọn yóò kọlù wá.”
Kwasekusithi amaJuda ababehlala eduze labo beza bazasitshela baphindaphinda besithi, “Lingaze liqonde ngaphi bazalihlasela kuphela.”
13 Nítorí náà mo dá ènìyàn díẹ̀ dúró níbi tí ó rẹlẹ̀ jù lẹ́yìn odi ní ibi gbangba, mo fi wọ́n síbẹ̀ nípa àwọn ìdílé wọn, pẹ̀lú àwọn idà wọn, àwọn ọ̀kọ̀ wọn àti àwọn ọrun wọn.
Ngasengimisa abanye abantu ngezimuli zabo ezindaweni lapho umduli owawuphansi khona, ezazingeneka lula, behlomile ngezinkemba, lemikhonto langemitshoko.
14 Lẹ́yìn ìgbà tí mo wo àwọn nǹkan yíká, mo dìde mo sì wí fún àwọn ọlọ́lá àwọn ìjòyè àti àwọn ènìyàn tókù pé, “Ẹ má ṣe bẹ̀rù u wọn. Ẹ rántí Olúwa, ẹni tí ó tóbi, tí ó sì ní ẹ̀rù, kí ẹ sì jà fún àwọn arákùnrin yín, àwọn ọmọkùnrin yín, àwọn ọmọbìnrin yín, àwọn ìyàwó yín àti àwọn ilé yín.”
Ngemva kokuba sengiwuhlolisisile wonke umumo, ngasukuma ngathi ezikhulwini, lezinduna lakubantu bonke jikelele, “Lingabesabi. Khumbulani uThixo, omkhulu owesabekayo, lilwele abafowenu, amadodana lamadodakazi enu, abafazi benu lemizi yenu.”
15 Nígbà tí àwọn ọ̀tá wa gbọ́ pé àwa ti mọ èrò wọn àti wí pé Ọlọ́run ti bà á jẹ́, gbogbo wa padà sí ibi odi, ẹnìkọ̀ọ̀kan sí ibi iṣẹ́ tirẹ̀.
Kwathi izitha zethu sezizwile ukuthi sasesilazi icebo lazo lokuthi uNkulunkulu wayeselifubisile, sonke sabuyela kuwo umduli, ngulowo kowakhe umsebenzi.
16 Láti ọjọ́ náà lọ, ìdajì àwọn ènìyàn ń ṣe iṣẹ́ náà, nígbà tí àwọn ìdajì tókù múra pẹ̀lú ọ̀kọ̀, asà, ọrun àti ìhámọ́ra. Àwọn ìjòyè sì pín ara wọn sẹ́yìn gbogbo ènìyàn Juda.
Kusukela ngalelolanga, ingxenye yamadoda engangilawo yenza umsebenzi, enye ingxenye yahloma ngemikhonto, lamahawu, lemitshoko lamabhatshi ensimbi. Izinduna zazimisa ngemva kwabo bonke abantu bakoJuda
17 Àwọn ẹni tí ó ń mọ odi. Àwọn tí ń ru àwọn ohun èlò ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú ọwọ́ kan, wọ́n sì fi ọwọ́ kejì di ohun ìjà mú,
ababesakha umduli. Labo ababethwala izinto zokwakha babesenza umsebenzi ngesandla esisodwa ngesinye umuntu ephethe isikhali,
18 olúkúlùkù àwọn ọ̀mọ̀lé fi idà wọn sí ẹ̀gbẹ́ wọn bí wọ́n ṣe ń ṣiṣẹ́. Ṣùgbọ́n ọkùnrin tí ń fọn ìpè dúró pẹ̀lú mi.
njalo ngulowo lalowo umakhi wayehlome inkemba ilengiswe eceleni kwakhe nxa esebenza. Kodwa indoda yokutshaya icilongo yahlala ikimi.
19 Nígbà náà ni mo sọ fún àwọn ọlọ́lá, àwọn ìjòyè àti àwọn ènìyàn tókù pé, “Iṣẹ́ náà fẹ̀ ó sì pọ̀, a sì ti jìnnà sí ara wa púpọ̀ lórí odi.
Ngasengisithi ezikhulwini, lezinduna lakubantu bonke jikelele, “Umsebenzi ubanzi usabalele, njalo sehlukene kakhulu omunye komunye kulandela umduli.
20 Níbikíbi tí ẹ bá ti gbọ́ ohùn ìpè, ẹ da ara pọ̀ mọ́ wa níbẹ̀. Ọlọ́run wa yóò jà fún wa!”
Lingezwa ingabe kungaphi okukhala khona icilongo, phuthumani khona lize kithi. UNkulunkulu wethu uzasilwela!”
21 Bẹ́ẹ̀ ni àwa ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú àwọn ìdajì ènìyàn tí ó di ọ̀kọ̀ mú, láti òwúrọ̀ kùtùkùtù títí di ìgbà tí ìràwọ̀ yóò fi yọ.
Yikho sawuqhuba umsebenzi ingxenye yamadoda ihlomile ngemikhonto, kusukela emathathakusa kuze kuphume izinkanyezi.
22 Ní ìgbà náà mo tún sọ fún àwọn ènìyàn pé, “Jẹ́ kí olúkúlùkù ènìyàn àti olùrànlọ́wọ́ rẹ̀ dúró ní Jerusalẹmu ní òru, nítorí kí wọn le jẹ́ ẹ̀ṣọ́ fún wa ní òru, kí wọn sì le ṣe iṣẹ́ ní ọ̀sán.”
Ngasonaleso isikhathi ngabuye ngathi ebantwini, “Akuthi yonke indoda kanye lomsizi wayo balale ngaphakathi kweJerusalema ebusuku, ukuze babengabalindi bethu ebusuku, babe ngabasebenzi emini.”
23 Bẹ́ẹ̀ ni èmi àti àwọn arákùnrin mi àti àwọn ènìyàn mi àti àwọn ẹ̀ṣọ́ tí ó wà pẹ̀lú mi kò bọ́ aṣọ wa, olúkúlùkù wa ní ohun ìjà tirẹ̀, kódà nígbà tí wọ́n bá ń lọ pọn omi.
Mina labafowethu, lamadoda ayelami, labalindi ababelami kasizange sihlubule izigqoko zethu; ngulowo waphatha isikhali sakhe loba engena emanzini.

< Nehemiah 4 >