< Nehemiah 4 >

1 Nígbà tí Sanballati gbọ́ pé àwa ń tún odi náà mọ, ó bínú, ó sì bínú púpọ̀. Ó fi àwọn ará Júù ṣe ẹlẹ́yà,
Rĩrĩa Sanibalati aaiguire atĩ nĩtwakaga rũthingo rĩngĩ, akĩrakara na agĩthirĩka mũno. Agĩthekerera Ayahudi,
2 ó sọ níwájú àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ àti níwájú àwọn ọmọ-ogun Samaria pé, “Kí ni àwọn aláìlera Júù wọ̀nyí ń ṣe yìí? Ṣé wọn yóò mú odi wọn padà ni? Ṣé wọn yóò rú ẹbọ ni? Ṣé wọn yóò parí i rẹ̀ lóòjọ́ ni bí? Ṣé wọ́n lè mú òkúta tí a ti sun láti inú òkìtì padà bọ̀ sípò tí ó jóná bí wọ́n ṣe wà?”
na arĩ mbere ya athiritũ ake na mbũtũ cia ita cia Samaria, akiuga atĩrĩ, “Ayahudi aya ahinyaru-rĩ, nĩ kĩĩ mareka? Nĩmegũcookereria rũthingo rwao? Nĩmekũruta magongona? Nĩmekũrĩkia wĩra ũyũ na mũthenya ũmwe? Maahota gũtũma mahiga macooke muoyo kuuma hĩba-inĩ ici cia mahuti maya mahĩĩte ũũ wothe?”
3 Tobiah ará Ammoni, ẹni tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, wí pé, “Ohun tí wọ́n ń mọ—bí kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ lásán bá gùn ún sókè, yóò fọ́ odi òkúta wọn lulẹ̀!”
Tobia ũrĩa Mũamoni, ũrĩa warĩ mwena wake, akiuga atĩrĩ, “Rũthingo rũu rwa mahiga maraaka-rĩ, o na mbwe ĩngĩrũhaica no ĩrũmomore!”
4 Gbọ́ ti wa, Ọlọ́run wa, nítorí àwa di ẹni ẹ̀gàn. Dá ẹ̀gàn wọn padà sórí ara wọn. Kí o sì fi wọ́n fún ìkógun ní ilẹ̀ ìgbèkùn.
No rĩrĩ, Wee Ngai witũ tũthikĩrĩrie, tondũ tũrĩ andũ anyarare. Garũra irumi icio ciao imacookerere. Maneane ta matahĩtwo bũrũri-inĩ wa ũkombo.
5 Má ṣe bo ẹ̀bi wọn tàbí wẹ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wọn nù kúrò níwájú rẹ, nítorí wọ́n mú ọ bínú níwájú àwọn ọ̀mọ̀lé.
Ndũkahithĩrĩre mahĩtia mao kana weherie mehia mao kuuma ũthiũ-inĩ waku, nĩgũkorwo nĩmarumĩte andũ arĩa maraaka.
6 Bẹ́ẹ̀ ni àwa mọ odi náà títí gbogbo rẹ̀ fi dé ìdajì gíga rẹ̀, nítorí àwọn ènìyàn ṣiṣẹ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn an wọn.
Nĩ ũndũ ũcio tũgĩaka rũthingo rũu rĩngĩ o nginya ruothe rũgĩkinya nuthu ya ũraihu waruo, nĩgũkorwo andũ acio maarutire wĩra na ngoro cia kwĩyendera.
7 Ṣùgbọ́n nígbà tí Sanballati, Tobiah, àwọn ará Arabia, ará Ammoni, àti àwọn ènìyàn Aṣdodu gbọ́ pé àtúnṣe odi Jerusalẹmu ti ga dé òkè àti pé a ti mọ àwọn ibi tí ó yá dí, inú bí wọn gidigidi.
No hĩndĩ ĩrĩa Sanibalati, na Tobia, na Aarabu, na Aamoni, na andũ a Ashidodi maiguire atĩ thingo cia Jerusalemu nĩciathiiaga na mbere gũcookererio na atĩ mĩanya nĩyathingagwo-rĩ, makĩrakara mũno.
8 Gbogbo wọn jọ gbìmọ̀ pọ̀ láti wá bá Jerusalẹmu jà àti láti dìde wàhálà sí í.
Magĩthiĩ ndundu marĩ othe, magĩciira ũrĩa megũka mahũũrane na Jerusalemu, na mambĩrĩrie ngũĩ kuo.
9 Ṣùgbọ́n àwa gbàdúrà sí Ọlọ́run wa, a sì yan olùṣọ́ ọ̀sán àti ti òru láti kojú ìhàlẹ̀ yìí.
No nĩtwahooire Ngai witũ na tũkĩiga arangĩri a gũtũgitĩra mũthenya na ũtukũ nĩ ũndũ nĩtwehĩtĩirwo.
10 Lákòókò yìí, àwọn ènìyàn Juda wí pé, “Agbára àwọn òṣìṣẹ́ ti dínkù, àlàpà púpọ̀ ni ó wà tó bẹ́ẹ̀ tí àwa kò fi le è mọ odi náà.”
O ihinda rĩu, andũ a Juda makiuga atĩrĩ, “Aruti a wĩra nĩmaroorwo nĩ hinya, na nĩ kũrĩ na mahuti maingĩ mũno matangĩreka twake rũthingo rũu rĩngĩ.”
11 Bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn ọ̀tá wa wí pé, “Kí wọn tó mọ̀ tàbí kí wọn tó rí wa, àwa yóò ti dé àárín wọn, a ó sì pa wọ́n, a ó sì dá iṣẹ́ náà dúró.”
O nacio thũ ciitũ ikiuga atĩrĩ, “Mũira wa mamenye ũhoro kana matuone, tũgũkorwo hamwe nao, tũmoorage na tũtũme wĩra ũcio ũtige kũrutwo.”
12 Nígbà náà ni àwọn Júù tí ó ń gbé ní ẹ̀gbẹ́ wọn wá sọ fún wa ní ìgbà mẹ́wàá pé, “Ibikíbi tí ẹ̀yin bá padà sí, wọn yóò kọlù wá.”
Hĩndĩ ĩyo Ayahudi arĩa maatũũraga hakuhĩ na thũ icio magĩũka, magĩtwĩra maita ikũmi atĩrĩ, “O kũrĩa mũngĩũrĩra-rĩ, nĩmegũtũtharĩkĩra.”
13 Nítorí náà mo dá ènìyàn díẹ̀ dúró níbi tí ó rẹlẹ̀ jù lẹ́yìn odi ní ibi gbangba, mo fi wọ́n síbẹ̀ nípa àwọn ìdílé wọn, pẹ̀lú àwọn idà wọn, àwọn ọ̀kọ̀ wọn àti àwọn ọrun wọn.
Nĩ ũndũ ũcio ngĩiga andũ amwe na thuutha wa kũrĩa rũthingo rwarĩ thĩ mũno na gũtaarĩ na ũgitĩri; ngĩmaiga kũringana na nyũmba ciao marĩ na hiũ ciao cia njora, na matimũ, na mota.
14 Lẹ́yìn ìgbà tí mo wo àwọn nǹkan yíká, mo dìde mo sì wí fún àwọn ọlọ́lá àwọn ìjòyè àti àwọn ènìyàn tókù pé, “Ẹ má ṣe bẹ̀rù u wọn. Ẹ rántí Olúwa, ẹni tí ó tóbi, tí ó sì ní ẹ̀rù, kí ẹ sì jà fún àwọn arákùnrin yín, àwọn ọmọkùnrin yín, àwọn ọmọbìnrin yín, àwọn ìyàwó yín àti àwọn ilé yín.”
Ndaarĩkia kuona ũrĩa maũndũ maatariĩ, ngĩrũgama ngĩĩra andũ arĩa maarĩ igweta, na anene, na andũ arĩa angĩ atĩrĩ, “Mũtikametigĩre. Ririkanai Mwathani, o we ũrĩa mũnene na wa kũmakania, nĩguo mũrũĩrĩre ariũ a thoguo, na aanake anyu, na airĩtu anyu, na atumia anyu, o na mĩciĩ yanyu.”
15 Nígbà tí àwọn ọ̀tá wa gbọ́ pé àwa ti mọ èrò wọn àti wí pé Ọlọ́run ti bà á jẹ́, gbogbo wa padà sí ibi odi, ẹnìkọ̀ọ̀kan sí ibi iṣẹ́ tirẹ̀.
Rĩrĩa thũ ciitũ ciamenyire atĩ nĩtwamenyete ũhoro wa ndundu yao, na atĩ Ngai nĩarigĩrĩirie ũndũ ũcio, ithuothe tũgĩcooka rũthingo-inĩ, o mũndũ agĩthiĩ wĩra-inĩ wake.
16 Láti ọjọ́ náà lọ, ìdajì àwọn ènìyàn ń ṣe iṣẹ́ náà, nígbà tí àwọn ìdajì tókù múra pẹ̀lú ọ̀kọ̀, asà, ọrun àti ìhámọ́ra. Àwọn ìjòyè sì pín ara wọn sẹ́yìn gbogbo ènìyàn Juda.
Kuuma mũthenya ũcio nuthu ya andũ akwa nĩo maarutaga wĩra nayo nuthu ĩyo ĩngĩ yao makĩheo matimũ, na ngo, na mota, o na nguo cia kĩgera. Anene nao makĩrũgama thuutha wa andũ othe a Juda
17 Àwọn ẹni tí ó ń mọ odi. Àwọn tí ń ru àwọn ohun èlò ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú ọwọ́ kan, wọ́n sì fi ọwọ́ kejì di ohun ìjà mú,
arĩa maakaga rũthingo. Nao arĩa maakuuaga indo cia mwako maarutaga wĩra na guoko kũmwe, nakuo kũrĩa kũngĩ kũnyiitĩte kĩndũ kĩa mbaara,
18 olúkúlùkù àwọn ọ̀mọ̀lé fi idà wọn sí ẹ̀gbẹ́ wọn bí wọ́n ṣe ń ṣiṣẹ́. Ṣùgbọ́n ọkùnrin tí ń fọn ìpè dúró pẹ̀lú mi.
nake mwaki o wothe aikaraga eyohete rũhiũ rwake rwa njora njohero o akĩrutaga wĩra. No mũhuhi wa karumbeta aanjikaraga hakuhĩ.
19 Nígbà náà ni mo sọ fún àwọn ọlọ́lá, àwọn ìjòyè àti àwọn ènìyàn tókù pé, “Iṣẹ́ náà fẹ̀ ó sì pọ̀, a sì ti jìnnà sí ara wa púpọ̀ lórí odi.
Ningĩ ngĩĩra arĩa maarĩ igweta, na anene, na andũ arĩa angĩ atĩrĩ, “Wĩra nĩ mũingĩ mũno na ũgatambũrũka, na nĩtũraihanĩrĩirie mũno mũndũ na ũrĩa ũngĩ rũthingo-inĩ.
20 Níbikíbi tí ẹ bá ti gbọ́ ohùn ìpè, ẹ da ara pọ̀ mọ́ wa níbẹ̀. Ọlọ́run wa yóò jà fún wa!”
Rĩrĩa rĩothe mũngĩigua karumbeta kaahuhwo, mũũke harĩa tũrĩ. Ngai witũ nĩwe ũgũtũrũĩrĩra!”
21 Bẹ́ẹ̀ ni àwa ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú àwọn ìdajì ènìyàn tí ó di ọ̀kọ̀ mú, láti òwúrọ̀ kùtùkùtù títí di ìgbà tí ìràwọ̀ yóò fi yọ.
Nĩ ũndũ ũcio tũgĩthiĩ na mbere na kũruta wĩra, nuthu ya andũ ĩnyiitĩte matimũ kuuma rũciinĩ nginya njata cioneke hwaĩ-inĩ.
22 Ní ìgbà náà mo tún sọ fún àwọn ènìyàn pé, “Jẹ́ kí olúkúlùkù ènìyàn àti olùrànlọ́wọ́ rẹ̀ dúró ní Jerusalẹmu ní òru, nítorí kí wọn le jẹ́ ẹ̀ṣọ́ fún wa ní òru, kí wọn sì le ṣe iṣẹ́ ní ọ̀sán.”
Hĩndĩ o ĩyo ngĩĩra andũ atĩrĩ, “Reke o mũndũ na mũteithia wake maikarage Jerusalemu thĩinĩ ũtukũ, nĩgeetha matũtungatagĩre ta arangĩri ũtukũ, na mũthenya makaruta wĩra.”
23 Bẹ́ẹ̀ ni èmi àti àwọn arákùnrin mi àti àwọn ènìyàn mi àti àwọn ẹ̀ṣọ́ tí ó wà pẹ̀lú mi kò bọ́ aṣọ wa, olúkúlùkù wa ní ohun ìjà tirẹ̀, kódà nígbà tí wọ́n bá ń lọ pọn omi.
Niĩ mwene, kana ariũ a baba, kana andũ akwa, kana arangĩri arĩa maarĩ hamwe na niĩ gũtirĩ warutaga nguo; o mũndũ aakoragwo na indo ciake cia mbaara o na agĩthiĩ gũtaha maaĩ.

< Nehemiah 4 >