< Nehemiah 4 >

1 Nígbà tí Sanballati gbọ́ pé àwa ń tún odi náà mọ, ó bínú, ó sì bínú púpọ̀. Ó fi àwọn ará Júù ṣe ẹlẹ́yà,
Kuin Sanballat kuuli meidän muuria rakentavan, syttyi hän vihaan ja närkästyi sangen suuresti, ja häpäisi Juudalaisia,
2 ó sọ níwájú àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ àti níwájú àwọn ọmọ-ogun Samaria pé, “Kí ni àwọn aláìlera Júù wọ̀nyí ń ṣe yìí? Ṣé wọn yóò mú odi wọn padà ni? Ṣé wọn yóò rú ẹbọ ni? Ṣé wọn yóò parí i rẹ̀ lóòjọ́ ni bí? Ṣé wọ́n lè mú òkúta tí a ti sun láti inú òkìtì padà bọ̀ sípò tí ó jóná bí wọ́n ṣe wà?”
Ja puhui veljeinsä ja voimallisten edessä Samariassa ja sanoi: mitä nämät voimattomat Juudalaiset tekevät? pitääkö heille niin sallittaman? pitääkö heidän uhraaman? pitääkö heidän sen täyttämän yhtenä päivänä? pitääkö heidän kiviä eläväksi tekemän, jotka ovat tuhkaläjä ja palaneet?
3 Tobiah ará Ammoni, ẹni tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, wí pé, “Ohun tí wọ́n ń mọ—bí kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ lásán bá gùn ún sókè, yóò fọ́ odi òkúta wọn lulẹ̀!”
Ja Tobia Ammonilainen sanoi hänen jälkeensä: rakentakoot vapaasti; jos ketut sinne menisivät, niin he kyllä jaottaisivat heidän kivimuurinsa.
4 Gbọ́ ti wa, Ọlọ́run wa, nítorí àwa di ẹni ẹ̀gàn. Dá ẹ̀gàn wọn padà sórí ara wọn. Kí o sì fi wọ́n fún ìkógun ní ilẹ̀ ìgbèkùn.
Kuule meidän Jumalamme, kuinka me olemme katsotut ylön, ja käännä heidän häväistyksensä heidän päänsä päälle, ja saata heitä häpiään vankeuden maassa.
5 Má ṣe bo ẹ̀bi wọn tàbí wẹ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wọn nù kúrò níwájú rẹ, nítorí wọ́n mú ọ bínú níwájú àwọn ọ̀mọ̀lé.
Älä peitä heidän pahoja tekojansa ja älä pyyhi heidän syntiänsä kasvois edestä; sillä he ovat vihan matkaan saattaneet, rakentajain läsnäollessa.
6 Bẹ́ẹ̀ ni àwa mọ odi náà títí gbogbo rẹ̀ fi dé ìdajì gíga rẹ̀, nítorí àwọn ènìyàn ṣiṣẹ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn an wọn.
Mutta me rakensimme muurin ja panimme hänen kaiketi yhteen hamaan puoliväliin asti; ja kansa sai sydämen työtä tehdäksensä.
7 Ṣùgbọ́n nígbà tí Sanballati, Tobiah, àwọn ará Arabia, ará Ammoni, àti àwọn ènìyàn Aṣdodu gbọ́ pé àtúnṣe odi Jerusalẹmu ti ga dé òkè àti pé a ti mọ àwọn ibi tí ó yá dí, inú bí wọn gidigidi.
Kuin Sanballat ja Tobia ja Arabialaiset ja Ammonilaiset ja Asdodilaiset kuulivat Jerusalemin muurit korotetuksi, ja ruvetuksi haljenneita parantamaan, vihastuivat he sangen suuresti.
8 Gbogbo wọn jọ gbìmọ̀ pọ̀ láti wá bá Jerusalẹmu jà àti láti dìde wàhálà sí í.
Ja he kaikki tekivät liiton keskenänsä tullaksensa sotimaan Jerusalemia vastaan, ja tekemään heille kapinaa.
9 Ṣùgbọ́n àwa gbàdúrà sí Ọlọ́run wa, a sì yan olùṣọ́ ọ̀sán àti ti òru láti kojú ìhàlẹ̀ yìí.
Mutta me rukoilimme meidän Jumalaamme ja panimme vartiat öin ja päivin heitä vastaan, heidän tähtensä.
10 Lákòókò yìí, àwọn ènìyàn Juda wí pé, “Agbára àwọn òṣìṣẹ́ ti dínkù, àlàpà púpọ̀ ni ó wà tó bẹ́ẹ̀ tí àwa kò fi le è mọ odi náà.”
Ja Juuda sanoi: kantajain voima on heikoksi tullut ja multaa on niin paljo, ettemme saa rakentaa muuria.
11 Bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn ọ̀tá wa wí pé, “Kí wọn tó mọ̀ tàbí kí wọn tó rí wa, àwa yóò ti dé àárín wọn, a ó sì pa wọ́n, a ó sì dá iṣẹ́ náà dúró.”
Ja meidän vihollisemme sanoivat: ei heidän pidä tietämän eli näkemän, ennenkuin me olemme juuri heidän keskellänsä, tapamme heidät ja estämme työn.
12 Nígbà náà ni àwọn Júù tí ó ń gbé ní ẹ̀gbẹ́ wọn wá sọ fún wa ní ìgbà mẹ́wàá pé, “Ibikíbi tí ẹ̀yin bá padà sí, wọn yóò kọlù wá.”
Ja kuin ne Juudalaiset, jotka heidän tykönänsä asuivat, tulivat ja sanoivat meille kymmenen kertaa: joka paikasta te vielä meidän tykömme palajatte;
13 Nítorí náà mo dá ènìyàn díẹ̀ dúró níbi tí ó rẹlẹ̀ jù lẹ́yìn odi ní ibi gbangba, mo fi wọ́n síbẹ̀ nípa àwọn ìdílé wọn, pẹ̀lú àwọn idà wọn, àwọn ọ̀kọ̀ wọn àti àwọn ọrun wọn.
Niin minä lähetin kansan alas muurin taa tuiviin paikkoihin, heidän sukukuntainsa jälkeen, miekkoinensa, keihäinensä ja joutsinensa.
14 Lẹ́yìn ìgbà tí mo wo àwọn nǹkan yíká, mo dìde mo sì wí fún àwọn ọlọ́lá àwọn ìjòyè àti àwọn ènìyàn tókù pé, “Ẹ má ṣe bẹ̀rù u wọn. Ẹ rántí Olúwa, ẹni tí ó tóbi, tí ó sì ní ẹ̀rù, kí ẹ sì jà fún àwọn arákùnrin yín, àwọn ọmọkùnrin yín, àwọn ọmọbìnrin yín, àwọn ìyàwó yín àti àwọn ilé yín.”
Ja minä katselin ja valmistin itseni, ja sanoin ylimmäisille ja päämiehille, ja muulle kansalle: älkäät peljätkö heitä, muistakaat suurta ja peljättävää Herraa, ja sotikaat teidän veljeinne, poikainne, tytärtenne, emäntäinne ja kotonne edestä.
15 Nígbà tí àwọn ọ̀tá wa gbọ́ pé àwa ti mọ èrò wọn àti wí pé Ọlọ́run ti bà á jẹ́, gbogbo wa padà sí ibi odi, ẹnìkọ̀ọ̀kan sí ibi iṣẹ́ tirẹ̀.
Mutta kuin meidän vihollisemme sen kuulivat, että me olimme tietää saaneet, niin Jumala teki heidän neuvonsa tyhjäksi: ja me palasimme kaikki muurin tykö, jokainen työhönsä.
16 Láti ọjọ́ náà lọ, ìdajì àwọn ènìyàn ń ṣe iṣẹ́ náà, nígbà tí àwọn ìdajì tókù múra pẹ̀lú ọ̀kọ̀, asà, ọrun àti ìhámọ́ra. Àwọn ìjòyè sì pín ara wọn sẹ́yìn gbogbo ènìyàn Juda.
Ja tapahtui siitä päivästä, että toinen puoli nuoria miehiäni teki työtä, ja toinen puoli piti keihäitä, kilpiä, joutsia ja rautapaitoja. Ja päämiehet seisoivat koko Juudan huoneen takana.
17 Àwọn ẹni tí ó ń mọ odi. Àwọn tí ń ru àwọn ohun èlò ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú ọwọ́ kan, wọ́n sì fi ọwọ́ kejì di ohun ìjà mú,
Ne, jotka rakensivat muuria ja kantoivat kuormia, ja jotka sälyttivät, yhdellä kädellä he tekivät työtä ja toisessa pitivät aseen.
18 olúkúlùkù àwọn ọ̀mọ̀lé fi idà wọn sí ẹ̀gbẹ́ wọn bí wọ́n ṣe ń ṣiṣẹ́. Ṣùgbọ́n ọkùnrin tí ń fọn ìpè dúró pẹ̀lú mi.
Ja jokaisella joka siellä rakensi, oli miekka sidottu vyölle, ja niin he rakensivat. Ja se joka soitti vaskitorvea, oli minun tykönäni.
19 Nígbà náà ni mo sọ fún àwọn ọlọ́lá, àwọn ìjòyè àti àwọn ènìyàn tókù pé, “Iṣẹ́ náà fẹ̀ ó sì pọ̀, a sì ti jìnnà sí ara wa púpọ̀ lórí odi.
Ja minä sanoin ylimmäisille ja päämiehille ja muulle kansalle: työ on suuri ja avara, ja me olemme hajalla muurin päällä, kaukana toinen toisestamme;
20 Níbikíbi tí ẹ bá ti gbọ́ ohùn ìpè, ẹ da ara pọ̀ mọ́ wa níbẹ̀. Ọlọ́run wa yóò jà fún wa!”
Millä paikalla te kuulette vaskitorven äänen, tulkaat sinne kokoon meidän tykömme: meidän Jumalamme sotii meidän edestämme.
21 Bẹ́ẹ̀ ni àwa ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú àwọn ìdajì ènìyàn tí ó di ọ̀kọ̀ mú, láti òwúrọ̀ kùtùkùtù títí di ìgbà tí ìràwọ̀ yóò fi yọ.
Niin tehkäämme siis työtä; ja toinen puoli heistä piti keihäitä päivän koittamasta niin siihen saakka, että tähdet näkyivät.
22 Ní ìgbà náà mo tún sọ fún àwọn ènìyàn pé, “Jẹ́ kí olúkúlùkù ènìyàn àti olùrànlọ́wọ́ rẹ̀ dúró ní Jerusalẹmu ní òru, nítorí kí wọn le jẹ́ ẹ̀ṣọ́ fún wa ní òru, kí wọn sì le ṣe iṣẹ́ ní ọ̀sán.”
Ja minä myös sanoin siihen aikaan kansalle: jokainen olkaan yötä palveliainsa kanssa keskellä Jerusalemia, niin että me yöllä ottaisimme vaarin vartiosta ja päivällä työstä.
23 Bẹ́ẹ̀ ni èmi àti àwọn arákùnrin mi àti àwọn ènìyàn mi àti àwọn ẹ̀ṣọ́ tí ó wà pẹ̀lú mi kò bọ́ aṣọ wa, olúkúlùkù wa ní ohun ìjà tirẹ̀, kódà nígbà tí wọ́n bá ń lọ pọn omi.
Mutta minä ja minun veljeni, ja minun palveliani ja vartiat, jotka minua seurasivat, emme riisuneet vaatteitamme; ja jokaisella oli hänen aseensa ja vesi.

< Nehemiah 4 >